< 2 Samuel 12 >

1 Olúwa sì rán Natani sí Dafidi òun sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Ọkùnrin méjì ń bẹ ní ìlú kan; ọ̀kan jẹ́ ọlọ́rọ̀, èkejì sì jẹ́ tálákà.
Wtedy PAN posłał Natana do Dawida. Ten przybył do niego i powiedział: W pewnym mieście było dwóch ludzi, jeden bogaty, a drugi ubogi.
2 Ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà sì ní àgùntàn àti màlúù lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Bogaty miał bardzo dużo owiec i wołów.
3 Ṣùgbọ́n ọkùnrin tálákà náà kò sì ní nǹkan bí kò ṣe àgùntàn kékeré kan èyí tí ó sì ń tọ́, ó sì dàgbà ní ọwọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀; a máa jẹ nínú oúnjẹ rẹ̀, a sí máa mu nínú ago rẹ̀, a sì máa dùbúlẹ̀ ní àyà rẹ̀, ó sì dàbí ọmọbìnrin kan fún un.
A ubogi nie miał nic oprócz jednej małej owieczki, którą kupił i żywił. Wyrosła przy nim wraz z jego dziećmi, jadła jego chleb i piła z jego kubka, spała na jego łonie i była mu jak córka.
4 “Àlejò kan sì tọ ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà wá, òun kò sì fẹ́ mú nínú àgùntàn rẹ̀, àti nínú màlúù rẹ̀, láti fi ṣe àlejò fún ẹni tí ó tọ̀ ọ́ wá, o sì mú àgùntàn ọkùnrin tálákà náà fi ṣe àlejò fún ọkùnrin tí ó tọ̀ ọ́ wá.”
I przyszedł gość do tego bogatego, a jemu było żal wziąć ze swoich owiec albo ze swoich wołów, aby przyrządzić [ucztę] dla gościa, który do niego przyszedł. Wziął więc owieczkę tego ubogiego i przyrządził ją dla człowieka, który do niego przyszedł.
5 Ìbínú Dafidi sì ru gidigidi sí ọkùnrin náà; ó sì wí fún Natani pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ọkùnrin náà tí ó ṣe nǹkan yìí, kíkú ni yóò kú.
Wtedy Dawid mocno zapłonął gniewem na tego człowieka i powiedział do Natana: Jak żyje PAN, człowiek, który to uczynił, zasługuje na śmierć;
6 Òun yóò sì san àgùntàn náà padà ní mẹ́rin mẹ́rin, nítorí tí ó ṣe nǹkan yìí àti nítorí tí kò ní àánú.”
Za owcę wynagrodzi poczwórnie, dlatego że tak uczynił i nie miał litości.
7 Natani sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ ni ọkùnrin náà. Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Èmi fi ọ́ jẹ ọba lórí Israẹli, èmi sì gbà ọ́ lọ́wọ́ Saulu.
Wtedy Natan powiedział do Dawida: Ty jesteś tym człowiekiem. Tak mówi PAN, Bóg Izraela: Ja cię namaściłem, abyś był królem nad Izraelem, i ja cię wybawiłem z rąk Saula;
8 Èmi sì fi ilé olúwa rẹ fún ọ, àti àwọn obìnrin olúwa rẹ sí àyà rẹ, èmi sì fi ìdílé Israẹli àti ti Juda fún ọ; tí àwọn wọ̀nyí bá sì kéré jù fún ọ èmi ìbá sì fún ọ sí i jù bẹ́ẹ̀ lọ.
Dałem ci dom twego pana i żony twego pana na twe łono, dałem ci dom Izraela i Judy, a gdyby tego było za mało, dałbym ci jeszcze więcej.
9 Èéṣe tí ìwọ fi kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Olúwa, tí ìwọ fi ṣe nǹkan tí ó burú lójú rẹ̀, àní tí ìwọ fi fi idà pa Uriah ará Hiti, àti tí ìwọ fi mú obìnrin rẹ̀ láti fi ṣe obìnrin rẹ, o sì fi idà àwọn ọmọ Ammoni pa á.
Dlaczego wzgardziłeś słowem PANA, czyniąc to zło w jego oczach? Zabiłeś mieczem Uriasza Chetytę, a jego żonę wziąłeś sobie za żonę, jego zaś zabiłeś mieczem synów Ammona.
10 Ǹjẹ́ nítorí náà idà kì yóò kúrò ní ilé rẹ títí láé; nítorí pé ìwọ gàn mí, ìwọ sì mú aya Uriah ará Hiti láti ṣe aya rẹ.’
Teraz więc miecz nigdy nie odstąpi od twojego domu, ponieważ wzgardziłeś mną i wziąłeś żonę Uriasza Chetyty, by była twoją żoną.
