< 2 Samuel 13 >
1 Ó sì ṣe, lẹ́yìn èyí, Absalomu ọmọ Dafidi ní àbúrò obìnrin kan tí ó ṣe arẹwà, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Tamari; Amnoni ọmọ Dafidi sì fẹ́ràn rẹ̀.
Después de esto, se supo que Absalón, el hijo de David, tenía una hermosa hermana, cuyo nombre era Tamar; y el hijo de David, Amnón, estaba enamorado de ella.
2 Amnoni sì banújẹ́ títí ó fi ṣe àìsàn nítorí Tamari àbúrò rẹ̀ obìnrin; nítorí pé wúńdíá ni; ó sì ṣe ohun tí ó ṣòro lójú Amnoni láti bá a dàpọ̀.
Y estaba tan profundamente enamorado que se enfermó a causa de su hermana Tamar; porque ella era virgen, por lo que a Amnón le resultaba difícil hacerle algo.
3 Ṣùgbọ́n Amnoni ní ọ̀rẹ́ kan, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Jonadabu, ọmọ Ṣimea ẹ̀gbọ́n Dafidi, Jonadabu sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn gidigidi.
Pero Amnón tenía un amigo que se llamaba Jonadab, el hijo de Simea, el hermano de David: y Jonadab era un hombre muy sabio.
4 Ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ ọmọ ọba ń fi ń rù lójoojúmọ́ báyìí? Ǹjẹ́ o kò ní sọ fún mi?” Amnoni sì wí fún un pé, “Èmi fẹ́ Tamari àbúrò Absalomu arákùnrin mi.”
Y él le dijo: Oh hijo del rey, ¿por qué te debilitas cada día? ¿No dirás cuál es tu problema? Y Amnón le dijo: Estoy enamorado de Tamar, la hermana de mi hermano Absalón.
5 Jonadabu sì wí fún un pé, “Dùbúlẹ̀ ní ibùsùn rẹ kí ìwọ sì díbọ́n pé, ìwọ kò sàn, baba rẹ yóò sì wá wò ọ́, ìwọ ó sì wí fún un pé, ‘Jọ̀wọ́ jẹ́ kí Tamari àbúrò mi wá kí ó sì fún mi ní oúnjẹ kí ó sì ṣe oúnjẹ náà níwájú mi kí èmi ó rí i, èmi ó sì jẹ ẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀.’”
Entonces Jonadab le dijo: Ve a tu cama y que parezca que estás enfermo. Y cuando tu padre venga a verte, dile: Deja que venga mi hermana Tamar, y prepare la comida delante de mí, para que pueda verla y comerla de su mano.
6 Amnoni sì dùbúlẹ̀, ó sì díbọ́n pé òun ṣàìsàn, ọba sì wá wò ó, Amnoni sì wí fún ọba pé, “Jọ̀wọ́, jẹ́ kí Tamari àbúrò mi ó wá, kí ó sì dín àkàrà méjì lójú mi, èmi ó sì jẹ ní ọwọ́ rẹ̀.”
Entonces, Amnón se acostó y se puso enfermo: y cuando el rey fue a verlo, Amnón le dijo al rey: Por favor, que mi hermana Tamar venga y me prepare uno o dos pasteles delante de mis ojos, para que Puedo tomar comida de su mano.
7 Dafidi sì ránṣẹ́ sí Tamari ní ilé pé, “Lọ sí ilé Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ, kí ó sì se oúnjẹ fún un.”
Luego, David envió a la casa a buscar a Tamar y le dijo: Ve ahora a la casa de tu hermano Amnón y consigue una comida para él.
8 Tamari sì lọ sí ilé Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ̀, òun sì ń bẹ ní ìdùbúlẹ̀. Tamari sì mú ìyẹ̀fun, ó sì pò ó, ó sì fi ṣe àkàrà lójú rẹ̀, ó sì dín àkàrà náà.
Entonces Tamar fue a la casa de su hermano Amnón; y él estaba en la cama. Y ella tomó pasta e hizo pasteles ante sus ojos, cocinándolos sobre el fuego.
9 Òun sì mú àwo náà, ó sì dà á sínú àwo mìíràn níwájú rẹ̀; ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti jẹ. Amnoni sì wí pé, “Jẹ́ kí gbogbo ọkùnrin jáde kúrò lọ́dọ̀ mi!” Wọ́n sì jáde olúkúlùkù ọkùnrin kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
Entonces ella tomó la olla y puso los pasteles delante de él, pero él no los tomó. Y Amnón dijo: Deja que todos se vayan de mí. Así que todos salieron.
