< 2 Samuel 11 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí ọdún yípo, ní àkókò ìgbà tí àwọn ọba máa ń jáde ogun, Dafidi sì rán Joabu, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, àti gbogbo Israẹli; wọ́n sì pa àwọn ọmọ Ammoni, wọ́n sì dó ti Rabba. Dafidi sì jókòó ní Jerusalẹmu.
Hagi mago mago kafumofo agu'afina zasi koma atu knamo'ma vaganerege'za kini vahe'mo'za ha' vahe'zami'a ha' ome hunezamantaza kanagino, Deviti'a Joapune mika Israeli sondia vahetaminena hate viho huno huzmantege'za, zamagra vu'za Amoni vahera ome zamahe'za zamazeri haviza nehu'za, Raba kuma ome avazagi kagi'naze. Hianagi Deviti'a ana hatera ovuno, Jerusalemi mani'ne.
2 Ó sì ṣe, ní ìgbà àṣálẹ́ kan, Dafidi sì dìde ní ibùsùn rẹ̀, ó sì ń rìn lórí òrùlé ilé ọba, láti orí òrùlé náà ni ó sì rí obìnrin kan tí ó ń wẹ̀ ara rẹ̀; obìnrin náà sì ṣe arẹwà lójú láti wò.
Hagi mago kinaga Deviti'a tafe'are mase'nereti otino noma'amofo agofetu vano nehuno keana, mago hentofa a'mo'a ti nefregeno ke'ne.
3 Dafidi sì ránṣẹ́ ó sì béèrè obìnrin náà. Ẹnìkan sì wí pé, “Èyí ha kọ́ ni Batṣeba, ọmọbìnrin Eliamu, aya Uriah ará Hiti.”
Hagi Deviti'a keteno mago vahe hunteno amanage hu'ne, Fenamu ara izapi ome ketenka eme nasamio, higeno ome keteno ete eme asamino, Eliamu mofa Batsiba Hiti ne' Uria nenaro'e.
4 Dafidi sì rán àwọn ìránṣẹ́, ó sì mú un; ó sì wọ inú ilé tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bá a dàpọ̀, nígbà tí ó sì wẹ ara rẹ̀ mọ́ tán, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀.
Anante Deviti'a eri'za vahe huzamantege'za vu'za ana ara ome avre'za ageno, anteno mase'ne. (Hagi e'inama hu'neana namunka mani'nereti vagarentegeno ti ome freno agra'a azeri agru nehigeno ke'ne.) Hagi Deviti'enema maseteno'a ete noma'arega vu'ne.
5 Obìnrin náà sì lóyún, ó sì ránṣẹ́ ó sì sọ fún Dafidi, ó sì wí pé, “Èmi ti lóyún.”
Hagi ana a'mo'ma keama amu'enema nehuno'a, Devitina kea atrenteno anage hu'ne, Namu'ene hue huno hu'ne.
6 Dafidi sì ránṣẹ́ sí Joabu, pé, “Rán Uriah ará Hiti sí mi.” Joabu sì rán Uriah sí Dafidi.
Higeno Deviti'a Joapuna ke atrenteno, Hiti ne' Uriana huntegeno eno, higeno Joapu'a Uriana huntegeno Devitintega vu'ne.
7 Nígbà tí Uriah sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Dafidi sì bi í léèrè báwo ni Joabu ti ṣe àti àlàáfíà àwọn ènìyàn náà, àti bí ogun náà ti ń ṣe.
Hagi Uria'ma Devitinte'ma ehanatigeno'a Deviti'a asamino, Joapuzane sondia vahera inankna hu'za mani'ne'za hara nehaze nehuno,
8 Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ, kí o sì wẹ ẹsẹ̀ rẹ.” Uriah sì jáde kúrò ní ilé ọba, oúnjẹ láti ọ̀dọ̀ ọba wá sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
anante Deviti'a Uriana hunteno, Vunka umani fru huo, huno huntegeno nevigeno'a, mago'a musezana antentege'za eri'za ome ami'naze.
9 Ṣùgbọ́n Uriah sun ní ẹnu-ọ̀nà ilé ọba lọ́dọ̀ gbogbo ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.
Hianagi Uria'a noma'arega ovu'neanki kini ne'mofo eri'za vahe'ene kini ne' ku'ma kahampi umaseno mani'ne.
10 Nígbà tí wọ́n sì sọ fún Dafidi pé, “Uriah kò sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀,” Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Ṣe bí ọ̀nà àjò ni ìwọ ti wá? Èéha ti ṣe tí ìwọ kò fi sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ.”
