< 2 Samuel 14 >

1 Joabu ọmọ Seruiah sì kíyèsi i, pé ọkàn ọba sì fà sí Absalomu.
Joab, fils de Tseruja, s'aperçut que le cœur du roi était tourné vers Absalom.
2 Joabu sì ránṣẹ́ sí Tekoa, ó sì mú ọlọ́gbọ́n obìnrin kan láti ibẹ̀ wá, ó sì wí fún un pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, ṣe bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀, kí o sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ sára, kí o má sì ṣe fi òróró pa ara, kí o sì dàbí obìnrin ti ó ti ń ṣọ̀fọ̀ fún òkú lọ́jọ́ púpọ̀.
Joab envoya à Tekoa et y fit venir une femme sage, à qui il dit: « Je t'en prie, agis comme une personne en deuil, mets des vêtements de deuil, je t'en prie, et ne t'oins pas d'huile, mais sois comme une femme qui a pleuré longtemps un mort.
3 Kí o sì tọ ọba wá, kí o sọ fún un gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ yìí.” Joabu sì fi ọ̀rọ̀ sí lẹ́nu.
Va vers le roi et parle-lui ainsi. » Joab mit les mots dans sa bouche.
4 Nígbà tí obìnrin àrá Tekoa sì ń fẹ́ sọ̀rọ̀ fún ọba, ó wólẹ̀, ó dojúbolẹ̀, o sí bu ọlá fún un, o sì wí pé, “Ọba, gbà mi.”
Lorsque la femme de Tekoa a parlé au roi, elle s'est prosternée à terre, s'est montrée respectueuse et a dit: « Au secours, ô roi! »
5 Ọba sì bi í léèrè pé, “Kín ni o ṣe ọ́?” Òun sì dáhùn wí pé, “Nítòótọ́ opó ni èmi ń ṣe, ọkọ mi sì kú.
Le roi lui dit: « Qu'est-ce qui te prend? » Elle répondit: « En vérité, je suis veuve, et mon mari est mort.
6 Ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ sì ti ní ọmọkùnrin méjì, àwọn méjèèjì sì jọ jà lóko, kò sì si ẹni tí yóò là wọ́n, èkínní sì lu èkejì, ó sì pa á.
Ton serviteur avait deux fils; ils se sont battus ensemble dans les champs, et il n'y avait personne pour les séparer; mais l'un a frappé l'autre et l'a tué.
7 Sì wò ó, gbogbo ìdílé dìde sí ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀, wọ́n sì wí pé, ‘Fi ẹni tí ó pa arákùnrin rẹ fún wa, àwa ó sì pa á ní ipò ẹ̀mí arákùnrin rẹ̀ tí ó pa, àwa ó sì pa àrólé náà run pẹ̀lú.’ Wọn ó sì pa iná mi tí ó kù, wọn kì yóò sì fi orúkọ tàbí ẹni tí ó kú sílẹ̀ fún ọkọ mi ní ayé.”
Voici que toute la famille s'est soulevée contre ton serviteur, et ils disent: « Délivrez celui qui a frappé son frère, afin que nous le tuions pour la vie de son frère qu'il a tué, et que nous fassions aussi périr l'héritier ». Ainsi, ils éteindraient mon charbon qui reste, et ne laisseraient à mon mari ni nom ni reste sur la surface de la terre. »
8 Ọba sì wí fún obìnrin náà pé, “Lọ sí ilé rẹ̀, èmi ó sì kìlọ̀ nítorí rẹ.”
Le roi dit à la femme: « Va dans ta maison, et je donnerai un ordre à ton sujet. »
9 Obìnrin ará Tekoa náà sì wí fún ọba pé, “Olúwa mi, ọba, jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ náà wà lórí mi, àti lórí ìdílé baba mí; kí ọba àti ìtẹ́ rẹ̀ ó jẹ́ aláìlẹ́bi.”
La femme de Tekoa dit au roi: « Mon seigneur, ô roi, que l'iniquité retombe sur moi et sur la maison de mon père, et que le roi et son trône soient sans reproche. »
10 Ọba sì wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀ sí ọ, mú ẹni náà tọ̀ mí wá, òun kì yóò sì tọ́ ọ mọ́.”
