< 2 Samuel 11 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí ọdún yípo, ní àkókò ìgbà tí àwọn ọba máa ń jáde ogun, Dafidi sì rán Joabu, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, àti gbogbo Israẹli; wọ́n sì pa àwọn ọmọ Ammoni, wọ́n sì dó ti Rabba. Dafidi sì jókòó ní Jerusalẹmu.
Au retour de l'année, au moment où les rois sortent, David envoya avec lui Joab et ses serviteurs, et tout Israël; ils détruisirent les fils d'Ammon et assiégèrent Rabba. Mais David resta à Jérusalem.
2 Ó sì ṣe, ní ìgbà àṣálẹ́ kan, Dafidi sì dìde ní ibùsùn rẹ̀, ó sì ń rìn lórí òrùlé ilé ọba, láti orí òrùlé náà ni ó sì rí obìnrin kan tí ó ń wẹ̀ ara rẹ̀; obìnrin náà sì ṣe arẹwà lójú láti wò.
Le soir, David se leva de son lit et se promena sur le toit de la maison du roi. Du toit, il vit une femme qui se baignait, et cette femme était très belle à voir.
3 Dafidi sì ránṣẹ́ ó sì béèrè obìnrin náà. Ẹnìkan sì wí pé, “Èyí ha kọ́ ni Batṣeba, ọmọbìnrin Eliamu, aya Uriah ará Hiti.”
David envoya demander des nouvelles de cette femme. On lui dit: « N'est-ce pas Bethsabée, fille d'Eliam, la femme d'Urie le Héthien? »
4 Dafidi sì rán àwọn ìránṣẹ́, ó sì mú un; ó sì wọ inú ilé tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bá a dàpọ̀, nígbà tí ó sì wẹ ara rẹ̀ mọ́ tán, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀.
David envoya des messagers, qui la prirent; elle entra chez lui, et il coucha avec elle (car elle était purifiée de son impureté); puis elle retourna dans sa maison.
5 Obìnrin náà sì lóyún, ó sì ránṣẹ́ ó sì sọ fún Dafidi, ó sì wí pé, “Èmi ti lóyún.”
La femme devint enceinte; elle envoya avertir David, et dit: « Je suis enceinte. »
6 Dafidi sì ránṣẹ́ sí Joabu, pé, “Rán Uriah ará Hiti sí mi.” Joabu sì rán Uriah sí Dafidi.
David envoya dire à Joab: « Envoie-moi Urie, le Hittite. » Joab envoya Urie à David.
7 Nígbà tí Uriah sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Dafidi sì bi í léèrè báwo ni Joabu ti ṣe àti àlàáfíà àwọn ènìyàn náà, àti bí ogun náà ti ń ṣe.
Lorsque Urie fut arrivé auprès de lui, David lui demanda comment allait Joab, comment se portait le peuple et comment la guerre avait prospéré.
8 Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ, kí o sì wẹ ẹsẹ̀ rẹ.” Uriah sì jáde kúrò ní ilé ọba, oúnjẹ láti ọ̀dọ̀ ọba wá sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
David dit à Urie: « Descends dans ta maison et lave-toi les pieds. » Urie sortit de la maison du roi, et un présent du roi fut envoyé après lui.
9 Ṣùgbọ́n Uriah sun ní ẹnu-ọ̀nà ilé ọba lọ́dọ̀ gbogbo ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.
Mais Urie se coucha à l'entrée de la maison du roi avec tous les serviteurs de son maître, et il ne descendit pas dans sa maison.
10 Nígbà tí wọ́n sì sọ fún Dafidi pé, “Uriah kò sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀,” Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Ṣe bí ọ̀nà àjò ni ìwọ ti wá? Èéha ti ṣe tí ìwọ kò fi sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ.”
