< 2 Samuel 12 >
1 Olúwa sì rán Natani sí Dafidi òun sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Ọkùnrin méjì ń bẹ ní ìlú kan; ọ̀kan jẹ́ ọlọ́rọ̀, èkejì sì jẹ́ tálákà.
Og HERREN sendte Natan til David. Da han kom ind til ham, sagde han: »Der boede to Mænd i samme By, en rig og en fattig.
2 Ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà sì ní àgùntàn àti màlúù lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Den rige havde Smaakvæg og Hornkvæg i Mængde,
3 Ṣùgbọ́n ọkùnrin tálákà náà kò sì ní nǹkan bí kò ṣe àgùntàn kékeré kan èyí tí ó sì ń tọ́, ó sì dàgbà ní ọwọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀; a máa jẹ nínú oúnjẹ rẹ̀, a sí máa mu nínú ago rẹ̀, a sì máa dùbúlẹ̀ ní àyà rẹ̀, ó sì dàbí ọmọbìnrin kan fún un.
medens den fattige ikke ejede andet end et eneste lille Lam, som han havde købt og opdrættet, og som var vokset op hos ham sammen med hans Børn; det aad af hans Brød, drak af hans Bæger og laa i hans Skød og var ham som en Datter.
4 “Àlejò kan sì tọ ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà wá, òun kò sì fẹ́ mú nínú àgùntàn rẹ̀, àti nínú màlúù rẹ̀, láti fi ṣe àlejò fún ẹni tí ó tọ̀ ọ́ wá, o sì mú àgùntàn ọkùnrin tálákà náà fi ṣe àlejò fún ọkùnrin tí ó tọ̀ ọ́ wá.”
Men da den rige Mand engang fik Besøg, ømmede han sig ved at tage noget af sit eget Smaakvæg eller Hornkvæg og tillave det til den vejfarende Mand, som var kommet til ham, men tog den fattige Mands Lam og tillavede det til sin Gæst!«
5 Ìbínú Dafidi sì ru gidigidi sí ọkùnrin náà; ó sì wí fún Natani pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ọkùnrin náà tí ó ṣe nǹkan yìí, kíkú ni yóò kú.
Da blussede Davids Vrede heftigt op mod den Mand, og han sagde til Natan: »Saa sandt HERREN lever: Den Mand, som gjorde det, er dødsens,
6 Òun yóò sì san àgùntàn náà padà ní mẹ́rin mẹ́rin, nítorí tí ó ṣe nǹkan yìí àti nítorí tí kò ní àánú.”
og Lammet skal han erstatte firefold, fordi han handlede saa hjerteløst!«
7 Natani sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ ni ọkùnrin náà. Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Èmi fi ọ́ jẹ ọba lórí Israẹli, èmi sì gbà ọ́ lọ́wọ́ Saulu.
Men Natan sagde til David: »Du er Manden! Saa siger HERREN, Israels Gud: Jeg salvede dig til Konge over Israel, og jeg friede dig af Sauls Haand;
8 Èmi sì fi ilé olúwa rẹ fún ọ, àti àwọn obìnrin olúwa rẹ sí àyà rẹ, èmi sì fi ìdílé Israẹli àti ti Juda fún ọ; tí àwọn wọ̀nyí bá sì kéré jù fún ọ èmi ìbá sì fún ọ sí i jù bẹ́ẹ̀ lọ.
jeg gav dig din Herres Hus, lagde din Herres Hustruer i din Favn og gav dig Israels og Judas Hus; og var det for lidet, vilde jeg have givet dig endnu mere, baade det ene og det andet.
9 Èéṣe tí ìwọ fi kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Olúwa, tí ìwọ fi ṣe nǹkan tí ó burú lójú rẹ̀, àní tí ìwọ fi fi idà pa Uriah ará Hiti, àti tí ìwọ fi mú obìnrin rẹ̀ láti fi ṣe obìnrin rẹ, o sì fi idà àwọn ọmọ Ammoni pa á.
Hvorfor har du da ringeagtet HERRENS Ord og gjort, hvad der er ondt i hans Øjne? Hetiten Urias har du dræbt med Sværdet; hans Hustru har du taget til Ægte, og ham har du slaaet ihjel med Ammoniternes Sværd.
10 Ǹjẹ́ nítorí náà idà kì yóò kúrò ní ilé rẹ títí láé; nítorí pé ìwọ gàn mí, ìwọ sì mú aya Uriah ará Hiti láti ṣe aya rẹ.’
Saa skal nu Sværdet aldrig vige fra dit Hus, fordi du ringeagtede mig og tog Hetiten Urias's Hustru til Ægte.
