< 2 Samuel 19 >

1 A sì rò fún Joabu pe, “Wò ó, ọba ń sọkún, ó sì ń gbààwẹ̀ fún Absalomu.”
Siangpahrang teh Absalom hanelah a khui a ka tie Joab koe a dei pouh awh.
2 Ìṣẹ́gun ọjọ́ náà sì di àwẹ̀ fún gbogbo àwọn ènìyàn náà, nítorí àwọn ènìyàn náà gbọ́ ní ọjọ́ náà bí inú ọba ti bàjẹ́ nítorí ọmọ rẹ̀.
Hot hnin e tânae teh tami pueng hanelah lungmathoe nahanelah doeh ao. Siangpahrang ni a capa pou a khuikakhai tie hah a thai awh.
3 Àwọn ènìyàn náà sì yọ́ lọ sí ìlú ní ọjọ́ náà gẹ́gẹ́ bí àwọn bí ènìyàn tí a dójútì ṣe máa ń yọ́ lọ nígbà tí wọ́n bá sá lójú ìjà.
Tarantuknae koehoi ka yawng e naw ni kayanae lahoi khothung duem a kâen awh e patetlah hot hnin navah arulahoi khothung duem a kâen awh.
4 Ọba sì bo ojú rẹ̀, ọba sì kígbe ní ohùn rara pé, “Á à! Ọmọ mi Absalomu! Absalomu ọmọ mi, ọmọ mi!”
Siangpahrang ni a minhmai a ramuk teh, Oe ka capa Absalom, Oe Absalom, ka capa, ka capa telah kacaipounglah a khuika.
5 Joabu sì wọ inú ilé tọ ọba lọ, ó sì wí pé, “Ìwọ dójúti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ lónìí, àwọn tí ó gba ẹ̀mí rẹ̀ là lónìí, àti ẹ̀mí àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àti ti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, àti àwọn aya rẹ̀, àti ẹ̀mí àwọn obìnrin rẹ.
Joab ni siangpahrang koe a cei teh, imthungkhu a kâen, na hringnae na canu na capa a hringnae hoi na yu hoi na yudonaw a hringnae karungngangnaw hah sahnin vah na kaya sak awh toe.
6 Nítorí pé ìwọ fẹ́ àwọn ọ̀tá rẹ, ìwọ sì kórìíra àwọn ọ̀rẹ́ rẹ. Nítorí tí ìwọ wí lónìí pé, Ìwọ kò náání àwọn ọmọ ọba tàbí àwọn ìránṣẹ́; èmi sì rí lónìí pé, ìbá ṣe pé Absalomu wà láààyè, kí gbogbo wa sì kú lónìí, ǹjẹ́ ìbá dùn mọ́ ọ gidigidi.
Nang na kamaithoenaw lung na pataw teh, nang lungpataw naw law teh na maithoe toe. Bangkongtetpawiteh, kacuenaw hoi ransanaw teh nama hanelah bang hoeh lah sahnin na kamnue sak. Absalom hring pawiteh, kaimanaw hah sahnin be kadout awh pawiteh, na lung a hawi han doeh telah sahnin ka hmunae lah ao atipouh.
7 Sì dìde nísinsin yìí, lọ, kí o sì sọ̀rọ̀ ìtùnú fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, nítorí pé èmi fi Olúwa búra, bí ìwọ kò bá lọ, ẹnìkan kì yóò bá ọ dúró ni alẹ́ yìí, èyí ni yóò sì burú fún ọ ju gbogbo ibi tí ojú rẹ ti ń rí láti ìgbà èwe rẹ wá títí ó fi di ìsinsin yìí.”
Thaw nateh alawilah tâcawt nateh, na sannaw hnâroumnae lawk dei pouh leih. Na tâcawt hoehpawiteh, tami buet touh hai atu tangmin nang koe kaawm awh mahoeh toe. Hote hno teh na nawca hoi sahnin totouh nang dawk kaawm e hlak hoe kathout han, telah BAWIPA thoebo laihoi ka dei telah atipouh.
