< 2 Samuel 16 >

1 Nígbà tí Dafidi sì fi díẹ̀ kọjá orí òkè náà, sì wò ó, Ṣiba ìránṣẹ́ Mefiboṣeti sì ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, òun àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ méjì tí a ti dì ní gàárì, àti igba ìṣù àkàrà lórí wọn, àti ọgọ́rùn-ún síírí àjàrà gbígbẹ, àti ọgọ́rùn-ún èso ẹ̀rún, àti ìgò ọtí wáìnì kan.
Mikor pedig Dávid egy kevéssé alább ment a hegy tetejéről, eleibe jöve Siba, a Mefibóset szolgája, két megnyergelt szamárral, melyeken kétszáz kenyér és száz kötés aszúszőlő és száz csomó füge és egy tömlő bor vala.
2 Ọba sì wí fún Ṣiba pé, “Kí ni wọ̀nyí?” Ṣiba sì wí pé, “Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ̀nyí ni fún àwọn ará ilé ọba láti máa gùn àti àkàrà yìí, àti èso ẹ̀rún yìí ni fún àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin láti jẹ; àti ọtí wáìnì yìí ni fún àwọn aláàárẹ̀ ní ijù láti mu.”
És monda a király Sibának: Mit akarsz ezzel? Felele Siba: A szamarak a király háznépéé legyenek, hogy rajtok járjanak; a kenyér pedig és a füge, hogy a szolgák megegyék, és a bor, hogy igyék, a ki megfárad a pusztában.
3 Ọba sì wí pé, “Ọmọ olúwa rẹ dà?” Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Wò ó, ó jókòó ní Jerusalẹmu; nítorí tí ó wí pé, ‘Lónìí ni ìdílé Israẹli yóò mú ìjọba baba mi padà wá fún mi.’”
És monda a király: Hol van most a te uradnak fia? Felele Siba a királynak: Ímé Jeruzsálemben marada, mert azt mondja: Visszaadja ma nékem Izráel háznépe az én atyámnak országát.
4 Ọba sì wí fún Ṣiba pé, “Wò ó, gbogbo nǹkan tí í ṣe ti Mefiboṣeti jẹ́ tìrẹ.” Ṣiba sì wí pé, “Mo túúbá, jẹ́ kí n rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ, olúwa mi ọba.”
És monda a király Sibának: Ímé minden tied legyen, valamije volt Mefibósetnek. Monda akkor Siba: Meghajtom magamat; vajha kegyelmet találnék előtted, óh uram király!
5 Dafidi ọba sì dé Bahurimu, sì wò ó, ọkùnrin kan ti ibẹ̀ jáde wá, láti ìdílé Saulu wá, orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣimei, ọmọ Gera, ó sì ń bú èébú bí o tí ń bọ̀.
Elméne azután Dávid király Bahurimig, és ímé onnan egy férfi jöve ki a Saul nemzetségéből való, kinek neve Sémei vala, Gérának fia, és kijövén szidalmazza vala őket.
6 Ó sì sọ òkúta sí Dafidi, àti sí gbogbo ìránṣẹ́ Dafidi ọba, àti sí gbogbo ènìyàn, gbogbo àwọn alágbára ọkùnrin sì wà lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti lọ́wọ́ òsì rẹ̀.
És kővel hajigálá Dávidot és Dávid királynak minden szolgáit, jóllehet az egész nép és az erős férfiak mindnyájan az ő jobb és balkeze felől valának.
7 Báyìí ni Ṣimei sì wí nígbà tí ó ń yọ èébú, “Jáde, ìwọ ọkùnrin ẹ̀jẹ̀, ìwọ ọkùnrin Beliali.
És így szóla Sémei szitkozódása közben: Eredj, eredj te vérszopó és istentelen ember!
8 Olúwa mú gbogbo ẹ̀jẹ̀ ìdílé Saulu padà wá sí orí rẹ, ní ipò ẹni tí ìwọ jẹ ọba; Olúwa ti fi ìjọba náà lé Absalomu ọmọ rẹ lọ́wọ́: sì wò ó, ìwà búburú rẹ ni ó mú èyí wá bá ọ, nítorí pé ọkùnrin ẹ̀jẹ̀ ni ìwọ.”
Megfizet most az Úr néked Saul egész házanépének véréért, a ki helyett te uralkodol; és adta az Úr az országot a te fiadnak, Absolonnak: és ímé te nyomorúságban vagy, mert vérszopó ember vagy!
9 Abiṣai ọmọ Seruiah sì wí fún ọba pé, “Èéṣe tí òkú ajá yìí fi ń bú olúwa mi ọba? Jẹ́ kí èmi kọjá, èmi bẹ̀ ọ́, kí èmi sì bẹ́ ẹ́ lórí.”
Monda pedig Abisai, Sérujának fia, a királynak: Hogyan szidalmazhatja ez a holt eb az én uramat, a királyt? Majd én elmegyek és fejét veszem.
10 Ọba sì wí pé, “Kín ni èmi ní ṣe pẹ̀lú yín, ẹ̀yin ọmọ Seruiah? Bí ó bá ń bú èébú, nítorí tí Olúwa ti wí fún un pé, ‘Bú Dafidi!’ Ta ni yóò sì wí pé, ‘Kín ni ìdí tí o fi ṣe bẹ́ẹ̀.’”
Monda pedig a király: Mi közöm van veletek, Sérujának fiai? Hadd szidalmazzon, mert az Úr mondotta néki: Szidalmazzad Dávidot; és ki mondhatja néki: Miért míveled ezt?
