< 2 Samuel 13 >

1 Ó sì ṣe, lẹ́yìn èyí, Absalomu ọmọ Dafidi ní àbúrò obìnrin kan tí ó ṣe arẹwà, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Tamari; Amnoni ọmọ Dafidi sì fẹ́ràn rẹ̀.
Thuutha wa mahinda macio-rĩ, Abisalomu mũrũ wa Daudi aarĩ na mwarĩ wa nyina mũthaka mũno wetagwo Tamaru, nake Amunoni mũrũ wa Daudi akĩmwenda mũno.
2 Amnoni sì banújẹ́ títí ó fi ṣe àìsàn nítorí Tamari àbúrò rẹ̀ obìnrin; nítorí pé wúńdíá ni; ó sì ṣe ohun tí ó ṣòro lójú Amnoni láti bá a dàpọ̀.
Amunoni agĩtangĩka nginya agĩĩtua nĩ mũrũaru nĩ ũndũ wa mwarĩ wa ithe Tamaru, nĩgũkorwo aarĩ mũirĩtu gathirange, na nĩonaga arĩ hinya kũmwĩka ũndũ o na ũrĩkũ.
3 Ṣùgbọ́n Amnoni ní ọ̀rẹ́ kan, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Jonadabu, ọmọ Ṣimea ẹ̀gbọ́n Dafidi, Jonadabu sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn gidigidi.
Na rĩrĩ, Amunoni aarĩ na mũratawe wetagwo Jonadabu mũrũ wa Shimea, mũrũ wa nyina na Daudi. Jonadabu aarĩ mũndũ mwara mũno.
4 Ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ ọmọ ọba ń fi ń rù lójoojúmọ́ báyìí? Ǹjẹ́ o kò ní sọ fún mi?” Amnoni sì wí fún un pé, “Èmi fẹ́ Tamari àbúrò Absalomu arákùnrin mi.”
Akĩũria Amunoni atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte wee mũrũ wa mũthamaki woneke o ũkĩhinyĩrĩrĩka rũciinĩ o rũciinĩ? Kaĩ ũtangĩnjĩĩra gĩtũmi?” Amunoni akĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩ kwenda nyendeete Tamaru, mwarĩ wa nyina na Abisalomu mũrũ wa baba.”
5 Jonadabu sì wí fún un pé, “Dùbúlẹ̀ ní ibùsùn rẹ kí ìwọ sì díbọ́n pé, ìwọ kò sàn, baba rẹ yóò sì wá wò ọ́, ìwọ ó sì wí fún un pé, ‘Jọ̀wọ́ jẹ́ kí Tamari àbúrò mi wá kí ó sì fún mi ní oúnjẹ kí ó sì ṣe oúnjẹ náà níwájú mi kí èmi ó rí i, èmi ó sì jẹ ẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀.’”
Jonadabu akĩmwĩra atĩrĩ, “Thiĩ ũrĩrĩ na wĩtue atĩ ũrĩ mũrũaru. Rĩrĩa thoguo arĩũka gũkuona, ũmwĩre atĩrĩ, ‘No nyende mwarĩ wa baba Tamaru oke aahe kĩndũ gĩa kũrĩa. Andugĩre irio ngĩonaga, nĩguo ndĩmuone, na ningĩ ndĩe acinyiitĩte na guoko gwake.’”
6 Amnoni sì dùbúlẹ̀, ó sì díbọ́n pé òun ṣàìsàn, ọba sì wá wò ó, Amnoni sì wí fún ọba pé, “Jọ̀wọ́, jẹ́ kí Tamari àbúrò mi ó wá, kí ó sì dín àkàrà méjì lójú mi, èmi ó sì jẹ ní ọwọ́ rẹ̀.”
Nĩ ũndũ ũcio Amunoni agĩkoma na agĩĩtua nĩ mũrũaru. Na rĩrĩa mũthamaki ookire kũmuona, Amunoni akĩmwĩra atĩrĩ, “No nyende mwarĩ wa baba Tamaru oke aathondekere tũmĩgate ngĩonaga, nĩguo ndĩe anyiitĩte na guoko gwake.”
7 Dafidi sì ránṣẹ́ sí Tamari ní ilé pé, “Lọ sí ilé Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ, kí ó sì se oúnjẹ fún un.”
Daudi agĩtũmanĩra Tamaru nyũmba-inĩ ya ũthamaki, akĩmwĩra atĩrĩ, “Thiĩ nyũmba ya mũrũ wa thoguo Amunoni, ũmũthondekere irio.”
