< 2 Samuel 15 >

1 Lẹ́yìn èyí náà, Absalomu sì pèsè kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin fún ara rẹ̀, àti àádọ́ta ọmọkùnrin tí yóò máa sáré níwájú rẹ̀.
Kwasekusithi emva kwalokhu uAbisalomu wazilungisela izinqola lamabhiza, labantu abangamatshumi amahlanu begijima phambi kwakhe.
2 Absalomu sì dìde ní kùtùkùtù, ó sì dúró ní apá kan ọ̀nà ẹnu ibodè. Bí ẹnìkan bá ní ẹjọ́ tí ó ń fẹ́ mú tọ ọba wá fún ìdájọ́, a sì pè é sọ́dọ̀ rẹ̀, a sì bi í pé, “Ará ìlú wo ni ìwọ?” Òun a sì dáhùn pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ti inú ọ̀kan nínú ẹ̀yà Israẹli wá.”
UAbisalomu wayesevuka ekuseni kakhulu eme eceleni kwendlela yesango; kwakusithi wonke umuntu olecala lomthetho eliya enkosini ukwahlulelwa, uAbisalomu ambize athi: Ungowawuphi umuzi? Lapho esithi: Inceku yakho ingowesinye sezizwe zakoIsrayeli;
3 Absalomu yóò sì wí fún un pé, “Wò ó, ọ̀ràn rẹ ṣá dára, ó sì tọ́, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ọba fi àṣẹ fún láti gbọ́ ọ̀ràn rẹ.”
uAbisalomu abesesithi kuye: Bona, indaba zakho zinhle zilungile, kodwa kakho owenkosi ukuthi akuzwe.
4 Absalomu a sì wí pé, “À bá jẹ́ fi mi ṣe onídàájọ́ ní ilẹ̀ yìí! Kí olúkúlùkù ẹni tí ó ní ẹjọ́ tàbí ọ̀ràn kan bá à lè máa tọ̀ mí wá, èmi ìbá sì ṣe ìdájọ́ òtítọ́ fún un.”
UAbisalomu abesesithi: Kungathi ngabe ngibekwe umahluleli elizweni, ukuthi wonke umuntu olecala lomthetho lodaba angeza kimi, njalo bengizamlungisela.
5 Bẹ́ẹ̀ ni bí ẹnìkan bá sì súnmọ́ láti tẹríba fún un, òun a sì nawọ́ rẹ̀, a sì dìímú, a sì fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
Kwakusithi lapho kusondela umuntu ukumkhothamela, elule isandla sakhe, ambambe, amange.
6 Irú ìwà báyìí ni Absalomu a máa hù sí gbogbo Israẹli tí ó tọ́ ọba wá nítorí ìdájọ́, Absalomu sì fi fa ọkàn àwọn ènìyàn Israẹli sọ́dọ̀ rẹ̀.
UAbisalomu wasesenza ngalindlela kuIsrayeli wonke, bona abeza enkosini ukwahlulelwa; ngalokho uAbisalomu wathumba inhliziyo yamadoda akoIsrayeli.
7 Ó sì ṣe lẹ́yìn ogójì ọdún, Absalomu sì wí fún ọba pé, “Èmi bẹ́ ọ́, jẹ́ kí èmi ó lọ, kí èmi sì san ìlérí mi tí èmi ti ṣe fún Olúwa, ní Hebroni.
Kwasekusithi ekupheleni kweminyaka engamatshumi amane uAbisalomu wathi enkosini: Ake ngiyekhokha isithembiso sami engasithembisa eNkosini eHebroni.
8 Nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ kan nígbà tí èmi ń bẹ ní Geṣuri ní Siria pé, ‘Bí Olúwa bá mú mi padà wá sí Jerusalẹmu, nítòótọ́, èmi ó sì sin Olúwa.’”
Ngoba inceku yakho yathembisa isithembiso ngisahlala eGeshuri eSiriya ngisithi: Uba iNkosi ingibuyisela lokungibuyisela eJerusalema, ngizayikhonza iNkosi.
9 Ọba sì wí fún un pé, “Máa lọ ní àlàáfíà.” Ó sì dìde, ó sì lọ sí Hebroni.
Inkosi yasisithi kuye: Hamba ngokuthula. Wasesukuma waya eHebroni.
10 Ṣùgbọ́n Absalomu rán àmì sáàrín gbogbo ẹ̀yà Israẹli pé, “Nígbà tí ẹ̀yin bá gbọ́ ìró ìpè, kí ẹ̀yin sì wí pé, ‘Absalomu jẹ ọba ní Hebroni.’”