10 Amnoni sì wí fún Tamari pé, “Mú oúnjẹ náà wá sí yàrá, èmi ó sì jẹ ẹ́ lọ́wọ́ rẹ.” Tamari sì mú àkàrà tí ó ṣe, ó sì mú un tọ Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ní yàrá.
Entonces Amnón dijo a Tamar: Toma la comida y entra en mi habitación, para que pueda tomarla de tu mano. Así que Tamar tomó los pasteles que había hecho y se fue con ellos al dormitorio de su hermano Amnón.
11 Nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn láti fi oúnjẹ fún un, òun sì dìímú, ó sì wí fún un pé, “Wá dùbúlẹ̀ tì mí, àbúrò mi.”
Cuando ella los tomó para dárselos, él la abrazó y le dijo: Ven a la cama, hermana mía.
12 Òun sì dá a lóhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀gbọ́n mi, má ṣe tẹ́ mi; nítorí pé kò tọ kí a ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀ ní Israẹli, ìwọ má ṣe hùwà òmùgọ̀ yìí.
Respondiendo, ella dijo: Oh hermano mío, no me avergüences; no está bien que se haga algo así en Israel. No hagas tal infamia.
13 Àti èmi, níbo ni èmi ó gbé ìtìjú mi wọ̀? Ìwọ ó sì dàbí ọ̀kan nínú àwọn aṣiwèrè ní Israẹli. Ǹjẹ́ nítorí náà, èmi bẹ̀ ọ́, sọ fún ọba; nítorí pé òun kì yóò kọ̀ láti fi mí fún ọ.”
¿Qué será de mí en mi vergüenza? y en cuanto a ti, serás despreciable por todo Israel. Ahora, ve y haz tu pedido al rey, porque él no me alejará de ti.
14 Ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti gbọ́ ohùn rẹ̀; ó sì fi agbára mú un, ó sì ṣẹ́gun rẹ̀, ó sì bá a dàpọ̀.
Pero él no le prestaría atención a lo que ella decía, pero siendo más fuerte que ella, la tomó por la fuerza y la violó.
15 Amnoni sì kórìíra rẹ̀ gidigidi, ìríra náà sì wá ju ìfẹ́ tí òun ti ní sí i rí lọ. Amnoni sì wí fún un pé, “Dìde, kí o sì máa lọ!”
Entonces Amnón estaba lleno de odio por ella, odiándola con un odio más grande que su amor anterior por ella. Y él le dijo: Levántate y vete.
16 Òun sì wí fún un pé, “Kó ha ní ìdí bí! Lílé tí ìwọ ń lé mi yìí burú ju èyí tí ìwọ ti ṣe sí mi lọ.” Ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ gbọ́ tirẹ̀.
Y ella le dijo: No es así, hermano mío, porque este gran error al despedirme es peor que lo que me hiciste antes. Pero él no le prestó atención.
17 Òun sì pe ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí í ṣe ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Jọ̀wọ́, ti obìnrin yìí sóde fún mi, kí o sì ti ìlẹ̀kùn mọ́ ọn.”
Entonces dio un grito al siervo que lo estaba esperando y le dijo: Saca a esta mujer y que la puerta quede cerrada con llave.
18 Òun sì ní aṣọ aláràbarà kan lára rẹ̀, nítorí irú aṣọ àwọ̀lékè bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọbìnrin ọba tí í ṣe wúńdíá máa ń wọ̀. Ìránṣẹ́ rẹ̀ sì mú un jáde, ó sì ti ìlẹ̀kùn mọ́ ọn.
Ahora tenía puesta una túnica larga, como en tiempos pasados que vestían las hijas vírgenes del rey. Entonces el criado la sacó, cerrando la puerta con llave.
19 Tamari sì bu eérú sí orí rẹ̀, ó sì fa aṣọ aláràbarà tí ń bẹ lára rẹ̀ ya, ó sì ká ọwọ́ rẹ̀ lé orí, ó sì ń kígbe bí ó ti ń lọ.
Y Tamar, en su dolor, puso polvo sobre su cabeza; y ella puso su mano en su cabeza y se fue llorando a gritos.
