< 2 Samuel 15 >

1 Lẹ́yìn èyí náà, Absalomu sì pèsè kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin fún ara rẹ̀, àti àádọ́ta ọmọkùnrin tí yóò máa sáré níwájú rẹ̀.
Il arriva ensuite qu'Absalon se fit faire des chars, il exerça des chevaux, et il eut cinquante hommes pour courir devant lui.
2 Absalomu sì dìde ní kùtùkùtù, ó sì dúró ní apá kan ọ̀nà ẹnu ibodè. Bí ẹnìkan bá ní ẹjọ́ tí ó ń fẹ́ mú tọ ọba wá fún ìdájọ́, a sì pè é sọ́dọ̀ rẹ̀, a sì bi í pé, “Ará ìlú wo ni ìwọ?” Òun a sì dáhùn pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ti inú ọ̀kan nínú ẹ̀yà Israẹli wá.”
Et Absalon se levait de grand matin, il se tenait sur le chemin près de la porte, et tout homme qui était en procès, qui allait demander jugement au roi, Absalon l'appelait et lui disait: De quelle ville es-tu? A quoi l'autre répondait: Ton serviteur est de l'une des tribus d'Israël.
3 Absalomu yóò sì wí fún un pé, “Wò ó, ọ̀ràn rẹ ṣá dára, ó sì tọ́, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ọba fi àṣẹ fún láti gbọ́ ọ̀ràn rẹ.”
Et Absalon lui disait: Ta cause est bonne et claire, mais il n'y a chez le roi personne pour t'écouter.
4 Absalomu a sì wí pé, “À bá jẹ́ fi mi ṣe onídàájọ́ ní ilẹ̀ yìí! Kí olúkúlùkù ẹni tí ó ní ẹjọ́ tàbí ọ̀ràn kan bá à lè máa tọ̀ mí wá, èmi ìbá sì ṣe ìdájọ́ òtítọ́ fún un.”
Et il ajoutait Que ne suis-je institué juge en cette terre; tout homme qui aurait procès ou contestation viendrait à moi, et je le jugerais?
5 Bẹ́ẹ̀ ni bí ẹnìkan bá sì súnmọ́ láti tẹríba fún un, òun a sì nawọ́ rẹ̀, a sì dìímú, a sì fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
Et lorsque l'homme s'approchait pour le saluer, il étendait la main, l'attirait à lui et le baisait.
6 Irú ìwà báyìí ni Absalomu a máa hù sí gbogbo Israẹli tí ó tọ́ ọba wá nítorí ìdájọ́, Absalomu sì fi fa ọkàn àwọn ènìyàn Israẹli sọ́dọ̀ rẹ̀.
Absalon agit de celle manière avec tous ceux d'Israël qui allaient en justice devant le roi, et il gagna le cœur de tous les hommes d'Israël.
7 Ó sì ṣe lẹ́yìn ogójì ọdún, Absalomu sì wí fún ọba pé, “Èmi bẹ́ ọ́, jẹ́ kí èmi ó lọ, kí èmi sì san ìlérí mi tí èmi ti ṣe fún Olúwa, ní Hebroni.
Il avait quarante ans passés, et il dit à son père: Je vais partir pour Hébron, afin de m'acquitter d'un vœu que j'ai fait au Seigneur.
8 Nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ kan nígbà tí èmi ń bẹ ní Geṣuri ní Siria pé, ‘Bí Olúwa bá mú mi padà wá sí Jerusalẹmu, nítòótọ́, èmi ó sì sin Olúwa.’”
Car ton serviteur, lorsqu'il demeurait à Gedsur en Syrie, a fait ce vœu: Si le Seigneur m'accorde de rentrer à Jérusalem, je ferai un sacrifice au Seigneur.
9 Ọba sì wí fún un pé, “Máa lọ ní àlàáfíà.” Ó sì dìde, ó sì lọ sí Hebroni.
Et le roi lui dit: Va en paix. Et il se leva et il alla en Hébron.
10 Ṣùgbọ́n Absalomu rán àmì sáàrín gbogbo ẹ̀yà Israẹli pé, “Nígbà tí ẹ̀yin bá gbọ́ ìró ìpè, kí ẹ̀yin sì wí pé, ‘Absalomu jẹ ọba ní Hebroni.’”
