< 2 Samuel 15 >
1 Lẹ́yìn èyí náà, Absalomu sì pèsè kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin fún ara rẹ̀, àti àádọ́ta ọmọkùnrin tí yóò máa sáré níwájú rẹ̀.
Történt ezek után, szerzett magának Ábsálóm kocsit meg lovakat, és ötven embert, kik futottak előtte.
2 Absalomu sì dìde ní kùtùkùtù, ó sì dúró ní apá kan ọ̀nà ẹnu ibodè. Bí ẹnìkan bá ní ẹjọ́ tí ó ń fẹ́ mú tọ ọba wá fún ìdájọ́, a sì pè é sọ́dọ̀ rẹ̀, a sì bi í pé, “Ará ìlú wo ni ìwọ?” Òun a sì dáhùn pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ti inú ọ̀kan nínú ẹ̀yà Israẹli wá.”
Korán föl szokott kelni Ábsálóm és kiállni a kapu útja mellé; és volt, minden ember, kinek pöre volt és ítéletre akart menni a királyhoz – azt megszólította Ábsálóm és mondta: Melyik városból való vagy? Mondta: Izrael törzseinek egyikéből való a te szolgád.
3 Absalomu yóò sì wí fún un pé, “Wò ó, ọ̀ràn rẹ ṣá dára, ó sì tọ́, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ọba fi àṣẹ fún láti gbọ́ ọ̀ràn rẹ.”
Ekkor szólt hozzá Ábsálóm: Lásd, szavaid jók és helyesek, de nem hallgat rád senki a király részéről.
4 Absalomu a sì wí pé, “À bá jẹ́ fi mi ṣe onídàájọ́ ní ilẹ̀ yìí! Kí olúkúlùkù ẹni tí ó ní ẹjọ́ tàbí ọ̀ràn kan bá à lè máa tọ̀ mí wá, èmi ìbá sì ṣe ìdájọ́ òtítọ́ fún un.”
Majd így szólt Ábsálóm: Vajha engem tennének bírául az országban s hozzám jönne minden ember, kinek pöre vagy ügye van, én meg igazat adnék neki.
5 Bẹ́ẹ̀ ni bí ẹnìkan bá sì súnmọ́ láti tẹríba fún un, òun a sì nawọ́ rẹ̀, a sì dìímú, a sì fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
És volt, mikor közeledett valaki, hogy leboruljon előtte, akkor kinyújtotta kezét, megfogta őt és megcsókolta.
6 Irú ìwà báyìí ni Absalomu a máa hù sí gbogbo Israẹli tí ó tọ́ ọba wá nítorí ìdájọ́, Absalomu sì fi fa ọkàn àwọn ènìyàn Israẹli sọ́dọ̀ rẹ̀.
Ily módon cselekedett Ábsálóm egész Izraellel, azokkal, kik a királyhoz ítéletre jöttek; így meglopta Ábsálóm Izrael embereinek szívét.
7 Ó sì ṣe lẹ́yìn ogójì ọdún, Absalomu sì wí fún ọba pé, “Èmi bẹ́ ọ́, jẹ́ kí èmi ó lọ, kí èmi sì san ìlérí mi tí èmi ti ṣe fún Olúwa, ní Hebroni.
Történt negyven év múlva, így szólt Ábsálóm a királyhoz: Hadd menjek, kérlek, hogy Chebrónban lerójam fogadásomat, melyet fogadtam az Örökkévalónak.
8 Nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ kan nígbà tí èmi ń bẹ ní Geṣuri ní Siria pé, ‘Bí Olúwa bá mú mi padà wá sí Jerusalẹmu, nítòótọ́, èmi ó sì sin Olúwa.’”
Mert fogadást tett a te szolgád, mikor Gesúrban, Arámban, laktam, mondván: ha engem vissza fog hozni az Örökkévaló Jeruzsálembe, akkor szolgálom az Örökkévalót.
9 Ọba sì wí fún un pé, “Máa lọ ní àlàáfíà.” Ó sì dìde, ó sì lọ sí Hebroni.
Mondta neki a király: Menj békével. Fölkelt és elment Chebrónba.