20 Absalomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ sì bí i léèrè pé, “Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ bá ọ sùn bí? Ǹjẹ́ àbúrò mi, dákẹ́; ẹ̀gbọ́n rẹ ní í ṣe; má fi nǹkan yìí sí ọkàn rẹ.” Tamari sì jókòó ní ìbànújẹ́ ní ilé Absalomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
Y su hermano Absalón le dijo: ¿Ha estado tu hermano Amnón contigo? Pero ahora, deja que termine tu llanto, hermana mía, él es tu hermano, no te tomes esto en serio. Entonces Tamar siguió viviendo devastada en la casa de su hermano Absalón.
21 Ṣùgbọ́n nígbà tí Dafidi ọba gbọ́ gbogbo nǹkan wọ̀nyí, inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi.
Pero cuando el rey David tuvo noticias de todas estas cosas, se enojó mucho; pero no causó problemas a su hijo Amnón, porque era querido por David, siendo su hijo mayor.
22 Absalomu kò sì bá Amnoni sọ nǹkan rere, tàbí búburú, nítorí pé Absalomu kórìíra Amnoni nítorí èyí tí ó ṣe, àní tí ó fi agbára mú Tamari àbúrò rẹ̀.
Pero Absalón no le dijo nada a su hermano Amnón, ni bueno ni malo: porque estaba lleno de odio por él, porque se había llevado a su hermana Tamar por la fuerza.
23 Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọdún méjì, Absalomu sì ní olùrẹ́run àgùntàn ní Baali-Hasori, èyí tí ó gbé Efraimu, Absalomu sì pe gbogbo àwọn ọmọ ọba.
Después de dos años completos, Absalón hizo que los hombres cortaran la lana de sus ovejas en Baal Hazor, que está cerca de Efraín, e invitó todos los hijos del rey a su banquete.
24 Absalomu sì tọ ọba wá, ó sì wí pé, “Wò ó, jọ̀wọ́, ìránṣẹ́ rẹ ní olùrẹ́run àgùntàn, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ọba, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ bá ìránṣẹ́ rẹ lọ.”
Entonces Absalón se acercó al rey y le dijo: Mira, mis siervos están cortando la lana de sus ovejas; ¿Se complacerá el rey y sus siervos acompañarme?
25 Ọba sì wí fún Absalomu pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ, ọmọ mi, mo bẹ̀ ọ́, má ṣe jẹ́ kí gbogbo wa lọ, kí a má bá à mú ọ náwó púpọ̀.” Ó sì rọ̀ ọ́ gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ lọ, òun sì súre fún un.
Y el rey dijo a Absalón: No, hijo mío, no vamos todos, o el número será demasiado grande para ti. E hizo nuevamente su petición, pero no quiso ir, pero le dio su bendición.
26 Absalomu sì wí pé, “Bí kò bá le rí bẹ́ẹ̀, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí Amnoni ẹ̀gbọ́n mi bá wa lọ.” Ọba sì wí pé, “Ìdí rẹ̀ tí yóò fi bá ọ lọ.”
Entonces Absalón dijo: Si no quieres ir, deja que mi hermano Amnón vaya con nosotros. Y el rey le dijo: ¿Hay alguna razón para que vaya contigo?
27 Absalomu sì rọ̀ ọ́, òun sì jẹ́ kí Amnoni àti gbogbo àwọn ọmọ ọba bá a lọ.
Pero Absalón siguió pidiéndole hasta que dejó que Amnón y todos los hijos del rey lo acompañaran. Y Absalón hizo una gran fiesta como una fiesta para un rey.
28 Absalomu sì fi àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Kí ẹ̀yin máa kíyèsi àkókò tí ọtí-wáinì yóò mú ọkàn Amnoni dùn, èmi ó sì wí fún yín pé, ‘Kọlu Amnoni,’ kí ẹ sì pa á. Ẹ má bẹ̀rù. Ṣé èmi ni ó fi àṣẹ fún yin? Ẹ ṣe gírí, kí ẹ ṣe bí alágbára ọmọ.”
Ahora Absalón había dado órdenes a sus sirvientes, diciendo: Ahora, tomen nota cuando el corazón de Amnón se alegra con el vino; y cuando les diga: ataca a Amnón, mátalo sin miedo: ¿no te he dado órdenes? Séan fuertes y valientes.
