< 2 Samuel 12 >

1 Olúwa sì rán Natani sí Dafidi òun sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Ọkùnrin méjì ń bẹ ní ìlú kan; ọ̀kan jẹ́ ọlọ́rọ̀, èkejì sì jẹ́ tálákà.
BOEIPA loh Nathan te David taengla a tueih tih a taeng a pha vaengah David te, “Kho pakhat ah hlang panit om tih, pakhat tah hlanglen, pakhat tah vawtthoek la om.
2 Ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà sì ní àgùntàn àti màlúù lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Hlanglen tah boiva khaw, saelhung khaw, a yet la muep a khueh.
3 Ṣùgbọ́n ọkùnrin tálákà náà kò sì ní nǹkan bí kò ṣe àgùntàn kékeré kan èyí tí ó sì ń tọ́, ó sì dàgbà ní ọwọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀; a máa jẹ nínú oúnjẹ rẹ̀, a sí máa mu nínú ago rẹ̀, a sì máa dùbúlẹ̀ ní àyà rẹ̀, ó sì dàbí ọmọbìnrin kan fún un.
Tedae khodaeng taengah tah a lai duen ca tumanu pakhat phoeiah a tloe om pawh. Te te a hing sak tih amah taengah a ca rhoek taengah rhoeng hang, a buhkam te a cah tih a boengloeng te a tul. A rhang dongah ip tih canu bangla a taengah a khueh.
4 “Àlejò kan sì tọ ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà wá, òun kò sì fẹ́ mú nínú àgùntàn rẹ̀, àti nínú màlúù rẹ̀, láti fi ṣe àlejò fún ẹni tí ó tọ̀ ọ́ wá, o sì mú àgùntàn ọkùnrin tálákà náà fi ṣe àlejò fún ọkùnrin tí ó tọ̀ ọ́ wá.”
Hlanglen pakhat tah tekah hlang taengah yinthing la a pawk pah. Tedae anih taengla aka thoeng yiin kok nah ham amah kah boiva neh a saelhung tah loh hamla a hnaih. Te dongah khodaeng ca kah tumanu te a loh pah tih anih taengla aka thoeng hlang ham te a ngawn pah,” a ti nah.
5 Ìbínú Dafidi sì ru gidigidi sí ọkùnrin náà; ó sì wí fún Natani pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ọkùnrin náà tí ó ṣe nǹkan yìí, kíkú ni yóò kú.
Te vaengah David kah a thintoek tah tekah hlang taengah sai khungdaeng. Te dongah Nathan te, “BOEIPA kah hingnah dongah te tla aka saii hlang tah duek ca kangna saeh.
6 Òun yóò sì san àgùntàn náà padà ní mẹ́rin mẹ́rin, nítorí tí ó ṣe nǹkan yìí àti nítorí tí kò ní àánú.”
A thinphat pawt tih hekah hno he a saii dongah tumanu te rhaepli la thuung saeh,” a ti nah.
7 Natani sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ ni ọkùnrin náà. Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Èmi fi ọ́ jẹ ọba lórí Israẹli, èmi sì gbà ọ́ lọ́wọ́ Saulu.
Te vaengah Nathan loh David te, “Tekah hlang tah namah ni. Israel Pathen BOEIPA loh, 'Kai loh Israel manghai la nang kang koelh tih Saul kut lamkah khaw kai long ni nang kan huul.
8 Èmi sì fi ilé olúwa rẹ fún ọ, àti àwọn obìnrin olúwa rẹ sí àyà rẹ, èmi sì fi ìdílé Israẹli àti ti Juda fún ọ; tí àwọn wọ̀nyí bá sì kéré jù fún ọ èmi ìbá sì fún ọ sí i jù bẹ́ẹ̀ lọ.
Na boeipa kah im te namah taengah, na boei rhoek kah a yuu rhoek khaw na rhang dongah kan tloeng coeng. Israel neh Judah imlo khaw nang taengah kam paek coeng. A yol bal atah he khaw ke khaw nang ham man kan thap ve.