Kodwa uAbisalomu wathuma izinhloli ezizweni zonke zakoIsrayeli esithi: Lapho lisizwa ukukhala kophondo, lizakuthi: UAbisalomu uyinkosi eHebroni!
11 Igba ọkùnrin sì bá Absalomu ti Jerusalẹmu jáde, nínú àwọn tí a ti pè; wọ́n sì lọ nínú àìmọ̀kan wọn, wọn kò sì mọ nǹkan kan.
Kwasekuhamba loAbisalomu amadoda angamakhulu amabili esuka eJerusalema, anxusiweyo, ahamba ebuqothweni bawo, njalo engazi lutho.
12 Absalomu sì ránṣẹ́ pe Ahitofeli ará Giloni, ìgbìmọ̀ Dafidi, láti ìlú rẹ̀ wá, àní láti Giloni, nígbà tí ó ń rú ẹbọ. Ìdìmọ̀lù náà sì le; àwọn ènìyàn sì ń pọ̀ sọ́dọ̀ Absalomu.
UAbisalomu wasethumela wabiza uAhithofeli weGilo, umeluleki kaDavida, esuka emzini wakhe, eGilo, esahlaba imihlatshelo. Njalo ugobe lwaqina, labantu bahamba banda kuAbisalomu.
13 Ẹnìkan sì wá rò fún Dafidi pé, “Ọkàn àwọn ọkùnrin Israẹli ṣí sí Absalomu.”
Kwasekufika isithunywa kuDavida, sisithi: Inhliziyo yabantu bakoIsrayeli ilandela uAbisalomu.
14 Dafidi sì wí fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó wá lọ́dọ̀ rẹ̀ ni Jerusalẹmu pé, “Ẹ dìde! Ẹ jẹ́ kí a sálọ, nítorí pé kò sí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ Absalomu; ẹ yára, kí a lọ kúrò, kí òun má bá à yára lé wa bá, kí ó má sì mú ibi bá wa, kí ó má sì fi ojú idà pa ìlú run.”
Wasesithi uDavida ezincekwini zakhe zonke ezazilaye eJerusalema: Sukumani, sibaleke, ngoba kasilakuphepha ebusweni bukaAbisalomu. Phangisani ukuhamba, hlezi aphangise asifice, asehlisele okubi, atshaye umuzi ngobukhali benkemba.
15 Àwọn ìránṣẹ́ ọba sì wí fún ọba pé, “Gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí olúwa wa ọba ń fẹ́, wò ó, àwa ìránṣẹ́ rẹ̀ ti murá.”
Izinceku zenkosi zasezisithi enkosini: Njengakho konke inkosi, inkosi yami, ekukhethayo, khangela, nanzi inceku zakho.
16 Ọba sì jáde, gbogbo ilé rẹ̀ sì tẹ̀lé e. Ọba sì fì mẹ́wàá nínú àwọn obìnrin rẹ̀ sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé.
Yasiphuma inkosi, layo yonke indlu yayo iyilandela. Inkosi yasitshiya abafazi abalitshumi, abafazi abancane, ukuze balinde indlu.
17 Ọba sì jáde, gbogbo ènìyàn sì tẹ̀lé e, wọ́n sì dúró ní ibìkan tí ó jìnnà.
Yasiphuma inkosi, labo bonke abantu beyilandela; bema endlini ekhatshana.
18 Gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì kọjá sí iwájú rẹ̀, àti gbogbo àwọn Kereti, àti gbogbo àwọn Peleti, àti gbogbo àwọn ará Gitti, ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn láti Gati wá, sì kọjá níwájú ọba.
Lazo zonke inceku zayo zedlula eceleni kwayo, njalo wonke amaKerethi lawo wonke amaPelethi lawo wonke amaGiti, amadoda angamakhulu ayisithupha, eza amlandela evela eGati, edlula phambi kwenkosi.
19 Ọba sì wí fún Ittai ará Gitti pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń bá wa lọ pẹ̀lú, padà, kí o sì ba ọba jókòó; nítorí pé àlejò ni ìwọ, ìwọ sì ti fi ìlú rẹ sílẹ̀.
Inkosi yasisithi kuIthayi umGiti: Lawe uhambelani lathi? Buyela uhlale lenkosi, ngoba ungowezizweni njalo ungumxotshwa endaweni yakho.