29 Àwọn ìránṣẹ́ Absalomu sì ṣe sí Amnoni gẹ́gẹ́ bí Absalomu ti pàṣẹ. Gbogbo àwọn ọmọ ọba sì dìde, olúkúlùkù gun ìbáaka rẹ̀, wọ́n sì sá.
Así que los sirvientes de Absalón hicieron con Amnón como Absalón les había dado órdenes. Entonces todos los hijos del rey se levantaron, y todos los hombres se subieron a su mula y salieron huyendo.
30 Nígbà tí wọ́n ń bẹ lọ́nà, ìròyìn sì dé ọ̀dọ̀ Dafidi pé, “Absalomu pa gbogbo àwọn ọmọ ọba, ọ̀kan kò sì kù nínú wọn.”
Ahora, mientras iban en camino, se le dio a David la noticia de que Absalón había dado muerte a todos los hijos del rey y que ninguno de ellos aún vivía.
31 Ọba sì dìde, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì dùbúlẹ̀ ni ilẹ̀; gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí wọ́n dúró tì í sì fà aṣọ wọn ya.
Entonces el rey se levantó con gran dolor, tendiéndose sobre la tierra; y todos sus siervos estaban a su lado, con sus ropas rasgadas.
32 Jonadabu ọmọ Ṣimea arákùnrin Dafidi sì dáhùn ó sì wí pé, “Kí olúwa mi ọba má ṣe rò pé wọ́n ti pa gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin àwọn ọmọ ọba; nítorí pé Amnoni nìkan ṣoṣo ni ó kú, nítorí láti ẹnu Absalomu wá ni a ti pinnu rẹ̀ láti ọjọ́ tí ó ti fi agbára mú Tamari àbúrò rẹ̀.
Y Jonadab, el hijo de Simea, hermano de David, dijo: No se dé a mi señor la idea de que todos los hijos del rey han sido ejecutados; porque sólo Amnón ha muerto: esto lo propuso Absalom desde el día en que tomó a su hermana Tamar por la fuerza.
33 Ǹjẹ́ kí olúwa mi ọba má ṣe fi nǹkan yìí sí ọkàn pé gbogbo àwọn ọmọ ọba ni o kú, nítorí Amnoni nìkan ṣoṣo ni ó kú.”
Así que ahora, no permita que mi señor el rey tome esto en serio, con la idea de que todos los hijos del rey están muertos, porque sólo Amnón está muerto.
34 Absalomu sì sá. Ọ̀dọ́mọkùnrin náà ti ń ṣọ́nà sì gbé ojú rẹ̀ sókè, o si rí i pé, “Ọ̀pọ̀ ènìyàn ń bọ́ lọ́nà lẹ́yìn rẹ̀ láti ìhà òkè wá.”
Pero Absalón salió huyendo. Y el joven que vigilaba, alzando los ojos, vio que una gran banda de personas bajaba la pendiente por el camino que estaba a sus espaldas; y el vigilante se acercó y le dijo al rey, diciendo: Vi a hombres que bajaban por el camino, desde la ladera.
35 Jonadabu sì wí fún ọba pé, “Wò ó, àwọn ọmọ ọba ń bọ́; gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó rí.”
Y Jonadab dijo al rey: Mira, vienen los hijos del rey; Como dijo tu siervo, así es.
36 Nígbà tí ó sì parí ọ̀rọ̀ tí ó ń sọ, sì wò ó àwọn ọmọ ọba dé, wọ́n sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún, ọba àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú sì sọkún ńlá ńlá.
Y mientras él hablaba, los hijos del rey vinieron, llorando y gritando: y el rey y todos sus siervos lloraron amargamente.
37 Absalomu sì sá, ó sì tọ Talmai lọ, ọmọ Ammihudu, ọba Geṣuri. Dafidi sì ń káàánú nítorí ọmọ rẹ̀ lójoojúmọ́.
Entonces Absalón salió huyendo y vino a Talmai, el hijo de Amiud, el rey de Gesur, donde estuvo durante tres años.
38 Absalomu sì sá, ó sì lọ sí Geṣuri ó sì gbé ibẹ̀ lọ́dún mẹ́ta.
Y el rey estaba sufriendo por su hijo todo el tiempo.
39 Ọkàn Dafidi ọba sì fà gidigidi sí Absalomu, nítorí tí ó tí gba ìpẹ̀ ní ti Amnoni: ó sá à ti kú.
Y el corazón de David deseaba ver a Absalón, pues ya había sido consolado por la muerte de Amnón.