< 2 Samuel 17 >
1 Ahitofeli sì wí fún Absalomu pé, “Èmi ó yan ẹgbàá mẹ́fà ọkùnrin èmi ó sì dìde, èmi ó sì lépa Dafidi lóru yìí.
Ahithophel ni Absalom koevah, tami 12, 000 rawi naseh. Sahnin tangmin ka thaw vaiteh Devit ka pâlei han.
2 Èmi ó sì yọ sí i nígbà tí àárẹ̀ bá mú un tí ọwọ́ rẹ̀ sì ṣe aláìle, èmi ó sì dá a ní ìjì, gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ yóò sì sá, èmi ó sì kọlu ọba nìkan ṣoṣo.
A tha a tawn teh a kut tha a youn navah, ka tuk vaiteh, a lung ka puen sak han. Ahni koe kaawm e pueng hah a yawng awh vaiteh, siangpahrang dueng hah ka thei han.
3 Èmi ó sì mú gbogbo àwọn ènìyàn padà sọ́dọ̀ rẹ bi ìgbà tí ìyàwó bá padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ rẹ̀. Ọkàn ẹnìkan ṣoṣo tí ìwọ ń wá yìí ni ó túmọ̀ sí ìpadàbọ̀ gbogbo wọn; gbogbo àwọn ènìyàn yóò sì wà ní àlàáfíà.”
Taminaw pueng nang koe ka thokhai han na tawng e teh tami pueng hoi a kâvan han. Tami pueng bout a ban awh vaiteh, karoumcacah ao awh han telah ati.
4 Ọ̀rọ̀ náà sì tọ́ lójú Absalomu, àti lójú gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli.
Hote lawk hah Absalom hoi Isarelnaw miphun kacuenaw ni a ngai awh.
5 Absalomu sì wí pé, “Ǹjẹ́ pe Huṣai ará Arki, àwa ó sì gbọ́ èyí tí ó wà lẹ́nu rẹ̀ pẹ̀lú.”
Absalom ni Arki tami Hushai hai kaw haw, a dei e hah maimouh ni thai pouh haw sei telah ati.
6 Huṣai sì dé ọ̀dọ̀ Absalomu, Absalomu sì wí fún un pé, “Báyìí ni Ahitofeli wí, kí àwa ṣe bí ọ̀rọ̀ rẹ bí? Bí ko bá sì tọ́ bẹ́ẹ̀, ìwọ wí.”
Hushai ni Absalom koe a pha toteh, Absalom ni Ahithophel ni hettelah a dei. A dei e patetlah sak han na maw, sak awh mahoeh maw. Nahoeh pawiteh, nang hai dei van haw telah atipouh.
7 Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Ìmọ̀ tí Ahitofeli gbà yìí, kò dára nísinsin yìí.”
Hushai ni Absalom koe a pha toteh, Absalom ni Ahithophel ni pouknae a thokhai e heh hawi hoeh.
8 Huṣai sì wí pé, “Ìwọ mọ baba rẹ àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé alágbára ni wọ́n, wọ́n sì wà ní kíkorò ọkàn bí àmọ̀tẹ́kùn tí a gbà ní ọmọ ni pápá, baba rẹ sì jẹ́ jagunjagun ọkùnrin kì yóò bá àwọn ènìyàn náà gbé pọ̀ lóru.
Hushai ni, na pa hoi a taminaw teh na panue toe. Athakaawme tami, ka matheng katang e tavom manu a ca la pouh e patetlah, doeh ao awh. Hahoi, na pa teh taran ka tuk e lah ao teh, taminaw koe roe mahoeh.
9 Kíyèsi i, ó ti fi ara rẹ̀ pamọ́ nísinsin yìí ni ihò kan, tàbí ní ibòmíràn: yóò sì ṣe, nígbà tí díẹ̀ nínú wọn bá kọ́ ṣubú, ẹnikẹ́ni tí ó bá gbọ́ yóò sì wí pé, ‘Ìparun sì ń bẹ́ nínú àwọn ènìyàn tí ń tọ Absalomu lẹ́yìn.’