8 Ọba sì dìde, ó sì jókòó ní ẹnu-ọ̀nà, wọ́n sì wí fún gbogbo àwọn ènìyàn náà pé, “Wò ó, ọba jókòó ní ẹnu-ọ̀nà.” Gbogbo ènìyàn sì wá sí iwájú ọba. Nítorí pé, Israẹli ti sá, olúkúlùkù sí àgọ́ rẹ̀.
Siangpahrang teh a thaw teh, rapan longkha koe a tahung. Siangpahrang rapan longkha koe a tahung e taminaw ni a thai awh toteh, ahni koe a cei awh. Isarelnaw teh amamae rim koelah be a kâran awh.
9 Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì ń bà ara wọn jà nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli, pé, “Ọba ti gbà wá là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, ó sì ti gbà wá kúrò lọ́wọ́ àwọn Filistini; òun sì wá sá kúrò ní ìlú nítorí Absalomu.
Isarel miphunnaw dawk buet touh hoi buet touh kâounnae ao. Siangpahrang ni taran kut dawk hoi na rungngang. Filistinnaw e kut dawk thung hoi na rungngang. Atuvah Absalom kecu dawk ram thung hoi a yawng.
10 Absalomu, tí àwa fi jẹ ọba lórí wa sì kú ní ogun, ǹjẹ́ èéṣe tí ẹ̀yin fi dákẹ́ tí ẹ̀yin kò sì sọ̀rọ̀ kan láti mú ọba padà wá?”
Maimouh ni satui awi awh e Absalom teh tarantuknae koe a due toe. Bangkongmaw siangpahrang bout bankhai awh hane na dei awh hoeh. Bangkong lawkkamuem lah na o awh telah a kâpakung awh.
11 Dafidi ọba sì ránṣẹ́ sí Sadoku, àti sí Abiatari àwọn àlùfáà pé, “Sọ fún àwọn àgbàgbà Juda, pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin fi kẹ́yìn láti mú ọba padà wá sí ilé rẹ̀? Ọ̀rọ̀ gbogbo Israẹli sì ti dé ọ̀dọ̀ ọba àní ní ilé rẹ̀.
Siangpahrang Devit ni vaihma Zadok hoi Abiathar koe, Judah kacuenaw koe bangkongmaw siangpahrang hah a im lah ceisak hane, bangkong hnuk na teng awh. Isarelnaw ni a dei awh e lawk patenghai siangpahrang koe a pha teh a thai toe.
12 Ẹ̀yin ni ara mi, ẹ̀yin ni egungun mi, àti ẹran-ara mi: èéṣì ti ṣe tí ẹ̀yin fi kẹ́yìn láti mú ọba padà wá.’
Nangmanaw teh ka hmaunawngha ka hru, ka tak doeh. Siangpahrang koe bout thaisak hane hah bangkong hnuk na teng awh.
13 Kí ẹ̀yin sì wí fún Amasa pé, ‘Egungun àti ẹran-ara mi kọ́ ni ìwọ jẹ́ bí? Kí Ọlọ́run ó ṣe bẹ́ẹ̀ sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí ìwọ kò ba ṣe olórí ogun níwájú mi títí, ní ipò Joabu.’”
Amasa koevah, nang hah kaie ka hru, ka tak lah na awm hoeh maw. Joab yueng lah ka hmaitung ransabawi lah na awm sak hoehpawiteh, Cathut ni ahawi ati e patetlah kai dawk sak naseh, telah dei pouh awh, telah tami a patoun.
14 Òun sì yí gbogbo àwọn ọkùnrin Juda lọ́kàn padà àní bí ọkàn ènìyàn kan; wọ́n sì ránṣẹ́ sí ọba, pé, “Ìwọ padà àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ.”