9 Èéṣe tí ìwọ fi kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Olúwa, tí ìwọ fi ṣe nǹkan tí ó burú lójú rẹ̀, àní tí ìwọ fi fi idà pa Uriah ará Hiti, àti tí ìwọ fi mú obìnrin rẹ̀ láti fi ṣe obìnrin rẹ, o sì fi idà àwọn ọmọ Ammoni pa á.
Balae tih a mikhmuh ah boethae saii ham BOEIPA ol te na sawtsit. Ka mikhmuh ah Khitti Uriah te cunghang neh na ngawn. A yuu te namah yuu la na rhawt pah phoeiah amah te Ammon koca rhoek kah cunghang neh na ngawn.
10 Ǹjẹ́ nítorí náà idà kì yóò kúrò ní ilé rẹ títí láé; nítorí pé ìwọ gàn mí, ìwọ sì mú aya Uriah ará Hiti láti ṣe aya rẹ.’
Kai nan hnaep tih Khitti Uriah yuu te na rhawt pah phoeiah namah yuu la na khueh. Te dongah kumhal duela na imkhui lamkah cunghang Te nong voel mahpawh.
11 “Báyìí ni Olúwa wí, kíyèsi i, ‘Èmi ó jẹ́ kí ibi kí ó dìde sí ọ láti inú ilé rẹ wá, èmi ó sì gba àwọn obìnrin rẹ lójú rẹ, èmi ó sì fi wọ́n fún aládùúgbò rẹ, òun ó sì bá àwọn obìnrin rẹ sùn níwájú òòrùn yìí.
BOEIPA loh he ni a. thui, na imkhui lamloh nang soah yoethaenah ka pai sak ni. Na yuu rhoek te na mikhmuh ah ka loh vetih na hui taengla ka paek ni. Na yuu rhoek te khothaih sale ah a ih puei ni.
12 Àti pé ìwọ ṣe é ní ìkọ̀kọ̀, ṣùgbọ́n èmi ó ṣe nǹkan yìí níwájú gbogbo Israẹli, àti níwájú òòrùn.’”
Yinhnuk ah na saii dae olka te kai loh Israel tom neh khomik hmaiah kam phoe ni, ' a ti,” a ti nah.
13 Dafidi sì wí fún Natani pé, “Èmi ṣẹ̀ sí Olúwa!” Natani sì wí fún Dafidi pé, “Olúwa pẹ̀lú sì ti mú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kúrò; ìwọ kì yóò kú.
Te daengah David loh Nathan taengah, “BOEIPA taengah ka tholh coeng,” a ti nah. Nathan loh David te, “BOEIPA loh na tholh a khoe coeng tih na duek mahpawh.
14 Ṣùgbọ́n nítorí nípa ìwà yìí, ìwọ fi ààyè sílẹ̀ fún àwọn ọ̀tá Olúwa láti sọ ọ̀rọ̀-òdì, ọmọ náà tí a ó bí fún ọ, kíkú ní yóò kú.”
Tedae te bang khoboe neh BOEIPA kah thunkha rhoek te yah na bai la na bai sak dongah nang ham camoe aka thaang Te duek rhoe duek ni,” a ti nah.
15 Natani sì lọ sí ilé rẹ̀ Olúwa sì fi ààrùn kọlu ọmọ náà tí obìnrin Uriah bí fún Dafidi, ó sì ṣe àìsàn púpọ̀.
Nathan loh amah im la a caeh nen tah Uriah yuu loh David ham a cun pah camoe te BOEIPA loh a vuek tih a rhawp pah.
16 Dafidi sì bẹ Ọlọ́run nítorí ọmọ náà, Dafidi sì gbààwẹ̀, ó sì wọ inú ilé lọ, ó sì dùbúlẹ̀ lórí ilé ni òru náà.
Te dongah David loh camoe hamla Pathen te a toem. Yaehnah khaw David loh a yaeh tih a khum puei. Diklai dongah yalh tih rhaehba sut.
