< 2 Samuel 15 >

1 Lẹ́yìn èyí náà, Absalomu sì pèsè kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin fún ara rẹ̀, àti àádọ́ta ọmọkùnrin tí yóò máa sáré níwájú rẹ̀.
И бысть по сих, и сотвори себе Авессалом колесницы и кони и пятьдесят муж текущих пред ним:
2 Absalomu sì dìde ní kùtùkùtù, ó sì dúró ní apá kan ọ̀nà ẹnu ibodè. Bí ẹnìkan bá ní ẹjọ́ tí ó ń fẹ́ mú tọ ọba wá fún ìdájọ́, a sì pè é sọ́dọ̀ rẹ̀, a sì bi í pé, “Ará ìlú wo ni ìwọ?” Òun a sì dáhùn pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ti inú ọ̀kan nínú ẹ̀yà Israẹli wá.”
и воставаше рано Авессалом, и стояше при самем пути врат: и бысть всяк муж, емуже бяше пря, прииде пред царя на суд, и возопи к нему Авессалом, и глаголаше ему: от коего града ты еси? И рече ему муж: от единаго колен Израилевых раб твой.
3 Absalomu yóò sì wí fún un pé, “Wò ó, ọ̀ràn rẹ ṣá dára, ó sì tọ́, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ọba fi àṣẹ fún láti gbọ́ ọ̀ràn rẹ.”
И рече к нему Авессалом: се, словеса твоя блага и удобна, но слушающаго несть ти от царя.
4 Absalomu a sì wí pé, “À bá jẹ́ fi mi ṣe onídàájọ́ ní ilẹ̀ yìí! Kí olúkúlùkù ẹni tí ó ní ẹjọ́ tàbí ọ̀ràn kan bá à lè máa tọ̀ mí wá, èmi ìbá sì ṣe ìdájọ́ òtítọ́ fún un.”
И рече Авессалом: кто мя поставит судию на земли, и ко мне приидет всяк муж имеяй прю и суд, и оправдаю его?
5 Bẹ́ẹ̀ ni bí ẹnìkan bá sì súnmọ́ láti tẹríba fún un, òun a sì nawọ́ rẹ̀, a sì dìímú, a sì fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
И бысть егда приближашеся муж поклонитися ему, и простираше руку свою, и приимаше его, и целоваше его.
6 Irú ìwà báyìí ni Absalomu a máa hù sí gbogbo Israẹli tí ó tọ́ ọba wá nítorí ìdájọ́, Absalomu sì fi fa ọkàn àwọn ènìyàn Israẹli sọ́dọ̀ rẹ̀.
И сотвори Авессалом по глаголу сему всему Израилю приходящым на суд к царю и приусвои Авессалом сердца сынов Израилевых.
7 Ó sì ṣe lẹ́yìn ogójì ọdún, Absalomu sì wí fún ọba pé, “Èmi bẹ́ ọ́, jẹ́ kí èmi ó lọ, kí èmi sì san ìlérí mi tí èmi ti ṣe fún Olúwa, ní Hebroni.
И бысть от конца четыредесяти лет, и рече Авессалом ко отцу своему: пойду ныне и воздам обеты моя, яже обещах Господу в Хевроне:
8 Nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ kan nígbà tí èmi ń bẹ ní Geṣuri ní Siria pé, ‘Bí Olúwa bá mú mi padà wá sí Jerusalẹmu, nítòótọ́, èmi ó sì sin Olúwa.’”
зане обет обеща раб твой, егда жих в Гедсуре Сирийстем, глаголя: аще возвращая возвратит мя Господь во Иерусалим, и послужу Господу.
9 Ọba sì wí fún un pé, “Máa lọ ní àlàáfíà.” Ó sì dìde, ó sì lọ sí Hebroni.
И рече ему царь: иди с миром. И востав иде в Хеврон.
10 Ṣùgbọ́n Absalomu rán àmì sáàrín gbogbo ẹ̀yà Israẹli pé, “Nígbà tí ẹ̀yin bá gbọ́ ìró ìpè, kí ẹ̀yin sì wí pé, ‘Absalomu jẹ ọba ní Hebroni.’”
