< 2 Samuel 16 >
1 Nígbà tí Dafidi sì fi díẹ̀ kọjá orí òkè náà, sì wò ó, Ṣiba ìránṣẹ́ Mefiboṣeti sì ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, òun àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ méjì tí a ti dì ní gàárì, àti igba ìṣù àkàrà lórí wọn, àti ọgọ́rùn-ún síírí àjàrà gbígbẹ, àti ọgọ́rùn-ún èso ẹ̀rún, àti ìgò ọtí wáìnì kan.
And whanne Dauid hadde passid a litil the cop of the hil, Siba, the child of Mysphobosech, apperide in to his comyng, with tweyne assis, that weren chargid with twei hundrid looues, and with an hundrid bundels of dried grapis, and with an hundrid gobetis of pressid figus, and with twei vessels of wyn.
2 Ọba sì wí fún Ṣiba pé, “Kí ni wọ̀nyí?” Ṣiba sì wí pé, “Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ̀nyí ni fún àwọn ará ilé ọba láti máa gùn àti àkàrà yìí, àti èso ẹ̀rún yìí ni fún àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin láti jẹ; àti ọtí wáìnì yìí ni fún àwọn aláàárẹ̀ ní ijù láti mu.”
And the kyng seide to Siba, What wolen these thingis to hem silf? And Siba answeride, My lord the kyng, the assis ben to the meyneals of the kyng, that thei sitte; the looues and `figis pressid ben to thi children to ete; forsothe the wyn is, that if ony man faile in deseert, he drynke.
3 Ọba sì wí pé, “Ọmọ olúwa rẹ dà?” Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Wò ó, ó jókòó ní Jerusalẹmu; nítorí tí ó wí pé, ‘Lónìí ni ìdílé Israẹli yóò mú ìjọba baba mi padà wá fún mi.’”
And the kyng seide, Where is the sone of thi lord? And Siba answeride to the kyng, He dwellide in Jerusalem, `and seide, To dai the Lord of the hows of Israel schal restore to me the rewme of my fadir.
4 Ọba sì wí fún Ṣiba pé, “Wò ó, gbogbo nǹkan tí í ṣe ti Mefiboṣeti jẹ́ tìrẹ.” Ṣiba sì wí pé, “Mo túúbá, jẹ́ kí n rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ, olúwa mi ọba.”
And the kyng seide to Siba, Alle thingis that weren of Mysphibosech ben thine. And Siba seide, Y preye, fynde Y grace bifor thee, my lord the kyng.
5 Dafidi ọba sì dé Bahurimu, sì wò ó, ọkùnrin kan ti ibẹ̀ jáde wá, láti ìdílé Saulu wá, orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣimei, ọmọ Gera, ó sì ń bú èébú bí o tí ń bọ̀.
Therfor kyng Dauid cam `til to Bahurym, and lo! a man of the meynee of the hows of Saul, Semey bi name, sone of Gera, yede out fro thennus; he yede forth goynge out, and curside.
6 Ó sì sọ òkúta sí Dafidi, àti sí gbogbo ìránṣẹ́ Dafidi ọba, àti sí gbogbo ènìyàn, gbogbo àwọn alágbára ọkùnrin sì wà lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti lọ́wọ́ òsì rẹ̀.
And he sente stoonys ayens Dauid, and ayens alle seruauntis of kyng Dauid; forsothe al the puple, and alle fiyteris yeden at the riytside and at the left side of the king.
7 Báyìí ni Ṣimei sì wí nígbà tí ó ń yọ èébú, “Jáde, ìwọ ọkùnrin ẹ̀jẹ̀, ìwọ ọkùnrin Beliali.
Sotheli Semey spak so, whanne he curside the kyng, Go out, go out, thou man of bloodis, and man of Belial!
8 Olúwa mú gbogbo ẹ̀jẹ̀ ìdílé Saulu padà wá sí orí rẹ, ní ipò ẹni tí ìwọ jẹ ọba; Olúwa ti fi ìjọba náà lé Absalomu ọmọ rẹ lọ́wọ́: sì wò ó, ìwà búburú rẹ ni ó mú èyí wá bá ọ, nítorí pé ọkùnrin ẹ̀jẹ̀ ni ìwọ.”
The Lord hath yolde to thee al the blood of the hows of Saul, for thou rauyschedist the rewme fro hym; and the Lord yaf the rewme in to the hond of Absolon, thi sone; and lo! thin yuels oppressen thee, for thou art a man of blodis.
9 Abiṣai ọmọ Seruiah sì wí fún ọba pé, “Èéṣe tí òkú ajá yìí fi ń bú olúwa mi ọba? Jẹ́ kí èmi kọjá, èmi bẹ̀ ọ́, kí èmi sì bẹ́ ẹ́ lórí.”
Forsothe Abisay, the sone of Saruye, seide to the kyng, Whi cursith this dogge, that schal die, my lord the kyng? Y schal go, and Y schal girde of his heed.
10 Ọba sì wí pé, “Kín ni èmi ní ṣe pẹ̀lú yín, ẹ̀yin ọmọ Seruiah? Bí ó bá ń bú èébú, nítorí tí Olúwa ti wí fún un pé, ‘Bú Dafidi!’ Ta ni yóò sì wí pé, ‘Kín ni ìdí tí o fi ṣe bẹ́ẹ̀.’”
