< 2 Samuel 16 >

1 Nígbà tí Dafidi sì fi díẹ̀ kọjá orí òkè náà, sì wò ó, Ṣiba ìránṣẹ́ Mefiboṣeti sì ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, òun àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ méjì tí a ti dì ní gàárì, àti igba ìṣù àkàrà lórí wọn, àti ọgọ́rùn-ún síírí àjàrà gbígbẹ, àti ọgọ́rùn-ún èso ẹ̀rún, àti ìgò ọtí wáìnì kan.
Кынд трекусе Давид пуцин де вырф, ятэ кэ Циба, служиторул луй Мефибошет, а венит ынаинтя луй ку дой мэгарь ыншеуаць, пе каре ерау доуэ суте де пынь, о сутэ де турте де стафиде, о сутэ де роаде де варэ ши ун бурдуф ку вин.
2 Ọba sì wí fún Ṣiba pé, “Kí ni wọ̀nyí?” Ṣiba sì wí pé, “Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ̀nyí ni fún àwọn ará ilé ọba láti máa gùn àti àkàrà yìí, àti èso ẹ̀rún yìí ni fún àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin láti jẹ; àti ọtí wáìnì yìí ni fún àwọn aláàárẹ̀ ní ijù láti mu.”
Ымпэратул а зис луй Циба: „Че врей сэ фачь ку ачестя?” Ши Циба а рэспунс: „Мэгарий сунт пентру каса ымпэратулуй, пентру кэлэрие, пыниле ши роаделе де варэ сунт пентру храна тинерилор ши винул, пентру потолиря сетей челор че вор фи обосиць ын пустиу.”
3 Ọba sì wí pé, “Ọmọ olúwa rẹ dà?” Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Wò ó, ó jókòó ní Jerusalẹmu; nítorí tí ó wí pé, ‘Lónìí ni ìdílé Israẹli yóò mú ìjọba baba mi padà wá fún mi.’”
Ымпэратул а зис: „Унде есте фиул стэпынулуй тэу?” Ши Циба а рэспунс ымпэратулуй: „Ятэ, а рэмас ла Иерусалим, кэч а зис: ‘Астэзь, каса луй Исраел ымь ва да ынапой ымпэрэция татэлуй меу.’”
4 Ọba sì wí fún Ṣiba pé, “Wò ó, gbogbo nǹkan tí í ṣe ti Mefiboṣeti jẹ́ tìrẹ.” Ṣiba sì wí pé, “Mo túúbá, jẹ́ kí n rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ, olúwa mi ọba.”
Ымпэратул а зис луй Циба: „Тот че есте ал луй Мефибошет есте ал тэу.” Ши Циба а зис: „Мэ ынкин ку плекэчуне! Сэ капэт тречере ынаинтя та, ымпэрате, домнул меу!”
5 Dafidi ọba sì dé Bahurimu, sì wò ó, ọkùnrin kan ti ibẹ̀ jáde wá, láti ìdílé Saulu wá, orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣimei, ọmọ Gera, ó sì ń bú èébú bí o tí ń bọ̀.
Давид ажунсесе пынэ ла Бахурим. Ши де аколо а ешит ун ом дин фамилия ши дин каса луй Саул, нумит Шимей, фиул луй Гера. Ел ынаинта блестемынд
6 Ó sì sọ òkúta sí Dafidi, àti sí gbogbo ìránṣẹ́ Dafidi ọba, àti sí gbogbo ènìyàn, gbogbo àwọn alágbára ọkùnrin sì wà lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti lọ́wọ́ òsì rẹ̀.
ши а арункат ку петре дупэ Давид ши дупэ тоць служиторий ымпэратулуй Давид, ын тимп че тот попорул ши тоць витежий стэтяу ла дряпта ши ла стынга ымпэратулуй.
7 Báyìí ni Ṣimei sì wí nígbà tí ó ń yọ èébú, “Jáde, ìwọ ọkùnrin ẹ̀jẹ̀, ìwọ ọkùnrin Beliali.
Шимей ворбя астфел кынд блестема: „Ду-те, ду-те, ом ал сынӂелуй, ом рэу!