11 Dafidi sì wí fún Abiṣai, àti fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wò ó, ọmọ mi tí ó ti inú mi wá, ń wá mi kiri, ǹjẹ́ mélòó mélòó ni ará Benjamini yìí yóò sì ṣe? Fi í sílẹ̀, sì jẹ́ kí o máa yan èébú; nítorí pé Olúwa ni ó sọ fún un.
És monda Dávid Abisainak és minden szolgáinak: Íme az én fiam, ki az én ágyékomból származott, kergeti az én életemet: hogyne cselekedné tehát e Benjáminita? Hagyjatok békét néki, hadd szidalmazzon; mert az Úr mondotta néki.
12 Bóyá Ọlọ́run yóò wo ìpọ́njú mi, Olúwa yóò sì fi ìre san án fún mi ní ipò èébú rẹ̀ lónìí.”
Netalán reá tekint az Úr az én nyomorúságomra, és jóval fizet még ma nékem az Úr az ő átka helyett.
13 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì ń lọ ní ọ̀nà, Ṣimei sì ń rìn òdìkejì òkè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, ó sì ń yan èébú bí ó ti ń lọ, ó sì ń sọ ọ́ lókùúta, ó sì ń fọ́n erùpẹ̀.
És megy vala Dávid és az ő népe az úton, Sémei pedig a hegyoldalon átellenében menvén, mentében átkozódik és köveket hajigál vala ő ellenébe, és port hány vala.
14 Ọba, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì dé Jordani, ó sì rẹ̀ wọ́n, wọ́n sì sinmi níbẹ̀.
Eljuta annakutána a király és az egész nép, mely vele vala, Ajefimbe, és ott megnyugovék.
15 Absalomu àti gbogbo àwọn ènìyàn, àwọn ọkùnrin Israẹli sì wá sí Jerusalẹmu, Ahitofeli sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
Absolon pedig és az egész nép, Izráelnek férfiai, bemenének Jeruzsálembe, és Akhitófel is ő vele.
16 Ó sì ṣe, nígbà tí Huṣai ará Arki, ọ̀rẹ́ Dafidi tọ Absalomu wá, Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Kí ọba ó pẹ́! Kí ọba ó pẹ́.”
Mikor pedig az Arkeából való Khúsai, a Dávid barátja bement Absolonhoz, monda Khúsai Absolonnak: Éljen a király, éljen a király!
17 Absalomu sì wí fún Huṣai pé, “Oore rẹ sí ọ̀rẹ́ rẹ ni èyí? Èéṣe tí ìwọ kò bá ọ̀rẹ́ rẹ lọ?”
És monda Absolon Khúsainak: Ez-é a barátod iránti szereteted? Miért nem mentél el barátoddal?
18 Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ nítorí ẹni tí Olúwa, àti gbogbo àwọn ènìyàn yìí, àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli bá yàn, tirẹ̀ lèmi ó jẹ́, òun lèmi ó sì bá jókòó.
Felele Khúsai Absolonnak: Nem, hanem a kit az Úr és ez a nép választ, és az Izráelnek minden fiai: azé leszek és azzal maradok.
19 Àti pé, ta ni èmi ó sì sìn? Kò ha yẹ kí èmi ó máa sìn níwájú ọmọ rẹ̀? Gẹ́gẹ́ bí èmi ti ń sìn rí níwájú baba rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó sìn níwájú rẹ.”
Azután ugyan kinek szolgálnék örömestebb, mint az én barátom fiának? A mint szolgáltam a te atyádnak, szintén olyan leszek te hozzád is.
20 Absalomu sì wí fún Ahitofeli pé, “Ẹ bá ará yín gbìmọ̀ ohun tí àwa ó ṣe.”
Monda pedig Absolon Akhitófelnek: Adjatok tanácsot, mit cselekedjünk?
21 Ahitofeli sì wí fún Absalomu pé, “Wọlé tọ àwọn obìnrin baba rẹ lọ, tí ó fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, gbogbo Israẹli yóò sì gbọ́ pé, ìwọ di ẹni ìríra sí baba rẹ, ọwọ́ gbogbo àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ yóò sì le.”
Felele Akhitófel Absolonnak: Menj be a te atyádnak ágyasaihoz, a kiket itthon hagyott, hogy őriznék a házat: és megérti az egész Izráel, hogy te atyád előtt gyűlöltté tetted magadat, és annál inkább megerősödnek mindazoknak kezeik, a kik melletted vannak.
22 Wọ́n sì tẹ́ àgọ́ kan fún Absalomu ní òrùlé; Absalomu sì wọlé tọ àwọn obìnrin baba rẹ̀ lójú gbogbo Israẹli.
Sátort vonának azért Absolonnak a tetőn, és beméne Absolon az ő atyjának ágyasaihoz, az egész Izráelnek szeme láttára.
23 Ìmọ̀ Ahitofeli tí ó máa ń gbà ni ìgbà náà, ó dàbí ẹni pé ènìyàn béèrè nǹkan lọ́wọ́ Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ìmọ̀ Ahitofeli fún Dafidi àti fún Absalomu sì rí.
És Akhitófel tanácsa, melyet adott, olyannak tekintetett abban az időben, mintha valaki az Isten szavát kérdezte volna; olyan volt Akhitófelnek minden tanácsa mind Dávid előtt, mind Absolon előtt.

< 2 Samuel 16 >