10 Ṣùgbọ́n Absalomu rán àmì sáàrín gbogbo ẹ̀yà Israẹli pé, “Nígbà tí ẹ̀yin bá gbọ́ ìró ìpè, kí ẹ̀yin sì wí pé, ‘Absalomu jẹ ọba ní Hebroni.’”
És küldött Ábsálóm kémeket mind az Izrael törzsei közé, mondván: Amint halljátok a harsona hangját, mondjátok: király lett Ábsálóm Chebrónban.
11 Igba ọkùnrin sì bá Absalomu ti Jerusalẹmu jáde, nínú àwọn tí a ti pè; wọ́n sì lọ nínú àìmọ̀kan wọn, wọn kò sì mọ nǹkan kan.
Ábsálómmal pedig ment kétszáz ember Jeruzsálemből, meg voltak hívva és mentek jóhiszemben, nem tudtak ugyanis semmiről.
12 Absalomu sì ránṣẹ́ pe Ahitofeli ará Giloni, ìgbìmọ̀ Dafidi, láti ìlú rẹ̀ wá, àní láti Giloni, nígbà tí ó ń rú ẹbọ. Ìdìmọ̀lù náà sì le; àwọn ènìyàn sì ń pọ̀ sọ́dọ̀ Absalomu.
És elhozatta Ábsálóm a Gílóbeli Achítófelt, Dávid tanácsosát, városából, Gílóból, mikor bemutatta az áldozatokat. És erős volt az összeesküvés és a nép egyre számosabb lett Ábsálóm mellett.
13 Ẹnìkan sì wá rò fún Dafidi pé, “Ọkàn àwọn ọkùnrin Israẹli ṣí sí Absalomu.”
És jött a hírmondó Dávidhoz, mondván: Ábsálóm felé fordult Izrael embereinek szíve.
14 Dafidi sì wí fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó wá lọ́dọ̀ rẹ̀ ni Jerusalẹmu pé, “Ẹ dìde! Ẹ jẹ́ kí a sálọ, nítorí pé kò sí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ Absalomu; ẹ yára, kí a lọ kúrò, kí òun má bá à yára lé wa bá, kí ó má sì mú ibi bá wa, kí ó má sì fi ojú idà pa ìlú run.”
Ekkor mondta Dávid mind a szolgáinak, kik vele voltak Jeruzsálemben: Keljetek föl, hadd szökjünk meg, mert nem lesz számunkra menekvés Ábsálóm elől; siessetek elmenni, nehogy sietve utolérjen és ránklökje a veszedelmet és megverje a várost a kard élével.
15 Àwọn ìránṣẹ́ ọba sì wí fún ọba pé, “Gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí olúwa wa ọba ń fẹ́, wò ó, àwa ìránṣẹ́ rẹ̀ ti murá.”
Szóltak a király szolgái a királyhoz: Egészen aszerint, amit jónak talál uram a király! Itt a szolgáid!
16 Ọba sì jáde, gbogbo ilé rẹ̀ sì tẹ̀lé e. Ọba sì fì mẹ́wàá nínú àwọn obìnrin rẹ̀ sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé.
Erre elindult a király meg egész háza az ő nyomában; és otthagyta a király a tíz ágyasnőt, hogy őrizzék a házat.
17 Ọba sì jáde, gbogbo ènìyàn sì tẹ̀lé e, wọ́n sì dúró ní ibìkan tí ó jìnnà.
Elindult a király meg az egész nép az ő nyomában, és megálltak a legszélső háznál.
18 Gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì kọjá sí iwájú rẹ̀, àti gbogbo àwọn Kereti, àti gbogbo àwọn Peleti, àti gbogbo àwọn ará Gitti, ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn láti Gati wá, sì kọjá níwájú ọba.
Mind a szolgái pedig elvonultak mellette s mind a keréti és mind a peléti, meg mind a Gátbeliek, hatszáz ember akik nyomában jöttek Gátból, elvonultak a király előtt.
19 Ọba sì wí fún Ittai ará Gitti pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń bá wa lọ pẹ̀lú, padà, kí o sì ba ọba jókòó; nítorí pé àlejò ni ìwọ, ìwọ sì ti fi ìlú rẹ sílẹ̀.
Ekkor szólt a király a Gátbeli Ittájhoz: Minek jössz te is velünk? Menj vissza s maradj a királynál; mert idegen vagy és el is költözhetsz helyedre.
