< 2 Samuel 10 >
1 Ó sì ṣe lẹ́yìn èyí, ọba àwọn ará Ammoni sì kú, Hanuni ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Un pēc tam Amona bērnu ķēniņš nomira, un viņa dēls Anons palika par ķēniņu viņa vietā.
2 Dafidi sì wí pé, “Èmi yóò ṣe oore fún Hanuni ọmọ Nahaṣi gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ sì ti ṣe oore fún mi.” Dafidi sì ránṣẹ́ láti tù Hanuni nínú láti ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wá, nítorí ti baba rẹ̀. Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì wá sí ilé àwọn ọmọ Ammoni.
Tad Dāvids sacīja: es darīšu žēlastību pie Anona, Nahasa dēla, tā kā viņa tēvs žēlastību darījis pie manis. Un Dāvids nosūtīja un lika viņu iepriecināt caur saviem kalpiem par viņa tēvu; un Dāvida kalpi nāca uz Amona bērnu zemi.
3 Àwọn olórí àwọn ọmọ Ammoni sì wí fún Hanuni olúwa wọn pé, “Ǹjẹ́ o rò pé Dafidi ń bu ọlá fún baba rẹ nígbà tí ó rán ènìyàn wá láti bá ọ kẹ́dùn? Kò ha ṣe pé Dafidi rán àwọn ìránṣẹ́ sí ọ láti wo ìlú àti láti yọ́ ọ wò àti láti gbà ọ́.”
Tad Amona bērnu lielkungi sacīja uz savu kungu Anonu: vai Dāvids tavu tēvu godina tavās acīs, ka viņš ir sūtījis iepriecinātājus pie tevis? Vai Dāvids savus kalpus nav tāpēc sūtījis pie tevis, ka viņš šo pilsētu izklausa un izlūko un izposta?
4 Hanuni sì mú àwọn ìránṣẹ́ Dafidi ó fá apá kan irùngbọ̀n wọn, ó sì gé ààbọ̀ kúrò ní agbádá wọn, títí ó fi dé ìdí wọn, ó sì rán wọn lọ.
Tad Anons ņēma Dāvida kalpus un tiem nodzina pusbārdu un tiem nogrieza vienu drēbju pusi līdz pašiem gurniem un tos atlaida.
5 Wọ́n sì sọ fún Dafidi, ó sì ránṣẹ́ lọ pàdé wọn, nítorí tí ojú ti àwọn ọkùnrin náà púpọ̀: ọba sì wí pé, “Ẹ dúró ní Jeriko títí irùngbọ̀n yín yóò fi hù, nígbà náà ni kí ẹ tó máa bọ̀.”
Kad tas nu Dāvidam tapa zināms, tad viņš tiem sūtīja pretī, jo šie vīri bija ļoti apsmieti. Un ķēniņš tiem lika sacīt: palieciet Jērikū, tiekams jūsu bārda būs ataugusi, un tad nāciet atpakaļ.
6 Àwọn ará Ammoni sì ri pé, wọ́n di ẹni ìríra níwájú Dafidi, àwọn ọmọ Ammoni sì ránṣẹ́, wọ́n sì fi owó bẹ́ ogún àwọn ará Siria ti Beti-Rehobu; àti Siria-Soba, ogún ẹgbẹ̀rún ẹlẹ́ṣẹ̀ àti ti ọba Maaka, ẹgbẹ̀rún ọkùnrin àti ti Tobu ẹgbàá mẹ́fà ọkùnrin lọ́wẹ̀.
Kad nu Amona bērni redzēja, ka tie bija palikuši smirdoši pie Dāvida, tad Amona bērni nosūtīja un saderēja no BetRekabas Sīriešiem un no Cobas Sīriešiem divdesmit tūkstoš kājniekus un no Maākas ķēniņa tūkstoš vīrus un no Tobas vīriem divpadsmit tūkstoš vīrus.
7 Dafidi sì gbọ́, ó sì rán Joabu, àti gbogbo ogún àwọn ọkùnrin alágbára.
Kad Dāvids to dzirdēja, tad viņš sūtīja Joabu un visu to vareno karaspēku.
8 Àwọn ọmọ Ammoni sì jáde wá, wọ́n sì tẹ́ ogun ní ẹnu odi; ará Siria-Soba, àti ti Rehobu, àti Tobu, àti Maaka, wọ́n sì tẹ ogun ni pápá fún ara wọn.
Un Amona bērni izgāja un taisījās uz kaušanos vārtu priekšā, bet tie Sīrieši no Cobas un Rekabas un tie vīri no Tobas un Maākas bija vieni paši savrup laukā.
9 Nígbà tí Joabu sì rí i pé ogun náà dojúkọ òun níwájú àti lẹ́yìn, ó sì yàn nínú gbogbo àwọn akíkanjú ọkùnrin ní Israẹli, ó sì tẹ́ ogun kọjú sí àwọn ará Siria.
