< 2 Samuel 16 >

1 Nígbà tí Dafidi sì fi díẹ̀ kọjá orí òkè náà, sì wò ó, Ṣiba ìránṣẹ́ Mefiboṣeti sì ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, òun àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ méjì tí a ti dì ní gàárì, àti igba ìṣù àkàrà lórí wọn, àti ọgọ́rùn-ún síírí àjàrà gbígbẹ, àti ọgọ́rùn-ún èso ẹ̀rún, àti ìgò ọtí wáìnì kan.
Da: ibidi da agolo da: iya heda: le, fonobahadi baligili, Mifibousiede ea hawa: hamosu dunu amo Saiba, da ema hedolowane doaga: i. E da dougi aduna oule misi. Amo da: iya da falaua ga: gi 200amola waini fage fofogai gagabu 100agoane amola gaheabolo ifa fage gagabu amola bulamagau gadofoga hamoi daba, waini hanoga nabai, amo dougi da: iya diafulubi ba: i.
2 Ọba sì wí fún Ṣiba pé, “Kí ni wọ̀nyí?” Ṣiba sì wí pé, “Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ̀nyí ni fún àwọn ará ilé ọba láti máa gùn àti àkàrà yìí, àti èso ẹ̀rún yìí ni fún àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin láti jẹ; àti ọtí wáìnì yìí ni fún àwọn aláàárẹ̀ ní ijù láti mu.”
Hina bagade Da: ibidi da ema amane adole ba: i, “Dia da amo liligi huluane adi hamomusa: gaguli misibala: ?” Saiba da bu adole i, “Hina noga: idafa! Dougi da dia sosogo fi ili fila heda: le masa: ne oule misi. Falaua ga: gi amola ifa fage da dia dunu ilia moma: ne amola waini hano da ilia wadela: i sogega ahoana hele nabasea, amo moma: ne gaguli misi.”
3 Ọba sì wí pé, “Ọmọ olúwa rẹ dà?” Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Wò ó, ó jókòó ní Jerusalẹmu; nítorí tí ó wí pé, ‘Lónìí ni ìdílé Israẹli yóò mú ìjọba baba mi padà wá fún mi.’”
Da: ibidi da amane adole ba: i, “Dia hina Solo amo ea aowa Mifibousiede da habila: ?” Saiba da bu adole i, “E da Yelusaleme amo ganodini ouesala. Bai Isala: ili dunu da ea aowa Solo ea hina bagade hou, amo ema bu imunu, amo e da dafawaneyale dawa: sa.”
4 Ọba sì wí fún Ṣiba pé, “Wò ó, gbogbo nǹkan tí í ṣe ti Mefiboṣeti jẹ́ tìrẹ.” Ṣiba sì wí pé, “Mo túúbá, jẹ́ kí n rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ, olúwa mi ọba.”
Hina bagade da Saibama amane sia: i, “Na da Mifibousiede ea musa: gagui huluane dima iaha.” Saiba da bu adole i, “Hina noga: idafa! Na da dia hawa: hamosu dunu esala. Na da eso huluane di hahawane ba: ma: ne hamomu da defea.”
5 Dafidi ọba sì dé Bahurimu, sì wò ó, ọkùnrin kan ti ibẹ̀ jáde wá, láti ìdílé Saulu wá, orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣimei, ọmọ Gera, ó sì ń bú èébú bí o tí ń bọ̀.
Da: ibidi da Bahiulimi moilaiga doaga: loba, Solo ea fi dunu afae, amo Simiai (Gila egefe) da ougiba: le misini, e da ilima gagabusu aligima: ne sia: sisia: asi.
6 Ó sì sọ òkúta sí Dafidi, àti sí gbogbo ìránṣẹ́ Dafidi ọba, àti sí gbogbo ènìyàn, gbogbo àwọn alágbára ọkùnrin sì wà lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti lọ́wọ́ òsì rẹ̀.
Simiai da muni Da: ibidi amola ea eagene ouligisu ilima igiga gagala: lu. Da: ibidi ea dunu amola ea da: i sosodo aligisu dunu da Da: ibidi sisiga: le lelu, be e da amo mae dawa: le, igiga gagala: i.