20 Lánàá yìí ni ìwọ dé, èmi ó ha sì mú kí ìwọ máa bá wá lọ káàkiri lónìí bí? Èmi ń lọ sí ibikíbi tí mo bá rí: padà, kí o sì mú àwọn arákùnrin rẹ padà, kí àánú àti òtítọ́ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
Ufike izolo; pho, lamuhla ngikuzulazulise ngokuhamba lathi, njengoba ngiya lapho engiya khona? Buyela ubuyisele abafowenu. Umusa leqiniso kakube lawe.
21 Ittai sì dá ọba lóhùn, ó sì wí pé, “Bí Olúwa tí ń bẹ láààyè, àti bí olúwa mi ọba ti ń bẹ láààyè, nítòótọ́ níbikíbi tí olúwa mi ọba bá gbé wà, ìbá à ṣe nínú ikú, tàbí nínú ìyè, níbẹ̀ pẹ̀lú ni ìránṣẹ́ rẹ yóò gbé wà.”
Kodwa uIthayi wayiphendula inkosi wathi: Kuphila kukaJehova, njalo kuphila kwenkosi yami, inkosi, isibili kuleyondawo lapho inkosi yami, inkosi, ezakuba kiyo, loba kusekufeni loba kusekuphileni, lalapho izakuba khona inceku yakho.
22 Dafidi sì wí fún Ittai pé, “Lọ kí o sì rékọjá!” Ittai ará Gitti náà sì rékọjá, àti gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àti gbogbo àwọn ọmọ kéékèèké tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀.
UDavida wasesithi kuIthayi: Hamba, uchaphe. UIthayi umGiti wasechapha kanye labantu bakhe bonke labantwanyana ababelaye.
23 Gbogbo ìlú náà sì fi ohùn rara sọkún, gbogbo ènìyàn sì rékọjá; ọba sì rékọjá àfonífojì Kidironi, gbogbo àwọn ènìyàn náà sì rékọjá, sí ìhà ọ̀nà ijù.
Ilizwe lonke lakhala inyembezi ngelizwi elikhulu, njalo abantu bonke bachapha. Inkosi yasichapha isifula iKidroni, labantu bonke bachapha, ngasendleleni yenkangala.
24 Sì wò ó, Sadoku pẹ̀lú àti gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sí ń ru àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run náà sọ̀kalẹ̀; Abiatari sí gòkè, títí gbogbo àwọn ènìyàn sì fi dẹ́kun àti máa kọjá láti ìlú wá.
Njalo khangela, uZadoki laye lawo wonke amaLevi elaye, bethwele umtshokotsho wesivumelwano sikaNkulunkulu, bawubeka phansi umtshokotsho kaNkulunkulu; uAbhiyatha wasesenyuka, abantu bonke baze baphela ukudlula bephuma emzini.
25 Ọba sì wí fún Sadoku pé, “Sì tún gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run náà padà sí ìlú, bí èmi bá rí ojúrere gbà lọ́dọ̀ Olúwa, yóò sì tún mú mi padà wá, yóò sì fi àpótí ẹ̀rí náà hàn mí àti ibùgbé rẹ̀.
Inkosi yasisithi kuZadoki: Buyisela umtshokotsho kaNkulunkulu emzini. Uba ngizathola umusa emehlweni eNkosi, izangibuyisa ingitshengise wona kanye lendawo yayo yokuhlala.
26 Ṣùgbọ́n bí òun bá sì wí pé, ‘Èmi kò ní inú dídùn sí ọ,’ wò ó, èmi nìyìí, jẹ́ kí òun ó ṣe sí mi gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ ní ojú rẹ̀.”
Kodwa uba isitsho njalo, ithi: Kangithokozi ngawe; khangela ngilapha, kayenze kimi njengokuhle emehlweni ayo.
27 Ọba sì wí fún Sadoku àlùfáà pé, “Aríran ha kọ́ ni ọ́? Padà sí ìlú ní àlàáfíà, àti àwọn ọmọ rẹ méjèèjì pẹ̀lú rẹ, Ahimasi ọmọ rẹ, àti Jonatani ọmọ Abiatari.
Inkosi yasisithi kuZadoki umpristi: Ungumboni yini? Buyela emzini ngokuthula, loAhimahazi indodana yakho loJonathani indodana kaAbhiyatha, amadodana enu womabili elani.
28 Wò ó, èmi ó dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ijù náà, títí ọ̀rọ̀ ó fi ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá láti sọ fún mi.”
Bona, ngizalinda emazibukweni enkangala, kuze kufike ilizwi elivela kini lokungibikela.
