< 2 Samuel 13 >

1 Ó sì ṣe, lẹ́yìn èyí, Absalomu ọmọ Dafidi ní àbúrò obìnrin kan tí ó ṣe arẹwà, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Tamari; Amnoni ọmọ Dafidi sì fẹ́ràn rẹ̀.
Te phoeiah om tih David capa Absalom tah a ngannu sakthen om. Anih ming tah Tamar tih David capa Amnon loh a lungnah.
2 Amnoni sì banújẹ́ títí ó fi ṣe àìsàn nítorí Tamari àbúrò rẹ̀ obìnrin; nítorí pé wúńdíá ni; ó sì ṣe ohun tí ó ṣòro lójú Amnoni láti bá a dàpọ̀.
A ngannu Tamar kong ah Amnon te tloh la a yuek. Anih te a oila pueng dongah khat khat a saii ham Amnon mik ah rhaisang.
3 Ṣùgbọ́n Amnoni ní ọ̀rẹ́ kan, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Jonadabu, ọmọ Ṣimea ẹ̀gbọ́n Dafidi, Jonadabu sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn gidigidi.
Te vaengah David maya Shimeah capa, a ming ah Jonadab tah Amnon kah a paya la om. Jonadab tah bahoeng aka cueih hlang la om.
4 Ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ ọmọ ọba ń fi ń rù lójoojúmọ́ báyìí? Ǹjẹ́ o kò ní sọ fún mi?” Amnoni sì wí fún un pé, “Èmi fẹ́ Tamari àbúrò Absalomu arákùnrin mi.”
Te dongah anih te, “Ba aih lae mincang bal, mincang bal nang manghai capa he na tattloel aih. Kai taengah na thui mahpawt a?” a ti nah. Te daengah Amnon loh, “Ka manuca Absalom ngannu Tamar ka ngaih,” a ti nah.
5 Jonadabu sì wí fún un pé, “Dùbúlẹ̀ ní ibùsùn rẹ kí ìwọ sì díbọ́n pé, ìwọ kò sàn, baba rẹ yóò sì wá wò ọ́, ìwọ ó sì wí fún un pé, ‘Jọ̀wọ́ jẹ́ kí Tamari àbúrò mi wá kí ó sì fún mi ní oúnjẹ kí ó sì ṣe oúnjẹ náà níwájú mi kí èmi ó rí i, èmi ó sì jẹ ẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀.’”
Te dongah anih te Jehonadab loh, “Na thingkong dongah satlo bangla yalh. Nang te sawt hamla na pa ha pawk vaengah amah taengah, ‘Ka ngannu Tamar ha pawk laeh vetih kai buh n'tuh lah mako. Ka mikhmuh ah buhmaeh a saii te ka hmu dae eh. Te daengah ni a kut dongkah ka caak eh,’ ti nah,” a ti nah.
6 Amnoni sì dùbúlẹ̀, ó sì díbọ́n pé òun ṣàìsàn, ọba sì wá wò ó, Amnoni sì wí fún ọba pé, “Jọ̀wọ́, jẹ́ kí Tamari àbúrò mi ó wá, kí ó sì dín àkàrà méjì lójú mi, èmi ó sì jẹ ní ọwọ́ rẹ̀.”
Amnon te satlo bangla yalh toengloeng tih anih te sawt hamla manghai te ha pawk. Te vaengah Amnon loh manghai taengah, “Ka ngannu Tamar ha pawk laeh saeh lamtah ka mikhmuh ah vaidam panit ah saii saeh. Te daengah ni anih kut lamkah te ka caak eh,” a ti nah.
7 Dafidi sì ránṣẹ́ sí Tamari ní ilé pé, “Lọ sí ilé Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ, kí ó sì se oúnjẹ fún un.”
Te dongah David loh Tamar te a im la a tah tih, “Na nganpa Amnon im la cet lamtah anih ham buhmaeh saii pah laeh,” a ti nah.
8 Tamari sì lọ sí ilé Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ̀, òun sì ń bẹ ní ìdùbúlẹ̀. Tamari sì mú ìyẹ̀fun, ó sì pò ó, ó sì fi ṣe àkàrà lójú rẹ̀, ó sì dín àkàrà náà.
Tamar te a nganpa Amnon im la a caeh vaengah anih te ana yalh pah. Vaidamtlam te a loh tih a duep, a duep phoeiah a mikhmuh ah a saii pah. Te phoeiah vaidam te a thong pah.
9 Òun sì mú àwo náà, ó sì dà á sínú àwo mìíràn níwájú rẹ̀; ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti jẹ. Amnoni sì wí pé, “Jẹ́ kí gbogbo ọkùnrin jáde kúrò lọ́dọ̀ mi!” Wọ́n sì jáde olúkúlùkù ọkùnrin kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
Thi-am te a loh tih a mikhmuh ah a poep pah hatah caak hamla a aal. Te phoeiah Amnon loh, “Ka taeng lamkah hlang he boeih tueih uh,” a ti nah. Te dongah hlang boeih te anih taeng lamloh nong uh.