20 Lánàá yìí ni ìwọ dé, èmi ó ha sì mú kí ìwọ máa bá wá lọ káàkiri lónìí bí? Èmi ń lọ sí ibikíbi tí mo bá rí: padà, kí o sì mú àwọn arákùnrin rẹ padà, kí àánú àti òtítọ́ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
Tegnap jöttél és már ma bujdostassalak, hogy velünk jöjj, míg én megyek, ahová megyek? Menj vissza és vidd vissza magaddal testvéreidet szeretettel és hűséggel!
21 Ittai sì dá ọba lóhùn, ó sì wí pé, “Bí Olúwa tí ń bẹ láààyè, àti bí olúwa mi ọba ti ń bẹ láààyè, nítòótọ́ níbikíbi tí olúwa mi ọba bá gbé wà, ìbá à ṣe nínú ikú, tàbí nínú ìyè, níbẹ̀ pẹ̀lú ni ìránṣẹ́ rẹ yóò gbé wà.”
Erre felelt Ittáj a királynak és mondta: Él az Örökkévaló és él uram a király, bizony azon a helyen, ahol lesz uram a király, akár életre, akár halálra, bizony ott lesz a te szolgád.
22 Dafidi sì wí fún Ittai pé, “Lọ kí o sì rékọjá!” Ittai ará Gitti náà sì rékọjá, àti gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àti gbogbo àwọn ọmọ kéékèèké tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀.
Ekkor szólt Dávid Ittájhoz: Menj hát és vonulj el. Elvonult tehát a Gátbeli Ittáj meg mind az emberei és mind a gyermekek kik vele voltak.
23 Gbogbo ìlú náà sì fi ohùn rara sọkún, gbogbo ènìyàn sì rékọjá; ọba sì rékọjá àfonífojì Kidironi, gbogbo àwọn ènìyàn náà sì rékọjá, sí ìhà ọ̀nà ijù.
Az egész ország hangosan sírt, míg az egész nép elvonult; a király pedig átkelt a Kidrón patakon és az egész nép átkelt vele, a pusztába való út felé.
24 Sì wò ó, Sadoku pẹ̀lú àti gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sí ń ru àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run náà sọ̀kalẹ̀; Abiatari sí gòkè, títí gbogbo àwọn ènìyàn sì fi dẹ́kun àti máa kọjá láti ìlú wá.
S ott volt Czádók is meg mind a leviták vele, hordozva Isten szövetségének ládáját, és letették az Isten ládáját – Ebjátár is fölment – míg végképen el nem vonult az egész nép a városból.
25 Ọba sì wí fún Sadoku pé, “Sì tún gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run náà padà sí ìlú, bí èmi bá rí ojúrere gbà lọ́dọ̀ Olúwa, yóò sì tún mú mi padà wá, yóò sì fi àpótí ẹ̀rí náà hàn mí àti ibùgbé rẹ̀.
És mondta a király Czádóknak: Vidd vissza az Isten ládáját a városba; ha majd kegyet találok az Örökkévaló szemeiben, akkor visszahoz engem és látnom engedi őt és hajlékát.
26 Ṣùgbọ́n bí òun bá sì wí pé, ‘Èmi kò ní inú dídùn sí ọ,’ wò ó, èmi nìyìí, jẹ́ kí òun ó ṣe sí mi gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ ní ojú rẹ̀.”
Ha pedig így szól: nem kedvellek, – itt vagyok, tegyen velem, amint jónak tetszik szemeiben.
27 Ọba sì wí fún Sadoku àlùfáà pé, “Aríran ha kọ́ ni ọ́? Padà sí ìlú ní àlàáfíà, àti àwọn ọmọ rẹ méjèèjì pẹ̀lú rẹ, Ahimasi ọmọ rẹ, àti Jonatani ọmọ Abiatari.
És szólt a király Czádókhoz a paphoz: Ugye látod? térj vissza a városba békével; Achímáacz fiad és Jónátán, Ebjátár fia, két fiatok veletek van.
28 Wò ó, èmi ó dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ijù náà, títí ọ̀rọ̀ ó fi ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá láti sọ fún mi.”
Lássátok, én majd késedelmezek a puszta síkságain, míg üzenet jön tőletek, hogy értesítsetek engem.