8 Tamari sì lọ sí ilé Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ̀, òun sì ń bẹ ní ìdùbúlẹ̀. Tamari sì mú ìyẹ̀fun, ó sì pò ó, ó sì fi ṣe àkàrà lójú rẹ̀, ó sì dín àkàrà náà.
Nĩ ũndũ ũcio Tamaru agĩthiĩ nyũmba ya mũrũ wa ithe Amunoni, akĩmũkora akomete. Akĩoya mũtu, akĩũkanda, agĩthondeka mũgate Amunoni akĩmuonaga, na akĩũruga.
9 Òun sì mú àwo náà, ó sì dà á sínú àwo mìíràn níwájú rẹ̀; ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti jẹ. Amnoni sì wí pé, “Jẹ́ kí gbogbo ọkùnrin jáde kúrò lọ́dọ̀ mi!” Wọ́n sì jáde olúkúlùkù ọkùnrin kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
Agĩcooka akĩoya rũgĩo, akĩmũihũrĩra mũgate, nowe akĩrega kũrĩa. Amunoni akiuga atĩrĩ, “Andũ othe nĩmeherio haha.” Nĩ ũndũ ũcio andũ othe makiuma nja, makĩmũtiga.
10 Amnoni sì wí fún Tamari pé, “Mú oúnjẹ náà wá sí yàrá, èmi ó sì jẹ ẹ́ lọ́wọ́ rẹ.” Tamari sì mú àkàrà tí ó ṣe, ó sì mú un tọ Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ní yàrá.
Hĩndĩ ĩyo Amunoni akĩĩra Tamaru atĩrĩ, “Ndehera irio haha nyũmba yakwa ya toro, nĩguo ndĩe ũcinyiitĩte na guoko gwaku.” Nake Tamaru akĩoya mũgate ũrĩa aathondekete, akĩũtwarĩra mũrũ wa ithe Amunoni nyũmba yake ya toro.
11 Nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn láti fi oúnjẹ fún un, òun sì dìímú, ó sì wí fún un pé, “Wá dùbúlẹ̀ tì mí, àbúrò mi.”
No rĩrĩa aamũtwarĩire nĩguo arĩe, Amunoni akĩmũnyiita, akiuga atĩrĩ, “Ũka ngome nawe, mwarĩ wa baba.”
12 Òun sì dá a lóhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀gbọ́n mi, má ṣe tẹ́ mi; nítorí pé kò tọ kí a ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀ ní Israẹli, ìwọ má ṣe hùwà òmùgọ̀ yìí.
Nake akĩmwĩra atĩrĩ, “Aca, mũrũ wa baba! Tiga kũnyiita na hinya. Ũndũ ta ũyũ ndwagĩrĩire gwĩkwo Isiraeli! Tiga gwĩka ũndũ ũyũ wa waganu.
13 Àti èmi, níbo ni èmi ó gbé ìtìjú mi wọ̀? Ìwọ ó sì dàbí ọ̀kan nínú àwọn aṣiwèrè ní Israẹli. Ǹjẹ́ nítorí náà, èmi bẹ̀ ọ́, sọ fún ọba; nítorí pé òun kì yóò kọ̀ láti fi mí fún ọ.”
Ha ũhoro wakwa naguo atĩa? Thoni ciakwa ingĩcitwara nakũ? O nawe-rĩ, ũhoro waku ũgũikara atĩa? Ũkuoneka ũhaana ta mũndũ ũmwe wa andũ arĩa aaganu na akĩĩgu thĩinĩ wa Isiraeli. Ndagũthaitha aria na mũthamaki; tondũ ndangĩgiria ũũhikie.”
14 Ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti gbọ́ ohùn rẹ̀; ó sì fi agbára mú un, ó sì ṣẹ́gun rẹ̀, ó sì bá a dàpọ̀.
Nowe akĩrega kũmũigua, na tondũ aarĩ na hinya kũmũkĩra, akĩmũnyiita na agĩkoma nake na hinya.
15 Amnoni sì kórìíra rẹ̀ gidigidi, ìríra náà sì wá ju ìfẹ́ tí òun ti ní sí i rí lọ. Amnoni sì wí fún un pé, “Dìde, kí o sì máa lọ!”
Ningĩ Amunoni akĩmũthũũra na rũthũũro rũnene makĩria. Ti-itherũ, aamũthũũrire gũkĩra ũrĩa aamwendete. Amunoni akĩmwĩra atĩrĩ, “Ũkĩra, wehere haha!”