De là, Absalon envoya des émissaires parmi toutes les tribus d'Israël, disant: Quand vous entendrez sonner du cor, dites: Absalon dans Hébron est proclamé roi.
11 Igba ọkùnrin sì bá Absalomu ti Jerusalẹmu jáde, nínú àwọn tí a ti pè; wọ́n sì lọ nínú àìmọ̀kan wọn, wọn kò sì mọ nǹkan kan.
Absalon avait avec lui deux cents hommes, des premiers de Jérusalem qui l'avaient suivi en toute simplicité, ne sachant rien de ses projets.
12 Absalomu sì ránṣẹ́ pe Ahitofeli ará Giloni, ìgbìmọ̀ Dafidi, láti ìlú rẹ̀ wá, àní láti Giloni, nígbà tí ó ń rú ẹbọ. Ìdìmọ̀lù náà sì le; àwọn ènìyàn sì ń pọ̀ sọ́dọ̀ Absalomu.
Et pendant le sacrifice, il fit venir de Gola, sa ville, Achitophel, fils de Théconi, conseiller de David. Et il y eut une conspiration redoutable, et le peuple qui était venu auprès d'Absalon, était très nombreux.
13 Ẹnìkan sì wá rò fún Dafidi pé, “Ọkàn àwọn ọkùnrin Israẹli ṣí sí Absalomu.”
Or, un homme courut l'annoncer à David, disant: Le cœur des hommes d'Israël s'est tourné vers Absalon.
14 Dafidi sì wí fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó wá lọ́dọ̀ rẹ̀ ni Jerusalẹmu pé, “Ẹ dìde! Ẹ jẹ́ kí a sálọ, nítorí pé kò sí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ Absalomu; ẹ yára, kí a lọ kúrò, kí òun má bá à yára lé wa bá, kí ó má sì mú ibi bá wa, kí ó má sì fi ojú idà pa ìlú run.”
Et David dit à tous les serviteurs qu'il avait avec lui en Jérusalem: Levez-vous et prenons la fuite, car il n'y a point pour nous de salut devant Absalon; hâtez-vous, de peur qu'il ne nous devance et ne nous prenne, qu'il ne nous apporte le mal, et qu'il ne passe la ville au fil de l'épée.
15 Àwọn ìránṣẹ́ ọba sì wí fún ọba pé, “Gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí olúwa wa ọba ń fẹ́, wò ó, àwa ìránṣẹ́ rẹ̀ ti murá.”
Et les serviteurs du roi lui dirent: Que ta volonté du roi notre maître soit faite; voici tes serviteurs.
16 Ọba sì jáde, gbogbo ilé rẹ̀ sì tẹ̀lé e. Ọba sì fì mẹ́wàá nínú àwọn obìnrin rẹ̀ sílẹ̀ láti máa ṣọ́ ilé.
Et le roi sortit à pied, avec toute sa maison; et le roi laissa, pour garder sa demeure, dix de ses concubines.
17 Ọba sì jáde, gbogbo ènìyàn sì tẹ̀lé e, wọ́n sì dúró ní ibìkan tí ó jìnnà.
Le roi sortit donc à pied avec tous ses serviteurs, et ils s'arrêtèrent à une maison éloignée.
18 Gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì kọjá sí iwájú rẹ̀, àti gbogbo àwọn Kereti, àti gbogbo àwọn Peleti, àti gbogbo àwọn ará Gitti, ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn láti Gati wá, sì kọjá níwájú ọba.
Là, tous ses serviteurs défilèrent devant lui; tout Chéléthi, tout Phéléthi; puis, ils firent halte sous les oliviers dans le désert. Tout le peuple le suivait de près ainsi que toute maison, et tous les hommes forts, au nombre de six cents combattants. Ils défilèrent devant lui comme tout Chéléthi, tout Phéléthi, et tous les Géthéens au nombre de six cents venus à pied de Geth; quand ceux ci passèrent devant le roi,
19 Ọba sì wí fún Ittai ará Gitti pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń bá wa lọ pẹ̀lú, padà, kí o sì ba ọba jókòó; nítorí pé àlejò ni ìwọ, ìwọ sì ti fi ìlú rẹ sílẹ̀.
Il dit à Ethi le Géthéen: Pourquoi es-tu venu aussi avec nous? Va-t'en et reste chez ton roi, car tu es étranger et tu as émigré de ta contrée natale.