29 Sadoku àti Abiatari sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run padà sí Jerusalẹmu, wọ́n sì gbé ibẹ̀.
Visszavitték tehát Czádók és Ebjátár Isten ládáját Jeruzsálembe, és ott maradtak.
30 Dafidi sì ń gòkè lọ ní òkè igi olifi, o sì ń sọkún bí ó ti ń gòkè lọ, ó sì bo orí rẹ̀, ó ń lọ láìní bàtà ní ẹsẹ̀, gbogbo ènìyàn tí o wà lọ́dọ̀ rẹ̀, olúkúlùkù ọkùnrin sì bo orí rẹ̀, wọ́n sì ń gòkè lọ, wọ́n ń sọkún bí wọ́n ti ń gòkè lọ.
Dávid pedig fölment az olajfák hegye hágóján, sírva, fölmentében, feje betakarva és mezítláb ment; az egész nép is, mely vele volt, betakarta kiki fejét, és fölmentek, sírva fölmentükben.
31 Ẹnìkan sì sọ fún Dafidi pé, “Ahitofeli wà nínú àwọn aṣọ̀tẹ̀ pẹ̀lú Absalomu.” Dafidi sì wí pé, “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, sọ ìmọ̀ Ahitofeli di asán.”
Dávidnak pedig tudtára adták, mondván: Achítófel az összeesküvők közt van Ábsálóm mellett; s így szólt Dávid: Tedd, kérlek, balgává Achítófel tanácsát, oh Örökkévaló!
32 Ó sì ṣe, Dafidi dé orí òkè, níbi tí ó gbé wólẹ̀ sin Ọlọ́run, sì wò ó, Huṣai ará Arki sì wá láti pàdé rẹ̀ pẹ̀lú aṣọ rẹ̀ yíya, àti erùpẹ̀, lórí rẹ̀.
Midőn Dávid épen a csúcsig ért, ahol Isten előtt leborulni szokott, íme, elébe jön az Arkibeli Chúsáj, megtépett köntössel és földdel a fején.
33 Dafidi sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá bá mi kọjá, ìwọ ó sì jẹ́ ìdíwọ́ fún mi.
És mondta neki Dávid: Ha vonulnál velem, terhemre lennél nekem;
34 Bí ìwọ bá sì padà sí ìlú, tí o sì wí fún Absalomu pé, ‘Èmi ó ṣe ìránṣẹ́ rẹ ọba, gẹ́gẹ́ bí èmi ti ṣe ìránṣẹ́ baba rẹ nígbà àtijọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó sì jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ nísinsin yìí,’ kí ìwọ sì bá ìmọ̀ Ahitofeli jẹ́.
de ha visszatérsz a városba és azt mondod Ábsálómnak: szolgád leszek én, oh király, atyád szolgája voltam régen, most meg a te szolgád leszek, – akkor majd meghiusítod javamra Achítófel tanácsát.
35 Ṣé Sadoku àti Abiatari àwọn àlùfáà wà níbẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀? Yóò sì ṣe, ohunkóhun tí ìwọ bá gbọ́ láti ilé ọba wá, ìwọ ó sì sọ fún Sadoku àti Abiatari àwọn àlùfáà.
Hiszen ott vannak veled Czádók és Ebjátár a papok, s lesz, minden dolgot, amit hallasz a király házából, tudtára adsz Czádók és Ebjátár papoknak.
36 Wò ó, àwọn ọmọ wọn méjèèjì sì wà níbẹ̀ pẹ̀lú wọn, Ahimasi ọmọ Sadoku, àti Jonatani ọmọ Abiatari; láti ọwọ́ wọn ni ẹ̀yin ó sì rán ohunkóhun tí ẹ̀yin bá gbọ́ sí mi.”
Íme, ott van velük két fiuk, Achímáacz Czádóké és Jónátán Ebjátáré; küldjetek általuk hozzám minden dolgot, mit hallani fogtok.
37 Huṣai ọ̀rẹ́ Dafidi sì wá sí ìlú, Absalomu sì wá sí Jerusalẹmu.
Bement tehát Chúsáj, Dávid barátja, a városba, midőn Ábsálóm Jeruzsálembe érkezett.