И посла Авессалом соглядатаи во вся колена Израилева, глаголя: егда услышите вы глас трубы рожаны, и рцыте: воцарися царь Авессалом в Хевроне.
11 Igba ọkùnrin sì bá Absalomu ti Jerusalẹmu jáde, nínú àwọn tí a ti pè; wọ́n sì lọ nínú àìmọ̀kan wọn, wọn kò sì mọ nǹkan kan.
И идоша со Авессаломом двести мужей от Иерусалима позвани: и идяху в простоте своей, и не разумеша всякаго глагола.
12 Absalomu sì ránṣẹ́ pe Ahitofeli ará Giloni, ìgbìmọ̀ Dafidi, láti ìlú rẹ̀ wá, àní láti Giloni, nígbà tí ó ń rú ẹbọ. Ìdìmọ̀lù náà sì le; àwọn ènìyàn sì ń pọ̀ sọ́dọ̀ Absalomu.
И посла Авессалом, и призва Ахитофела Галамонийскаго, советника Давидова, от града его Голамы, егда жряше жертвы. И бысть смятение крепко: и людий множество идущих со Авессаломом.
13 Ẹnìkan sì wá rò fún Dafidi pé, “Ọkàn àwọn ọkùnrin Israẹli ṣí sí Absalomu.”
И прииде вестник к Давиду, глаголя: бысть сердце мужей Израилевых со Авессаломом.
14 Dafidi sì wí fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó wá lọ́dọ̀ rẹ̀ ni Jerusalẹmu pé, “Ẹ dìde! Ẹ jẹ́ kí a sálọ, nítorí pé kò sí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ Absalomu; ẹ yára, kí a lọ kúrò, kí òun má bá à yára lé wa bá, kí ó má sì mú ibi bá wa, kí ó má sì fi ojú idà pa ìlú run.”
И рече Давид всем отроком своим сущым с ним во Иерусалиме: востаните, и бежим, яко несть нам спасения от лица Авессаломля: ускорите ити, да не ускорит и возмет нас, и наведет на нас злобу, и избиет град острием меча.
15 Àwọn ìránṣẹ́ ọba sì wí fún ọba pé, “Gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí olúwa wa ọba ń fẹ́, wò ó, àwa ìránṣẹ́ rẹ̀ ti murá.”
И реша отроцы царевы к царю: вся елика заповесть господь наш царь, се, мы отроцы твои.
16 Ọba sì jáde, gbogbo ilé rẹ̀ sì tẹ̀lé e. Ọba sì fì mẹ́wàá nínú àwọn obìnrin rẹ̀ sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé.
И изыде царь и весь дом его ногами своими, и остави царь десять жен подложниц своих хранити дом.
17 Ọba sì jáde, gbogbo ènìyàn sì tẹ̀lé e, wọ́n sì dúró ní ibìkan tí ó jìnnà.
И изыде царь и вси отроцы его пеши и сташа в Дому Сущем Далече:
18 Gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì kọjá sí iwájú rẹ̀, àti gbogbo àwọn Kereti, àti gbogbo àwọn Peleti, àti gbogbo àwọn ará Gitti, ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn láti Gati wá, sì kọjá níwájú ọba.
и вси отроцы его от обою страну его идяху, и вси Хелефее и вси Фелефее и вси Гефее, шесть сот мужей шедше пеши от Гефа предидяху пред лицем царевым.
19 Ọba sì wí fún Ittai ará Gitti pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń bá wa lọ pẹ̀lú, padà, kí o sì ba ọba jókòó; nítorí pé àlejò ni ìwọ, ìwọ sì ti fi ìlú rẹ sílẹ̀.
