< 2 Samuel 11 >
1 Lẹ́yìn ìgbà tí ọdún yípo, ní àkókò ìgbà tí àwọn ọba máa ń jáde ogun, Dafidi sì rán Joabu, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, àti gbogbo Israẹli; wọ́n sì pa àwọn ọmọ Ammoni, wọ́n sì dó ti Rabba. Dafidi sì jókòó ní Jerusalẹmu.
Și s-a întâmplat, după terminarea anului, pe timpul când împărații ies la bătălie, că David a trimis pe Ioab și pe servitorii săi cu el și tot Israelul; și i-au nimicit pe fiii lui Amon și au asediat Raba. Dar David a rămas încă la Ierusalim.
2 Ó sì ṣe, ní ìgbà àṣálẹ́ kan, Dafidi sì dìde ní ibùsùn rẹ̀, ó sì ń rìn lórí òrùlé ilé ọba, láti orí òrùlé náà ni ó sì rí obìnrin kan tí ó ń wẹ̀ ara rẹ̀; obìnrin náà sì ṣe arẹwà lójú láti wò.
Și s-a întâmplat, spre seară, că David s-a ridicat din patul său și s-a plimbat pe acoperișul casei împăratului; și de pe acoperiș a văzut o femeie spălându-se; și femeia era foarte frumoasă la vedere.
3 Dafidi sì ránṣẹ́ ó sì béèrè obìnrin náà. Ẹnìkan sì wí pé, “Èyí ha kọ́ ni Batṣeba, ọmọbìnrin Eliamu, aya Uriah ará Hiti.”
Și David a trimis și a cercetat despre femeie. Și unul a spus: Nu este aceasta Bat-Șeba, fiica lui Eliam, soția lui Urie hititul?
4 Dafidi sì rán àwọn ìránṣẹ́, ó sì mú un; ó sì wọ inú ilé tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bá a dàpọ̀, nígbà tí ó sì wẹ ara rẹ̀ mọ́ tán, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀.
Și David a trimis mesageri și au luat-o; și ea a intrat la el și el s-a culcat cu ea; fiindcă ea era purificată de necurăția ei; și s-a întors acasă.
5 Obìnrin náà sì lóyún, ó sì ránṣẹ́ ó sì sọ fún Dafidi, ó sì wí pé, “Èmi ti lóyún.”
Și femeia a rămas însărcinată și a trimis să spună lui David și a zis: Sunt însărcinată.
6 Dafidi sì ránṣẹ́ sí Joabu, pé, “Rán Uriah ará Hiti sí mi.” Joabu sì rán Uriah sí Dafidi.
Și David a trimis la Ioab, spunând: Trimite-mi pe Urie hititul. Și Ioab l-a trimis pe Urie la David.
7 Nígbà tí Uriah sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Dafidi sì bi í léèrè báwo ni Joabu ti ṣe àti àlàáfíà àwọn ènìyàn náà, àti bí ogun náà ti ń ṣe.
Și după ce Urie a venit la el, David l-a întrebat ce mai făcea Ioab și ce mai făcea poporul și cum mergea războiul.
8 Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ, kí o sì wẹ ẹsẹ̀ rẹ.” Uriah sì jáde kúrò ní ilé ọba, oúnjẹ láti ọ̀dọ̀ ọba wá sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
Și David i-a spus lui Urie: Coboară acasă la tine și spală-ți picioarele. Și Urie s-a depărtat de casa împăratului și l-a urmat un dar de mâncare de la împărat.
9 Ṣùgbọ́n Uriah sun ní ẹnu-ọ̀nà ilé ọba lọ́dọ̀ gbogbo ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.
Dar Urie a dormit la ușa casei împăratului cu toți servitorii domnului său și nu a coborât acasă.
10 Nígbà tí wọ́n sì sọ fún Dafidi pé, “Uriah kò sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀,” Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Ṣe bí ọ̀nà àjò ni ìwọ ti wá? Èéha ti ṣe tí ìwọ kò fi sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ.”
