< 2 Samuel 10 >

1 Ó sì ṣe lẹ́yìn èyí, ọba àwọn ará Ammoni sì kú, Hanuni ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Și s-a întâmplat după aceasta, că împăratul copiilor lui Amon a murit și Hanun, fiul său, a domnit în locul său.
2 Dafidi sì wí pé, “Èmi yóò ṣe oore fún Hanuni ọmọ Nahaṣi gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ sì ti ṣe oore fún mi.” Dafidi sì ránṣẹ́ láti tù Hanuni nínú láti ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wá, nítorí ti baba rẹ̀. Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì wá sí ilé àwọn ọmọ Ammoni.
Atunci David a spus: Voi arăta bunătate lui Hanun, fiul lui Nahaș, precum tatăl său mi-a arătat mie bunătate. Și David a trimis să îl mângâie prin servitorii săi pentru tatăl său. Și servitorii lui David au venit în țara copiilor lui Amon.
3 Àwọn olórí àwọn ọmọ Ammoni sì wí fún Hanuni olúwa wọn pé, “Ǹjẹ́ o rò pé Dafidi ń bu ọlá fún baba rẹ nígbà tí ó rán ènìyàn wá láti bá ọ kẹ́dùn? Kò ha ṣe pé Dafidi rán àwọn ìránṣẹ́ sí ọ láti wo ìlú àti láti yọ́ ọ wò àti láti gbà ọ́.”
Și prinții copiilor lui Amon i-au spus lui Hanun, domnul lor: Gândești tu că David onorează pe tatăl tău, că a trimis mângâietori la tine? Nu a trimis David mai degrabă pe servitorii săi la tine ca să cerceteze cetatea și să o spioneze și să o dărâme?
4 Hanuni sì mú àwọn ìránṣẹ́ Dafidi ó fá apá kan irùngbọ̀n wọn, ó sì gé ààbọ̀ kúrò ní agbádá wọn, títí ó fi dé ìdí wọn, ó sì rán wọn lọ.
De aceea Hanun i-a luat pe servitorii lui David și le-a ras bărbile pe jumătate și le-a tăiat hainele la mijloc, până la fese, și i-a trimis.
5 Wọ́n sì sọ fún Dafidi, ó sì ránṣẹ́ lọ pàdé wọn, nítorí tí ojú ti àwọn ọkùnrin náà púpọ̀: ọba sì wí pé, “Ẹ dúró ní Jeriko títí irùngbọ̀n yín yóò fi hù, nígbà náà ni kí ẹ tó máa bọ̀.”
Când i-au spus aceasta lui David, el a trimis să îi întâlnească, deoarece oamenii erau foarte rușinați; și împăratul a spus: Rămâneți la Ierihon până vă cresc bărbile și apoi întoarceți-vă.
6 Àwọn ará Ammoni sì ri pé, wọ́n di ẹni ìríra níwájú Dafidi, àwọn ọmọ Ammoni sì ránṣẹ́, wọ́n sì fi owó bẹ́ ogún àwọn ará Siria ti Beti-Rehobu; àti Siria-Soba, ogún ẹgbẹ̀rún ẹlẹ́ṣẹ̀ àti ti ọba Maaka, ẹgbẹ̀rún ọkùnrin àti ti Tobu ẹgbàá mẹ́fà ọkùnrin lọ́wẹ̀.
Și când copiii lui Amon au văzut că s-au împuțit înaintea lui David, copiii lui Amon au trimis și au angajat pe sirienii din Bet-Rehob și pe sirienii din Țoba, douăzeci de mii de pedeștri, și de la împăratul Maaca, o mie de bărbați, și din Iștob, douăsprezece mii de bărbați.
7 Dafidi sì gbọ́, ó sì rán Joabu, àti gbogbo ogún àwọn ọkùnrin alágbára.
Și când David a auzit de aceasta, l-a trimis pe Ioab și toată oștirea războinicilor.
8 Àwọn ọmọ Ammoni sì jáde wá, wọ́n sì tẹ́ ogun ní ẹnu odi; ará Siria-Soba, àti ti Rehobu, àti Tobu, àti Maaka, wọ́n sì tẹ ogun ni pápá fún ara wọn.
Și copiii lui Amon au ieșit și s-au desfășurat pentru bătălie la intrarea porții; și sirienii din Țoba și din Rehob și Iștob și Maaca, erau singuri pe câmp.
9 Nígbà tí Joabu sì rí i pé ogun náà dojúkọ òun níwájú àti lẹ́yìn, ó sì yàn nínú gbogbo àwọn akíkanjú ọkùnrin ní Israẹli, ó sì tẹ́ ogun kọjú sí àwọn ará Siria.