И рече царь ко Еффею Геффеину: почто и ты идеши с нами? Возвратися и живи с царем, яко чуждь еси ты, и яко преселился еси ты от места твоего:
20 Lánàá yìí ni ìwọ dé, èmi ó ha sì mú kí ìwọ máa bá wá lọ káàkiri lónìí bí? Èmi ń lọ sí ibikíbi tí mo bá rí: padà, kí o sì mú àwọn arákùnrin rẹ padà, kí àánú àti òtítọ́ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
аще вчера пришел еси, и днесь ли подвигну тя ити с нами? И аз иду, аможе пойду: иди и возвратися, и возврати братию твою с тобою, и Господь да сотворит с тобою милость и истину.
21 Ittai sì dá ọba lóhùn, ó sì wí pé, “Bí Olúwa tí ń bẹ láààyè, àti bí olúwa mi ọba ti ń bẹ láààyè, nítòótọ́ níbikíbi tí olúwa mi ọba bá gbé wà, ìbá à ṣe nínú ikú, tàbí nínú ìyè, níbẹ̀ pẹ̀lú ni ìránṣẹ́ rẹ yóò gbé wà.”
И отвеща Еффей к царю и рече: жив Господь, и жив господин мой царь, яко на месте, идеже будет господин мой царь, или в смерти, или в животе, тамо будет раб твой.
22 Dafidi sì wí fún Ittai pé, “Lọ kí o sì rékọjá!” Ittai ará Gitti náà sì rékọjá, àti gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àti gbogbo àwọn ọmọ kéékèèké tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀.
И рече царь ко Еффею: гряди, и прейди со мною. И прейде Еффей Геффеин и царь и вси отроцы его и весь народ иже с ним.
23 Gbogbo ìlú náà sì fi ohùn rara sọkún, gbogbo ènìyàn sì rékọjá; ọba sì rékọjá àfonífojì Kidironi, gbogbo àwọn ènìyàn náà sì rékọjá, sí ìhà ọ̀nà ijù.
И вся земля плакашеся гласом великим. И вси людие прехождаху по потоку Кедрску, и царь прейде чрез поток Кедрский, и вси людие и царь идяху к лицу пути пустыннаго.
24 Sì wò ó, Sadoku pẹ̀lú àti gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sí ń ru àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run náà sọ̀kalẹ̀; Abiatari sí gòkè, títí gbogbo àwọn ènìyàn sì fi dẹ́kun àti máa kọjá láti ìlú wá.
И се, и Садок иерей и вси левити с ним, носяще кивот завета Господня от Вефары: и поставиша кивот Божий: и Авиафар взыде, дондеже престаша вси людие исходити из града.
25 Ọba sì wí fún Sadoku pé, “Sì tún gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run náà padà sí ìlú, bí èmi bá rí ojúrere gbà lọ́dọ̀ Olúwa, yóò sì tún mú mi padà wá, yóò sì fi àpótí ẹ̀rí náà hàn mí àti ibùgbé rẹ̀.
И рече царь к Садоку: возврати кивот Божий во град, и да станет на месте своем: аще обрящу благодать пред очима Господнима, и возвратит мя, и покажет ми его и лепоту его:
26 Ṣùgbọ́n bí òun bá sì wí pé, ‘Èmi kò ní inú dídùn sí ọ,’ wò ó, èmi nìyìí, jẹ́ kí òun ó ṣe sí mi gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ ní ojú rẹ̀.”
и аще тако речет: не благоволих в тебе: се, аз есмь, да сотворит ми по благому пред очима Своима.
27 Ọba sì wí fún Sadoku àlùfáà pé, “Aríran ha kọ́ ni ọ́? Padà sí ìlú ní àlàáfíà, àti àwọn ọmọ rẹ méjèèjì pẹ̀lú rẹ, Ahimasi ọmọ rẹ, àti Jonatani ọmọ Abiatari.
И рече царь Садоку иерею: видите, ты возвращаешися во град с миром и Ахимаас сын твой и Ионафан сын Авиафаров, два сыны ваши с вами:
28 Wò ó, èmi ó dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ijù náà, títí ọ̀rọ̀ ó fi ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá láti sọ fún mi.”
видите, аз вселяюся во аравоф пустынный, дондеже приидет ми слово от вас, еже возвестити ми.