Și când i-au spus lui David, zicând: Urie nu a coborât acasă. Și David i-a spus lui Urie: Nu te-ai întors din călătorie? De ce nu ai coborât acasă?
11 Uriah sì wí fún Dafidi pé, “Àpótí ẹ̀rí, àti Israẹli, àti Juda jókòó nínú àgọ́; àti Joabu olúwa mi, àti àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi wà ní ibùdó ní pápá, èmi ó ha lọ sí ilé mi, láti jẹ àti láti mu, àti láti bá obìnrin mi sùn? Bí ìwọ bá wà láààyè, àti bí ẹ̀mí rẹ́ si ti ń bẹ láààyè, èmi kì yóò ṣe nǹkan yìí.”
Și Urie i-a spus lui David: Chivotul și Israel și Iuda, locuiesc în corturi; și domnul meu Ioab și servitorii domnului meu, sunt așezați în tabără în câmp deschis; să intru eu atunci în casa mea, să mănânc și să beau și să mă culc cu soția mea? Precum trăiești tu și precum trăiește sufletul tău, nu voi face acest lucru.
12 Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Sì dúró níhìn-ín lónìí, lọ́la èmi ó sì jẹ́ kí ìwọ ó lọ.” Uriah sì dúró ní Jerusalẹmu ní ọjọ́ náà, àti ọjọ́ kejì.
Și David i-a spus lui Urie: Rămâi aici și astăzi, și mâine te voi lăsa să pleci. Astfel Urie a rămas la Ierusalim în acea zi și a doua zi.
13 Dafidi sì pè é, ó sì jẹ, ó sì mú nítorí rẹ̀; ó sì mu kí ọtí pa á; òun sì jáde ní alẹ́ lọ sí ibùsùn rẹ̀ lọ́dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.
Și când David l-a chemat, el a mâncat și a băut înaintea lui și l-a îmbătat; și seara el a ieșit afară să se culce în patul său cu servitorii domnului său, dar nu a coborât acasă.
14 Ó sì ṣe ní òwúrọ̀, Dafidi sì kọ̀wé sí Joabu, ó fi rán Uriah.
Și s-a întâmplat, dimineața, că David a scris o scrisoare lui Ioab și a trimis-o prin mâna lui Urie.
15 Ó sì kọ sínú ìwé pé, “Fi Uriah síwájú ibi tí ogun gbé le, kí ẹ sì fàsẹ́yìn, kí wọn lè kọlù ú, kí ó sì kú.”
Și a scris în scrisoare, spunând: Puneți-l pe Urie în fruntea bătăliei celei mai încinse și retrageți-vă de la el, ca să fie lovit și să moară.
16 Ó sì ṣe nígbà tí Joabu ṣe àkíyèsí ìlú náà, ó sì yan Uriah sí ibi kàn ní ibi tí òun mọ̀ pé àwọn alágbára ọkùnrin ń bẹ níbẹ̀.
Și s-a întâmplat, când Ioab observa cetatea, că l-a pus pe Urie la locul unde știa că erau bărbați viteji.
17 Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì jáde wá, wọ́n sì bá Joabu jà, díẹ̀ sì ṣubú nínú àwọn ènìyàn náà nínú àwọn ìránṣẹ́ Dafidi, Uriah ará Hiti sì kú pẹ̀lú.
Și bărbații cetății au ieșit afară și au luptat cu Ioab; și au căzut unii din popor dintre servitorii lui David; și Urie hititul a murit de asemenea.
18 Joabu sì ránṣẹ́ ó sì ro gbogbo nǹkan ogun náà fún Dafidi.
Atunci Ioab a trimis și a spus lui David toate lucrurile referitoare la război;
19 Ó sì pàṣẹ fún ìránṣẹ́ náà pé, “Nígbà tí ìwọ bá sì parí àti máa ro gbogbo nǹkan ogun náà fún ọba.