Le roi dit: « Si quelqu'un te dit quelque chose, amène-le moi, et il ne t'ennuiera plus. »
11 Ó sì wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí ọba ó rántí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, kí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ má ṣe ní ipá láti ṣe ìparun, kí wọn o má bá a pa ọmọ mi!” Òun sì wí pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè ọ̀kan nínú irun orí ọmọ rẹ ki yóò bọ sílẹ̀.”
Et elle dit: « Je te prie, que le roi se souvienne de Yahvé, ton Dieu, afin que le vengeur du sang ne détruise plus, de peur qu'on ne fasse périr mon fils. » Il a dit: « Yahvé est vivant, aucun cheveu de ton fils ne tombera sur la terre. »
12 Obìnrin náà sì wí pé, “Èmí bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ sọ̀rọ̀ kan fún olúwa mi ọba.” Òun si wí pé, “Máa wí.”
Alors la femme dit: « Je te prie de laisser ton serviteur dire un mot à mon seigneur le roi. » Il a dit: « Dis-le. »
13 Obìnrin náà sì wí pé, “Nítorí kín ni ìwọ sì ṣe ro irú nǹkan yìí sí àwọn ènìyàn Ọlọ́run? Nítorí pé ní sísọ nǹkan yìí ọba ní ẹ̀bi, nítorí pé ọba kò mú ìsáǹsá rẹ̀ bọ̀ wá ilé.
La femme dit: « Pourquoi donc as-tu imaginé une telle chose contre le peuple de Dieu? Car en prononçant cette parole, le roi est comme un coupable, en ce que le roi ne ramène pas son banni.
14 Nítorí pé àwa ó sá à kú, a ó sì dàbí omi tí a tú sílẹ̀ tí a kò sì lè ṣàjọ mọ́; nítorí bí Ọlọ́run kò ti gbà ẹ̀mí rẹ̀, ó sì ti ṣe ọ̀nà kí a má bá a lé ìsáǹsá rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
Car nous devons mourir, et nous sommes comme de l'eau répandue sur le sol, qui ne peut être recueillie; et Dieu n'ôte pas la vie, mais il conçoit des moyens, afin que celui qui est banni ne soit pas exclu de lui.
15 “Ǹjẹ́ nítorí náà ni èmi sì ṣe wá sọ nǹkan yìí fún olúwa mi ọba, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ènìyàn ti dẹ́rùbà mí; ìránṣẹ́bìnrin rẹ sì wí pé, ‘Ǹjẹ́ èmi ó sọ fún ọba; ó lè rí bẹ́ẹ̀ pé ọba yóò ṣe ìfẹ́ ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ fún un.
Maintenant, si je suis venu pour dire cette parole à mon seigneur le roi, c'est parce que le peuple m'a fait peur. Ton serviteur a dit: « Je vais maintenant parler au roi; il se peut que le roi exauce la demande de son serviteur ».
16 Nítorí pé ọba ò gbọ́, láti gbà ìránṣẹ́bìnrin rẹ sílẹ̀ lọ́wọ́ ọkùnrin náà tí ó ń fẹ́ gé èmi àti ọmọ mi pẹ̀lú kúrò nínú ilẹ̀ ìní Ọlọ́run.’
Car le roi écoutera, pour délivrer son serviteur de la main de l'homme qui voulait nous faire périr, moi et mon fils, hors de l'héritage de Dieu.
17 “Ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ sì wí pé, ‘Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ ọba olúwa mi yóò sì jásí ìtùnú; nítorí bí angẹli Ọlọ́run bẹ́ẹ̀ ni olúwa mi ọba láti mọ rere àti búburú: Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò sì wà pẹ̀lú rẹ.’”