Hottelah Judah miphunnaw hah lungthin buet touh e patetlah ao sak. Siangpahrang koevah, a taminaw hoi ban awh telah dei pouh hanelah taminaw hah a patoun.
15 Ọba sì padà, o sì wá sí odò Jordani. Juda sì wá sí Gilgali láti lọ pàdé ọba, àti láti mú ọba kọjá odò Jordani.
Siangpahrang teh a ban teh, Jordan tui koe a pha. Judahnaw ni siangpahrang a dawn awh teh, Jordan tui namran lah thak hanelah Gilgal kho koelah a cei awh.
16 Ṣimei ọmọ Gera, ará Benjamini ti Bahurimu, ó yára ó sì bá àwọn ọkùnrin Juda sọ̀kalẹ̀ láti pàdé Dafidi ọba.
Benjamin miphun Bahurim kho e tami Gera capa Shimei teh karanglah siangpahrang dawn hanelah Judahnaw koe a cei van.
17 Ẹgbẹ̀rún ọmọkùnrin sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀ nínú àwọn ọmọkùnrin Benjamini, Ṣiba ìránṣẹ́ ilé Saulu, àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àti ogún ìránṣẹ́ sì pẹ̀lú rẹ̀; wọ́n sì gòkè odò Jordani ṣáájú ọba.
Benjamin miphun 1, 000, Sawl imthung e a san Ziba hoi a capa 15 touh hoi a san 20 touh a tho awh teh, siangpahrang e a hmaitung vah Jordan tui a raka awh.
18 Ọkọ̀ èrò kan ti rékọjá láti kó àwọn ènìyàn ilé ọba sí òkè, àti láti ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ̀. Ṣimei ọmọ Gera wólẹ̀. Ó sì dojúbolẹ̀ níwájú ọba, bí ó tí gòkè odò Jordani.
Siangpahrang imthungnaw a thak sak nahanelah, a panki e sak nahanelah, a ceikhai awh. Jordan tui a raka awh navah, Gera capa Shimei teh siangpahrang hmalah a tabo.
19 Ó sì wí fún ọba pé, “Kí olúwa mi ó má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ sí mi lọ́rùn, má sì ṣe rántí àfojúdi tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ṣe ni ọjọ́ tí olúwa mi ọba jáde ní Jerusalẹmu, kí ọba má sì fi sí inú.
Ka bawipa ni payonnae ka tawn e lah na pouk hanh naseh. Siangpahrang ka bawipa ni Jerusalem a tâcotakhai hnin vah, na san ni kalan hoeh e lah sak e hah, na pâkuem pouh hanh. Siangpahrang ni a lung dawk pâkuem hanh naseh.
20 Nítorí pé ìránṣẹ́ rẹ mọ̀ pé èmi ti ṣẹ̀; sì wò ó, mo wá lónìí yìí, ẹni àkọ́kọ́ ní gbogbo ìdílé Josẹfu tí yóò sọ̀kalẹ̀ wá pàdé olúwa mi ọba.”
Na san ni yonnae ka sak e hah na san kai ni ka panue. Hateiteh, Joseph imthungnaw dawk, ka bawipa dawn hanelah ahmaloe ka tho e doeh telah ati.
21 Ṣùgbọ́n Abiṣai ọmọ Seruiah dáhùn ó sì wí pé, “Kò ha tọ́ kí a pa Ṣimei nítorí èyí? Nítorí pé òun ti bú ẹni àmì òróró Olúwa.”
Zeruiah capa Abisai ni BAWIPA ni satui a awi e thoe a bo dawkvah, Shimei hah dei hane nahoehmaw telah ati.
22 Dafidi sì wí pé, “Kí ni èmi ní ṣe pẹ̀lú yín, ẹ̀yin ọmọ Seruiah tí ẹ dàbí ọ̀tá fún mi lónìí? A ha lè pa ènìyàn kan lónìí ní Israẹli? Tàbí èmi kò ha mọ̀ pé lónìí èmi ni ọba Israẹli.”