Khenhaw! atuvah, lungngoum buetbuet touh koe a kâhro han doeh. Nahoeh pawiteh, alouke hmuen koe a kâhro han doeh. Tami tangawn ahmaloe la rawm lah dout awh pawiteh, hote kamthang ka thai e ni Absalom hnukkâbangnaw teh, a due awh toe telah a dei awh han.
10 Ẹni tí ó sì ṣe alágbára, tí ọkàn rẹ̀ sì dàbí ọkàn kìnnìún, yóò sì rẹ̀ ẹ́: nítorí gbogbo Israẹli ti mọ̀ pé alágbára ni baba rẹ, àti pé, àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ jẹ́ alágbára.
Tarankahawi e tami, sendek e lungthin ka tawn e patenghai a lung a pout han. Bangkongtetpawiteh, Isarelnaw pueng ni na pa teh athakaawme hoi ama koe kaawm e naw teh tami a thakasai e seng doeh tie hah a panue awh.
11 “Nítorí náà èmi dámọ̀ràn pé, kí gbogbo Israẹli wọ́jọ pọ̀ sọ́dọ̀ rẹ, láti Dani títí dé Beerṣeba, gẹ́gẹ́ bí iyanrìn létí òkun fún ọ̀pọ̀lọpọ̀; àti pé, kí ìwọ tìkára rẹ̀ ó lọ sí ogun náà.
Hatdawkvah pouknae na poe han ka ngai e teh, Dan kho hoi Beersheba kho totouh, Isarelnaw teh tuipui teng e sadi yit touh nang koe a kamkhueng awh teh, nangmanaw hai tarantuknae koe cet van awh nateh,
12 Àwa ó sì yọ sí i níbikíbi tí àwa o gbé rí i, àwa ó sì yí i ká bí ìrì ti ń ṣẹ̀ sí ilẹ̀ àní, ọkàn kan kì yóò kù pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀.
hottelah kâhmo thainae a hmuen pueng koe, talai dawk tadamtui ka bawt e patetlah muen na ramuk awh vaiteh, ama hoi ahni koe kaawm pueng buet touh hai pâhlung awh mahoeh.
13 Bí o bá sì bọ́ sí ìlú kan, gbogbo Israẹli yóò mú okùn wá sí ìlú náà, àwa ó sì fà á lọ sí odò, títí a kì yóò fi rí òkúta kéékèèké kan níbẹ̀.”
Hothloilah, khopui buet touh koe kâen pawiteh, Isarelnaw pueng ni tangron sin vaiteh hote kho dawk cei awh vaiteh, talungcanaw buet touh boehai ao hoeh totouh, palang vah koung sawn awh han telah ati.
14 Absalomu àti gbogbo ọkùnrin Israẹli sì wí pé, “Ìmọ̀ Huṣai ará Arki sàn ju ìmọ̀ Ahitofeli lọ! Nítorí Olúwa fẹ́ láti yí ìmọ̀ rere ti Ahitofeli po.” Nítorí kí Olúwa lè mú ibi wá sórí Absalomu.
Absalom hoi Isarelnaw ni Arki tami Hushai ni pouknae a poe e teh Ahithophel ni pouknae a poe e hlak ahawi telah ati awh. Bangkongtetpawiteh, BAWIPA ni Absalom e lathueng runae a pha sak thai nahan BAWIPA ni kahawipoung e Ahithophel pouknae a poe e a tapuet sak han a ngai dawk doeh.
15 Huṣai sì wí fún Sadoku àti fún Abiatari àwọn àlùfáà pé, “Báyìí ni Ahitofeli ti bá Absalomu àti àwọn àgbàgbà Israẹli dámọ̀ràn, báyìí lèmi sì bá a dámọ̀ràn.