7 Báyìí ni Ṣimei sì wí nígbà tí ó ń yọ èébú, “Jáde, ìwọ ọkùnrin ẹ̀jẹ̀, ìwọ ọkùnrin Beliali.
Simiai da gagabui aligima: ne ilegele, amane sia: i, “Gadili masa! Gadili masa! Di da fasu dunu! Di da wadela: i hamosu dunu!
8 Olúwa mú gbogbo ẹ̀jẹ̀ ìdílé Saulu padà wá sí orí rẹ, ní ipò ẹni tí ìwọ jẹ ọba; Olúwa ti fi ìjọba náà lé Absalomu ọmọ rẹ lọ́wọ́: sì wò ó, ìwà búburú rẹ ni ó mú èyí wá bá ọ, nítorí pé ọkùnrin ẹ̀jẹ̀ ni ìwọ.”
Di da Solo ea hina bagade hou samogei. Amola, di da Solo ea sosogo fi bagohame fane legeiba: le, Hina Gode da dima se iaha. Hina Gode da hina bagade hou dima fadegale, dia mano A: basalome igili i dagoi. Di fane legesu dunu! Di da wadela: lesi dagoi ba: sa!”
9 Abiṣai ọmọ Seruiah sì wí fún ọba pé, “Èéṣe tí òkú ajá yìí fi ń bú olúwa mi ọba? Jẹ́ kí èmi kọjá, èmi bẹ̀ ọ́, kí èmi sì bẹ́ ẹ́ lórí.”
Abisia: i (ea ame da Selouaia) da hina bagadema amane sia: i, “Hina noga: idafa! Di abuliba: le, amo wa: me dima gagabui aligisa, amo ea logo hame hedofasala: ? Dia na asili, ea dialuma damuni fasima: ne sia: ma!”
10 Ọba sì wí pé, “Kín ni èmi ní ṣe pẹ̀lú yín, ẹ̀yin ọmọ Seruiah? Bí ó bá ń bú èébú, nítorí tí Olúwa ti wí fún un pé, ‘Bú Dafidi!’ Ta ni yóò sì wí pé, ‘Kín ni ìdí tí o fi ṣe bẹ́ẹ̀.’”
Hina bagade da Abisia: i amola ea ola Youa: be elama amane sia: i, “Amo da alia liligi hame! E da nama gagabusa galea, Hina Gode da ema amane hamoma: ne adoiba: le, amo hou ea bai ema adole ba: mu da hamedei.”
11 Dafidi sì wí fún Abiṣai, àti fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wò ó, ọmọ mi tí ó ti inú mi wá, ń wá mi kiri, ǹjẹ́ mélòó mélòó ni ará Benjamini yìí yóò sì ṣe? Fi í sílẹ̀, sì jẹ́ kí o máa yan èébú; nítorí pé Olúwa ni ó sọ fún un.
Amola Da: ibidi da Abisia: i amola ea eagene ouligisu dunu huluane ilima amane sia: i, “Nagofedafa da na fane legemusa: logo hogolala. Amaiba: le, amo Bediamini dunu ea hou ba: beba: le, mae fofogadigima! Hina Gode da adobeba: le, e da nama gagabusu aligima: ne sia: sa. Amaiba: le, ema mae sia: ma. E da amo hou hamomu da defea.
12 Bóyá Ọlọ́run yóò wo ìpọ́njú mi, Olúwa yóò sì fi ìre san án fún mi ní ipò èébú rẹ̀ lónìí.”
Amabela: ? Hina Gode da na da: i dioi bagade ba: ma: bela: ? Amasea, e da amo gagabusu aligima: ne fadegale, nama hahawane hou ima: bela: ?”
13 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì ń lọ ní ọ̀nà, Ṣimei sì ń rìn òdìkejì òkè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, ó sì ń yan èébú bí ó ti ń lọ, ó sì ń sọ ọ́ lókùúta, ó sì ń fọ́n erùpẹ̀.
Amaiba: le, Da: ibidi amola ea dunu da bu logoga ahoanu. Simiai da ili galu agolo bega: ahoanu. E da ilima gagabusa amola, ilima igi amola osoboga gagala: sa ahoanu.
14 Ọba, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì dé Jordani, ó sì rẹ̀ wọ́n, wọ́n sì sinmi níbẹ̀.
