< 2 Samuel 12 >

1 Olúwa sì rán Natani sí Dafidi òun sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Ọkùnrin méjì ń bẹ ní ìlú kan; ọ̀kan jẹ́ ọlọ́rọ̀, èkejì sì jẹ́ tálákà.
And the Lord sent Nathan unto David, and he came unto him and said to him, Two men were once in one city, the one rich and the other poor.
2 Ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà sì ní àgùntàn àti màlúù lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
The rich man had flocks and herds, in great abundance.
3 Ṣùgbọ́n ọkùnrin tálákà náà kò sì ní nǹkan bí kò ṣe àgùntàn kékeré kan èyí tí ó sì ń tọ́, ó sì dàgbà ní ọwọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀; a máa jẹ nínú oúnjẹ rẹ̀, a sí máa mu nínú ago rẹ̀, a sì máa dùbúlẹ̀ ní àyà rẹ̀, ó sì dàbí ọmọbìnrin kan fún un.
But the poor man had nothing, save one little ewe, which he had bought; and he nourished it, and it grew up with him and with his children together; of his bread it used to eat, and out of his cup it used to drink, and in his bosom it used to lie, and it was to him as a daughter.
4 “Àlejò kan sì tọ ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà wá, òun kò sì fẹ́ mú nínú àgùntàn rẹ̀, àti nínú màlúù rẹ̀, láti fi ṣe àlejò fún ẹni tí ó tọ̀ ọ́ wá, o sì mú àgùntàn ọkùnrin tálákà náà fi ṣe àlejò fún ọkùnrin tí ó tọ̀ ọ́ wá.”
And there came a traveler unto the rich man; and he felt compunction to take from his own flocks and from his own herds to dress for the wayfarer that was come to him; but he took the ewe of the poor man, and dressed it for the man that was come to him.
5 Ìbínú Dafidi sì ru gidigidi sí ọkùnrin náà; ó sì wí fún Natani pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ọkùnrin náà tí ó ṣe nǹkan yìí, kíkú ni yóò kú.
And the anger of David was greatly kindled against the man; and he said to Nathan, As the Lord liveth, surely the man that hath done this deserveth to die;
6 Òun yóò sì san àgùntàn náà padà ní mẹ́rin mẹ́rin, nítorí tí ó ṣe nǹkan yìí àti nítorí tí kò ní àánú.”
And the ewe he shall pay fourfold, for punishment that he hath done this thing, and because he had no compassion.
7 Natani sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ ni ọkùnrin náà. Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Èmi fi ọ́ jẹ ọba lórí Israẹli, èmi sì gbà ọ́ lọ́wọ́ Saulu.
Then said Nathan to David, Thou art the man! Thus hath said the Lord, the God of Israel, It is I who anointed thee as king over Israel, and it is I who delivered thee out of the hand of Saul;
8 Èmi sì fi ilé olúwa rẹ fún ọ, àti àwọn obìnrin olúwa rẹ sí àyà rẹ, èmi sì fi ìdílé Israẹli àti ti Juda fún ọ; tí àwọn wọ̀nyí bá sì kéré jù fún ọ èmi ìbá sì fún ọ sí i jù bẹ́ẹ̀ lọ.
And I gave unto thee the house of thy master, and [put] the wives of thy master into thy bosom, and gave unto thee the house of Israel and Judah: and if this be too little, I could bestow on thee yet many more like these things.
9 Èéṣe tí ìwọ fi kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Olúwa, tí ìwọ fi ṣe nǹkan tí ó burú lójú rẹ̀, àní tí ìwọ fi fi idà pa Uriah ará Hiti, àti tí ìwọ fi mú obìnrin rẹ̀ láti fi ṣe obìnrin rẹ, o sì fi idà àwọn ọmọ Ammoni pa á.
Wherefore hast thou despised the word of the Lord to do what is evil in his eyes? Uriyah the Hittite hast thou smitten with the sword, and his wife hast thou taken unto thee for wife; but him hast thou slain with the sword of the children of 'Ammon.
10 Ǹjẹ́ nítorí náà idà kì yóò kúrò ní ilé rẹ títí láé; nítorí pé ìwọ gàn mí, ìwọ sì mú aya Uriah ará Hiti láti ṣe aya rẹ.’
And now, the sword shall not depart from thy house for ever; for the reason that thou hast despised me, and hast taken the wife of Uriyah the Hittite to be thy wife.
