< 2 Samuel 11 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí ọdún yípo, ní àkókò ìgbà tí àwọn ọba máa ń jáde ogun, Dafidi sì rán Joabu, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, àti gbogbo Israẹli; wọ́n sì pa àwọn ọmọ Ammoni, wọ́n sì dó ti Rabba. Dafidi sì jókòó ní Jerusalẹmu.
Le cours de l'année ramena le temps où les rois se mettent en campagne, et David fit partir Joab, ses serviteurs et tout Israël; ils ravagèrent la contrée des fils d'Ammon, et ils assiégèrent Rhabbath; cependant, David était resté à Jérusalem.
2 Ó sì ṣe, ní ìgbà àṣálẹ́ kan, Dafidi sì dìde ní ibùsùn rẹ̀, ó sì ń rìn lórí òrùlé ilé ọba, láti orí òrùlé náà ni ó sì rí obìnrin kan tí ó ń wẹ̀ ara rẹ̀; obìnrin náà sì ṣe arẹwà lójú láti wò.
Et ceci advint: sur le soir, David se leva de sa couche, et il se promena sur la plate-forme de la maison royale; et, de sa plate-forme, il vit une femme qui se baignait; or, la femme était extrêmement belle de visage.
3 Dafidi sì ránṣẹ́ ó sì béèrè obìnrin náà. Ẹnìkan sì wí pé, “Èyí ha kọ́ ni Batṣeba, ọmọbìnrin Eliamu, aya Uriah ará Hiti.”
Et David envoya, et il s'informa de la femme, et on lui dit: N'est-ce point Bersabée, fille d'Eliab, femme d'Urie l'Hettéen?
4 Dafidi sì rán àwọn ìránṣẹ́, ó sì mú un; ó sì wọ inú ilé tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bá a dàpọ̀, nígbà tí ó sì wẹ ara rẹ̀ mọ́ tán, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀.
Aussitôt, David, dépêchant des messagers, la fit prendre, s'approcha d'elle, et dormit avec elle; puis, lorsqu'elle se fut purifiée de son impureté, elle retourna en sa maison.
5 Obìnrin náà sì lóyún, ó sì ránṣẹ́ ó sì sọ fún Dafidi, ó sì wí pé, “Èmi ti lóyún.”
La femme conçut; elle le fit savoir à David, et elle dit: Je suis enceinte.
6 Dafidi sì ránṣẹ́ sí Joabu, pé, “Rán Uriah ará Hiti sí mi.” Joabu sì rán Uriah sí Dafidi.
Et David fit dire à Joab: Envoie près de moi Urie l'Hettéen, et Joab envoya Urie près de David.
7 Nígbà tí Uriah sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Dafidi sì bi í léèrè báwo ni Joabu ti ṣe àti àlàáfíà àwọn ènìyàn náà, àti bí ogun náà ti ń ṣe.
Urie arriva, et il entra chez le roi, et David lui demanda comment allaient Joab, et l'armée, et la guerre.
8 Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ, kí o sì wẹ ẹsẹ̀ rẹ.” Uriah sì jáde kúrò ní ilé ọba, oúnjẹ láti ọ̀dọ̀ ọba wá sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
Et David dit à Urie: Va à ta maison, et lave-toi les pieds. Urie sortit donc de la demeure royale, et, derrière lui, on porta un mets de la table du roi.
9 Ṣùgbọ́n Uriah sun ní ẹnu-ọ̀nà ilé ọba lọ́dọ̀ gbogbo ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.
Mais Urie dormit devant la porte du roi, parmi les serviteurs de son maître, et il n'alla pas jusqu'à sa maison.
10 Nígbà tí wọ́n sì sọ fún Dafidi pé, “Uriah kò sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀,” Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Ṣe bí ọ̀nà àjò ni ìwọ ti wá? Èéha ti ṣe tí ìwọ kò fi sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ.”
On l'alla dire à David; il sut qu'Urie n'était pas allé jusqu'à sa maison, et David dit à Urie: Ne viens-tu pas de faire un voyage? Pourquoi n'es-tu pas entré en ta demeure?