Când Ioab a văzut că frontul bătăliei era împotriva lui dinainte și dinapoi, a ales din toți bărbații aleși ai lui Israel și i-a desfășurat împotriva sirienilor;
10 Ó sì fi àwọn ènìyàn tí ó kù lé Abiṣai àbúrò rẹ̀ lọ́wọ́, kí ó lè tẹ ogun kọjú sí àwọn ọmọ Ammoni.
Și restul poporului l-a dat în mâna lui Abișai, fratele său, ca să îi desfășoare împotriva copiilor lui Amon.
11 Ó sì wí pé, “Bí agbára àwọn ará Siria bá pọ̀ ju èmi lọ, ìwọ yóò sì wá ràn mí lọ́wọ́, ṣùgbọ́n bí ọwọ́ àwọn ọmọ Ammoni bá sì pọ̀jù ọ́ lọ, èmi ó sì wá ràn ọ́ lọ́wọ́.
Și a spus: Dacă sirienii sunt prea tari pentru mine, atunci tu să mă ajuți; dar dacă fiii lui Amon sunt prea tari pentru tine, atunci eu voi veni și te voi ajuta.
12 Mú ọkàn lè, jẹ́ kí a ṣe onígboyà nítorí àwọn ènìyàn wa, àti nítorí àwọn ìlú Ọlọ́run wa; Olúwa yóò sì ṣe èyí tí ó dára lójú rẹ̀.”
Încurajează-te și să fim bărbați pentru poporul nostru și pentru cetățile Dumnezeului nostru; și DOMNUL să facă ce îi pare bine.
13 Joabu àti àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì bá àwọn ará Siria pàdé ìjà, wọ́n sì sá níwájú rẹ̀.
Și Ioab și poporul care era cu el s-au apropiat să lupte împotriva sirienilor; iar ei au fugit dinaintea lui.
14 Nígbà tí àwọn ọmọ Ammoni sì rí i pé àwọn ará Siria sá, àwọn pẹ̀lú sì sá níwájú Abiṣai, wọ́n sì wọ inú ìlú lọ. Joabu sì padà kúrò lẹ́yìn àwọn ọmọ Ammoni, ó sì wá sí Jerusalẹmu.
Și când copiii lui Amon au văzut că sirienii fugiseră, atunci au fugit și ei dinaintea lui Abișai și au intrat în cetate. Astfel Ioab s-a întors de la copiii lui Amon și a venit la Ierusalim.
15 Nígbà tí àwọn ará Siria sì rí i pé àwọn ṣubú níwájú Israẹli, wọ́n sì kó ara wọn jọ
Și când sirienii au văzut că au fost loviți înaintea lui Israel, s-au adunat împreună.
16 Hadadeseri sì ránṣẹ́, ó sì mú àwọn Siria tí ó wà ní òkè odò Eufurate jáde wá, wọ́n sì wá sí Helami; Sobaki olórí ogun Hadadeseri sì ṣe olórí wọn.
Și Hadadezer a trimis și i-a scos pe sirienii care erau dincolo de râu; și au venit la Helam; și Șobac, căpetenia oștirii lui Hadadezer, mergea în fruntea lor.
17 Nígbà tí a sọ fún Dafidi, ó sì kó gbogbo Israẹli jọ, wọ́n sì kọjá Jordani, wọ́n sì wá sí Helami, àwọn ará Siria sì tẹ́ ogun kọjú sí Dafidi, wọ́n sì bá a jà.
Și când i s-a spus lui David, el a adunat tot Israelul și a trecut Iordanul și a venit la Helam. Și sirienii s-au desfășurat împotriva lui David și au luptat cu el.
18 Àwọn ará Siria sì sá níwájú Israẹli, Dafidi sì pa nínú àwọn ará Siria ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin àwọn oníkẹ̀kẹ́, àti ọ̀kẹ́ méjì ẹlẹ́ṣin, wọ́n sì kọlu Sobaki olórí ogun wọn, ó sì kú níbẹ̀.
Și sirienii au fugit dinaintea lui Israel; și David a ucis șapte sute de conducători de care dintr-ai sirienilor și patruzeci de mii de călăreți și a lovit pe Șobac, căpetenia oștirii lor, care a murit acolo.
19 Nígbà tí gbogbo àwọn ọba tí ó wà lábẹ́ Hadadeseri sì rí i pé wọ́n di bíbì ṣubú níwájú Israẹli, wọ́n sì bá Israẹli làjà, wọ́n sì ń sìn wọ́n. Àwọn ará Siria sì bẹ̀rù láti máa ran àwọn ọmọ Ammoni lọ́wọ́ mọ́.
Și când toți împărații care erau servitori lui Hadadezer au văzut că erau loviți înaintea lui Israel, au făcut pace cu Israel și le-au servit. Astfel sirienii s-au temut să îi mai ajute pe copiii lui Amon.

< 2 Samuel 10 >