11 “Báyìí ni Olúwa wí, kíyèsi i, ‘Èmi ó jẹ́ kí ibi kí ó dìde sí ọ láti inú ilé rẹ wá, èmi ó sì gba àwọn obìnrin rẹ lójú rẹ, èmi ó sì fi wọ́n fún aládùúgbò rẹ, òun ó sì bá àwọn obìnrin rẹ sùn níwájú òòrùn yìí.
Thus hath said the Lord, Behold, I will raise up against thee evil out of thy own house, and I will take away thy wives before thy eyes, and I will give them unto thy neighbor; and he shall lie with thy wives before the face of this sun.
12 Àti pé ìwọ ṣe é ní ìkọ̀kọ̀, ṣùgbọ́n èmi ó ṣe nǹkan yìí níwájú gbogbo Israẹli, àti níwájú òòrùn.’”
For thou hast done it in secret; but I will surely do this thing before all Israel, and before the sun.
13 Dafidi sì wí fún Natani pé, “Èmi ṣẹ̀ sí Olúwa!” Natani sì wí fún Dafidi pé, “Olúwa pẹ̀lú sì ti mú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kúrò; ìwọ kì yóò kú.
Then said David unto Nathan, I have sinned against the Lord. And Nathan said to David, Also the Lord hath caused thy sin to pass away: thou shalt not die.
14 Ṣùgbọ́n nítorí nípa ìwà yìí, ìwọ fi ààyè sílẹ̀ fún àwọn ọ̀tá Olúwa láti sọ ọ̀rọ̀-òdì, ọmọ náà tí a ó bí fún ọ, kíkú ní yóò kú.”
Nevertheless, because thou hast given great cause to the enemies of the Lord to blaspheme through this thing, the child also that hath been born unto thee shall surely die.
15 Natani sì lọ sí ilé rẹ̀ Olúwa sì fi ààrùn kọlu ọmọ náà tí obìnrin Uriah bí fún Dafidi, ó sì ṣe àìsàn púpọ̀.
And Nathan went to his house; and the Lord struck the child that Uriyah's wife had born unto David, that it became very sick.
16 Dafidi sì bẹ Ọlọ́run nítorí ọmọ náà, Dafidi sì gbààwẹ̀, ó sì wọ inú ilé lọ, ó sì dùbúlẹ̀ lórí ilé ni òru náà.
And David besought God in behalf of the lad; and David kept a fast, and came home, and lay over night upon the earth.
17 Àwọn àgbàgbà ilé rẹ̀ sì dìde tọ̀ ọ́ lọ, láti gbé e dìde lórí ilé, ó sì kọ̀, kò sì bá wọn jẹun.
And the elders of the house arose about him, to raise him up from the earth; but he would not, and he did not partake of any bread with them.
18 Ní ọjọ́ keje, ọmọ náà sì kú. Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì bẹ̀rù láti wí fún un pé, ọmọ náà kú: nítorí tí wọ́n wí pé, “Kíyèsi i, nígbà tí ọmọ náà ń bẹ láààyè, àwa sọ̀rọ̀ fún un, òun kọ̀ si gbọ́ ohùn wa! Ǹjẹ́ yóò ti ṣe ara rẹ̀ ní èṣe tó, bí àwa bá wí fún un pé, ọmọ náà kú.”
And it came to pass on the seventh day that the child died; and the servants of David were afraid to tell him, that the child was dead; for they said, Behold, while the child was yet alive, we spoke to him, and he would not hearken to our voice: how then shall we say to him, The child is dead! he might do [himself] a hurt.
19 Nígbà tí Dafidi sì rí pé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, Dafidi sì kíyèsi i, pé ọmọ náà kú, Dafidi sì béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ọmọ náà kú bí?” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Ó kú.”
But when David saw that his servants were whispering to each other, David understood that the child was dead; wherefore David said unto his servants, Is the child dead? and they said, he is dead.
20 Dafidi sì dìde ní ilẹ̀, ó sì wẹ̀, ó fi òróró pa ara, ó sì pààrọ̀ aṣọ rẹ̀, ó sì wọ inú ilé Olúwa lọ, ó sì wólẹ̀ sin, ó sì wá sí ilé rẹ̀ ó sì béèrè, wọ́n sì gbé oúnjẹ kalẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì jẹun.
David then rose up from the earth, and washed and anointed himself, and changed his garments, and went into the house of the Lord and prostrated himself; and then he came to his own house, and asked that they should set food before him, and he ate.