Ton serviteur dit: « Que la parole de mon seigneur le roi apporte le repos, car comme un ange de Dieu, mon seigneur le roi sait discerner le bien et le mal. Que Yahvé, ton Dieu, soit avec toi. »
18 Ọba sì dáhùn, ó sì wí fún obìnrin náà pé, “Má ṣe fi nǹkan tí èmi ó béèrè lọ́wọ́ rẹ pamọ́ fún mi, èmi bẹ̀ ọ́.” Obìnrin náà wí pé, “Jẹ́ kí olúwa mi ọba máa wí?”
Alors le roi répondit à la femme: « Je t'en prie, ne me cache rien de ce que je te demande. » La femme dit: « Que mon seigneur le roi parle maintenant. »
19 Ọba sì wí pé, “Ọwọ́ Joabu kò ha wà pẹ̀lú rẹ nínú gbogbo èyí?” Obìnrin náà sì dáhùn ó sì wí pé, “Bí ẹ̀mí rẹ ti ń bẹ láààyè, olúwa mi ọba, kò sí ìyípadà sí ọwọ́ ọ̀tún, tàbí sí ọwọ́ òsì nínú gbogbo èyí tí olúwa mi ọba ti wí, nítorí pé Joabu ìránṣẹ́ rẹ, òun ni ó rán mi, òun ni ó sì fi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí ìránṣẹ́bìnrin rẹ lẹ́nu.
Le roi dit: « La main de Joab est-elle avec toi dans tout cela? » La femme répondit: « Aussi vrai que ton âme est vivante, mon seigneur le roi, personne ne peut se détourner à droite ou à gauche de ce que mon seigneur le roi a dit; car ton serviteur Joab m'a pressée, et il a mis toutes ces paroles dans la bouche de ta servante.
20 Láti mú irú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí wá ni Joabu ìránṣẹ́ rẹ ṣe ṣe nǹkan yìí: olúwa mi sì gbọ́n, gẹ́gẹ́ bí ọgbọ́n angẹli Ọlọ́run, láti mọ gbogbo nǹkan tí ń bẹ̀ ní ayé.”
Ton serviteur Joab a fait cela pour changer la face de l'affaire. Mon seigneur est sage, selon la sagesse d'un ange de Dieu, pour connaître toutes les choses qui sont sur la terre. »
21 Ọba sì wí fún Joabu pé, “Wò ó, èmi ó ṣe nǹkan yìí, nítorí náà lọ, kí o sì mú ọmọdékùnrin náà Absalomu padà wá.”
Le roi dit à Joab: « Voici, j'ai accordé cette chose. Va donc, et ramène le jeune homme Absalom. »
22 Joabu sì wólẹ̀ ó dojú rẹ̀ bolẹ̀, ó sì tẹríba fún un, ó sì súre fún ọba. Joabu sì wí pé, “Lónìí ni ìránṣẹ́ rẹ mọ̀ pé, èmi rí oore-ọ̀fẹ́ gbà lójú rẹ, olúwa mi, ọba, nítorí pé ọba ṣe ìfẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀.”
Joab tomba à terre sur sa face, fit preuve de respect et bénit le roi. Joab dit: « Ton serviteur sait aujourd'hui que j'ai trouvé grâce à tes yeux, mon seigneur, ô roi, puisque le roi a exécuté la demande de son serviteur. »
23 Joabu sì dìde, ó sì lọ sí Geṣuri, ó sì mú Absalomu wá sí Jerusalẹmu.
Joab se leva, alla à Gueschur, et amena Absalom à Jérusalem.
24 Ọba sì wí pé, “Jẹ́ kí ó yípadà lọ sí ilé rẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ó rí ojú mi.” Absalomu sì yípadà sí ilé rẹ̀, kò sì rí ojú ọba.
Le roi dit: « Qu'il retourne dans sa maison, mais qu'il ne voie pas mon visage. » Absalom retourna donc dans sa maison, et ne vit pas le visage du roi.
25 Kó sì sí arẹwà kan ní gbogbo Israẹli tí à bá yìn bí Absalomu: láti àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀ títí dé àtàrí rẹ̀ kò sí àbùkù kan lára rẹ̀.
Or, dans tout Israël, il n'y avait personne qui fût aussi loué qu'Absalom pour sa beauté. Depuis la plante de son pied jusqu'au sommet de sa tête, il n'y avait en lui aucun défaut.