8 Olúwa mú gbogbo ẹ̀jẹ̀ ìdílé Saulu padà wá sí orí rẹ, ní ipò ẹni tí ìwọ jẹ ọba; Olúwa ti fi ìjọba náà lé Absalomu ọmọ rẹ lọ́wọ́: sì wò ó, ìwà búburú rẹ ni ó mú èyí wá bá ọ, nítorí pé ọkùnrin ẹ̀jẹ̀ ni ìwọ.”
Домнул фаче сэ кадэ асупра та педяпса пентру тот сынӂеле касей луй Саул, ал кэруй скаун де домние л-ай луат, ши Домнул а дат ымпэрэция ын мыниле фиулуй тэу Абсалом, ши ятэ-те ненорочит, кэч ешть ун ом ал сынӂелуй!”
9 Abiṣai ọmọ Seruiah sì wí fún ọba pé, “Èéṣe tí òkú ajá yìí fi ń bú olúwa mi ọba? Jẹ́ kí èmi kọjá, èmi bẹ̀ ọ́, kí èmi sì bẹ́ ẹ́ lórí.”
Атунч, Абишай, фиул Церуей, а зис ымпэратулуй: „Пентру че блестемэ ачест кыне морт пе домнул меу, ымпэратул? Ласэ-мэ, те рог, сэ мэ дук сэ-й тай капул.”
10 Ọba sì wí pé, “Kín ni èmi ní ṣe pẹ̀lú yín, ẹ̀yin ọmọ Seruiah? Bí ó bá ń bú èébú, nítorí tí Olúwa ti wí fún un pé, ‘Bú Dafidi!’ Ta ni yóò sì wí pé, ‘Kín ni ìdí tí o fi ṣe bẹ́ẹ̀.’”
Дар ымпэратул а зис: „Че авець вой ку мине, фиий Церуей? Дакэ блестемэ, ынсямнэ кэ Домнул й-а зис: ‘Блестемэ пе Давид!’ Чине-й ва зиче дар: ‘Пентру че фачь аша?’”
11 Dafidi sì wí fún Abiṣai, àti fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wò ó, ọmọ mi tí ó ti inú mi wá, ń wá mi kiri, ǹjẹ́ mélòó mélòó ni ará Benjamini yìí yóò sì ṣe? Fi í sílẹ̀, sì jẹ́ kí o máa yan èébú; nítorí pé Olúwa ni ó sọ fún un.
Ши Давид а зис луй Абишай ши тутурор служиторилор сэй: „Ятэ кэ фиул меу, каре а ешит дин трупул меу, вря сэ-мь я вяца, ку кыт май мулт бениамитул ачеста! Лэсаци-л сэ блестеме, кэч Домнул й-а зис.
12 Bóyá Ọlọ́run yóò wo ìpọ́njú mi, Olúwa yóò sì fi ìre san án fún mi ní ipò èébú rẹ̀ lónìí.”
Поате кэ Домнул Се ва уйта ла неказул меу ши-мь ва фаче бине ын локул блестемелор де азь.”
13 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì ń lọ ní ọ̀nà, Ṣimei sì ń rìn òdìkejì òkè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, ó sì ń yan èébú bí ó ti ń lọ, ó sì ń sọ ọ́ lókùúta, ó sì ń fọ́n erùpẹ̀.
Давид ши оамений луй шь-ау вэзут де друм. Шимей мерӂя пе коаста мунтелуй, ын дрептул луй Давид, ши, мергынд, блестема, арунка ку петре ымпотрива луй ши вынтура праф.
14 Ọba, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì dé Jordani, ó sì rẹ̀ wọ́n, wọ́n sì sinmi níbẹ̀.
Ымпэратул ши тот попорул каре ера ку ел ау ажунс ла Аиефим ши аколо с-ау одихнит.