11 “Báyìí ni Olúwa wí, kíyèsi i, ‘Èmi ó jẹ́ kí ibi kí ó dìde sí ọ láti inú ilé rẹ wá, èmi ó sì gba àwọn obìnrin rẹ lójú rẹ, èmi ó sì fi wọ́n fún aládùúgbò rẹ, òun ó sì bá àwọn obìnrin rẹ sùn níwájú òòrùn yìí.
Saa siger HERREN: Se, jeg lader Ulykke komme over dig fra dit eget Hus, og jeg tager dine Hustruer bort for Øjnene af dig og giver dem til en anden, som skal ligge hos dine Hustruer ved højlys Dag.
12 Àti pé ìwọ ṣe é ní ìkọ̀kọ̀, ṣùgbọ́n èmi ó ṣe nǹkan yìí níwájú gbogbo Israẹli, àti níwájú òòrùn.’”
Thi du handlede i det skjulte, men jeg vil opfylde dette Ord i hele Israels Paasyn og ved højlys Dag!«
13 Dafidi sì wí fún Natani pé, “Èmi ṣẹ̀ sí Olúwa!” Natani sì wí fún Dafidi pé, “Olúwa pẹ̀lú sì ti mú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kúrò; ìwọ kì yóò kú.
Da sagde David til Natan: »Jeg har syndet mod HERREN!« Og Natan sagde til David: »Saa har HERREN ogsaa tilgivet dig din Synd; du skal ikke dø.
14 Ṣùgbọ́n nítorí nípa ìwà yìí, ìwọ fi ààyè sílẹ̀ fún àwọn ọ̀tá Olúwa láti sọ ọ̀rọ̀-òdì, ọmọ náà tí a ó bí fún ọ, kíkú ní yóò kú.”
Men fordi du ved denne Gerning har vist Foragt for HERREN, skal Sønnen, som er født dig, visselig dø!«
15 Natani sì lọ sí ilé rẹ̀ Olúwa sì fi ààrùn kọlu ọmọ náà tí obìnrin Uriah bí fún Dafidi, ó sì ṣe àìsàn púpọ̀.
Derpaa gik Natan til sit Hus. Og HERREN ramte det Barn, Urias's Hustru havde født David, med Sygdom.
16 Dafidi sì bẹ Ọlọ́run nítorí ọmọ náà, Dafidi sì gbààwẹ̀, ó sì wọ inú ilé lọ, ó sì dùbúlẹ̀ lórí ilé ni òru náà.
Da søgte David Gud for Barnet, holdt Faste og gik hen og lagde sig om Natten paa Jorden i Sæk.
17 Àwọn àgbàgbà ilé rẹ̀ sì dìde tọ̀ ọ́ lọ, láti gbé e dìde lórí ilé, ó sì kọ̀, kò sì bá wọn jẹun.
De ældste i hans Hus kom til ham for at faa ham til at rejse sig, men han vilde ikke, og han holdt ikke Maaltid sammen med dem.
18 Ní ọjọ́ keje, ọmọ náà sì kú. Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì bẹ̀rù láti wí fún un pé, ọmọ náà kú: nítorí tí wọ́n wí pé, “Kíyèsi i, nígbà tí ọmọ náà ń bẹ láààyè, àwa sọ̀rọ̀ fún un, òun kọ̀ si gbọ́ ohùn wa! Ǹjẹ́ yóò ti ṣe ara rẹ̀ ní èṣe tó, bí àwa bá wí fún un pé, ọmọ náà kú.”
Syvendedagen døde Barnet; men Davids Folk turde ikke lade ham vide, at Barnet var død, thi de tænkte: »Da Barnet levede, vilde han ikke laane os Øre, naar vi talte til ham; hvor kan vi da nu sige til ham, at Barnet er død? Han kunde gøre en Ulykke!«
19 Nígbà tí Dafidi sì rí pé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, Dafidi sì kíyèsi i, pé ọmọ náà kú, Dafidi sì béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ọmọ náà kú bí?” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Ó kú.”
Men da David saa, at hans Folk hviskede sammen, skønnede han, at Barnet var død. Saa spurgte David sine Folk: »Er Barnet død?« Og de svarede: »Ja, han er død!«
20 Dafidi sì dìde ní ilẹ̀, ó sì wẹ̀, ó fi òróró pa ara, ó sì pààrọ̀ aṣọ rẹ̀, ó sì wọ inú ilé Olúwa lọ, ó sì wólẹ̀ sin, ó sì wá sí ilé rẹ̀ ó sì béèrè, wọ́n sì gbé oúnjẹ kalẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì jẹun.
Da rejste David sig fra Jorden, tvættede og salvede sig, tog andre Klæder paa og gik ind i HERRENS Hus og bad; saa gik han hjem, forlangte at faa Mad sat frem og spiste.