29 Sadoku àti Abiatari sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run padà sí Jerusalẹmu, wọ́n sì gbé ibẹ̀.
Ngakho uZadoki loAbhiyatha bawubuyisela umtshokotsho kaNkulunkulu eJerusalema, bahlala khona.
30 Dafidi sì ń gòkè lọ ní òkè igi olifi, o sì ń sọkún bí ó ti ń gòkè lọ, ó sì bo orí rẹ̀, ó ń lọ láìní bàtà ní ẹsẹ̀, gbogbo ènìyàn tí o wà lọ́dọ̀ rẹ̀, olúkúlùkù ọkùnrin sì bo orí rẹ̀, wọ́n sì ń gòkè lọ, wọ́n ń sọkún bí wọ́n ti ń gòkè lọ.
UDavida wasesenyuka ngomqanso wemihlwathi, esenyuka ekhala inyembezi, embomboze ikhanda lakhe, wahamba engelamanyathela; labo bonke abantu ababelaye bambomboza, ngulowo lalowo ikhanda lakhe, benyuka, besenyuka bekhala inyembezi.
31 Ẹnìkan sì sọ fún Dafidi pé, “Ahitofeli wà nínú àwọn aṣọ̀tẹ̀ pẹ̀lú Absalomu.” Dafidi sì wí pé, “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, sọ ìmọ̀ Ahitofeli di asán.”
Kwasekubikwa kuDavida kwathiwa: UAhithofeli uphakathi kwabakugobe loAbisalomu. UDavida wasesithi: Nkosi, ake enze icebo likaAhithofeli libe yibuthutha.
32 Ó sì ṣe, Dafidi dé orí òkè, níbi tí ó gbé wólẹ̀ sin Ọlọ́run, sì wò ó, Huṣai ará Arki sì wá láti pàdé rẹ̀ pẹ̀lú aṣọ rẹ̀ yíya, àti erùpẹ̀, lórí rẹ̀.
Kwasekusithi uDavida esefike engqongeni lapho ayekhonza khona uNkulunkulu, khangela, uHushayi umArki wamhlangabeza, isembatho sakhe sidatshuliwe, lenhlabathi isekhanda lakhe.
33 Dafidi sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá bá mi kọjá, ìwọ ó sì jẹ́ ìdíwọ́ fún mi.
UDavida wasesithi kuye: Uba usedlula lami, uzakuba ngumthwalo kimi.
34 Bí ìwọ bá sì padà sí ìlú, tí o sì wí fún Absalomu pé, ‘Èmi ó ṣe ìránṣẹ́ rẹ ọba, gẹ́gẹ́ bí èmi ti ṣe ìránṣẹ́ baba rẹ nígbà àtijọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó sì jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ nísinsin yìí,’ kí ìwọ sì bá ìmọ̀ Ahitofeli jẹ́.
Kodwa uba ubuyela emzini uthi kuAbisalomu: Ngizakuba yinceku yakho, nkosi; kade ngiyinceku kayihlo, kodwa khathesi sengizakuba yinceku yakho; khona uzangichithela icebo likaAhithofeli.
35 Ṣé Sadoku àti Abiatari àwọn àlùfáà wà níbẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀? Yóò sì ṣe, ohunkóhun tí ìwọ bá gbọ́ láti ilé ọba wá, ìwọ ó sì sọ fún Sadoku àti Abiatari àwọn àlùfáà.
Njalo kabakho yini kanye lawe lapho oZadoki loAbhiyatha abapristi? Ngakho kuzakuthi yonke indaba oyizwayo endlini yenkosi, uyitshele oZadoki loAbhiyatha abapristi.
36 Wò ó, àwọn ọmọ wọn méjèèjì sì wà níbẹ̀ pẹ̀lú wọn, Ahimasi ọmọ Sadoku, àti Jonatani ọmọ Abiatari; láti ọwọ́ wọn ni ẹ̀yin ó sì rán ohunkóhun tí ẹ̀yin bá gbọ́ sí mi.”
Khangela, kukhona lapho kanye labo amadodana abo amabili, uAhimahazi okaZadoki, loJonathani okaAbhiyatha; njalo uzathumela ngesandla sabo kimi yonke into ozayizwa.
37 Huṣai ọ̀rẹ́ Dafidi sì wá sí ìlú, Absalomu sì wá sí Jerusalẹmu.
UHushayi umngane kaDavida wasefika emzini, loAbisalomu wafika eJerusalema.

< 2 Samuel 15 >