And the kyng seide, Ye sones of Saruye, what is to me and to you? Suffre ye hym, that he curse; for the Lord comaundide to hym, that he schulde curse Dauid; and who is he that dare seie, Whi dide he so?
11 Dafidi sì wí fún Abiṣai, àti fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wò ó, ọmọ mi tí ó ti inú mi wá, ń wá mi kiri, ǹjẹ́ mélòó mélòó ni ará Benjamini yìí yóò sì ṣe? Fi í sílẹ̀, sì jẹ́ kí o máa yan èébú; nítorí pé Olúwa ni ó sọ fún un.
And the kyng seide to Abysay, and to alle hise seruauntis, Lo! my sone, that yede out of my wombe, sekith my lijf; hou myche more now this sone of Gemyny? Suffre ye hym, that he curse bi comaundement of the Lord;
12 Bóyá Ọlọ́run yóò wo ìpọ́njú mi, Olúwa yóò sì fi ìre san án fún mi ní ipò èébú rẹ̀ lónìí.”
if in hap the Lord biholde my turmentyng, and yelde good to me for this `cursyng of this dai.
13 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì ń lọ ní ọ̀nà, Ṣimei sì ń rìn òdìkejì òkè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, ó sì ń yan èébú bí ó ti ń lọ, ó sì ń sọ ọ́ lókùúta, ó sì ń fọ́n erùpẹ̀.
Therfor Dauid yede, and hise felowis, bi the weie with hym; forsothe Semey yede bi the slade of the hil `bi the side ayens hym; and curside, and sente stoonus ayens him, and spreynte erthe.
14 Ọba, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì dé Jordani, ó sì rẹ̀ wọ́n, wọ́n sì sinmi níbẹ̀.
And so `Dauid the king cam, and al the puple weery with hym, and thei weren refreischid there.
15 Absalomu àti gbogbo àwọn ènìyàn, àwọn ọkùnrin Israẹli sì wá sí Jerusalẹmu, Ahitofeli sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
Forsothe Absolon, and al the puple of Israel entriden in to Jerusalem, but also Achitofel with hym.
16 Ó sì ṣe, nígbà tí Huṣai ará Arki, ọ̀rẹ́ Dafidi tọ Absalomu wá, Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Kí ọba ó pẹ́! Kí ọba ó pẹ́.”
Sotheli whanne Chusi of Arath, the frend of Dauid, hadde come to Absolon, he spak to Absolon, Heil, kyng! heil, kyng!
17 Absalomu sì wí fún Huṣai pé, “Oore rẹ sí ọ̀rẹ́ rẹ ni èyí? Èéṣe tí ìwọ kò bá ọ̀rẹ́ rẹ lọ?”
To whom Absolon seide, This is thi grace to thi freend; whi yedist thou not with thi freend?
18 Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ nítorí ẹni tí Olúwa, àti gbogbo àwọn ènìyàn yìí, àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli bá yàn, tirẹ̀ lèmi ó jẹ́, òun lèmi ó sì bá jókòó.
And Chusi answeride to Absolon, Nay, for Y shal be seruaunt of hym, whom the Lord hath chose, and al this puple, and al Israel; and Y schal dwelle with him.
19 Àti pé, ta ni èmi ó sì sìn? Kò ha yẹ kí èmi ó máa sìn níwájú ọmọ rẹ̀? Gẹ́gẹ́ bí èmi ti ń sìn rí níwájú baba rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó sìn níwájú rẹ.”
But that Y seie also this, to whom schal Y serue? whethir not to the sone of the kyng? as Y obeiede to thi fadir, so Y schal obeie to thee.
20 Absalomu sì wí fún Ahitofeli pé, “Ẹ bá ará yín gbìmọ̀ ohun tí àwa ó ṣe.”
Forsothe Absolon seide to Achitofel, Take ye counsel, what we owen to do.
21 Ahitofeli sì wí fún Absalomu pé, “Wọlé tọ àwọn obìnrin baba rẹ lọ, tí ó fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, gbogbo Israẹli yóò sì gbọ́ pé, ìwọ di ẹni ìríra sí baba rẹ, ọwọ́ gbogbo àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ yóò sì le.”
And Achytofel seide to Absolon, Entre thou to the concubyns of thi fadir, whiche he lefte to kepe the hows; that whanne al Israel herith, that thou hast defoulid thi fadir, the hondis of hem be strengthid with thee.
22 Wọ́n sì tẹ́ àgọ́ kan fún Absalomu ní òrùlé; Absalomu sì wọlé tọ àwọn obìnrin baba rẹ̀ lójú gbogbo Israẹli.
Therfor thei tildeden Absolon a tabernacle in the soler, and he entride to the concubyns of his fadir bifor al Israel.
23 Ìmọ̀ Ahitofeli tí ó máa ń gbà ni ìgbà náà, ó dàbí ẹni pé ènìyàn béèrè nǹkan lọ́wọ́ Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ìmọ̀ Ahitofeli fún Dafidi àti fún Absalomu sì rí.
Sotheli the counsel of Achitofel, which he yaf in tho daies, was as if a man counselide God; so was al the counsel of Achitofel, bothe whanne he was with Dauid, and whanne he was with Absolon.