Hina bagade amola ea dunu huluane da hele nabawane, Yoda: ne Hano amoga doaga: i. Amogawi ilia da helefi.
15 Absalomu àti gbogbo àwọn ènìyàn, àwọn ọkùnrin Israẹli sì wá sí Jerusalẹmu, Ahitofeli sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
A: basalome amola ema fa: no bobogebe Isala: ili dunu huluane da Yelusaleme moilai bai bagadega golili sa: i. Ahidoufele da ili galuwane golili sa: i.
16 Ó sì ṣe, nígbà tí Huṣai ará Arki, ọ̀rẹ́ Dafidi tọ Absalomu wá, Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Kí ọba ó pẹ́! Kí ọba ó pẹ́.”
Hiusiai (Da: ibidi ea sama) da A: basalomema doaga: le, amane wele sia: i, “Hina bagade! Gebe esaloma: mu! Gebe esaloma: mu!”
17 Absalomu sì wí fún Huṣai pé, “Oore rẹ sí ọ̀rẹ́ rẹ ni èyí? Èéṣe tí ìwọ kò bá ọ̀rẹ́ rẹ lọ?”
A: basalome da ema amane sia: i, “Di da dia sama Da: ibidi fisiagabela: ? Di abuliba: le ali hame asibala: ?”
18 Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ nítorí ẹni tí Olúwa, àti gbogbo àwọn ènìyàn yìí, àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli bá yàn, tirẹ̀ lèmi ó jẹ́, òun lèmi ó sì bá jókòó.
Hiusiai da bu adole i, “Na da habodane e amola ahoabela: ? Na da dunu amo Hina Gode da ilegei amola Isala: ili dunu huluane ilimagale ahoa. Na da ani esalumu.
19 Àti pé, ta ni èmi ó sì sìn? Kò ha yẹ kí èmi ó máa sìn níwájú ọmọ rẹ̀? Gẹ́gẹ́ bí èmi ti ń sìn rí níwájú baba rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó sìn níwájú rẹ.”
Na da na hina eagofe amo ea hawa: fawane hamomu da defea. Na da dia ada ea hawa: hamoi amo defele dia hawa: hamomu.”
20 Absalomu sì wí fún Ahitofeli pé, “Ẹ bá ará yín gbìmọ̀ ohun tí àwa ó ṣe.”
Amalalu, A:basalome da delegili, Ahidoufelema amane sia: i, “Wali ninia huluane da guiguda: esalebe goea! Di da ninia hamoma: ne, adi fada: i sia: sia: sala: ?”
21 Ahitofeli sì wí fún Absalomu pé, “Wọlé tọ àwọn obìnrin baba rẹ lọ, tí ó fi sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé, gbogbo Israẹli yóò sì gbọ́ pé, ìwọ di ẹni ìríra sí baba rẹ, ọwọ́ gbogbo àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ yóò sì le.”
Ahidoufele da ema bu adole i, “Dia asili, dia ada ea gidisedagi uda amo e da hina bagade diasu ouligimusa: guiguda: yolesi, amo huluane adole lama. Amasea, Isala: ili dunu da dia ada da dia ha lai dunu, amo noga: le dawa: mu. Amola dima fa: no bobogesu dunu da dogo denesi ba: mu.”
22 Wọ́n sì tẹ́ àgọ́ kan fún Absalomu ní òrùlé; Absalomu sì wọlé tọ àwọn obìnrin baba rẹ̀ lójú gbogbo Israẹli.
Amaiba: le, ilia da hina bagade diasu gadodili fa: i amo da: iya abula diasu gagui. Amogawi, dunu huluane ba: ma: ne, A:basalome da ea ada ea gidisedagi uda huluane adole lai.
23 Ìmọ̀ Ahitofeli tí ó máa ń gbà ni ìgbà náà, ó dàbí ẹni pé ènìyàn béèrè nǹkan lọ́wọ́ Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ìmọ̀ Ahitofeli fún Dafidi àti fún Absalomu sì rí.
Amo esoga, nowa da Ahidoufele ea fada: i sia: nabaloba, ilia da amo sia: da Gode Ea sia: defele dafawaneyale dawa: su. Da: ibidi amola A: basalome da amo sia: fa: no bobogesu.

< 2 Samuel 16 >