< 2 Samuel 12 >

1 Olúwa sì rán Natani sí Dafidi òun sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Ọkùnrin méjì ń bẹ ní ìlú kan; ọ̀kan jẹ́ ọlọ́rọ̀, èkejì sì jẹ́ tálákà.
Och Herren sände Nathan till David. När han kom till honom, sade han till honom: Det voro två män uti en stad; den ene rik, den andre fattig.
2 Ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà sì ní àgùntàn àti màlúù lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Den rike hade ganska mycken får och fä;
3 Ṣùgbọ́n ọkùnrin tálákà náà kò sì ní nǹkan bí kò ṣe àgùntàn kékeré kan èyí tí ó sì ń tọ́, ó sì dàgbà ní ọwọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀; a máa jẹ nínú oúnjẹ rẹ̀, a sí máa mu nínú ago rẹ̀, a sì máa dùbúlẹ̀ ní àyà rẹ̀, ó sì dàbí ọmọbìnrin kan fún un.
Men den fattige icke utan ett litet får, hans endesta, hvilket han köpt hade, och uppfödde det, att det uppväxte när honom, och bredovid hans barn. Det åt af hans beta, och drack af hans drickekar, och sof i hans famn, och han höll det såsom ena dotter.
4 “Àlejò kan sì tọ ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà wá, òun kò sì fẹ́ mú nínú àgùntàn rẹ̀, àti nínú màlúù rẹ̀, láti fi ṣe àlejò fún ẹni tí ó tọ̀ ọ́ wá, o sì mú àgùntàn ọkùnrin tálákà náà fi ṣe àlejò fún ọkùnrin tí ó tọ̀ ọ́ wá.”
Men då till den rika mannen kom en gäst, nändes han icke taga af sin får och fä, till att tillreda något åt den gästen, som till honom kommen var; och tog den fattiga mannens får, och redde det till för den mannen, som till honom kommen var.
5 Ìbínú Dafidi sì ru gidigidi sí ọkùnrin náà; ó sì wí fún Natani pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ọkùnrin náà tí ó ṣe nǹkan yìí, kíkú ni yóò kú.
Då förgrymmade sig David med stora vrede emot den mannen, och sade till Nathan: Så sant som Herren lefver, den mannen är dödsens barn, som detta gjort hafver.
6 Òun yóò sì san àgùntàn náà padà ní mẹ́rin mẹ́rin, nítorí tí ó ṣe nǹkan yìí àti nítorí tí kò ní àánú.”
Dertill skall han betala fåret fyradubbelt igen, efter han sådant gjort hafver, och icke hade det fördrag.
7 Natani sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ ni ọkùnrin náà. Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Èmi fi ọ́ jẹ ọba lórí Israẹli, èmi sì gbà ọ́ lọ́wọ́ Saulu.
Då sade Nathan till David: Du äst den mannen. Så säger Herren Israels Gud: Jag hafver smort dig till en Konung öfver Israel, och hafver frälst dig utu Sauls hand;
8 Èmi sì fi ilé olúwa rẹ fún ọ, àti àwọn obìnrin olúwa rẹ sí àyà rẹ, èmi sì fi ìdílé Israẹli àti ti Juda fún ọ; tí àwọn wọ̀nyí bá sì kéré jù fún ọ èmi ìbá sì fún ọ sí i jù bẹ́ẹ̀ lọ.
Och hafver gifvit dig dins herras hus; dertill hans hustrur i din famn, och hafver gifvit dig Israels hus och Juda; och är det icke nog, vill jag ännu det och det göra dig dertill.
9 Èéṣe tí ìwọ fi kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Olúwa, tí ìwọ fi ṣe nǹkan tí ó burú lójú rẹ̀, àní tí ìwọ fi fi idà pa Uriah ará Hiti, àti tí ìwọ fi mú obìnrin rẹ̀ láti fi ṣe obìnrin rẹ, o sì fi idà àwọn ọmọ Ammoni pa á.
Hvi hafver du då föraktat Herrans ord, att du sådant ondt för hans ögon göra skulle? Uria den Hetheen hafver du slagit med svärd; hans hustru hafver du tagit dig till hustru; men honom hafver du dräpit med Ammons barnas svärd.
10 Ǹjẹ́ nítorí náà idà kì yóò kúrò ní ilé rẹ títí láé; nítorí pé ìwọ gàn mí, ìwọ sì mú aya Uriah ará Hiti láti ṣe aya rẹ.’
Nu, så skall icke svärd återvända af ditt hus till evig tid; efter du hafver föraktat mig, och Uria den Hetheens hustru tagit, att hon skall vara din hustru.