Hushai ni vaihma Zadok hoi Abiathar koevah, hottelah Ahithophel ni Absalom hoi Isarelnaw hah pouknae a poe, hahoi kai ni hai pouknae hot patetlah ka poe toe telah ati.
16 Nítorí náà yára ránṣẹ́ nísinsin yìí kí o sì sọ fún Dafidi pé, ‘Má ṣe dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ijù náà lálẹ́ yìí, ṣùgbọ́n yára rékọjá kí a má bá a gbé ọba mì, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ.’”
Hatdawkvah, atu tangmin vah, kahrawngum ayawn dawk roe laipalah, pou cet awh. Nahoeh pawiteh, siangpahrang hoi a taminaw pueng teh koung a thei payon awh han doeh telah Devit koe karanglah dei pouh awh telah ati.
17 Jonatani àti Ahimasi sì dúró ní En-Rogeli ọ̀dọ́mọdébìnrin kan sì lọ, ó sì sọ fún wọn, wọ́n sì lọ wọ́n sọ fún Dafidi ọba nítorí pé kí a má bá à rí wọn pé wọ́n wọ ìlú.
Jonathan hoi Ahimaaz teh Enrogel vah ao awh teh, sannu buet touh ni ahnimouh koe ouk a dei pouh teh, ahnimouh ni Devit koe patuen ouk a dei pouh awh. Bangkongtetpawiteh, khopui thung kâen e hah apinihai hmu hanelah awm hoeh.
18 Ṣùgbọ́n ọ̀dọ́mọdékùnrin kan rí wọn, ó sì wí fún Absalomu, ṣùgbọ́n àwọn méjèèjì sì yára lọ kúrò, wọ́n sì wá sí ilé ọkùnrin kan ní Bahurimu, ẹni tí ó ní kànga kan ní ọgbà rẹ̀, wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ sí ibẹ̀.
Hatei, camo ni a hmu awh teh, Absalom koe a dei pouh. Hottelah kahni touh hoi vai touh lahoi a yawng roi. Bahurim tami buet touh thongma dawk tuikhu ka tawn e im dawk a kâen roi teh tuikhu dawk a kâhro roi.
19 Obìnrin rẹ̀ sì mú nǹkan ó fi bo kànga náà, ó sì sá àgbàdo sórí rẹ̀, a kò sì mọ̀.
Hahoi, a yu ni tuikhu teh a khuem hoi a khuem teh cakang muen a vaw sin dawkvah apinihai panuek hoeh.
20 Àwọn ìránṣẹ́ Absalomu sì tọ obìnrin náà wá sí ilé náà, wọ́n sì béèrè pé, “Níbo ni Ahimasi àti Jonatani gbé wà?” Obìnrin náà sì wí fún wọn pé, “Wọ́n ti gòkè rékọjá ìṣàn odò náà.” Wọ́n sì wá wọn kiri, wọn kò sì rí wọn, wọ́n sì yípadà sí Jerusalẹmu.
Absalom e a sannaw hote im koe a pha awh navah, Ahimaaz hoi Jonathan hah namaw ao roi telah napui koe a pacei awh. Napui ni, palang namran lah yo a pha han doeh toe telah atipouh. Ahnimouh ni a tawng awh teh hmawt awh hoeh toe. Hateh Jerusalem lah a ban awh.
21 Ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti lọ tán, àwọn ọkùnrin náà sì jáde kúrò nínú kànga, wọ́n sì lọ wọ́n sì rò fún Dafidi ọba. Wọ́n sọ fún Dafidi pé, “Dìde kí o sì gòkè odò kánkán, nítorí pé báyìí ni Ahitofeli gbìmọ̀ sí ọ.”