26 Nígbà tí ó bá sì rẹ́ irun orí rẹ̀ (nítorí pé lọ́dọọdún ni òun máa ń rẹ́ ẹ. Nígbà tí ó bá wúwo fún un, òun a sì máa rẹ́ ẹ) òun sì wọn irun orí rẹ̀, ó sì jásí igba ṣékélì nínú òsùwọ̀n ọba.
Lorsqu'il se coupait les cheveux de sa tête (c'était à la fin de chaque année qu'il les coupait; comme ils étaient lourds pour lui, il les coupait), il pesait les cheveux de sa tête à deux cents sicles, selon le poids du roi.
27 A sì bí ọmọkùnrin mẹ́ta fún Absalomu àti ọmọbìnrin kan ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tamari: òun sì jẹ́ obìnrin tí ó lẹ́wà lójú.
Trois fils naquirent à Absalom, et une fille, dont le nom était Tamar. C'était une femme qui avait un beau visage.
28 Absalomu sì gbé ni ọdún méjì ní Jerusalẹmu kò sì rí ojú ọba.
Absalom vécut deux années entières à Jérusalem, et il ne vit pas le visage du roi.
29 Absalomu sì ránṣẹ́ sí Joabu, láti rán an sí ọba, ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ wá sọ́dọ̀ rẹ̀; ó sì ránṣẹ́ lẹ́ẹ̀kejì òun kò sì fẹ́ wá.
Absalom envoya alors chercher Joab, pour l'envoyer auprès du roi, mais celui-ci ne voulut pas venir à lui. Il envoya encore une seconde fois, mais il ne voulut pas venir.
30 Ó sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wò ó, oko Joabu gbé ti èmi, ó sì ní ọkà barle níbẹ̀; ẹ lọ kí ẹ sì ti iná bọ̀ ọ́.” Àwọn ìránṣẹ́ Absalomu sì tiná bọ oko náà.
Il dit alors à ses serviteurs: « Voici, le champ de Joab est près du mien, et il y a de l'orge. Allez-y et mettez-y le feu. » Les serviteurs d'Absalom mirent donc le feu au champ.
31 Joabu sì dìde, ó sì tọ Absalomu wá ní ilé, ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ fi tiná bọ oko mi?”
Alors Joab se leva et vint chez Absalom, dans sa maison, et lui dit: « Pourquoi tes serviteurs ont-ils mis le feu à mon champ? »
32 Absalomu sì dá Joabu lóhùn pé, “Wò ó, èmi ránṣẹ́ sí ọ, wí pé, ‘Wá níhìn-ín yìí, èmi ó sì rán ọ lọ sọ́dọ̀ ọba, láti béèrè pé, “Kí ni èmi ti Geṣuri wá si? Ìbá sàn fún mí bí ó ṣe pé èmi wà lọ́hùn ún síbẹ̀!”’ Ǹjẹ́ nísinsin yìí jẹ́ kí èmi lọ síwájú ọba bí ó bá sì ṣe ẹ̀bi ń bẹ nínú mi, kí ó pa mí.”
Absalom répondit à Joab: « Voici, je t'ai envoyé dire: Viens ici, afin que je t'envoie dire au roi: « Pourquoi suis-je venu de Gueshur? Il vaudrait mieux que j'y sois encore. Maintenant, que je voie la face du roi, et s'il y a en moi de l'iniquité, qu'il me fasse mourir ».
33 Joabu sì tọ ọba wá, ó sì rò fún un: ó sì ránṣẹ́ pe Absalomu, òun sì wá sọ́dọ̀ ọba, ó tẹríba fún un, ó sì dojú rẹ̀ bolẹ̀ níwájú ọba, ọba sì fi ẹnu ko Absalomu lẹ́nu.
Joab se rendit auprès du roi et lui en fit part. Après avoir appelé Absalom, il vint auprès du roi et se prosterna à terre, face contre terre, devant le roi; et le roi embrassa Absalom.

< 2 Samuel 14 >