11 Uriah sì wí fún Dafidi pé, “Àpótí ẹ̀rí, àti Israẹli, àti Juda jókòó nínú àgọ́; àti Joabu olúwa mi, àti àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi wà ní ibùdó ní pápá, èmi ó ha lọ sí ilé mi, láti jẹ àti láti mu, àti láti bá obìnrin mi sùn? Bí ìwọ bá wà láààyè, àti bí ẹ̀mí rẹ́ si ti ń bẹ láààyè, èmi kì yóò ṣe nǹkan yìí.”
Et Urie répondit à David: L'arche, Israël et Juda demeurent sous des tentes; mon maître Joab et les serviteurs de mon maître sont campés eu plein air, et moi j'entrerais en ma maison pour manger et boire, et dormir avec ma femme! Comment ferais-je pareille chose? Vive ton âme! je ne la ferai jamais.
12 Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Sì dúró níhìn-ín lónìí, lọ́la èmi ó sì jẹ́ kí ìwọ ó lọ.” Uriah sì dúró ní Jerusalẹmu ní ọjọ́ náà, àti ọjọ́ kejì.
Et David dit à Urie: Demeure encore avec nous aujourd'hui; demain, je te congédierai. Urie passa donc à Jérusalem cette journée là et le lendemain.
13 Dafidi sì pè é, ó sì jẹ, ó sì mú nítorí rẹ̀; ó sì mu kí ọtí pa á; òun sì jáde ní alẹ́ lọ sí ibùsùn rẹ̀ lọ́dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.
Ensuite, David l'invita; il mangea, il but, il s'enivra, et il sortit sur le soir pour dormir où il s'était déjà couché, parmi les serviteurs de son maître; mais il n'entra point en sa maison.
14 Ó sì ṣe ní òwúrọ̀, Dafidi sì kọ̀wé sí Joabu, ó fi rán Uriah.
Le jour parut, et David écrivit une lettre à Joab, et il la remit à Urie.
15 Ó sì kọ sínú ìwé pé, “Fi Uriah síwájú ibi tí ogun gbé le, kí ẹ sì fàsẹ́yìn, kí wọn lè kọlù ú, kí ó sì kú.”
Voici ce qu'en sa lettre il disait: Conduis Urie au fort du péril, et laisse-le là seul; qu'il soit frappé et qu'il meure.
16 Ó sì ṣe nígbà tí Joabu ṣe àkíyèsí ìlú náà, ó sì yan Uriah sí ibi kàn ní ibi tí òun mọ̀ pé àwọn alágbára ọkùnrin ń bẹ níbẹ̀.
Et, pendant que Joab plaçait des gardes autour de la ville, il donna à Urie un poste où il savait qu'il se trouvait des hommes vaillants.
17 Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì jáde wá, wọ́n sì bá Joabu jà, díẹ̀ sì ṣubú nínú àwọn ènìyàn náà nínú àwọn ìránṣẹ́ Dafidi, Uriah ará Hiti sì kú pẹ̀lú.
Ces hommes, en effet, firent une sortie; ils combattirent Joab; plusieurs hommes de l'armée, serviteurs de David, tombèrent, et Urie l'Hettéen fut au nombre des morts.
18 Joabu sì ránṣẹ́ ó sì ro gbogbo nǹkan ogun náà fún Dafidi.
Et Joab envoya rapporter à David tout ce qui venait de se passer dans ce combat.
19 Ó sì pàṣẹ fún ìránṣẹ́ náà pé, “Nígbà tí ìwọ bá sì parí àti máa ro gbogbo nǹkan ogun náà fún ọba.
Et il donna ses instructions au messager, disant: Lorsque tu auras fini de rapporter à David tout ce qui s'est passé dans le combat,
20 Bí ó bá ṣe pé, ìbínú ọba bá ru, ti òun sì wí fún ọ pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin fi súnmọ́ ìlú náà láti bá wọn jà, ẹ̀yin kò mọ̀ pé wọn ó tafà láti orí odi wá.