10 Amnoni sì wí fún Tamari pé, “Mú oúnjẹ náà wá sí yàrá, èmi ó sì jẹ ẹ́ lọ́wọ́ rẹ.” Tamari sì mú àkàrà tí ó ṣe, ó sì mú un tọ Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ní yàrá.
Te phoeiah Amnon loh Tamar te, “Imkhui la buhmaeh hang khuen lamtah na kut dongah ka ca eh,” a ti nah. Te dongah vaidam a saii te Tamar loh a loh tih imkhui kah a nganpa Amnon taengla a kun puei.
11 Nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn láti fi oúnjẹ fún un, òun sì dìímú, ó sì wí fún un pé, “Wá dùbúlẹ̀ tì mí, àbúrò mi.”
A caak ham a taengah a tawn pah vaengah tah amah te vik a tuuk tih, “Ka ngannu halo lamtah kamah neh yalh sih,” a ti nah.
12 Òun sì dá a lóhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀gbọ́n mi, má ṣe tẹ́ mi; nítorí pé kò tọ kí a ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀ ní Israẹli, ìwọ má ṣe hùwà òmùgọ̀ yìí.
Tedae anih te, “Ka nganpa aw te tlam moenih, kai m'poeih boeh, Israel khuiah te bang te a saii noek moenih. Boethaehalang he saii boeh.
13 Àti èmi, níbo ni èmi ó gbé ìtìjú mi wọ̀? Ìwọ ó sì dàbí ọ̀kan nínú àwọn aṣiwèrè ní Israẹli. Ǹjẹ́ nítorí náà, èmi bẹ̀ ọ́, sọ fún ọba; nítorí pé òun kì yóò kọ̀ láti fi mí fún ọ.”
Kai he kamah kah kokhahnah neh melam ka caeh eh. Namah khaw Israel khuiah hlang ang boeiloeih bangla na om ve. Manghai taengah thui kanoek lamtah nang taengah tah kai khaw n'hloh mahpawh,” a ti nah.
14 Ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti gbọ́ ohùn rẹ̀; ó sì fi agbára mú un, ó sì ṣẹ́gun rẹ̀, ó sì bá a dàpọ̀.
Tedae a ol te yaak ngaih pawh. A ngannu te rhap a kop tih a yalh puei.
15 Amnoni sì kórìíra rẹ̀ gidigidi, ìríra náà sì wá ju ìfẹ́ tí òun ti ní sí i rí lọ. Amnoni sì wí fún un pé, “Dìde, kí o sì máa lọ!”
Te phoeiah tah anih te Amnon loh lat a hnoel tih a hmuhuetnah bahoeng a nah pah. A thiinah vaengkah a hmuhuetnah te a lungnah vaengkah lungnah lakah nah. Te dongah anih te Amnon loh, “Thoo, cet laeh,” a ti nah.
16 Òun sì wí fún un pé, “Kó ha ní ìdí bí! Lílé tí ìwọ ń lé mi yìí burú ju èyí tí ìwọ ti ṣe sí mi lọ.” Ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ gbọ́ tirẹ̀.
Amnon te, “He lakah a tloe la aka len boethae kah a kong a mai he a om moenih. Kai nan saii tih nan haek te,” a ti nah. Tedae anih ol te yaak ngaih voel pawh.
17 Òun sì pe ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí í ṣe ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Jọ̀wọ́, ti obìnrin yìí sóde fún mi, kí o sì ti ìlẹ̀kùn mọ́ ọn.”
Te dongah amah aka khut a taengca te, “Anih te kai taeng lamloh kawtpoeng la tueih uh lamtah anih hnukah thohkhaih te kalh laeh,” a ti nah.
18 Òun sì ní aṣọ aláràbarà kan lára rẹ̀, nítorí irú aṣọ àwọ̀lékè bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọbìnrin ọba tí í ṣe wúńdíá máa ń wọ̀. Ìránṣẹ́ rẹ̀ sì mú un jáde, ó sì ti ìlẹ̀kùn mọ́ ọn.
Te vaengah a pum dongah pendum angkidung a bai. Te bang te manghai canu rhoek loh oila kah hnikul la a bai uh. Amnon aka khut loh Tamar te vongvoel la a thak tih a hnukah thohkhaih te kalh.
19 Tamari sì bu eérú sí orí rẹ̀, ó sì fa aṣọ aláràbarà tí ń bẹ lára rẹ̀ ya, ó sì ká ọwọ́ rẹ̀ lé orí, ó sì ń kígbe bí ó ti ń lọ.