Hahoi, a ban awh hnukkhu, Ahimaaz hoi Jonathan teh tuikhu dawk hoi a tâco roi teh, Devit siangpahrang koe a dei pouh roi. Devit koevah thaw awh nateh karanglah cet awh leih. Bangkongtetpawiteh, hettelah Ahithophel ni nang na taranlahoi pouknae a poe telah atipouh.
22 Dafidi sì dìde, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì gòkè odò Jordani: kí ilẹ̀ tó mọ́, ènìyàn kò kù tí kò gòkè odò Jordani.
Devit hoi ama koe kaawm e pueng a thaw awh teh, Jordan tui a raka awh. Khodai nah be a raka awh toe. Ka rakat hoeh e tami buet touh hai awm hoeh.
23 Nígbà tí Ahitofeli sì rí i pé wọn kò fi ìmọ̀ tirẹ̀ ṣe, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ni gàárì, ó sì dìde, ó lọ ilé rẹ̀, ó sì palẹ̀ ilé rẹ̀ mọ̀, ó sì so, ó sì kú, a sì sin ín sí ibojì baba rẹ̀. Absalomu gbógun ti Dafidi.
Ahithophel ni pouknae a poe e hah tarawi awh hoeh tie a thai awh toteh, la a rakueng awh teh ama kho lah a cei awh. A imthungnaw kho a saknae kong kahawicalah cing a thui hnukkhu a kaithi. A mintoenaw e phuen koe a pakawp awh.
24 Dafidi sì wá sí Mahanaimu, Absalomu sì gòkè odò Jordani, òun àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli pẹ̀lú rẹ̀.
Devit ni Mahanaim kho koe a pha navah, Absalom teh Isarelnaw hoi Jordan tui a raka awh.
25 Absalomu sì fi Amasa ṣe olórí ogun ní ipò Joabu: Amasa ẹni tí í ṣe ọmọ ẹnìkan, orúkọ ẹni tí a ń pè ní Itira, ará Israẹli, tí ó wọlé tọ Abigaili ọmọbìnrin Nahaṣi, arábìnrin Seruiah, ìyá Joabu.
Absalom ni Joab e yueng lah Amasa hah ransabawi lah a hruek. Amasa teh Joab e a manu Zeruiah e a nawngha Nahash canu Abigail ka ipkhai e Ishmael miphun Ithra capa doeh.
26 Israẹli àti Absalomu sì dó ní ilẹ̀ Gileadi.
Isarel miphunnaw hoi Absalom teh Gilead ram dawk a tungpup awh.
27 Nígbà tí Dafidi sì wá sí Mahanaimu, Ṣobi ọmọ Nahaṣi ti Rabba tí àwọn ọmọ Ammoni, àti Makiri ọmọ Ammieli ti Lo-Debari, àti Barsillai ará Gileadi ti Rogelimu.
Devit teh Mahanaim kho a pha toteh, Ammon ram Rabbah tami Nahash capa Shobi hoi Lodebar, Amiel capa Makhir hoi Rogelim hoi Gilead tami Barzillai tinaw ni,
28 Mú àwọn àkéte, àti àwọn àwo, àti ìkòkò amọ̀, àti alikama, àti ọkà barle, àti ìyẹ̀fun, àti àgbàdo díndín, àti ẹ̀wà, àti erèé, àti lẹntili.
Hote taminaw teh kahrawngum vah a vonhlam awh, a tawntam awh, tui a kahran awh telah ati awh dawkvah, Devit hoi a taminaw ni canei hanelah catun, barli, pe a phunphun,
29 Àti oyin, àti òrí-àmọ́, àti àgùntàn, àti wàràǹkàṣì màlúù, wá fún Dafidi àti fún àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀, láti jẹ: nítorí tí wọ́n wí pé, “Ebi ń pa àwọn ènìyàn, ó sì rẹ̀ wọ́n, òǹgbẹ sì ń gbẹ wọ́n ní aginjù.”
khoitui, sanutuikamkak, tu, iphah, ailo, kawlung naw hah a sin pouh awh.