21 Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì bí léèrè pé, “Kí ni èyí tí ìwọ ṣe yìí? Nítorí ọmọ náà nígbà tí ó ń bẹ láààyè ìwọ gbààwẹ̀, o sì sọkún; ṣùgbọ́n nígbà tí ọmọ náà kú, ó dìde ó sì jẹun.”
Da sagde hans Folk til ham: »Hvorledes er det dog, du bærer dig ad? Medens Barnet endnu levede, fastede du og græd; og nu da Barnet er død, rejser du dig og spiser!«
22 Ó sì wí pé, “Nígbà tí ọmọ náà ń bẹ láààyè, èmi gbààwẹ̀, èmi sì sọkún: nítorí tí èmi wí pé, ‘Ta ni ó mọ̀? Bí Olúwa ó ṣàánú mi, kí ọmọ náà le yè.’
Han svarede: »Saa længe Barnet levede, fastede jeg og græd; thi jeg tænkte: Maaske er HERREN mig naadig, saa Barnet bliver i Live.
23 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó ti kú, nítorí kín ni èmi ó ṣe máa gbààwẹ̀? Èmi ha tún lè mú un padà bí? Èmi ni yóò tọ̀ ọ́ lọ, òun kì yóò sì tún tọ̀ mí wá.”
Men hvorfor skulde jeg faste, nu han er død? Kan jeg bringe ham tilbage igen? Jeg gaar til ham, men han kommer ikke tilbage til mig!«
24 Dafidi sì ṣìpẹ̀ fún Batṣeba aya rẹ̀, ó sì wọlé tọ̀ ọ́, ó sì bá a dàpọ̀, òun sì bí ọmọkùnrin kan, Dafidi sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Solomoni, Olúwa sì fẹ́ ẹ.
Derpaa trøstede David sin Hustru Batseba, og efter at han var gaaet ind til hende og havde ligget hos hende, fødte hun en Søn, som han kaldte Salomo, og ham elskede HERREN.
25 Ó sì rán Natani wòlíì, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jedidiah, nítorí Olúwa.
Han overgav ham til Profeten Natan, og paa HERRENS Ord kaldte denne ham Jedidja.
26 Joabu sì bá Rabba ti àwọn ọmọ Ammoni jagun, ó sì gba ìlú ọba wọn.
Joab angreb imidlertid Rabba i Ammon og indtog Vandbyen.
27 Joabu sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Dafidi, ó sì wí pé, “Èmi ti bá Rabba jà, èmi sì ti gba àwọn ìlú olómi.
Derpaa sendte Joab Bud til David og lod sige: »Jeg har angrebet Rabba og indtaget Vandbyen;
28 Ǹjẹ́ nítorí náà kó àwọn ènìyàn ìyókù jọ, kí o sì dó ti ìlú náà, kí o sì gbà á, kí èmi má bá à gba ìlú náà kí a má ba à pè é ní orúkọ mi.”
kald nu Resten af Hæren sammen, saa du kan belejre Byen og indtage den, for at det ikke skal blive mig, der indtager den og faar mit Navn udraabt over den!«
29 Dafidi sì kó gbogbo ènìyàn náà jọ, sí Rabba, ó sì bá a jà, ó sì gbà á.
Da samlede David hele Hæren og drog til Rabba, angreb og indtog det.
30 Òun sì gba adé ọba wọn kúrò lórí rẹ̀, ìwúwo rẹ̀ sì jẹ́ tálẹ́ǹtì wúrà kan, ó sì ní òkúta oníyebíye lára rẹ̀; a sì fi dé Dafidi lórí. Òun sì kó ìkógun ìlú náà ni ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Og han tog Kronen af Milkoms Hoved; den var af Guld og vejede en Talent; der var en Ædelsten paa den, og den blev sat paa Davids Hoved. Et vældigt Bytte fra Byen førte han med sig,
31 Ó sì kó àwọn ènìyàn náà tí ó wà nínú rẹ̀, ó sì fi wọ́n sí iṣẹ́ ayùn, àti sí iṣẹ́ nǹkan ìtulẹ̀ tí a fi irin ṣe, àti sí iṣẹ́ àáké irin, ó sì fi wọ́n sí iṣẹ́ bíríkì ṣíṣe, bẹ́ẹ̀ náà ni òun sì ṣe sí gbogbo ìlú àwọn ọmọ Ammoni. Dafidi àti gbogbo àwọn ènìyàn náà sì padà sí Jerusalẹmu.
og Indbyggerne slæbte han bort, satte dem til Savene, Jernhakkerne og Jernøkserne og lod dem trælle ved Teglovnene. Saaledes gjorde han ved alle Ammoniternes Byer. Derpaa vendte David og hele Hæren tilbage til Jerusalem.