Devit ni nangmanaw Zeruiah capanaw sahnin kai na taran hane, kai hoi bangmaw na kâseng awh. Sahnin Isarel ka kâtet pueng thei hanelah maw kai teh sahnin Isarel siangpahrang lah ka o tie ka panuek hoeh na maw telah ati.
23 Ọba sì wí fún Ṣimei pé, “Ìwọ kì yóò kú!” Ọba sì búra fún un.
Siangpahrang ni Shimei koevah, na dout mahoeh telah lawk a kam.
24 Mefiboṣeti ọmọ Saulu sì sọ̀kalẹ̀ láti wá pàdé ọba, kò wẹ ẹsẹ̀ rẹ̀, kò sí tọ́ irùngbọ̀n rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fọ aṣọ rẹ̀ láti ọjọ́ tí ọba ti jáde títí ó fi di ọjọ́ tí ó fi padà ní àlàáfíà.
Sawl capa Mephibosheth teh siangpahrang dawn hanelah a tho. Siangpahrang a cei hnin hoiyah karoumcalah bout a tho hoehnahlan totouh, a khok pâsu hoeh, a pâkhamuen ngaw hoeh, a hni hai pâsu hoeh.
25 Nígbà tí òun sì wá sí Jerusalẹmu láti pàdé ọba, ọba sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ kò fi bá mi lọ, Mefiboṣeti?”
Siangpahrang dawn hanelah Jerusalem kho koe a pha navah, siangpahrang ni Mephibosheth, bangkong kai koe na cei van hoeh telah ati.
26 Òun sì dáhùn wí pé, “Olúwa mi, ọba, ìránṣẹ́ mi ni ó tàn mí, nítorí ìránṣẹ́ rẹ wí fún un pé, ‘Di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún mi èmi ó gùn ún, èmi ó sì tọ ọba lọ.’ Nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ yarọ.
Oe siangpahrang ka bawipa, ka san ni na dum. Bangkongtetpawiteh, na san ni siangpahrang koe cei hanelah la kâcui thai nahanlah kârasoup han ka ti ei, na san teh ka khokkhem.
27 Ó sì sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí ìránṣẹ́ rẹ, fún olúwa mi ọba, ṣùgbọ́n bí angẹli Ọlọ́run ni olúwa mi ọba rí, nítorí náà ṣe èyí tí ó dára lójú rẹ.
Siangpahrang ka bawipa nang koevah, na san heh na pathoe. Hateiteh, siangpahrang ka bawipa teh, Cathut kalvantami patetlah ao. Ahawi na tie patetlah sak lawih.
28 Nítorí pé gbogbo ilé baba mi bí òkú ènìyàn ni wọ́n sá à rí níwájú olúwa mi ọba, ìwọ sì fi ipò fún ìránṣẹ́ rẹ láàrín àwọn tí ó ń jẹun ní ibi oúnjẹ. Nítorí náà àre kín ni èmi ní tí èmi yóò fi máa ké pe ọba síbẹ̀.”
Bangkongtetpawiteh, imthungnaw heh siangpahrang hmaitung be thei hanelah a kamcu. Hatei, na san teh caboi dawk rawca ka ven e lah na o sak. Hatdawkvah, siagpahrang koevah kai ni hno alouke ka hei ngam hane bangmaw kaawm telah atipouh.
29 Ọba sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń sọ ọ̀ràn ara rẹ fún mi èmi sá à ti wí pé, kí ìwọ àti Ṣiba pín ilẹ̀ náà.”
Siangpahrang ni nange kong bangmaw dei hanelah kaawm. Nang hoi Ziba ni lawhmuen na kârei roi han telah kai ni ka dei toe tayaw telah ati.