Kad nu Joabs redzēja, ka karš pret viņu taisījās no priekšas un no aizmugures, tad viņš izlasīja no visiem jauniem Israēla vīriem un nostājās Sīriešiem pretī.
10 Ó sì fi àwọn ènìyàn tí ó kù lé Abiṣai àbúrò rẹ̀ lọ́wọ́, kí ó lè tẹ ogun kọjú sí àwọn ọmọ Ammoni.
Un tos citus ļaudis viņš deva savam brālim Abizajum rokā, un tas nostājās pret Amona bērniem. Un viņš sacīja:
11 Ó sì wí pé, “Bí agbára àwọn ará Siria bá pọ̀ ju èmi lọ, ìwọ yóò sì wá ràn mí lọ́wọ́, ṣùgbọ́n bí ọwọ́ àwọn ọmọ Ammoni bá sì pọ̀jù ọ́ lọ, èmi ó sì wá ràn ọ́ lọ́wọ́.
Ja Sīrieši būs stiprāki nekā es, tad nāc tu man palīgā, bet ja Amona bērni būs stiprāki nekā tu, tad es tev iešu palīgā.
12 Mú ọkàn lè, jẹ́ kí a ṣe onígboyà nítorí àwọn ènìyàn wa, àti nítorí àwọn ìlú Ọlọ́run wa; Olúwa yóò sì ṣe èyí tí ó dára lójú rẹ̀.”
Turies stipri un lai stipri stāvam priekš mūsu ļaudīm un priekš mūsu Dieva pilsētām, bet Tas Kungs lai dara, kā Viņam labi patīk.
13 Joabu àti àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì bá àwọn ará Siria pàdé ìjà, wọ́n sì sá níwájú rẹ̀.
Un Joabs ar tiem ļaudīm, kas pie viņa bija, gāja kauties Sīriešiem virsū, bet šie bēga viņa priekšā.
14 Nígbà tí àwọn ọmọ Ammoni sì rí i pé àwọn ará Siria sá, àwọn pẹ̀lú sì sá níwájú Abiṣai, wọ́n sì wọ inú ìlú lọ. Joabu sì padà kúrò lẹ́yìn àwọn ọmọ Ammoni, ó sì wá sí Jerusalẹmu.
Un kad Amona bērni to redzēja, ka Sīrieši bēga, tad tie arīdzan bēga Abizajus priekšā un nāca pilsētā, un Joabs griezās atpakaļ no Amona bērniem un nāca uz Jeruzālemi.
15 Nígbà tí àwọn ará Siria sì rí i pé àwọn ṣubú níwájú Israẹli, wọ́n sì kó ara wọn jọ
Kad nu Sīrieši redzēja, ka Israēla priekšā bija sakauti, tad tie atkal sapulcējās.
16 Hadadeseri sì ránṣẹ́, ó sì mú àwọn Siria tí ó wà ní òkè odò Eufurate jáde wá, wọ́n sì wá sí Helami; Sobaki olórí ogun Hadadeseri sì ṣe olórí wọn.
Un HadadEzers nosūtīja un lika tiem Sīriešiem nākt, kas bija viņpus upes, un tie nāca uz Elamu, un Zobaks, HadadEzera kara lielskungs, gāja viņu priekšā.
17 Nígbà tí a sọ fún Dafidi, ó sì kó gbogbo Israẹli jọ, wọ́n sì kọjá Jordani, wọ́n sì wá sí Helami, àwọn ará Siria sì tẹ́ ogun kọjú sí Dafidi, wọ́n sì bá a jà.
Kad tas Dāvidam tapa sacīts, tad viņš sapulcināja visu Israēli un pārgāja pār Jardāni un nāca uz Elamu, un Sīrieši nostājās Dāvidam pretī un ar to kāvās.
18 Àwọn ará Siria sì sá níwájú Israẹli, Dafidi sì pa nínú àwọn ará Siria ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin àwọn oníkẹ̀kẹ́, àti ọ̀kẹ́ méjì ẹlẹ́ṣin, wọ́n sì kọlu Sobaki olórí ogun wọn, ó sì kú níbẹ̀.
Bet Sīrieši bēga Israēla priekšā, un Dāvids nokāva no Sīriešiem septiņsimt ratus un četrdesmit tūkstoš jātniekus; viņš sita arī Zobaku, viņu kara lielkungu, ka tas tur nomira.
19 Nígbà tí gbogbo àwọn ọba tí ó wà lábẹ́ Hadadeseri sì rí i pé wọ́n di bíbì ṣubú níwájú Israẹli, wọ́n sì bá Israẹli làjà, wọ́n sì ń sìn wọ́n. Àwọn ará Siria sì bẹ̀rù láti máa ran àwọn ọmọ Ammoni lọ́wọ́ mọ́.
Kad nu visi ķēniņi, kas bija HadadEzera kalpi, redzēja, ka bija sakauti Israēla priekšā, tad tie derēja mieru ar Israēli un viņam kalpoja, un Sīrieši bijās, uz priekšu nākt palīgā Amona bērniem.