Lorsqu'on eut dit à David: « Urie n'est pas descendu dans sa maison », David dit à Urie: « Ne reviens-tu pas d'un voyage? Pourquoi n'es-tu pas descendu dans ta maison? »
11 Uriah sì wí fún Dafidi pé, “Àpótí ẹ̀rí, àti Israẹli, àti Juda jókòó nínú àgọ́; àti Joabu olúwa mi, àti àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi wà ní ibùdó ní pápá, èmi ó ha lọ sí ilé mi, láti jẹ àti láti mu, àti láti bá obìnrin mi sùn? Bí ìwọ bá wà láààyè, àti bí ẹ̀mí rẹ́ si ti ń bẹ láààyè, èmi kì yóò ṣe nǹkan yìí.”
Urie dit à David: « L'arche, Israël et Juda sont sous des tentes, et mon seigneur Joab et les serviteurs de mon seigneur campent en plein champ. Irai-je donc dans ma maison pour manger et boire, et pour coucher avec ma femme? Aussi longtemps que tu vivras et que ton âme vivra, je ne ferai pas cela! ».
12 Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Sì dúró níhìn-ín lónìí, lọ́la èmi ó sì jẹ́ kí ìwọ ó lọ.” Uriah sì dúró ní Jerusalẹmu ní ọjọ́ náà, àti ọjọ́ kejì.
David dit à Urie: « Reste ici aujourd'hui encore, et demain je te laisserai partir. » Urie resta donc à Jérusalem ce jour-là et le lendemain.
13 Dafidi sì pè é, ó sì jẹ, ó sì mú nítorí rẹ̀; ó sì mu kí ọtí pa á; òun sì jáde ní alẹ́ lọ sí ibùsùn rẹ̀ lọ́dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.
Lorsque David l'eut appelé, il mangea et but en sa présence, et il le fit boire. Le soir, il sortit pour se coucher sur son lit avec les serviteurs de son seigneur, mais il ne descendit pas dans sa maison.
14 Ó sì ṣe ní òwúrọ̀, Dafidi sì kọ̀wé sí Joabu, ó fi rán Uriah.
Le matin, David écrivit une lettre à Joab et l'envoya par la main d'Urie.
15 Ó sì kọ sínú ìwé pé, “Fi Uriah síwájú ibi tí ogun gbé le, kí ẹ sì fàsẹ́yìn, kí wọn lè kọlù ú, kí ó sì kú.”
Il écrivit dans la lettre: « Envoie Urie au premier rang du combat le plus acharné, et retire-toi de lui, afin qu'il soit frappé et qu'il meure. »
16 Ó sì ṣe nígbà tí Joabu ṣe àkíyèsí ìlú náà, ó sì yan Uriah sí ibi kàn ní ibi tí òun mọ̀ pé àwọn alágbára ọkùnrin ń bẹ níbẹ̀.
Joab, qui surveillait la ville, plaça Urie à l'endroit où il savait qu'il y avait des hommes vaillants.
17 Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì jáde wá, wọ́n sì bá Joabu jà, díẹ̀ sì ṣubú nínú àwọn ènìyàn náà nínú àwọn ìránṣẹ́ Dafidi, Uriah ará Hiti sì kú pẹ̀lú.
Les hommes de la ville sortirent et se battirent avec Joab. Une partie du peuple tomba, même des serviteurs de David, et Urie, le Hittite, mourut aussi.
18 Joabu sì ránṣẹ́ ó sì ro gbogbo nǹkan ogun náà fún Dafidi.
Joab envoya raconter à David tout ce qui s'était passé pendant la guerre.
19 Ó sì pàṣẹ fún ìránṣẹ́ náà pé, “Nígbà tí ìwọ bá sì parí àti máa ro gbogbo nǹkan ogun náà fún ọba.