11 “Báyìí ni Olúwa wí, kíyèsi i, ‘Èmi ó jẹ́ kí ibi kí ó dìde sí ọ láti inú ilé rẹ wá, èmi ó sì gba àwọn obìnrin rẹ lójú rẹ, èmi ó sì fi wọ́n fún aládùúgbò rẹ, òun ó sì bá àwọn obìnrin rẹ sùn níwájú òòrùn yìí.
Detta säger Herren: Si, jag skall uppväcka ondt öfver dig, utaf ditt eget hus, och skall taga dina hustrur för din ögon, och skall gifva dinom nästa, att han skall ligga när dina hustrur om ljusa dagen.
12 Àti pé ìwọ ṣe é ní ìkọ̀kọ̀, ṣùgbọ́n èmi ó ṣe nǹkan yìí níwájú gbogbo Israẹli, àti níwájú òòrùn.’”
Ty du hafver gjort det hemliga; men jag vill detta göra för hela Israel, på ljusa dagen.
13 Dafidi sì wí fún Natani pé, “Èmi ṣẹ̀ sí Olúwa!” Natani sì wí fún Dafidi pé, “Olúwa pẹ̀lú sì ti mú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kúrò; ìwọ kì yóò kú.
Då sade David till Nathan: Jag hafver syndat emot Herranom. Nathan sade till David: Så hafver ock Herren tagit din synd bort; du skall icke dö.
14 Ṣùgbọ́n nítorí nípa ìwà yìí, ìwọ fi ààyè sílẹ̀ fún àwọn ọ̀tá Olúwa láti sọ ọ̀rọ̀-òdì, ọmọ náà tí a ó bí fún ọ, kíkú ní yóò kú.”
Men efter du hafver med detta ärendet kommit Herrans fiendar till att förhäda, skall den sonen, som dig födder är, döden dö.
15 Natani sì lọ sí ilé rẹ̀ Olúwa sì fi ààrùn kọlu ọmọ náà tí obìnrin Uriah bí fún Dafidi, ó sì ṣe àìsàn púpọ̀.
Och Nathan gick hem i sitt hus. Men Herren slog barnet, som Uria hustru David födt hade, så att det vardt dödssjukt.
16 Dafidi sì bẹ Ọlọ́run nítorí ọmọ náà, Dafidi sì gbààwẹ̀, ó sì wọ inú ilé lọ, ó sì dùbúlẹ̀ lórí ilé ni òru náà.
Och David bad Gud om barnet, och fastade, och gick in, och låg öfver natt ena på jordene.
17 Àwọn àgbàgbà ilé rẹ̀ sì dìde tọ̀ ọ́ lọ, láti gbé e dìde lórí ilé, ó sì kọ̀, kò sì bá wọn jẹun.
Då stodo upp de äldste i hans hus, och ville rätta honom upp af jordene; men han ville icke, och åt icke heller med dem.
18 Ní ọjọ́ keje, ọmọ náà sì kú. Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì bẹ̀rù láti wí fún un pé, ọmọ náà kú: nítorí tí wọ́n wí pé, “Kíyèsi i, nígbà tí ọmọ náà ń bẹ láààyè, àwa sọ̀rọ̀ fún un, òun kọ̀ si gbọ́ ohùn wa! Ǹjẹ́ yóò ti ṣe ara rẹ̀ ní èṣe tó, bí àwa bá wí fún un pé, ọmọ náà kú.”
På sjunde dagenom blef barnet dödt; och Davids tjenare torde icke säga honom att barnet var dödt; ty de tänkte: Si, då barnet ännu var lefvandes, talade vi med honom, och han hörde vår röst intet; huru mycket mer skall det göra honom ondt, om vi säge: Barnet är dödt?
19 Nígbà tí Dafidi sì rí pé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, Dafidi sì kíyèsi i, pé ọmọ náà kú, Dafidi sì béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ọmọ náà kú bí?” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Ó kú.”
Och David fick se att hans tjenare talade i mjugg, och förmärkte att barnet var dödt, och sade till sina tjenare: Är barnet dödt? De sade: Ja.
20 Dafidi sì dìde ní ilẹ̀, ó sì wẹ̀, ó fi òróró pa ara, ó sì pààrọ̀ aṣọ rẹ̀, ó sì wọ inú ilé Olúwa lọ, ó sì wólẹ̀ sin, ó sì wá sí ilé rẹ̀ ó sì béèrè, wọ́n sì gbé oúnjẹ kalẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì jẹun.
Då stod David upp af jordene, och tvådde sig, och smorde sig, och lade annor kläder uppå, och gick in uti Herrans hus, och tillbad; och då han kom hem igen i sitt hus, lät han komma mat upp för sig, och åt.