21 Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì bí léèrè pé, “Kí ni èyí tí ìwọ ṣe yìí? Nítorí ọmọ náà nígbà tí ó ń bẹ láààyè ìwọ gbààwẹ̀, o sì sọkún; ṣùgbọ́n nígbà tí ọmọ náà kú, ó dìde ó sì jẹun.”
And his servants then said unto him, What is this thing which thou hast done? On account of the child when living thou didst fast and weep; but as soon as the child was dead thou didst arise and eat bread!
22 Ó sì wí pé, “Nígbà tí ọmọ náà ń bẹ láààyè, èmi gbààwẹ̀, èmi sì sọkún: nítorí tí èmi wí pé, ‘Ta ni ó mọ̀? Bí Olúwa ó ṣàánú mi, kí ọmọ náà le yè.’
And he said, While the child was yet alive, I fasted and wept; because I said, Who knoweth, but that the Lord will be gracious to me, that the child may live?
23 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó ti kú, nítorí kín ni èmi ó ṣe máa gbààwẹ̀? Èmi ha tún lè mú un padà bí? Èmi ni yóò tọ̀ ọ́ lọ, òun kì yóò sì tún tọ̀ mí wá.”
But now he is dead, wherefore should I fast then? can I restore him again? I am going to him; but he will not return to me.
24 Dafidi sì ṣìpẹ̀ fún Batṣeba aya rẹ̀, ó sì wọlé tọ̀ ọ́, ó sì bá a dàpọ̀, òun sì bí ọmọkùnrin kan, Dafidi sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Solomoni, Olúwa sì fẹ́ ẹ.
And David comforted Bath-sheba' his wife, and he went in unto her, and lay with her; and she bore a son, and called his name Solomon; and the Lord loved him.
25 Ó sì rán Natani wòlíì, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jedidiah, nítorí Olúwa.
And he sent by the hand of Nathan the prophet, and called his name, Yedideyah in behalf of the Lord.
26 Joabu sì bá Rabba ti àwọn ọmọ Ammoni jagun, ó sì gba ìlú ọba wọn.
And Joab fought against Rabbah of the children of 'Ammon, and captured the royal city.
27 Joabu sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Dafidi, ó sì wí pé, “Èmi ti bá Rabba jà, èmi sì ti gba àwọn ìlú olómi.
And Joab sent messengers to David; and said, I have fought against Rabbah, and have also captured the water-town.
28 Ǹjẹ́ nítorí náà kó àwọn ènìyàn ìyókù jọ, kí o sì dó ti ìlú náà, kí o sì gbà á, kí èmi má bá à gba ìlú náà kí a má ba à pè é ní orúkọ mi.”
And now gather the rest of the people together, and encamp against the city, and capture it: lest I capture the city myself, and it be called by my name.
29 Dafidi sì kó gbogbo ènìyàn náà jọ, sí Rabba, ó sì bá a jà, ó sì gbà á.
And David gathered all the people together and went to Rabbah, and fought against it, and captured it.
30 Òun sì gba adé ọba wọn kúrò lórí rẹ̀, ìwúwo rẹ̀ sì jẹ́ tálẹ́ǹtì wúrà kan, ó sì ní òkúta oníyebíye lára rẹ̀; a sì fi dé Dafidi lórí. Òun sì kó ìkógun ìlú náà ni ọ̀pọ̀lọpọ̀.
And he took the crown of Malkam from off his head, and its weight was a talent of gold, and [on it was] a precious stone, and it was set on the head of David; and the booty of the city he brought out in great abundance.
31 Ó sì kó àwọn ènìyàn náà tí ó wà nínú rẹ̀, ó sì fi wọ́n sí iṣẹ́ ayùn, àti sí iṣẹ́ nǹkan ìtulẹ̀ tí a fi irin ṣe, àti sí iṣẹ́ àáké irin, ó sì fi wọ́n sí iṣẹ́ bíríkì ṣíṣe, bẹ́ẹ̀ náà ni òun sì ṣe sí gbogbo ìlú àwọn ọmọ Ammoni. Dafidi àti gbogbo àwọn ènìyàn náà sì padà sí Jerusalẹmu.
And the people that were therein he brought forward, and put them under saws, and under iron threshing-wagons, and under axes of iron, and made them pass through brick-kilns; and thus did he unto all the cities of the children of 'Ammon: and David returned with them with all the people unto Jerusalem.

< 2 Samuel 12 >