Mago'a vahe'mo'za Devitina eme asami'za, Uria'a noma'arega uorami'ne, hu'za hazageno Deviti'a kehigeno Uria'a egeno anage huno asami'ne, za'za kna umani'nanteti e'nananki na'a higenka nonka'arega ovu'nane?
11 Uriah sì wí fún Dafidi pé, “Àpótí ẹ̀rí, àti Israẹli, àti Juda jókòó nínú àgọ́; àti Joabu olúwa mi, àti àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi wà ní ibùdó ní pápá, èmi ó ha lọ sí ilé mi, láti jẹ àti láti mu, àti láti bá obìnrin mi sùn? Bí ìwọ bá wà láààyè, àti bí ẹ̀mí rẹ́ si ti ń bẹ láààyè, èmi kì yóò ṣe nǹkan yìí.”
Anage higeno Uria'a Devitina kenona hunteno, Ra Anumzamofo huhagerafi huvempage vogisigi, Israeli sondia vaheki, Juda vahe'mo'za seli nompi manizageno, rankva vahe'ni'a Joapu'ene sondia vahete kva vahetamina ha' kampima seli nomaki'za mani'nenafina nagrama noniaregama vu'na ne'za ome nenena, a'ninema mase so'e huzamo'a knarera osu'ne. Hagi tamagerafa hu'na e'ina huzana osutfa hugahue.
12 Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Sì dúró níhìn-ín lónìí, lọ́la èmi ó sì jẹ́ kí ìwọ ó lọ.” Uriah sì dúró ní Jerusalẹmu ní ọjọ́ náà, àti ọjọ́ kejì.
Anage higeno Deviti'a Uriana asamino, Meni kenagera are mase'negena, okina huganta'nena ete hate vuo. Higeno Uria'a Jerusalemi ana kenagera maseno magokna mani'ne.
13 Dafidi sì pè é, ó sì jẹ, ó sì mú nítorí rẹ̀; ó sì mu kí ọtí pa á; òun sì jáde ní alẹ́ lọ sí ibùsùn rẹ̀ lọ́dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.
Hagi Deviti'a ke higeno noma'afi Uria'a eno Deviti'ene ne'zana nenegeno, akatina rama'a ami'geno neno neginagi hu'ne. Hu'neanagi ana kinaga Uria'a noma'arega vunora a'anena uomase'neanki, Deviti eri'za vahe'ene ko'ma mase'nere umase'ne.
14 Ó sì ṣe ní òwúrọ̀, Dafidi sì kọ̀wé sí Joabu, ó fi rán Uriah.
Hagi nanterana Deviti'a mago avona Joapuntega krenenteno, Uriana huntegeno erino vu'ne.
15 Ó sì kọ sínú ìwé pé, “Fi Uriah síwájú ibi tí ogun gbé le, kí ẹ sì fàsẹ́yìn, kí wọn lè kọlù ú, kí ó sì kú.”
Hagi ana avompina amanage huno krente'ne, Uriana ha'ma hanavemati'za nehanafi avuga avrenentenka sondia vahera kehuge'za atre'za esageno, anampi Uriana ahesageno frino.
16 Ó sì ṣe nígbà tí Joabu ṣe àkíyèsí ìlú náà, ó sì yan Uriah sí ibi kàn ní ibi tí òun mọ̀ pé àwọn alágbára ọkùnrin ń bẹ níbẹ̀.
Higeno Joapu'a hara nehuno negegeno ha'mo'ma ra higeno, hanave ha' vahe'mo'zama ha'ma nehaza kaziga Uriana avrentegeno hara hu'ne.
17 Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì jáde wá, wọ́n sì bá Joabu jà, díẹ̀ sì ṣubú nínú àwọn ènìyàn náà nínú àwọn ìránṣẹ́ Dafidi, Uriah ará Hiti sì kú pẹ̀lú.
Hagi rankuma agu'afinti vahe'ma e'za hara eme huzmante'za mago'a Deviti sondia vahera zamahage'za frizageno, anampina Hiti ne' Urianena ahegeno fri'ne.
18 Joabu sì ránṣẹ́ ó sì ro gbogbo nǹkan ogun náà fún Dafidi.
Ana higeno Joapu'a ana miko'zama ha'pima fore'ma hiazana kema erino vu vahe huzmantege'za Devitina ome asami'naze.
19 Ó sì pàṣẹ fún ìránṣẹ́ náà pé, “Nígbà tí ìwọ bá sì parí àti máa ro gbogbo nǹkan ogun náà fún ọba.
Hagi Joapu'a kema erino vu vahera hunteno, Ama miko'zama fore'ma hia zamofo nanekea kini nera asami vagaro.