11 “Báyìí ni Olúwa wí, kíyèsi i, ‘Èmi ó jẹ́ kí ibi kí ó dìde sí ọ láti inú ilé rẹ wá, èmi ó sì gba àwọn obìnrin rẹ lójú rẹ, èmi ó sì fi wọ́n fún aládùúgbò rẹ, òun ó sì bá àwọn obìnrin rẹ sùn níwájú òòrùn yìí.
Tak mówi PAN: Oto wzbudzę przeciwko tobie nieszczęście z twego własnego domu, wezmę twoje żony sprzed twoich oczu i dam je twemu bliźniemu, a on położy się z twoimi żonami wobec tego słońca.
12 Àti pé ìwọ ṣe é ní ìkọ̀kọ̀, ṣùgbọ́n èmi ó ṣe nǹkan yìí níwájú gbogbo Israẹli, àti níwájú òòrùn.’”
I chociaż ty uczyniłeś to potajemnie, ja jednak uczynię to przed całym Izraelem i przed słońcem.
13 Dafidi sì wí fún Natani pé, “Èmi ṣẹ̀ sí Olúwa!” Natani sì wí fún Dafidi pé, “Olúwa pẹ̀lú sì ti mú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kúrò; ìwọ kì yóò kú.
Wtedy Dawid powiedział do Natana: Zgrzeszyłem przeciw PANU. Natan zaś odpowiedział Dawidowi: PAN też przebaczył ci twój grzech, nie umrzesz.
14 Ṣùgbọ́n nítorí nípa ìwà yìí, ìwọ fi ààyè sílẹ̀ fún àwọn ọ̀tá Olúwa láti sọ ọ̀rọ̀-òdì, ọmọ náà tí a ó bí fún ọ, kíkú ní yóò kú.”
Ponieważ jednak przez ten czyn dałeś wrogom PANA powód, by bluźnili, syn, który ci się urodził, na pewno umrze.
15 Natani sì lọ sí ilé rẹ̀ Olúwa sì fi ààrùn kọlu ọmọ náà tí obìnrin Uriah bí fún Dafidi, ó sì ṣe àìsàn púpọ̀.
Potem Natan wrócił do swego domu. A PAN poraził dziecko, które żona Uriasza urodziła Dawidowi, i ciężko zachorowało.
16 Dafidi sì bẹ Ọlọ́run nítorí ọmọ náà, Dafidi sì gbààwẹ̀, ó sì wọ inú ilé lọ, ó sì dùbúlẹ̀ lórí ilé ni òru náà.
Wtedy Dawid wstawił się u Boga za dzieckiem. I Dawid pościł, a gdy wrócił [do siebie], leżał całą noc na ziemi.
17 Àwọn àgbàgbà ilé rẹ̀ sì dìde tọ̀ ọ́ lọ, láti gbé e dìde lórí ilé, ó sì kọ̀, kò sì bá wọn jẹun.
I starsi jego domu przyszli do niego, aby go podnieść z ziemi. On jednak nie chciał i nie jadł z nimi chleba.
18 Ní ọjọ́ keje, ọmọ náà sì kú. Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì bẹ̀rù láti wí fún un pé, ọmọ náà kú: nítorí tí wọ́n wí pé, “Kíyèsi i, nígbà tí ọmọ náà ń bẹ láààyè, àwa sọ̀rọ̀ fún un, òun kọ̀ si gbọ́ ohùn wa! Ǹjẹ́ yóò ti ṣe ara rẹ̀ ní èṣe tó, bí àwa bá wí fún un pé, ọmọ náà kú.”
A siódmego dnia dziecko umarło. I słudzy Dawida bali się powiedzieć mu, że dziecko umarło. Mówili bowiem: Oto póki dziecko [jeszcze] żyło, mówiliśmy do niego, a on nie słuchał naszego głosu. Jak powiemy, że dziecko umarło, dopiero będzie się trapił.
19 Nígbà tí Dafidi sì rí pé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, Dafidi sì kíyèsi i, pé ọmọ náà kú, Dafidi sì béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ọmọ náà kú bí?” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Ó kú.”
Gdy jednak Dawid zobaczył, że jego słudzy szepcą [między sobą], zrozumiał, że dziecko umarło. Dawid więc zapytał swoich sług: Czy dziecko umarło? Odpowiedzieli: Umarło.
20 Dafidi sì dìde ní ilẹ̀, ó sì wẹ̀, ó fi òróró pa ara, ó sì pààrọ̀ aṣọ rẹ̀, ó sì wọ inú ilé Olúwa lọ, ó sì wólẹ̀ sin, ó sì wá sí ilé rẹ̀ ó sì béèrè, wọ́n sì gbé oúnjẹ kalẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì jẹun.
Wtedy Dawid wstał z ziemi, umył się i namaścił, zmienił swoje szaty i wszedł do domu PANA, aby oddać [mu] pokłon. Potem wrócił do swego domu i kazał przynieść posiłek, i położyli przed nim chleb, i jadł.