29 Sadoku àti Abiatari sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run padà sí Jerusalẹmu, wọ́n sì gbé ibẹ̀.
И возврати Садок и Авиафар кивот Божий во Иерусалим, и седе тамо.
30 Dafidi sì ń gòkè lọ ní òkè igi olifi, o sì ń sọkún bí ó ti ń gòkè lọ, ó sì bo orí rẹ̀, ó ń lọ láìní bàtà ní ẹsẹ̀, gbogbo ènìyàn tí o wà lọ́dọ̀ rẹ̀, olúkúlùkù ọkùnrin sì bo orí rẹ̀, wọ́n sì ń gòkè lọ, wọ́n ń sọkún bí wọ́n ti ń gòkè lọ.
И Давид восхождаше восходом на гору Елеонскую восходя и плачася, и покрыв главу свою, и сам идяше босыма ногама: и вси людие иже с ним покрыша кийждо главу свою, и восхождаху восходяще и плачущеся.
31 Ẹnìkan sì sọ fún Dafidi pé, “Ahitofeli wà nínú àwọn aṣọ̀tẹ̀ pẹ̀lú Absalomu.” Dafidi sì wí pé, “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, sọ ìmọ̀ Ahitofeli di asán.”
И возвестиша Давиду глаголюще: и Ахитофел в мятежницех со Авессаломом. И рече Давид: разруши совет Ахитофелев, Господи, Боже мой.
32 Ó sì ṣe, Dafidi dé orí òkè, níbi tí ó gbé wólẹ̀ sin Ọlọ́run, sì wò ó, Huṣai ará Arki sì wá láti pàdé rẹ̀ pẹ̀lú aṣọ rẹ̀ yíya, àti erùpẹ̀, lórí rẹ̀.
И бе Давид грядый даже до роса, идеже поклонися Богу. И се, на сретение ему (изыде) Хусий первый друг Давидов, растерзав ризы своя, и персть на главе его.
33 Dafidi sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá bá mi kọjá, ìwọ ó sì jẹ́ ìdíwọ́ fún mi.
И рече ему Давид: аще пойдеши со мною, и будеши ми в тягость:
34 Bí ìwọ bá sì padà sí ìlú, tí o sì wí fún Absalomu pé, ‘Èmi ó ṣe ìránṣẹ́ rẹ ọba, gẹ́gẹ́ bí èmi ti ṣe ìránṣẹ́ baba rẹ nígbà àtijọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó sì jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ nísinsin yìí,’ kí ìwọ sì bá ìmọ̀ Ahitofeli jẹ́.
аще же возвратишися во град и речеши Авессалому: минуша братия твоя, и царь за мною мину отец твой, и ныне раб твой есмь, царю, пощади мя жива быти: раб бех отца твоего тогда и доселе, ныне же аз твой раб: и разруши ми совет Ахитофелев:
35 Ṣé Sadoku àti Abiatari àwọn àlùfáà wà níbẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀? Yóò sì ṣe, ohunkóhun tí ìwọ bá gbọ́ láti ilé ọba wá, ìwọ ó sì sọ fún Sadoku àti Abiatari àwọn àlùfáà.
и се, с тобою тамо Садок и Авиафар иерее: и будет всяк глагол, егоже услышиши из уст царских, и скажеши Садоку и Авиафару иереем:
36 Wò ó, àwọn ọmọ wọn méjèèjì sì wà níbẹ̀ pẹ̀lú wọn, Ahimasi ọmọ Sadoku, àti Jonatani ọmọ Abiatari; láti ọwọ́ wọn ni ẹ̀yin ó sì rán ohunkóhun tí ẹ̀yin bá gbọ́ sí mi.”
се, тамо с ними два сына их, Ахимаас сын Садоков и Ионафан сын Авиафаров: и послите рукою их ко мне всяк глагол, егоже аще услышите.
37 Huṣai ọ̀rẹ́ Dafidi sì wá sí ìlú, Absalomu sì wá sí Jerusalẹmu.
И вниде Хусий друг Давидов во град, и Авессалом тогда вхождаше во Иерусалим.

< 2 Samuel 15 >