20 Lánàá yìí ni ìwọ dé, èmi ó ha sì mú kí ìwọ máa bá wá lọ káàkiri lónìí bí? Èmi ń lọ sí ibikíbi tí mo bá rí: padà, kí o sì mú àwọn arákùnrin rẹ padà, kí àánú àti òtítọ́ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
Tu ne fais que d'arriver; dois-je sitôt t'emmener avec nous? Tu changerais encore de lieux; hier tu es sorti, et aujourd'hui je te ferais venir avec nous! Pour moi, j'irai où je pourrai; va-t'en et emmène tes frères qui t'ont suivi, le Seigneur te traitera selon sa miséricorde et sa vérité.
21 Ittai sì dá ọba lóhùn, ó sì wí pé, “Bí Olúwa tí ń bẹ láààyè, àti bí olúwa mi ọba ti ń bẹ láààyè, nítòótọ́ níbikíbi tí olúwa mi ọba bá gbé wà, ìbá à ṣe nínú ikú, tàbí nínú ìyè, níbẹ̀ pẹ̀lú ni ìránṣẹ́ rẹ yóò gbé wà.”
Or, Ethi répondit au roi: Vive le Seigneur et vive le roi mon maître! où ira mon maître, à la vie et à la mort, là sera ton serviteur.
22 Dafidi sì wí fún Ittai pé, “Lọ kí o sì rékọjá!” Ittai ará Gitti náà sì rékọjá, àti gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àti gbogbo àwọn ọmọ kéékèèké tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀.
Et le roi dit à Ethi: Viens et traverse le torrent. Alors, le Géthéen Ethi, le roi, tous ses serviteurs, toute la foule qui le suivait, passèrent.
23 Gbogbo ìlú náà sì fi ohùn rara sọkún, gbogbo ènìyàn sì rékọjá; ọba sì rékọjá àfonífojì Kidironi, gbogbo àwọn ènìyàn náà sì rékọjá, sí ìhà ọ̀nà ijù.
Cependant, toute la terre pleurait en jetant les hauts cris, tout le peuple avait passé le torrent de Cédron, le roi l'avait traversé aussi. Et tous prirent le chemin qui mène au désert.
24 Sì wò ó, Sadoku pẹ̀lú àti gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sí ń ru àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run náà sọ̀kalẹ̀; Abiatari sí gòkè, títí gbogbo àwọn ènìyàn sì fi dẹ́kun àti máa kọjá láti ìlú wá.
A ce moment, Sadoc et avec lui tous les lévites parurent, apportant de Bélhor l'arche de l'alliance du Seigneur; ils firent arrêter l'arche de Dieu sur le mont des Oliviers, et Abiathar y monta jusqu'à ce que le peuple cessât de sortir de Jérusalem.
25 Ọba sì wí fún Sadoku pé, “Sì tún gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run náà padà sí ìlú, bí èmi bá rí ojúrere gbà lọ́dọ̀ Olúwa, yóò sì tún mú mi padà wá, yóò sì fi àpótí ẹ̀rí náà hàn mí àti ibùgbé rẹ̀.
Et le roi dit à Sadoc: Retourne à la ville avec l'arche de Dieu; si je trouve grâce devant le Seigneur, il m'y fera rentrer moi-même; il me fera revoir l'arche et sa beauté.
26 Ṣùgbọ́n bí òun bá sì wí pé, ‘Èmi kò ní inú dídùn sí ọ,’ wò ó, èmi nìyìí, jẹ́ kí òun ó ṣe sí mi gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ ní ojú rẹ̀.”
Et s'il me dit: Je ne me complais plus à être en toi; me voici, qu'il fasse de moi ce que bon lui semble.
27 Ọba sì wí fún Sadoku àlùfáà pé, “Aríran ha kọ́ ni ọ́? Padà sí ìlú ní àlàáfíà, àti àwọn ọmọ rẹ méjèèjì pẹ̀lú rẹ, Ahimasi ọmọ rẹ, àti Jonatani ọmọ Abiatari.
Le roi dit donc à Sadoc le prêtre: Retourne en paix à la ville avec Achimaas, ton fils, et Jonathan, fils d'Abiathar, vos deux fils vous suivront.
28 Wò ó, èmi ó dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ijù náà, títí ọ̀rọ̀ ó fi ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá láti sọ fún mi.”
Pour moi, je m'en vais en Araboth du désert, où je serai sous les armes, jusqu'à ce que vous m'ayez fait savoir quelque nouvelle.