21 Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì bí léèrè pé, “Kí ni èyí tí ìwọ ṣe yìí? Nítorí ọmọ náà nígbà tí ó ń bẹ láààyè ìwọ gbààwẹ̀, o sì sọkún; ṣùgbọ́n nígbà tí ọmọ náà kú, ó dìde ó sì jẹun.”
Då sade hans tjenare till honom: Hvad är det för ett ting, som du gör? Då barnet lefde, fastade du, och gret; men nu, sedan det dödt är, står du upp, och äter!
22 Ó sì wí pé, “Nígbà tí ọmọ náà ń bẹ láààyè, èmi gbààwẹ̀, èmi sì sọkún: nítorí tí èmi wí pé, ‘Ta ni ó mọ̀? Bí Olúwa ó ṣàánú mi, kí ọmọ náà le yè.’
Han sade: För barnets skull fastade jag, och gret, då det lefde; ty jag tänkte: Ho vet, om Herren varder mig nådelig, så att barnet må blifva vid lif.
23 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó ti kú, nítorí kín ni èmi ó ṣe máa gbààwẹ̀? Èmi ha tún lè mú un padà bí? Èmi ni yóò tọ̀ ọ́ lọ, òun kì yóò sì tún tọ̀ mí wá.”
Men nu, sedan det dödt är, hvad skulle jag fasta? Kan jag ock hemta honom igen? Jag går väl till honom, men han kommer intet till mig igen.
24 Dafidi sì ṣìpẹ̀ fún Batṣeba aya rẹ̀, ó sì wọlé tọ̀ ọ́, ó sì bá a dàpọ̀, òun sì bí ọmọkùnrin kan, Dafidi sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Solomoni, Olúwa sì fẹ́ ẹ.
Och då David hade hugsvalat sina hustru BathSeba, gick han in till henne, och sof när henne; och hon födde en son, den kallade han Salomo; och Herren älskade honom.
25 Ó sì rán Natani wòlíì, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jedidiah, nítorí Olúwa.
Och han fick honom under Nathans hand, Prophetens; han kallade honom JedidJa, för Herrans skull.
26 Joabu sì bá Rabba ti àwọn ọmọ Ammoni jagun, ó sì gba ìlú ọba wọn.
Så stridde nu Joab emot Rabba Ammons barnas, och vann den Konungsliga staden;
27 Joabu sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Dafidi, ó sì wí pé, “Èmi ti bá Rabba jà, èmi sì ti gba àwọn ìlú olómi.
Och sände båd till David, och lät säga honom: Jag hafver stridt emot Rabba, och hafver ock vunnit vattustaden.
28 Ǹjẹ́ nítorí náà kó àwọn ènìyàn ìyókù jọ, kí o sì dó ti ìlú náà, kí o sì gbà á, kí èmi má bá à gba ìlú náà kí a má ba à pè é ní orúkọ mi.”
Så tag nu tillhopa det folk, som qvart är, och belägg staden, och vinn honom; på det att jag icke vinner honom, och får der namnet af.
29 Dafidi sì kó gbogbo ènìyàn náà jọ, sí Rabba, ó sì bá a jà, ó sì gbà á.
Alltså tog David allt folket tillhopa, och drog åstad, och stridde emot Rabba, och vann honom;
30 Òun sì gba adé ọba wọn kúrò lórí rẹ̀, ìwúwo rẹ̀ sì jẹ́ tálẹ́ǹtì wúrà kan, ó sì ní òkúta oníyebíye lára rẹ̀; a sì fi dé Dafidi lórí. Òun sì kó ìkógun ìlú náà ni ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Och tog deras Konungs krono utaf hans hufvud, hvilken hade i vigt en centener guld, och ädla stenar; och den vardt satt David på hans hufvud; och förde ganska mycket rof utu staden.
31 Ó sì kó àwọn ènìyàn náà tí ó wà nínú rẹ̀, ó sì fi wọ́n sí iṣẹ́ ayùn, àti sí iṣẹ́ nǹkan ìtulẹ̀ tí a fi irin ṣe, àti sí iṣẹ́ àáké irin, ó sì fi wọ́n sí iṣẹ́ bíríkì ṣíṣe, bẹ́ẹ̀ náà ni òun sì ṣe sí gbogbo ìlú àwọn ọmọ Ammoni. Dafidi àti gbogbo àwọn ènìyàn náà sì padà sí Jerusalẹmu.
Och folket derinne förde han ut, och lade dem under jernsågar och taggar, och jernkilar, och brände dem upp uti tegelugnar; så gjorde han alla Ammons barnas städer. Så vände då David och allt folket om igen till Jerusalem.

< 2 Samuel 12 >