Il donna cet ordre au messager: « Quand tu auras fini de raconter au roi tout ce qui s'est passé pendant la guerre,
20 Bí ó bá ṣe pé, ìbínú ọba bá ru, ti òun sì wí fún ọ pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin fi súnmọ́ ìlú náà láti bá wọn jà, ẹ̀yin kò mọ̀ pé wọn ó tafà láti orí odi wá.
si la colère du roi se manifeste et qu'il te demande: « Pourquoi t'es-tu approché de la ville pour combattre? Ne savais-tu pas qu'on tirerait du haut de la muraille?
21 Ta ni ó pa Abimeleki ọmọ Jerubu-Beṣeti? Kì í ṣe obìnrin ni ó yí òkúta-ọlọ lù ú láti orí odi wá, tí ó sì kú ní Tebesi? Èéha ti rí tí ẹ̀yin fi súnmọ́ odi náà? Ìwọ yóò sì wí fún un pé, Uriah ìránṣẹ́ rẹ ará Hiti kú pẹ̀lú.’”
Qui a frappé Abimélec, fils de Jerubbesheth? Une femme n'a-t-elle pas jeté sur lui, du haut de la muraille, une meule de moulin, de sorte qu'il est mort à Thèbes? Pourquoi t'es-tu approché de la muraille? Tu diras alors: « Ton serviteur Urie, le Héthien, est mort lui aussi ».
22 Ìránṣẹ́ náà sì lọ, ó sì wá, ó sì jẹ́ gbogbo iṣẹ́ tí Joabu rán an fún Dafidi.
Le messager partit, et vint montrer à David tout ce que Joab lui avait envoyé chercher.
23 Ìránṣẹ́ náà sì wí fún Dafidi pé, “Nítòótọ́ àwọn ọkùnrin náà lágbára jù wá lọ, wọ́n sì jáde tọ̀ wá wá ní pápá, àwa sì tẹ̀lé wọn títí wọ́n fi dé ẹ̀yìn odi.
Le messager dit à David: « Les hommes ont eu raison de nous, ils sont sortis dans les champs, et nous les avons poursuivis jusqu'à l'entrée de la porte.
24 Àwọn tafàtafà sì ta sí ìránṣẹ́ rẹ láti orí odi wá, díẹ̀ nínú àwọn ìránṣẹ́ ọba sì kú, ìránṣẹ́ rẹ̀ Uriah ará Hiti sì kú pẹ̀lú.”
Les tireurs ont tiré sur tes serviteurs du côté de la muraille; certains des serviteurs du roi sont morts, et ton serviteur Urie le Hittite est également mort. »
25 Dafidi sì wí fún ìránṣẹ́ náà pé, “Báyìí ni ìwọ yóò wí fún Joabu pé, ‘Má ṣe jẹ́ kí nǹkan yìí burú ní ojú rẹ, nítorí pé idà a máa pa lọ́tùn ún lósì, mú ìjà rẹ le sí ìlú náà, kí o sì bì í ṣubú.’ Kí ìwọ sì mú un lọ́kàn le.”
David dit au messager: « Dis à Joab: « Que cela ne te déplaise, car l'épée dévore aussi bien les uns que les autres. Fortifie ton combat contre la ville, et renverse-la ». Encourage-le. »
26 Nígbà tí aya Uriah sì gbọ́ pé Uriah ọkọ rẹ̀ kú, ó sì ṣọ̀fọ̀ nítorí ọkọ rẹ̀.
Lorsque la femme d'Urie apprit qu'Urie, son mari, était mort, elle porta le deuil de son mari.
27 Nígbà tí ìṣọ̀fọ̀ náà sì kọjá tan, Dafidi sì ránṣẹ́, o sì mú un wá sí ilé rẹ̀, ó sì di aya rẹ̀, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un, ṣùgbọ́n nǹkan náà tí Dafidi ṣe burú níwájú Olúwa.
Lorsque le deuil fut terminé, David l'envoya chercher et la prit dans sa maison; elle devint sa femme et lui donna un fils. Mais ce que David avait fait déplut à Yahvé.

< 2 Samuel 11 >