29 Sadoku àti Abiatari sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run padà sí Jerusalẹmu, wọ́n sì gbé ibẹ̀.
Ainsi, Sadoc et Abiathar ramenèrent à Jérusalem l'arche de Dieu, et elle y demeura.
30 Dafidi sì ń gòkè lọ ní òkè igi olifi, o sì ń sọkún bí ó ti ń gòkè lọ, ó sì bo orí rẹ̀, ó ń lọ láìní bàtà ní ẹsẹ̀, gbogbo ènìyàn tí o wà lọ́dọ̀ rẹ̀, olúkúlùkù ọkùnrin sì bo orí rẹ̀, wọ́n sì ń gòkè lọ, wọ́n ń sọkún bí wọ́n ti ń gòkè lọ.
Et David monta sur la montagne des Oliviers; en montant, il pleurait, la tête voilée; il allait pieds nus, et avec lui tout le peuple, la tête voilée, montait et pleurait.
31 Ẹnìkan sì sọ fún Dafidi pé, “Ahitofeli wà nínú àwọn aṣọ̀tẹ̀ pẹ̀lú Absalomu.” Dafidi sì wí pé, “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, sọ ìmọ̀ Ahitofeli di asán.”
Or, des gens vinrent dire à David: Achitophel est au nombre des séditieux qui suivent Absalon. Et David dit: Seigneur mon Dieu, confondez les desseins d'Achitophel.
32 Ó sì ṣe, Dafidi dé orí òkè, níbi tí ó gbé wólẹ̀ sin Ọlọ́run, sì wò ó, Huṣai ará Arki sì wá láti pàdé rẹ̀ pẹ̀lú aṣọ rẹ̀ yíya, àti erùpẹ̀, lórí rẹ̀.
David était allé jusqu'à Rhos, où il adorait le Seigneur, quand arriva devant lui Chusaï, son compagnon bien-aimé, les vêtements déchirés, la tête couverte de cendres.
33 Dafidi sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá bá mi kọjá, ìwọ ó sì jẹ́ ìdíwọ́ fún mi.
Et David lui dit: Si tu viens avec nous, tu seras pour moi un fardeau;
34 Bí ìwọ bá sì padà sí ìlú, tí o sì wí fún Absalomu pé, ‘Èmi ó ṣe ìránṣẹ́ rẹ ọba, gẹ́gẹ́ bí èmi ti ṣe ìránṣẹ́ baba rẹ nígbà àtijọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó sì jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ nísinsin yìí,’ kí ìwọ sì bá ìmọ̀ Ahitofeli jẹ́.
Mais si tu retournes à la ville, et si tu dis à Absalon: J'ai vu passer tes frères; j'ai vu passer le roi ton père, et maintenant, ô roi! je suis ton serviteur, laisse-moi vivre; j'étais jadis, et tout à l'heure encore, serviteur de ton père, et maintenant je suis le tien; tu confondras les desseins d'Achitophel.
35 Ṣé Sadoku àti Abiatari àwọn àlùfáà wà níbẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀? Yóò sì ṣe, ohunkóhun tí ìwọ bá gbọ́ láti ilé ọba wá, ìwọ ó sì sọ fún Sadoku àti Abiatari àwọn àlùfáà.
Tu auras avec toi Sadoc et Abiathar les prêtres, et toute parole que tu pourras surprendre dans la maison du roi, tu en donneras connaissance aux prêtres Sadoc et Abiathar.
36 Wò ó, àwọn ọmọ wọn méjèèjì sì wà níbẹ̀ pẹ̀lú wọn, Ahimasi ọmọ Sadoku, àti Jonatani ọmọ Abiatari; láti ọwọ́ wọn ni ẹ̀yin ó sì rán ohunkóhun tí ẹ̀yin bá gbọ́ sí mi.”
Ils ont avec eux leurs deux fils Achimaas, fils de Sadoc, et Jonathan, fils d'Abiathar; vous me ferez savoir, en me les envoyant, toute parole que vous aurez surprise.
37 Huṣai ọ̀rẹ́ Dafidi sì wá sí ìlú, Absalomu sì wá sí Jerusalẹmu.
Et Chusaï, le favori de David, rentra dans Jérusalem au moment où Absalon venait d'y faire son entrée.

< 2 Samuel 15 >