16 Òun sì wí fún un pé, “Kó ha ní ìdí bí! Lílé tí ìwọ ń lé mi yìí burú ju èyí tí ìwọ ti ṣe sí mi lọ.” Ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ gbọ́ tirẹ̀.
Tamaru akĩmwĩra atĩrĩ, “Aca! Kũnyingata thiĩ nĩ ihĩtia inene makĩria gũkĩra ũguo wanjĩka.” Nowe akĩrega kũmũigua.
17 Òun sì pe ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí í ṣe ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Jọ̀wọ́, ti obìnrin yìí sóde fún mi, kí o sì ti ìlẹ̀kùn mọ́ ọn.”
Nake Amunoni agĩĩta ndungata yake, akĩmĩĩra atĩrĩ, “Eheria mũndũ-wa-nja ũyũ haha, na oima ũhinge mũrango.”
18 Òun sì ní aṣọ aláràbarà kan lára rẹ̀, nítorí irú aṣọ àwọ̀lékè bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọbìnrin ọba tí í ṣe wúńdíá máa ń wọ̀. Ìránṣẹ́ rẹ̀ sì mú un jáde, ó sì ti ìlẹ̀kùn mọ́ ọn.
Nĩ ũndũ ũcio ndungata yake ĩkĩmũikia na nja, na ĩkĩhinga mũrango. Nake Tamaru eehumbĩte nguo ndaaya yagemetio na magemio ma goro, tondũ airĩtu arĩa gathirange a mũthamaki meehumbaga nguo ta ĩyo.
19 Tamari sì bu eérú sí orí rẹ̀, ó sì fa aṣọ aláràbarà tí ń bẹ lára rẹ̀ ya, ó sì ká ọwọ́ rẹ̀ lé orí, ó sì ń kígbe bí ó ti ń lọ.
Tamaru akĩĩitĩrĩria mũhu mũtwe, na agĩtarũra nguo ĩyo ndaaya ngʼemie ĩrĩa eehumbĩte. Agĩcooka akĩigĩrĩra guoko gwake mũtwe, agĩthiĩ akĩrĩraga aanĩrĩire.
20 Absalomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ sì bí i léèrè pé, “Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ bá ọ sùn bí? Ǹjẹ́ àbúrò mi, dákẹ́; ẹ̀gbọ́n rẹ ní í ṣe; má fi nǹkan yìí sí ọkàn rẹ.” Tamari sì jókòó ní ìbànújẹ́ ní ilé Absalomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
Nake mũrũ wa nyina Abisalomu akĩmũũria atĩrĩ, “Kaĩ muuma na Amunoni, mũrũ wa thoguo? Rĩu ta gĩkire, mwarĩ wa maitũ, tondũ we nĩ mũrũ wa thoguo. Tiga kũigua ũũru ngoro nĩ ũndũ wa ũndũ ũcio.” Nake Tamaru agĩtũũra mũciĩ kwa mũrũ wa nyina Abisalomu, arĩ mũndũ-wa-nja ũrĩ na kĩeha kĩnene.
21 Ṣùgbọ́n nígbà tí Dafidi ọba gbọ́ gbogbo nǹkan wọ̀nyí, inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi.
Hĩndĩ ĩrĩa Mũthamaki Daudi aiguire maũndũ macio mothe-rĩ, akĩrakara mũno.
22 Absalomu kò sì bá Amnoni sọ nǹkan rere, tàbí búburú, nítorí pé Absalomu kórìíra Amnoni nítorí èyí tí ó ṣe, àní tí ó fi agbára mú Tamari àbúrò rẹ̀.
Abisalomu ndaigana kwaria na Amunoni ũndũ o na ũrĩkũ, mwega kana mũũru; nĩathũũrire Amunoni tondũ nĩaconorithĩtie mwarĩ wa nyina Tamaru.
23 Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọdún méjì, Absalomu sì ní olùrẹ́run àgùntàn ní Baali-Hasori, èyí tí ó gbé Efraimu, Absalomu sì pe gbogbo àwọn ọmọ ọba.
Mĩaka ĩĩrĩ yathira, hĩndĩ ĩrĩa amuri a ngʼondu guoya a Abisalomu maarĩ kũu Baali-Hazoru hakuhĩ na mũhaka wa Efiraimu-rĩ, agĩĩta ariũ a mũthamaki othe mathiĩ kuo.
24 Absalomu sì tọ ọba wá, ó sì wí pé, “Wò ó, jọ̀wọ́, ìránṣẹ́ rẹ ní olùrẹ́run àgùntàn, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ọba, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ bá ìránṣẹ́ rẹ lọ.”