17 Àwọn àgbàgbà ilé rẹ̀ sì dìde tọ̀ ọ́ lọ, láti gbé e dìde lórí ilé, ó sì kọ̀, kò sì bá wọn jẹun.
A imkhui kah patong rhoek loh anih Te diklai lamloh thoh hamla a taengah pai uh. Tedae ngaih pawt tih amih taengah buh ca voel pawh.
18 Ní ọjọ́ keje, ọmọ náà sì kú. Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì bẹ̀rù láti wí fún un pé, ọmọ náà kú: nítorí tí wọ́n wí pé, “Kíyèsi i, nígbà tí ọmọ náà ń bẹ láààyè, àwa sọ̀rọ̀ fún un, òun kọ̀ si gbọ́ ohùn wa! Ǹjẹ́ yóò ti ṣe ara rẹ̀ ní èṣe tó, bí àwa bá wí fún un pé, ọmọ náà kú.”
A hnin rhih dongah camoe te duek. Tedae camoe a duek te amah taengah puen hamla David kah sal rhoek loh a rhih uh. “Camoe a hing la a om vaengah pataeng anih te m'voek uh dae mamih ol te a hnatun moenih ta. Boethae saii mai koinih camoe a duek Te anih taengah metlam n'ti eh?,” a ti uh.
19 Nígbà tí Dafidi sì rí pé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, Dafidi sì kíyèsi i, pé ọmọ náà kú, Dafidi sì béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ọmọ náà kú bí?” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Ó kú.”
Tedae a sal rhoek a sisuk uh te David loh a hmuh vaengah camoe duek tila David loh a yakming. Te vaengah David loh a sal rhoek te, “Camoe te duek coeng a?,” a ti nah hatah, “Duek coeng,” a ti na uh.
20 Dafidi sì dìde ní ilẹ̀, ó sì wẹ̀, ó fi òróró pa ara, ó sì pààrọ̀ aṣọ rẹ̀, ó sì wọ inú ilé Olúwa lọ, ó sì wólẹ̀ sin, ó sì wá sí ilé rẹ̀ ó sì béèrè, wọ́n sì gbé oúnjẹ kalẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì jẹun.
Te daengah David Te diklai lamloh thoo tih, pumrho a silh, situi a hluk, a himbai hainak te a tho. Te phoeiah BOEIPA kah im te a paan tih a bawk. Amah im la a mael phoeiah caak a hoe dongah a tawn pa uh tih a caak.
21 Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì bí léèrè pé, “Kí ni èyí tí ìwọ ṣe yìí? Nítorí ọmọ náà nígbà tí ó ń bẹ láààyè ìwọ gbààwẹ̀, o sì sọkún; ṣùgbọ́n nígbà tí ọmọ náà kú, ó dìde ó sì jẹun.”
Te vaengah a sal rhoek loh amah taengah, “Hebang khoboe he metlamnim, camoe a hing vaengah caak yaeh na saii tih na rhap. Camoe a duek vaengah nim na thoo tih buh na caak,” a ti na uh.
22 Ó sì wí pé, “Nígbà tí ọmọ náà ń bẹ láààyè, èmi gbààwẹ̀, èmi sì sọkún: nítorí tí èmi wí pé, ‘Ta ni ó mọ̀? Bí Olúwa ó ṣàánú mi, kí ọmọ náà le yè.’
Tedae, “Camoe a hing vaengah caak ka yaeh tih ka rhah te, 'U long a ming, BOEIPA kai he n'rhen khaw n'rhen mai vetih camoe te hing mai mako,’ ka ti dae ta.
23 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó ti kú, nítorí kín ni èmi ó ṣe máa gbààwẹ̀? Èmi ha tún lè mú un padà bí? Èmi ni yóò tọ̀ ọ́ lọ, òun kì yóò sì tún tọ̀ mí wá.”