21 Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì bí léèrè pé, “Kí ni èyí tí ìwọ ṣe yìí? Nítorí ọmọ náà nígbà tí ó ń bẹ láààyè ìwọ gbààwẹ̀, o sì sọkún; ṣùgbọ́n nígbà tí ọmọ náà kú, ó dìde ó sì jẹun.”
Jego słudzy zapytali go: Co znaczy to, co uczyniłeś? Póki dziecko jeszcze żyło, pościłeś i płakałeś, a gdy dziecko umarło, wstałeś i jadłeś chleb.
22 Ó sì wí pé, “Nígbà tí ọmọ náà ń bẹ láààyè, èmi gbààwẹ̀, èmi sì sọkún: nítorí tí èmi wí pé, ‘Ta ni ó mọ̀? Bí Olúwa ó ṣàánú mi, kí ọmọ náà le yè.’
Odpowiedział: Póki dziecko jeszcze żyło, pościłem i płakałem. Mówiłem bowiem: Któż wie, może PAN zmiłuje się nade mną i dziecko będzie żyło.
23 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó ti kú, nítorí kín ni èmi ó ṣe máa gbààwẹ̀? Èmi ha tún lè mú un padà bí? Èmi ni yóò tọ̀ ọ́ lọ, òun kì yóò sì tún tọ̀ mí wá.”
Lecz teraz, gdy już umarło, dlaczego miałbym pościć? Czy mogę je przywrócić [do życia]? Ja pójdę do niego, ale ono do mnie nie wróci.
24 Dafidi sì ṣìpẹ̀ fún Batṣeba aya rẹ̀, ó sì wọlé tọ̀ ọ́, ó sì bá a dàpọ̀, òun sì bí ọmọkùnrin kan, Dafidi sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Solomoni, Olúwa sì fẹ́ ẹ.
I Dawid pocieszał swoją żonę Batszebę. Wszedł do niej i położył się z nią. Potem urodziła syna, a on nadał mu imię Salomon. A PAN go umiłował.
25 Ó sì rán Natani wòlíì, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jedidiah, nítorí Olúwa.
Posłał więc przez Natana proroka i nadał mu imię Jedidija ze względu na PANA.
26 Joabu sì bá Rabba ti àwọn ọmọ Ammoni jagun, ó sì gba ìlú ọba wọn.
Potem Joab walczył przeciw Rabbie synów Ammona i zdobył miasto królewskie.
27 Joabu sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Dafidi, ó sì wí pé, “Èmi ti bá Rabba jà, èmi sì ti gba àwọn ìlú olómi.
I Joab wysłał posłańców do Dawida, i powiedział: Walczyłem przeciw Rabbie i zdobyłem miasto wód.
28 Ǹjẹ́ nítorí náà kó àwọn ènìyàn ìyókù jọ, kí o sì dó ti ìlú náà, kí o sì gbà á, kí èmi má bá à gba ìlú náà kí a má ba à pè é ní orúkọ mi.”
Teraz więc zbierz resztę ludu, oblegaj miasto i zdobądź je, abym to nie ja zdobył miasto i aby nie przypisano zwycięstwa memu imieniu.
29 Dafidi sì kó gbogbo ènìyàn náà jọ, sí Rabba, ó sì bá a jà, ó sì gbà á.
Dawid zebrał więc cały lud, udał się do Rabby, walczył przeciwko niej i zdobył ją.
30 Òun sì gba adé ọba wọn kúrò lórí rẹ̀, ìwúwo rẹ̀ sì jẹ́ tálẹ́ǹtì wúrà kan, ó sì ní òkúta oníyebíye lára rẹ̀; a sì fi dé Dafidi lórí. Òun sì kó ìkógun ìlú náà ni ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Zdjął też koronę z głowy jej króla, która ważyła talent złota i [była] ozdobiona drogocennymi kamieniami. I włożono ją na głowę Dawida. Wywiózł też z miasta bardzo wielki łup.
31 Ó sì kó àwọn ènìyàn náà tí ó wà nínú rẹ̀, ó sì fi wọ́n sí iṣẹ́ ayùn, àti sí iṣẹ́ nǹkan ìtulẹ̀ tí a fi irin ṣe, àti sí iṣẹ́ àáké irin, ó sì fi wọ́n sí iṣẹ́ bíríkì ṣíṣe, bẹ́ẹ̀ náà ni òun sì ṣe sí gbogbo ìlú àwọn ọmọ Ammoni. Dafidi àti gbogbo àwọn ènìyàn náà sì padà sí Jerusalẹmu.
Wyprowadził mieszkańców miasta i podał ich pod piły, żelazne brony i żelazne siekiery i zmusił ich do przejścia przez piec do wypalania cegieł. Tak uczynił ze wszystkimi miastami synów Ammona. Potem Dawid wrócił wraz z całym ludem do Jerozolimy.

< 2 Samuel 12 >