Și a poruncit mesagerului, zicând: După ce vei fi terminat de spus împăratului lucrurile despre război,
20 Bí ó bá ṣe pé, ìbínú ọba bá ru, ti òun sì wí fún ọ pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin fi súnmọ́ ìlú náà láti bá wọn jà, ẹ̀yin kò mọ̀ pé wọn ó tafà láti orí odi wá.
Și dacă va fi astfel, că furia împăratului se va ridica și îți va spune: Pentru ce v-ați apropiat atât de mult de cetate când ați luptat? Nu ați știut că vor trage de pe zid?
21 Ta ni ó pa Abimeleki ọmọ Jerubu-Beṣeti? Kì í ṣe obìnrin ni ó yí òkúta-ọlọ lù ú láti orí odi wá, tí ó sì kú ní Tebesi? Èéha ti rí tí ẹ̀yin fi súnmọ́ odi náà? Ìwọ yóò sì wí fún un pé, Uriah ìránṣẹ́ rẹ ará Hiti kú pẹ̀lú.’”
Cine a lovit pe Abimelec, fiul lui Ierubeșet? Nu a aruncat o femeie o bucată de piatră de moară de pe zid, încât el a murit la Tebeț? De ce v-ați apropiat de zid? Atunci tu să spui: A murit și servitorul tău Urie, hititul.
22 Ìránṣẹ́ náà sì lọ, ó sì wá, ó sì jẹ́ gbogbo iṣẹ́ tí Joabu rán an fún Dafidi.
Astfel mesagerul a plecat și a venit și i-a arătat lui David despre toate pentru care îl trimisese Ioab.
23 Ìránṣẹ́ náà sì wí fún Dafidi pé, “Nítòótọ́ àwọn ọkùnrin náà lágbára jù wá lọ, wọ́n sì jáde tọ̀ wá wá ní pápá, àwa sì tẹ̀lé wọn títí wọ́n fi dé ẹ̀yìn odi.
Și mesagerul i-a spus lui David: Într-adevăr, oamenii au fost mai tari decât noi și au ieșit la noi în câmp și am fost asupra lor până la intrarea porții.
24 Àwọn tafàtafà sì ta sí ìránṣẹ́ rẹ láti orí odi wá, díẹ̀ nínú àwọn ìránṣẹ́ ọba sì kú, ìránṣẹ́ rẹ̀ Uriah ará Hiti sì kú pẹ̀lú.”
Și trăgătorii au tras de pe zid asupra servitorilor tăi; și unii dintre servitorii împăratului au murit; a murit și servitorul tău Urie, hititul.
25 Dafidi sì wí fún ìránṣẹ́ náà pé, “Báyìí ni ìwọ yóò wí fún Joabu pé, ‘Má ṣe jẹ́ kí nǹkan yìí burú ní ojú rẹ, nítorí pé idà a máa pa lọ́tùn ún lósì, mú ìjà rẹ le sí ìlú náà, kí o sì bì í ṣubú.’ Kí ìwọ sì mú un lọ́kàn le.”
Atunci David i-a spus mesagerului: Astfel să spui lui Ioab: Să nu îți displacă acest lucru, pentru că sabia mănâncă pe unul la fel ca și pe altul; întărește mai mult bătălia împotriva cetății și dărâm-o; și încurajează-l.
26 Nígbà tí aya Uriah sì gbọ́ pé Uriah ọkọ rẹ̀ kú, ó sì ṣọ̀fọ̀ nítorí ọkọ rẹ̀.
Și când soția lui Urie a auzit că Urie soțul ei era mort, l-a jelit pe soțul ei.
27 Nígbà tí ìṣọ̀fọ̀ náà sì kọjá tan, Dafidi sì ránṣẹ́, o sì mú un wá sí ilé rẹ̀, ó sì di aya rẹ̀, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un, ṣùgbọ́n nǹkan náà tí Dafidi ṣe burú níwájú Olúwa.
Și când jelirea a trecut, David a trimis și a adus-o acasă și ea i-a devenit soție și i-a născut un fiu. Dar lucrul pe care David îl făcuse nu a plăcut DOMNULUI.