15 Absalomu àti gbogbo àwọn ènìyàn, àwọn ọkùnrin Israẹli sì wá sí Jerusalẹmu, Ahitofeli sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
Абсалом ши тот попорул, бэрбаций луй Исраел, интрасерэ ын Иерусалим. Ахитофел ера ши ел ку Абсалом.
16 Ó sì ṣe, nígbà tí Huṣai ará Arki, ọ̀rẹ́ Dafidi tọ Absalomu wá, Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Kí ọba ó pẹ́! Kí ọba ó pẹ́.”
Кынд а ажунс Хушай, Аркитул, приетенул луй Давид, ла Абсалом, й-а зис: „Трэяскэ ымпэратул! Трэяскэ ымпэратул!”
17 Absalomu sì wí fún Huṣai pé, “Oore rẹ sí ọ̀rẹ́ rẹ ni èyí? Èéṣe tí ìwọ kò bá ọ̀rẹ́ rẹ lọ?”
Ши Абсалом а зис луй Хушай: „Ятэ кыт де мулт ций ту ла приетенул тэу! Пентру че ну те-ай дус ку приетенул тэу?”
18 Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ nítorí ẹni tí Olúwa, àti gbogbo àwọn ènìyàn yìí, àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli bá yàn, tirẹ̀ lèmi ó jẹ́, òun lèmi ó sì bá jókòó.
Хушай а рэспунс луй Абсалом: „Пентру кэ вряу сэ фиу ал ачелуя пе каре л-а алес Домнул ши тот попорул ачеста ши тоць бэрбаций луй Исраел ши ку ел вряу сэ рэмын.
19 Àti pé, ta ni èmi ó sì sìn? Kò ha yẹ kí èmi ó máa sìn níwájú ọmọ rẹ̀? Gẹ́gẹ́ bí èmi ti ń sìn rí níwájú baba rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó sìn níwájú rẹ.”
Де алтфел, куй ый вой служи? Ну фиулуй сэу? Кум ам служит татэлуй тэу, аша ыць вой служи ши цие.”
20 Absalomu sì wí fún Ahitofeli pé, “Ẹ bá ará yín gbìmọ̀ ohun tí àwa ó ṣe.”
Абсалом а зис луй Ахитофел: „Сфэтуици-вэ ымпреунэ. Че авем де фэкут?”
21 Ahitofeli sì wí fún Absalomu pé, “Wọlé tọ àwọn obìnrin baba rẹ lọ, tí ó fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, gbogbo Israẹli yóò sì gbọ́ pé, ìwọ di ẹni ìríra sí baba rẹ, ọwọ́ gbogbo àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ yóò sì le.”
Ши Ахитофел а зис луй Абсалом: „Интрэ ла циитоареле пе каре ле-а лэсат татэл тэу пентру паза касей; астфел тот Исраелул ва шти кэ те-ай фэкут урыт татэлуй тэу ши мыниле тутурор челор че сунт ку тине се вор ынтэри.”
22 Wọ́n sì tẹ́ àgọ́ kan fún Absalomu ní òrùlé; Absalomu sì wọlé tọ àwọn obìnrin baba rẹ̀ lójú gbogbo Israẹli.
Ау ынтинс ун корт пентру Абсалом пе акопериш, ши Абсалом а интрат ла циитоареле татэлуй сэу, ын фаца ынтрегулуй Исраел.
23 Ìmọ̀ Ahitofeli tí ó máa ń gbà ni ìgbà náà, ó dàbí ẹni pé ènìyàn béèrè nǹkan lọ́wọ́ Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ìmọ̀ Ahitofeli fún Dafidi àti fún Absalomu sì rí.
Сфатул дат пе время ачея де Ахитофел авя тот атыта путере ка ши кынд ар фи ынтребат кяр пе Думнезеу. Тот аша ера ку тоате сфатуриле луй Ахитофел, фие пентру Давид, фие пентру Абсалом.

< 2 Samuel 16 >