30 Mefiboṣeti sì wí fún ọba pé, “Jẹ́ kí ó mú gbogbo rẹ̀, kí olúwa mi ọba sá à ti padà bọ̀ wá ilé rẹ̀ ni àlàáfíà.”
Mephibosheth ni siangpahrang koevah, siangpahrang teh ama im vah karoumcalah a pha dawkvah, ama ni abuemlahoi lat lawi naseh telah atipouh.
31 Barsillai ará Gileadi sì sọ̀kalẹ̀ láti Rogelimu wá, ó sì bá ọba gòkè odò Jordani, láti ṣe ìkẹ́ rẹ̀ sí ìkọjá odò Jordani.
Gilead tami Barzillai hah Rogelim kho lahoi a tho teh, siangpahrang teh Jordan tui rakakhai hanelah ahni koe a cei van.
32 Barsillai sì jẹ́ arúgbó ọkùnrin gidigidi, ẹni ogbó ọgọ́rin ọdún sì ni, ó sì pèsè ohun jíjẹ fún ọba nígbà tí ó ti wà ní Mahanaimu; nítorí pé ọkùnrin ọlọ́lá ni òun ń ṣe.
Barzillai teh a kum 80 touh a pha toe. A matawng toe. Mahanaim vah siangpahrang ao nah thung teh canei hane kawi ouk a poe. Bangkongtetpawiteh, ahni teh ka tawnta poung e lah ao.
33 Ọba sì wí fún Barsillai pé, “Ìwọ wá bá mi gòkè odò, èmi ó sì máa pèsè fún ọ ní Jerusalẹmu.”
Siangpahrang ni Barzillai koevah, kai koe tho van nateh, Jerusalem kho kai koe awm nateh, na kawk han telah atipouh.
34 Barsillai sì wí fún ọba pé, “Ọjọ́ mélòó ni ọdún ẹ̀mí mi kù, tí èmi ó fi bá ọba gòkè lọ sí Jerusalẹmu.
Barzillai ni siangpahrang koevah, nâsittouh maw ka hring rah vaiteh, Jerusalem siangpahrang koe ka cei van han vaiyoe.
35 Ẹni ogbó ọgọ́rin ọdún sá à ni èmi lónìí, ǹjẹ́ èmi mọ ìyàtọ̀ nínú rere àti búburú? Ǹjẹ́ ìránṣẹ́ rẹ le mọ adùn ohun tí òun ń jẹ tàbí ohun ti òun ń mu bí? Èmi tún lè mọ adùn ohùn àwọn ọkùnrin tí ń kọrin àti àwọn obìnrin tí ń kọrin bí, ǹjẹ́ nítorí kín ni ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe jẹ́ ìyọnu síbẹ̀ fún olúwa mi ọba.
Sahnin kai teh kum 80 touh ka pha toe. A thoe hoi hawi kapek thai hoeh toe. Kai ni ka canei e a tui hoi tui hoeh e hai ka panue yaw toung. Tongpa napui naw e la sak pawlawk hai ka thai hoeh toe. Na san kai ni siangpahrang ka bawipa hanelah, hmuenri lah khuet ka o han vaw.
36 Ìránṣẹ́ rẹ yóò sì sin ọba lọ díẹ̀ gòkè odò Jordani; èéṣì ṣe tí ọba yóò fi san ẹ̀san yìí fún mi.
Na san ni siangpahrang koe, Jordan tui na raka totouh dueng doeh ka tho thai ti. Bangkong nama siangpahrang ni het patetlae tawkphu khuet na poe han vaw.
37 Èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ padà, èmi ó sì kú ní ìlú mi, a ó sì sin mí ní ibojì baba àti ìyá mi. Sì wo Kimhamu ìránṣẹ́ rẹ, yóò bá olúwa mi ọba gòkè; ìwọ ó sì ṣe ohun tí ó bá tọ́ lójú rẹ fún un.”
Na san kai teh ka onae kho dawk, apa e tangkom koe ka due hanelah na ban sak leih. Na san Khimham ao doeh. Siangpahrang hoi rei cet sak. Ahawi na tie patetlah na sak han telah atipouh.