Tedae a duek coeng dongah ba ham lae kai loh ka yaeh voel eh. Anih ha mael ham te ka saii thai aya? Kamah tah anih taengla ka cet suidae anih tah kai taengla ha mael pawh,” a ti.
24 Dafidi sì ṣìpẹ̀ fún Batṣeba aya rẹ̀, ó sì wọlé tọ̀ ọ́, ó sì bá a dàpọ̀, òun sì bí ọmọkùnrin kan, Dafidi sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Solomoni, Olúwa sì fẹ́ ẹ.
Te phoeiah David loh a yuu Bathsheba te a hloep tih a taengla a kun thil. Te vaengah anih te a yalh puei tih ca tongpa a sak pah. A ming a sak vaengah Solomon la a sak tih BOEIPA loh anih a lungnah.
25 Ó sì rán Natani wòlíì, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jedidiah, nítorí Olúwa.
Te dongah tonghma Nathan kut ah ol a pat tih camoe ming te BOEIPA kah Jedidiah la a khue.
26 Joabu sì bá Rabba ti àwọn ọmọ Ammoni jagun, ó sì gba ìlú ọba wọn.
Te vaengah Joab loh Ammon koca rhoek kah Rabbah te a vathoh thil tih mangpa khopuei te a rhawt pah.
27 Joabu sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Dafidi, ó sì wí pé, “Èmi ti bá Rabba jà, èmi sì ti gba àwọn ìlú olómi.
Te vaengah Joab loh David taengah puencawn a tueih tih, “Rabbah te ka vathoh thil tih, tui kah khopuei te khaw ka buem coeng.
28 Ǹjẹ́ nítorí náà kó àwọn ènìyàn ìyókù jọ, kí o sì dó ti ìlú náà, kí o sì gbà á, kí èmi má bá à gba ìlú náà kí a má ba à pè é ní orúkọ mi.”
Te dongah pilnam hlangrhuel te coi laeh. Khopuei te rhaeh thil lamtah buem laeh. Kamah loh khopuei te ka buem vetih kamah ming la ka khue ve,” a ti nah.
29 Dafidi sì kó gbogbo ènìyàn náà jọ, sí Rabba, ó sì bá a jà, ó sì gbà á.
Te dongah David loh pilnam te boeih a coi tih Rabbah la cet. Te phoeiah a vathoh thil bal tih Rabbah Te buem.
30 Òun sì gba adé ọba wọn kúrò lórí rẹ̀, ìwúwo rẹ̀ sì jẹ́ tálẹ́ǹtì wúrà kan, ó sì ní òkúta oníyebíye lára rẹ̀; a sì fi dé Dafidi lórí. Òun sì kó ìkógun ìlú náà ni ọ̀pọ̀lọpọ̀.
A manghai kah rhuisam te a lu dong lamkah a dul pah vaengah sui neh lung vang Te a khiing he talent khat lo. TeTe David lu dongah a khuem tih khopuei kah kutbuem a loh khaw muep yet.
31 Ó sì kó àwọn ènìyàn náà tí ó wà nínú rẹ̀, ó sì fi wọ́n sí iṣẹ́ ayùn, àti sí iṣẹ́ nǹkan ìtulẹ̀ tí a fi irin ṣe, àti sí iṣẹ́ àáké irin, ó sì fi wọ́n sí iṣẹ́ bíríkì ṣíṣe, bẹ́ẹ̀ náà ni òun sì ṣe sí gbogbo ìlú àwọn ọmọ Ammoni. Dafidi àti gbogbo àwọn ènìyàn náà sì padà sí Jerusalẹmu.
A khuikah pilnam te a khuen tih hlawh taengah, thi tlang taengah, thi yoeng taengah a khueh. Amih te taptlang dongah a tueih. Te tlamTe Ammon koca rhoek kah khopuei tom te a saii daengah David neh pilnam pum loh Jerusalem la mael pueng.

< 2 Samuel 12 >