Tamar loh a lu dongah hmaiphu a phul tih a pum dongkah pendum angkidung khaw a phen. Te phoeiah a kut te a lu dongah a pingpoei tih a caeh, caeh doeah rhap.
20 Absalomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ sì bí i léèrè pé, “Amnoni ẹ̀gbọ́n rẹ bá ọ sùn bí? Ǹjẹ́ àbúrò mi, dákẹ́; ẹ̀gbọ́n rẹ ní í ṣe; má fi nǹkan yìí sí ọkàn rẹ.” Tamari sì jókòó ní ìbànújẹ́ ní ilé Absalomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
Te dongah anih te a nganpa Absalom loh, “Na nganpa Amnon a nang taengah aka om? Ka ngannu na hilphah laeh anih a nang nganpa, he olka dongah na lungbuei khueh boeh,” a ti nah. Te dongah Tamar tah a nganpa Absalom im ah kho a sak tih pong van.
21 Ṣùgbọ́n nígbà tí Dafidi ọba gbọ́ gbogbo nǹkan wọ̀nyí, inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi.
Tedae he rhoek kah olka boeih te manghai David loh a yaak vaengah amah khaw muep sai coeng.
22 Absalomu kò sì bá Amnoni sọ nǹkan rere, tàbí búburú, nítorí pé Absalomu kórìíra Amnoni nítorí èyí tí ó ṣe, àní tí ó fi agbára mú Tamari àbúrò rẹ̀.
A ngannu Tamar a poeih dongkah olka dongah Absalom loh Amnon te a hmuhuet tih a thae a then akhaw Absalom loh Amnon te voek pawh.
23 Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọdún méjì, Absalomu sì ní olùrẹ́run àgùntàn ní Baali-Hasori, èyí tí ó gbé Efraimu, Absalomu sì pe gbogbo àwọn ọmọ ọba.
A kum khohnin a pha vaengah Ephraim taengkah Baalhazor ah Absalom ham mul vok a saii uh tih manghai ca rhoek boeih te Absalom loh a khue.
24 Absalomu sì tọ ọba wá, ó sì wí pé, “Wò ó, jọ̀wọ́, ìránṣẹ́ rẹ ní olùrẹ́run àgùntàn, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí ọba, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ bá ìránṣẹ́ rẹ lọ.”
Te dongah Absalom te manghai taengla kun tih, “Na sal ham mul aka vo rhoek cet uh pawn ni ke, manghai namah neh, na sal neh a sal rhoek te ta,” a ti nah.
25 Ọba sì wí fún Absalomu pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ, ọmọ mi, mo bẹ̀ ọ́, má ṣe jẹ́ kí gbogbo wa lọ, kí a má bá à mú ọ náwó púpọ̀.” Ó sì rọ̀ ọ́ gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ lọ, òun sì súre fún un.
Manghai loh Absalom te, “Ka capa te tlam moenih, mamih boeih n'cet tarha mahpawh, te daengah ni namah te n'nan pawt eh,” a ti nah. A taengah a cahoeh ngawn dae paan pah ham tah huem pawt tih anih te yoethen a paek.
26 Absalomu sì wí pé, “Bí kò bá le rí bẹ́ẹ̀, èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí Amnoni ẹ̀gbọ́n mi bá wa lọ.” Ọba sì wí pé, “Ìdí rẹ̀ tí yóò fi bá ọ lọ.”
Absalom loh, “Te pawt atah ka maya Amnon tah kaimih taengah m'paan mai mako,” a ti nah. Tedae amah te manghai loh, “Balae tih nang te m'paan eh?” a ti nah.
27 Absalomu sì rọ̀ ọ́, òun sì jẹ́ kí Amnoni àti gbogbo àwọn ọmọ ọba bá a lọ.
Tedae anih te Absalom loh a cahoeh dongah Amnon neh manghai capa rhoek boeih te a taengla a tueih pah.
28 Absalomu sì fi àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Kí ẹ̀yin máa kíyèsi àkókò tí ọtí-wáinì yóò mú ọkàn Amnoni dùn, èmi ó sì wí fún yín pé, ‘Kọlu Amnoni,’ kí ẹ sì pa á. Ẹ má bẹ̀rù. Ṣé èmi ni ó fi àṣẹ fún yin? Ẹ ṣe gírí, kí ẹ ṣe bí alágbára ọmọ.”
Te vaengah Absalom loh a tueihyoeih rhoek te a uen tih, “Misurtui lamloh Amnon kah lungbuei a umya vaengah hmu uh laeh, nangmih taengah, ‘Amnon te ngawn uh lamtah duek sak uh, anih te rhih uh boeh, nangmih te kang uen pawt nim? Ning uh lamtah tatthai capa bangla om uh,’ ka ti,” a ti nah.