Abisalomu agĩthiĩ kũrĩ mũthamaki, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ndungata yaku nĩĩtĩte amuri ngʼondu guoya. Hihi mũthamaki na anene ake no moke tũkorwo hamwe.”
25 Ọba sì wí fún Absalomu pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ, ọmọ mi, mo bẹ̀ ọ́, má ṣe jẹ́ kí gbogbo wa lọ, kí a má bá à mú ọ náwó púpọ̀.” Ó sì rọ̀ ọ́ gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ lọ, òun sì súre fún un.
Mũthamaki agĩcookia atĩrĩ, “Aca, mũrũ wakwa. Tũtiagĩrĩirwo nĩ gũthiĩ ithuothe; twahota gũtuĩka mũrigo harĩwe.” O na gũtuĩka Abisalomu nĩamũthaithire-rĩ, nĩaregire biũ gũthiĩ, no akĩmũhe kĩrathimo gĩake.
26 Absalomu sì wí pé, “Bí kò bá le rí bẹ́ẹ̀, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí Amnoni ẹ̀gbọ́n mi bá wa lọ.” Ọba sì wí pé, “Ìdí rẹ̀ tí yóò fi bá ọ lọ.”
Ningĩ Abisalomu akĩmwĩra atĩrĩ, “Angĩkorwo ti ũguo-rĩ, ndagũthaitha ũreke mũrũ wa baba Amunoni athiĩ na ithuĩ.” Nake mũthamaki akĩmũũria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩgũtũma athiĩ na inyuĩ?”
27 Absalomu sì rọ̀ ọ́, òun sì jẹ́ kí Amnoni àti gbogbo àwọn ọmọ ọba bá a lọ.
Nowe Abisalomu akĩmũringĩrĩria, na nĩ ũndũ ũcio mũthamaki akĩreka Amunoni mathiĩ nake, hamwe na ariũ acio angĩ a mũthamaki.
28 Absalomu sì fi àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Kí ẹ̀yin máa kíyèsi àkókò tí ọtí-wáinì yóò mú ọkàn Amnoni dùn, èmi ó sì wí fún yín pé, ‘Kọlu Amnoni,’ kí ẹ sì pa á. Ẹ má bẹ̀rù. Ṣé èmi ni ó fi àṣẹ fún yin? Ẹ ṣe gírí, kí ẹ ṣe bí alágbára ọmọ.”
Abisalomu agĩatha andũ ake, akĩmeera atĩrĩ, “Ta thikĩrĩriai! Rĩrĩa Amunoni arĩkorwo akenete nĩ kũnyua ndibei akarĩĩo, na inyuĩ ndĩmwĩre atĩrĩ, ‘Ringai agwe thĩ,’ hĩndĩ ĩyo mũũragei. Mũtigetigĩre. Githĩ ti niĩ ndĩmũheete watho ũcio? Ũmĩrĩriai mũtuĩke njamba.”
29 Àwọn ìránṣẹ́ Absalomu sì ṣe sí Amnoni gẹ́gẹ́ bí Absalomu ti pàṣẹ. Gbogbo àwọn ọmọ ọba sì dìde, olúkúlùkù gun ìbáaka rẹ̀, wọ́n sì sá.
Nĩ ũndũ ũcio andũ a Abisalomu magĩĩka Amunoni o ta ũrĩa Abisalomu aamaathĩte. Hĩndĩ ĩyo ariũ othe a mũthamaki magĩũkĩra, makĩhaica nyũmbũ ciao, makĩũra.
30 Nígbà tí wọ́n ń bẹ lọ́nà, ìròyìn sì dé ọ̀dọ̀ Dafidi pé, “Absalomu pa gbogbo àwọn ọmọ ọba, ọ̀kan kò sì kù nínú wọn.”
Marĩ njĩra-inĩ makĩũra-rĩ, ũhoro ũcio ũgĩkinyĩra Daudi, akĩĩrwo atĩrĩ, “Abisalomu nĩoragĩte ariũ othe a mũthamaki; gũtirĩ o na ũmwe ũtigarĩte.”
31 Ọba sì dìde, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì dùbúlẹ̀ ni ilẹ̀; gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí wọ́n dúró tì í sì fà aṣọ wọn ya.
Nake mũthamaki agĩũkĩra, agĩtembũranga nguo ciake, agĩkoma thĩ; o nacio ndungata ciake ikĩrũgama hakuhĩ nake, na igĩtembũranga nguo ciacio.
