< 2 Samuel 16 >

1 Nígbà tí Dafidi sì fi díẹ̀ kọjá orí òkè náà, sì wò ó, Ṣiba ìránṣẹ́ Mefiboṣeti sì ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, òun àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ méjì tí a ti dì ní gàárì, àti igba ìṣù àkàrà lórí wọn, àti ọgọ́rùn-ún síírí àjàrà gbígbẹ, àti ọgọ́rùn-ún èso ẹ̀rún, àti ìgò ọtí wáìnì kan.
Și după ce David trecuse puțin dincolo de vârful dealului, iată, Țiba, servitorul lui Mefiboșet l-a întâlnit, cu o pereche de măgari înșeuați, și pe ei două sute de pâini și o sută de mănunchiuri de stafide și o sută de fructe de vară și un burduf cu vin.
2 Ọba sì wí fún Ṣiba pé, “Kí ni wọ̀nyí?” Ṣiba sì wí pé, “Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ̀nyí ni fún àwọn ará ilé ọba láti máa gùn àti àkàrà yìí, àti èso ẹ̀rún yìí ni fún àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin láti jẹ; àti ọtí wáìnì yìí ni fún àwọn aláàárẹ̀ ní ijù láti mu.”
Și împăratul a spus lui Țiba: Ce dorești să însemne acestea? Și Țiba a spus: Măgarii sunt pentru casa împăratului pentru a fi călăriți; și pâinile și fructele de vară pentru tineri să mănânce; și vinul pentru cei leșinați în pustiu, ca să îl bea.
3 Ọba sì wí pé, “Ọmọ olúwa rẹ dà?” Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Wò ó, ó jókòó ní Jerusalẹmu; nítorí tí ó wí pé, ‘Lónìí ni ìdílé Israẹli yóò mú ìjọba baba mi padà wá fún mi.’”
Și împăratul a spus: Unde este fiul stăpânului tău? Și Țiba a spus împăratului: Iată, el rămâne la Ierusalim, fiindcă a spus: Astăzi casa lui Israel îmi va da înapoi împărăția tatălui meu.
4 Ọba sì wí fún Ṣiba pé, “Wò ó, gbogbo nǹkan tí í ṣe ti Mefiboṣeti jẹ́ tìrẹ.” Ṣiba sì wí pé, “Mo túúbá, jẹ́ kí n rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ, olúwa mi ọba.”
Atunci a spus împăratul lui Țiba: Iată, ale tale sunt toate câte au aparținut lui Mefiboșet. Și Țiba a spus: Cu umilință te implor să găsesc favoare înaintea ochilor tăi, împărate, domnul meu.
5 Dafidi ọba sì dé Bahurimu, sì wò ó, ọkùnrin kan ti ibẹ̀ jáde wá, láti ìdílé Saulu wá, orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣimei, ọmọ Gera, ó sì ń bú èébú bí o tí ń bọ̀.
Și când împăratul David a venit la Bahurim, iată, de acolo a ieșit un om din familia casei lui Saul, al cărui nume era Șimei, fiul lui Ghera; el a ieșit și a tot blestemat pe când ieșea,
6 Ó sì sọ òkúta sí Dafidi, àti sí gbogbo ìránṣẹ́ Dafidi ọba, àti sí gbogbo ènìyàn, gbogbo àwọn alágbára ọkùnrin sì wà lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti lọ́wọ́ òsì rẹ̀.
Și a aruncat cu pietre spre David și spre toți servitorii împăratului David; și tot poporul și toți războinicii erau la dreapta lui și la stânga lui.
7 Báyìí ni Ṣimei sì wí nígbà tí ó ń yọ èébú, “Jáde, ìwọ ọkùnrin ẹ̀jẹ̀, ìwọ ọkùnrin Beliali.
Și astfel spunea Șimei, când blestema: Ieși afară, ieși afară, tu om sângeros și tu om al lui Belial;
8 Olúwa mú gbogbo ẹ̀jẹ̀ ìdílé Saulu padà wá sí orí rẹ, ní ipò ẹni tí ìwọ jẹ ọba; Olúwa ti fi ìjọba náà lé Absalomu ọmọ rẹ lọ́wọ́: sì wò ó, ìwà búburú rẹ ni ó mú èyí wá bá ọ, nítorí pé ọkùnrin ẹ̀jẹ̀ ni ìwọ.”
DOMNUL a întors asupra ta tot sângele casei lui Saul, în locul căruia ai domnit; și DOMNUL a dat împărăția în mâna lui Absalom, fiul tău; și, iată, tu ești prins în ticăloșia ta, pentru că ești un om sângeros.
9 Abiṣai ọmọ Seruiah sì wí fún ọba pé, “Èéṣe tí òkú ajá yìí fi ń bú olúwa mi ọba? Jẹ́ kí èmi kọjá, èmi bẹ̀ ọ́, kí èmi sì bẹ́ ẹ́ lórí.”
Atunci Abișai, fiul Țeruiei, a spus împăratului: De ce să blesteme acest câine mort pe domnul meu, împăratul? Lasă-mă să trec, te rog și să îi iau capul.
10 Ọba sì wí pé, “Kín ni èmi ní ṣe pẹ̀lú yín, ẹ̀yin ọmọ Seruiah? Bí ó bá ń bú èébú, nítorí tí Olúwa ti wí fún un pé, ‘Bú Dafidi!’ Ta ni yóò sì wí pé, ‘Kín ni ìdí tí o fi ṣe bẹ́ẹ̀.’”