29 Àwọn ìránṣẹ́ Absalomu sì ṣe sí Amnoni gẹ́gẹ́ bí Absalomu ti pàṣẹ. Gbogbo àwọn ọmọ ọba sì dìde, olúkúlùkù gun ìbáaka rẹ̀, wọ́n sì sá.
Te dongah Absalom kah a uen bangla Amnon te Absalom kah tueihyoeih rhoek loh a saii uh. Te dongah manghai capa rhoek tah boeih thoo uh tih a muli-marhang dongah rhip ngol uh tih rhaelrham uh.
30 Nígbà tí wọ́n ń bẹ lọ́nà, ìròyìn sì dé ọ̀dọ̀ Dafidi pé, “Absalomu pa gbogbo àwọn ọmọ ọba, ọ̀kan kò sì kù nínú wọn.”
Amih te a longpueng uh vaengah olthang tah David taengla pawk coeng tih, “Absalom loh manghai capa rhoek te boeih a ngawn tih amih te pakhat khaw a hlun moenih,” a ti nah.
31 Ọba sì dìde, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì dùbúlẹ̀ ni ilẹ̀; gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí wọ́n dúró tì í sì fà aṣọ wọn ya.
Te dongah manghai te thoo tih a himbai te a phen tih lai dongah yalh. Te vaengah a sal aka pai rhoek boeih long khaw himbai te a phen uh.
32 Jonadabu ọmọ Ṣimea arákùnrin Dafidi sì dáhùn ó sì wí pé, “Kí olúwa mi ọba má ṣe rò pé wọ́n ti pa gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọdékùnrin àwọn ọmọ ọba; nítorí pé Amnoni nìkan ṣoṣo ni ó kú, nítorí láti ẹnu Absalomu wá ni a ti pinnu rẹ̀ láti ọjọ́ tí ó ti fi agbára mú Tamari àbúrò rẹ̀.
Tedae David maya Shimeah capa Jonadab loh a doo tih, “Ka boeipa loh manghai capa camoe rhoek la rhenten thui boeh. Amnon amah bueng ni a ngawn uh. A ngannu Tamar te a poeih pah hnin lamloh anih te Absalom loh a ka dongah a ngawn tangtae la a khueh coeng.
33 Ǹjẹ́ kí olúwa mi ọba má ṣe fi nǹkan yìí sí ọkàn pé gbogbo àwọn ọmọ ọba ni o kú, nítorí Amnoni nìkan ṣoṣo ni ó kú.”
Te dongah manghai capa rhoek boeih duek coeng a ti ol te ka boeipa manghai loh a lungbuei ah khueh boel saeh. Amnon amah bueng ni a duek,” a ti nah.
34 Absalomu sì sá. Ọ̀dọ́mọkùnrin náà ti ń ṣọ́nà sì gbé ojú rẹ̀ sókè, o si rí i pé, “Ọ̀pọ̀ ènìyàn ń bọ́ lọ́nà lẹ́yìn rẹ̀ láti ìhà òkè wá.”
Absalom a yong vaengah rhaltawt camoe te a mik, mik ah a dan. Te vaengah anih hnukah tlang hlaep longpuei ah aka cet pilnam te yet te kak a hmuh.
35 Jonadabu sì wí fún ọba pé, “Wò ó, àwọn ọmọ ọba ń bọ́; gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó rí.”
Te dongah Jonadab loh manghai taengah, “Manghai capa rhoek ha pawk uh coeng ke, na sal kah ol bangla om tangkhuet,” a ti nah.
36 Nígbà tí ó sì parí ọ̀rọ̀ tí ó ń sọ, sì wò ó àwọn ọmọ ọba dé, wọ́n sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún, ọba àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú sì sọkún ńlá ńlá.
A thui te a khah van neh manghai capa rhoek te pahoi ha pawk uh. Te vaengah a ol a huel uh tih rhap uh. Te dongah manghai neh a sal rhoek boeih khaw rhahnah neh a nah la hluk hluk rhap uh.
37 Absalomu sì sá, ó sì tọ Talmai lọ, ọmọ Ammihudu, ọba Geṣuri. Dafidi sì ń káàánú nítorí ọmọ rẹ̀ lójoojúmọ́.
Absalom te yong tih Geshuri manghai Ammihud capa Talmai taengla cet. Tedae a capa dongah hnin takuem nguekcoi.
38 Absalomu sì sá, ó sì lọ sí Geṣuri ó sì gbé ibẹ̀ lọ́dún mẹ́ta.
Absalom te yong tih Geshuri la aka cet te kum thum pahoi om.
39 Ọkàn Dafidi ọba sì fà gidigidi sí Absalomu, nítorí tí ó tí gba ìpẹ̀ ní ti Amnoni: ó sá à ti kú.
Tedae David manghai tah Amnon a duek dongah te hal tih Absalom taengla a caeh ham khaw a toeng.

< 2 Samuel 13 >