38 Ọba sì dáhùn wí pé, “Kimhamu yóò bá mi gòkè, èmi ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ̀ fún un; ohunkóhun tí ìwọ bá sì béèrè lọ́wọ́ mi, èmi ó ṣe é fún ọ.”
Siangpahrang ni Khimham teh kai hoi rei ka cei roi han. Ahawi na tie patetlah ahni dawk ka sak han. Na hei e pueng hai na sak pouh han telah atipouh.
39 Gbogbo àwọn ènìyàn sì gòkè odò Jordani ọba sì gòkè; ọba sì fi ẹnu ko Barsillai lẹ́nu, ó sì súre fún un; òun sì padà sí ilé rẹ̀.
Tami pueng hai Jordan tui namran lah a raka awh. Siangpahrang ama dueng a raka hnukkhu, Barzillai hah a tapam a paco teh yawhawi a poe teh aonae koe lah a ban.
40 Ọba sì ń lọ́ sí Gilgali, Kimhamu sì ń bà a lọ, gbogbo àwọn ènìyàn Juda sì ń ṣe ìkẹ́ ọba, àti ààbọ̀ àwọn ènìyàn Israẹli.
Siangpahrang teh Gilgal kho a cei. Khimham hai ahni koe a cei van. Judahnaw ni siangpahrang teh a thak awh. Isarel taminaw ni hai a thak awh van.
41 Sì wò ó, gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì tọ ọba wá, wọ́n sì wí fún ọba pé, “Èéṣe tí àwọn arákùnrin wa àwọn ọkùnrin Juda fi jí ọ kúrò, tí wọ́n sì fi mú ọba àti àwọn ará ilé rẹ̀ gòkè odò Jordani, àti gbogbo àwọn ènìyàn Dafidi pẹ̀lú rẹ?”
Isarelnaw pueng siangpahrang koe a tho awh teh, bangkongmaw hmaunawngha Judahnaw ni hoe a hnai awh teh, siangpahrang hoi a imthungnaw hoi Jordan tui namran lah koung a ceikhai awh telah ati awh.
42 Gbogbo ọkùnrin Juda sì dá àwọn ọkùnrin Israẹli lóhùn pé, “Nítorí pé ọba bá wa tan ni; èéṣe tí ẹ̀yin fi bínú nítorí ọ̀ràn yìí? Àwa jẹ nínú oúnjẹ ọba rárá bí? Tàbí ó fi ẹ̀bùn kan fún wa bí?”
Judahnaw ni siangpahrang teh kaimouh hoi kâhnai e lah ao dawkvah, bangkongmaw hete kong dawk na lungkhuek. Siangpahrang e rawcanaw kaimouh ni ka ca ka nei awh maw. Kaimouh koe na poe awh e hno ao maw telah Isarelnaw hanelah atipouh.
43 Àwọn ọkùnrin Israẹli náà sì dá àwọn ọkùnrin Juda lóhùn pé, “Àwa ní ipá mẹ́wàá nínú ọba, àwa sì ní nínú Dafidi jù yín lọ, èéṣì ṣe tí ẹ̀yin kò fi kà wá sí, tí ìmọ̀ wa kò fi ṣáájú láti mú ọba wa padà?” Ọ̀rọ̀ àwọn ọkùnrin Juda sì le ju ọ̀rọ̀ àwọn ọkùnrin Israẹli.
Isarelnaw ni Judahnaw koe kaimouh ni siangpahrang dawk hra touh coe hane ka tawn awh. Devit dawkvah nangmanaw hlak pang hane hoe ka tawn awh. Siangpahrang ban sak hane kong dawk kaimouh hoi apuengcue kâpannae awm laipalah, bangkong kaimanaw na dudam awh telah Judahnaw koe bout a dei pouh awh. Judahnaw e lawk hah Isarelnaw e lawk hlak hoe a hram.

< 2 Samuel 19 >