20 Bí ó bá ṣe pé, ìbínú ọba bá ru, ti òun sì wí fún ọ pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin fi súnmọ́ ìlú náà láti bá wọn jà, ẹ̀yin kò mọ̀ pé wọn ó tafà láti orí odi wá.
Hagi agra arimpama ahesigeno'a, amanage hugahie, nahigeta rankuma keginamofo tavaontera vu'naze? Zamagrama kuma keginamofo agofetuti'ma kevema tamahesaza zana tamagra ontahi'nazo?
21 Ta ni ó pa Abimeleki ọmọ Jerubu-Beṣeti? Kì í ṣe obìnrin ni ó yí òkúta-ọlọ lù ú láti orí odi wá, tí ó sì kú ní Tebesi? Èéha ti rí tí ẹ̀yin fi súnmọ́ odi náà? Ìwọ yóò sì wí fún un pé, Uriah ìránṣẹ́ rẹ ará Hiti kú pẹ̀lú.’”
Hagi ko'ma Abimelekinte'ma fore'ma hu'nea zana tamagekaninefi? Hagi Abimeleki'a Gidioni nemofokino, Tebesi kuma'mofo tava'onte oti'negeno, mago a'mo ku'ma keginamofo agofetu oti'neno witima refuzafu nepaza ra havenu erino ahegeno fri'ne. E'ina hu'negu nahigeta tamagra ana kegina tava'ontera vu'naze? Huno kini ne'mo'ma kantahigesigenka, anampina Uria'ene fri'ne hunka asamio.
22 Ìránṣẹ́ náà sì lọ, ó sì wá, ó sì jẹ́ gbogbo iṣẹ́ tí Joabu rán an fún Dafidi.
Higeno ana kema erino vu vahe'mo'a vu'ne. Hagi ana miko kema Joapu'ma huntea kea Devitina eme asami vagare'ne.
23 Ìránṣẹ́ náà sì wí fún Dafidi pé, “Nítòótọ́ àwọn ọkùnrin náà lágbára jù wá lọ, wọ́n sì jáde tọ̀ wá wá ní pápá, àwa sì tẹ̀lé wọn títí wọ́n fi dé ẹ̀yìn odi.
Hagi ana eri'za nemo'a Devitina asamino, Ko agupofi hara hanavetiza eme hurante'nazanagi tagra inene huta rankuma'mofo kafante hara huta vu'none.
24 Àwọn tafàtafà sì ta sí ìránṣẹ́ rẹ láti orí odi wá, díẹ̀ nínú àwọn ìránṣẹ́ ọba sì kú, ìránṣẹ́ rẹ̀ Uriah ará Hiti sì kú pẹ̀lú.”
Hagi mago'a Amoni sondia vahe'mo'za kuma keginamofo agofetu manine'za kevereti tahazage'za kini ne'moka mago'a eri'za vaheka'a fri'naze. Hagi anampina Hiti ne' eri'za neka'a Uria'a fri'ne.
25 Dafidi sì wí fún ìránṣẹ́ náà pé, “Báyìí ni ìwọ yóò wí fún Joabu pé, ‘Má ṣe jẹ́ kí nǹkan yìí burú ní ojú rẹ, nítorí pé idà a máa pa lọ́tùn ún lósì, mú ìjà rẹ le sí ìlú náà, kí o sì bì í ṣubú.’ Kí ìwọ sì mú un lọ́kàn le.”
Hagi Deviti'a kema erino vu'nea nera asamino, Joapuna asamigeno ama ana zankura agesa ontahino, na'ankure mago ne'mo'a hapima fri'nia zana antahino keno osu'negu, ome asamigeno hanavetino hara nehuno, ana kumara erino. Amama kasamua kereti azeri hankanavetio.
26 Nígbà tí aya Uriah sì gbọ́ pé Uriah ọkọ rẹ̀ kú, ó sì ṣọ̀fọ̀ nítorí ọkọ rẹ̀.
Hagi Uria nenaro'ma antahiama nevema hapima ahe'naze higeno'a, asunku huno zavi ate'ne.
27 Nígbà tí ìṣọ̀fọ̀ náà sì kọjá tan, Dafidi sì ránṣẹ́, o sì mú un wá sí ilé rẹ̀, ó sì di aya rẹ̀, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un, ṣùgbọ́n nǹkan náà tí Dafidi ṣe burú níwájú Olúwa.
Hagi asunku'ma huvaregeno'a, Deviti'a huzamantege'za ana ara avre'za ageno a' avrentegeno mani'neno ne' mofavre kasente'ne. Hianagi Deviti'ma hu'nea zankura Ra Anumzamo'a musena osu'ne.

< 2 Samuel 11 >