Și împăratul a spus: Ce am eu a face cu voi, fii ai Țeruiei? Lasă-l să blesteme, deoarece DOMNUL i-a spus: Blestemă pe David. Cine va spune atunci: Pentru ce ai făcut astfel?
11 Dafidi sì wí fún Abiṣai, àti fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wò ó, ọmọ mi tí ó ti inú mi wá, ń wá mi kiri, ǹjẹ́ mélòó mélòó ni ará Benjamini yìí yóò sì ṣe? Fi í sílẹ̀, sì jẹ́ kí o máa yan èébú; nítorí pé Olúwa ni ó sọ fún un.
Și David i-a spus lui Abișai și tuturor servitorilor săi: Iată, fiul meu, care a ieșit din adâncurile mele, îmi caută viața: cu cât mai mult acum poate acest beniamit să o facă? Lăsați-l în pace și lăsați-l să blesteme, fiindcă DOMNUL i-a cerut.
12 Bóyá Ọlọ́run yóò wo ìpọ́njú mi, Olúwa yóò sì fi ìre san án fún mi ní ipò èébú rẹ̀ lónìí.”
Poate că DOMNUL va privi la nenorocirea mea și DOMNUL îmi va răsplăti cu bine pentru blestemul lui de astăzi.
13 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì ń lọ ní ọ̀nà, Ṣimei sì ń rìn òdìkejì òkè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, ó sì ń yan èébú bí ó ti ń lọ, ó sì ń sọ ọ́ lókùúta, ó sì ń fọ́n erùpẹ̀.
Și precum David și oamenii săi mergeau pe cale, Șimei mergea pe coasta dealului în dreptul lui și blestema în timp ce mergea și arunca pietre spre el și arunca praf.
14 Ọba, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì dé Jordani, ó sì rẹ̀ wọ́n, wọ́n sì sinmi níbẹ̀.
Și împăratul și tot poporul care era cu el, au ajuns obosiți și s-au răcorit acolo.
15 Absalomu àti gbogbo àwọn ènìyàn, àwọn ọkùnrin Israẹli sì wá sí Jerusalẹmu, Ahitofeli sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
Și Absalom și tot poporul, bărbații lui Israel, au venit la Ierusalim și Ahitofel a venit cu el.
16 Ó sì ṣe, nígbà tí Huṣai ará Arki, ọ̀rẹ́ Dafidi tọ Absalomu wá, Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Kí ọba ó pẹ́! Kí ọba ó pẹ́.”
Și s-a întâmplat, când Hușai architul, prietenul lui David, a venit la Absalom, că Hușai i-a spus lui Absalom: Trăiască împăratul! Trăiască împăratul!
17 Absalomu sì wí fún Huṣai pé, “Oore rẹ sí ọ̀rẹ́ rẹ ni èyí? Èéṣe tí ìwọ kò bá ọ̀rẹ́ rẹ lọ?”
Și Absalom i-a spus lui Hușai: Este aceasta bunătatea ta față de prietenul tău? De ce nu ai mers cu prietenul tău?
18 Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ nítorí ẹni tí Olúwa, àti gbogbo àwọn ènìyàn yìí, àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli bá yàn, tirẹ̀ lèmi ó jẹ́, òun lèmi ó sì bá jókòó.
Și Hușai i-a spus lui Absalom: Nu; ci pe cine l-a ales DOMNUL și acest popor și toți bărbații lui Israel, al lui voi fi și cu el voi rămâne.
19 Àti pé, ta ni èmi ó sì sìn? Kò ha yẹ kí èmi ó máa sìn níwájú ọmọ rẹ̀? Gẹ́gẹ́ bí èmi ti ń sìn rí níwájú baba rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó sìn níwájú rẹ.”
Și din nou, cui să servesc? Să nu servesc în fața fiului său? Cum am servit în fața tatălui tău, astfel voi fi în fața ta.
20 Absalomu sì wí fún Ahitofeli pé, “Ẹ bá ará yín gbìmọ̀ ohun tí àwa ó ṣe.”
Atunci i-a spus Absalom lui Ahitofel: Sfătuiți-vă între voi ce să facem.
21 Ahitofeli sì wí fún Absalomu pé, “Wọlé tọ àwọn obìnrin baba rẹ lọ, tí ó fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, gbogbo Israẹli yóò sì gbọ́ pé, ìwọ di ẹni ìríra sí baba rẹ, ọwọ́ gbogbo àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ yóò sì le.”
Și Ahitofel i-a spus lui Absalom: Intră la concubinele tatălui tău, pe care el le-a lăsat pentru a păzi casa; și tot Israelul va auzi că ești detestat de tatăl tău; atunci mâinile tuturor celor care sunt cu tine vor fi tari.
22 Wọ́n sì tẹ́ àgọ́ kan fún Absalomu ní òrùlé; Absalomu sì wọlé tọ àwọn obìnrin baba rẹ̀ lójú gbogbo Israẹli.
Astfel, i-au întins lui Absalom un cort pe acoperișul casei; și Absalom a intrat la concubinele tatălui său înaintea ochilor întregului Israel.
23 Ìmọ̀ Ahitofeli tí ó máa ń gbà ni ìgbà náà, ó dàbí ẹni pé ènìyàn béèrè nǹkan lọ́wọ́ Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ìmọ̀ Ahitofeli fún Dafidi àti fún Absalomu sì rí.
Și sfatul lui Ahitofel, pe care îl dădea în acele zile, era ca și cum un om ar fi întrebat oracolul lui Dumnezeu; astfel era întreg sfatul lui Ahitofel deopotrivă pentru David și pentru Absalom.

< 2 Samuel 16 >