Peut-être le roi se mettra-t-il en colère, et te dira-t-il: Pourquoi donc combattre si près de la ville? Ne saviez-vous pas que du haut des remparts on vous atteindrait?
21 Ta ni ó pa Abimeleki ọmọ Jerubu-Beṣeti? Kì í ṣe obìnrin ni ó yí òkúta-ọlọ lù ú láti orí odi wá, tí ó sì kú ní Tebesi? Èéha ti rí tí ẹ̀yin fi súnmọ́ odi náà? Ìwọ yóò sì wí fún un pé, Uriah ìránṣẹ́ rẹ ará Hiti kú pẹ̀lú.’”
Qui donc a renversé Abimélech, fils de Jérobaal, fils de Ner? N'est-ce pas une femme qui lui a lancé, de la muraille, un éclat de meule dont il est mort à Thamasi? Pourquoi donc vous êtes-vous approchés du rempart? Alors, tu répondras: Urie l'Hettéen, ton serviteur, est du nombre des morts.
22 Ìránṣẹ́ náà sì lọ, ó sì wá, ó sì jẹ́ gbogbo iṣẹ́ tí Joabu rán an fún Dafidi.
Le messager de Joab se rendit à Jérusalem, et, selon l'ordre de Joab, il fit au roi le rapport de tout ce qui était arrivé à la guerre.
23 Ìránṣẹ́ náà sì wí fún Dafidi pé, “Nítòótọ́ àwọn ọkùnrin náà lágbára jù wá lọ, wọ́n sì jáde tọ̀ wá wá ní pápá, àwa sì tẹ̀lé wọn títí wọ́n fi dé ẹ̀yìn odi.
Le messager répondit à David: Parce que ceux de la ville ont prévalu sur nous; ils ont fait une sortie dans la campagne; puis, nous les avons repoussés jusqu'aux portes de la ville.
24 Àwọn tafàtafà sì ta sí ìránṣẹ́ rẹ láti orí odi wá, díẹ̀ nínú àwọn ìránṣẹ́ ọba sì kú, ìránṣẹ́ rẹ̀ Uriah ará Hiti sì kú pẹ̀lú.”
Alors, des archers ont tiré du haut des remparts sur tes serviteurs; plusieurs des serviteurs du roi ont péri; ton serviteur Urie l'Hettéen est du nombre des morts.
25 Dafidi sì wí fún ìránṣẹ́ náà pé, “Báyìí ni ìwọ yóò wí fún Joabu pé, ‘Má ṣe jẹ́ kí nǹkan yìí burú ní ojú rẹ, nítorí pé idà a máa pa lọ́tùn ún lósì, mú ìjà rẹ le sí ìlú náà, kí o sì bì í ṣubú.’ Kí ìwọ sì mú un lọ́kàn le.”
Et David dit au messager: Voici ce que tu diras à Joab: Ne t'afflige pas de cet événement; le glaive dévore tantôt celui-ci, tantôt celui-là; fortifie tes postes autour de la ville, enlève-la, et t'en rends maître.
26 Nígbà tí aya Uriah sì gbọ́ pé Uriah ọkọ rẹ̀ kú, ó sì ṣọ̀fọ̀ nítorí ọkọ rẹ̀.
Et la femme d'Urie apprit que son mari était mort, et elle pleura sur son mari.
27 Nígbà tí ìṣọ̀fọ̀ náà sì kọjá tan, Dafidi sì ránṣẹ́, o sì mú un wá sí ilé rẹ̀, ó sì di aya rẹ̀, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un, ṣùgbọ́n nǹkan náà tí Dafidi ṣe burú níwájú Olúwa.
Le temps du deuil écoulé, David envoya près d'elle, la fit venir en sa demeure, et la prit pour femme; elle lui enfanta un fils. Mais l'action que David avait commise était mauvaise aux yeux du Seigneur.

< 2 Samuel 11 >