32 Jonadabu ọmọ Ṣimea arákùnrin Dafidi sì dáhùn ó sì wí pé, “Kí olúwa mi ọba má ṣe rò pé wọ́n ti pa gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin àwọn ọmọ ọba; nítorí pé Amnoni nìkan ṣoṣo ni ó kú, nítorí láti ẹnu Absalomu wá ni a ti pinnu rẹ̀ láti ọjọ́ tí ó ti fi agbára mú Tamari àbúrò rẹ̀.
No Jonadabu mũrũ wa Shimea, mũrũ wa nyina na Daudi, akiuga atĩrĩ, “Mwathi wakwa, tiga gwĩciiria atĩ moragĩte ariũ othe a mũthamaki; no Amunoni wiki ũkuĩte. Ũndũ ũcio ũtũire ũrĩ muoroto wa Abisalomu kuuma mũthenya ũrĩa Amunoni aanyiitire mwarĩ wa nyina Tamaru na hinya.
33 Ǹjẹ́ kí olúwa mi ọba má ṣe fi nǹkan yìí sí ọkàn pé gbogbo àwọn ọmọ ọba ni o kú, nítorí Amnoni nìkan ṣoṣo ni ó kú.”
Mũthamaki mwathi wakwa ndagĩrĩirwo nĩkũrũmbũiya ũhoro ũcio wa atĩ ariũ othe a mũthamaki nĩmakuĩte. Amunoni nowe wiki ũkuĩte.”
34 Absalomu sì sá. Ọ̀dọ́mọkùnrin náà ti ń ṣọ́nà sì gbé ojú rẹ̀ sókè, o si rí i pé, “Ọ̀pọ̀ ènìyàn ń bọ́ lọ́nà lẹ́yìn rẹ̀ láti ìhà òkè wá.”
Hĩndĩ ĩyo Abisalomu nĩakoretwo orĩte. Na rĩrĩ, mũndũ ũrĩa warangagĩra itũũra agĩcũthĩrĩria na akĩona andũ aingĩ njĩra-inĩ mwena wake wa ithũĩro, maikũrũkĩire mwena-inĩ wa kĩrĩma. Nake mũrangĩri agĩthiĩ akĩĩra mũthamaki atĩrĩ, “Nĩndĩrona andũ mwena ũũrĩa wa Horonaimu, mwena-inĩ wa kĩrĩma.”
35 Jonadabu sì wí fún ọba pé, “Wò ó, àwọn ọmọ ọba ń bọ́; gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó rí.”
Jonadabu akĩĩra mũthamaki atĩrĩ, “Ta kĩone, ariũ a mũthamaki marĩ haha; o ta ũrĩa ndungata yaku ĩkwĩrire, ũguo noguo gũtariĩ.”
36 Nígbà tí ó sì parí ọ̀rọ̀ tí ó ń sọ, sì wò ó àwọn ọmọ ọba dé, wọ́n sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún, ọba àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú sì sọkún ńlá ńlá.
Na aarĩkia kwaria o ro ũguo-rĩ, ariũ a mũthamaki magĩũka makĩrĩraga na mũgambo mũnene. O nake mũthamaki na ndungata ciake ciothe makĩrĩra marĩ na ruo rũnene.
37 Absalomu sì sá, ó sì tọ Talmai lọ, ọmọ Ammihudu, ọba Geṣuri. Dafidi sì ń káàánú nítorí ọmọ rẹ̀ lójoojúmọ́.
Nake Abisalomu akĩũra agĩthiĩ gwa Talimai mũrũ wa Amihudi, mũthamaki wa Geshuru. Nowe Mũthamaki Daudi agĩcakaĩra mũriũ mũthenya o mũthenya.
38 Absalomu sì sá, ó sì lọ sí Geṣuri ó sì gbé ibẹ̀ lọ́dún mẹ́ta.
Thuutha wa Abisalomu kũũrĩra Geshuru, aikarire kuo mĩaka ĩtatũ.
39 Ọkàn Dafidi ọba sì fà gidigidi sí Absalomu, nítorí tí ó tí gba ìpẹ̀ ní ti Amnoni: ó sá à ti kú.
Nayo ngoro ya mũthamaki nĩyeriragĩria gũthiĩ kũrĩ Abisalomu, tondũ nĩahooreretio ũhoro-inĩ ũkoniĩ gĩkuũ kĩa Amunoni.

< 2 Samuel 13 >