< 2 Samuel 10 >

1 Ó sì ṣe lẹ́yìn èyí, ọba àwọn ará Ammoni sì kú, Hanuni ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Forsothe it was doon aftir these thingis, that Naas, kyng of the sones of Amon, diede; and Anoon, his sone, regnede for hym. And Dauid seide,
2 Dafidi sì wí pé, “Èmi yóò ṣe oore fún Hanuni ọmọ Nahaṣi gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ sì ti ṣe oore fún mi.” Dafidi sì ránṣẹ́ láti tù Hanuni nínú láti ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wá, nítorí ti baba rẹ̀. Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì wá sí ilé àwọn ọmọ Ammoni.
Y schal do mercy with Anon, the sone of Naas, as his fadir dide mercy with me. Therfor Dauid sente coumfortynge hym by hise seruauntis on the deeth of the fadir. Sotheli whanne the seruauntis of Dauid hadden come in to the lond of the sones of Amon,
3 Àwọn olórí àwọn ọmọ Ammoni sì wí fún Hanuni olúwa wọn pé, “Ǹjẹ́ o rò pé Dafidi ń bu ọlá fún baba rẹ nígbà tí ó rán ènìyàn wá láti bá ọ kẹ́dùn? Kò ha ṣe pé Dafidi rán àwọn ìránṣẹ́ sí ọ láti wo ìlú àti láti yọ́ ọ wò àti láti gbà ọ́.”
princes of the sones of Amon seiden to Anon, her lord, Gessist thou that for the onour of thi fadir Dauid sente coumfortouris to thee; and not herfor Dauid sente hise seruauntis to thee, that he schulde aspie, and enserche the citee, and distrie it?
4 Hanuni sì mú àwọn ìránṣẹ́ Dafidi ó fá apá kan irùngbọ̀n wọn, ó sì gé ààbọ̀ kúrò ní agbádá wọn, títí ó fi dé ìdí wọn, ó sì rán wọn lọ.
Therfor Anoon took the seruauntis of Dauid, and schauyde half the part of `the beerd of hem, and he kittide awey the myddil clothis of hem `til to the buttokis; and lefte hem.
5 Wọ́n sì sọ fún Dafidi, ó sì ránṣẹ́ lọ pàdé wọn, nítorí tí ojú ti àwọn ọkùnrin náà púpọ̀: ọba sì wí pé, “Ẹ dúró ní Jeriko títí irùngbọ̀n yín yóò fi hù, nígbà náà ni kí ẹ tó máa bọ̀.”
And whanne this was teld to Dauid, he sente in to the comyng of hem, for the men weren schent ful vilensly. And Dauid comaundide to hem, Dwelle ye in Jerico, til youre beerd wexe, and thanne turne ye ayen.
6 Àwọn ará Ammoni sì ri pé, wọ́n di ẹni ìríra níwájú Dafidi, àwọn ọmọ Ammoni sì ránṣẹ́, wọ́n sì fi owó bẹ́ ogún àwọn ará Siria ti Beti-Rehobu; àti Siria-Soba, ogún ẹgbẹ̀rún ẹlẹ́ṣẹ̀ àti ti ọba Maaka, ẹgbẹ̀rún ọkùnrin àti ti Tobu ẹgbàá mẹ́fà ọkùnrin lọ́wẹ̀.
Sotheli the sones of Amon sien, that thei hadden do wrong to Dauid, and thei senten, and hiriden bi meede Roob of Sirye, and Soba of Sirie, twenti thousynde of foot men, and of kyng Maacha, a thousynde men, and of Istob twelue thousynde of men.
7 Dafidi sì gbọ́, ó sì rán Joabu, àti gbogbo ogún àwọn ọkùnrin alágbára.
And whanne Dauid hadde herd this, he sent Joab and al the oost of fiyteris.
8 Àwọn ọmọ Ammoni sì jáde wá, wọ́n sì tẹ́ ogun ní ẹnu odi; ará Siria-Soba, àti ti Rehobu, àti Tobu, àti Maaka, wọ́n sì tẹ ogun ni pápá fún ara wọn.
Therfor the sones of Amon yeden out, and dressiden scheltrun bifor hem in the entryng of the yate. Forsothe Soba, and Roob of Sirie, and Istob, and Maacha weren asidis half in the feeld.
9 Nígbà tí Joabu sì rí i pé ogun náà dojúkọ òun níwájú àti lẹ́yìn, ó sì yàn nínú gbogbo àwọn akíkanjú ọkùnrin ní Israẹli, ó sì tẹ́ ogun kọjú sí àwọn ará Siria.
Therfor Joab siy, that batel was maad redi ayens hym, bothe euene ayens and bihynde the bak; and he chees to hym silf of alle the chosun men of Israel, and ordeynede scheltrun ayens Sirus.
10 Ó sì fi àwọn ènìyàn tí ó kù lé Abiṣai àbúrò rẹ̀ lọ́wọ́, kí ó lè tẹ ogun kọjú sí àwọn ọmọ Ammoni.
Forsothe he bitook to Abisai, his brothir, the tother part of the puple, which dresside scheltrun ayens the sones of Amon.
11 Ó sì wí pé, “Bí agbára àwọn ará Siria bá pọ̀ ju èmi lọ, ìwọ yóò sì wá ràn mí lọ́wọ́, ṣùgbọ́n bí ọwọ́ àwọn ọmọ Ammoni bá sì pọ̀jù ọ́ lọ, èmi ó sì wá ràn ọ́ lọ́wọ́.
And Joab seide, If men of Sirie han the maistrie ayens me, thou schalt be to me in to help; sotheli if the sones of Amon han the maistrie ayens thee, Y schal helpe thee;
12 Mú ọkàn lè, jẹ́ kí a ṣe onígboyà nítorí àwọn ènìyàn wa, àti nítorí àwọn ìlú Ọlọ́run wa; Olúwa yóò sì ṣe èyí tí ó dára lójú rẹ̀.”
be thou a strong man, and fiyte we for oure puple, and for the citee of oure God; forsothe the Lord schal do that, that is good in his siyt.
13 Joabu àti àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì bá àwọn ará Siria pàdé ìjà, wọ́n sì sá níwájú rẹ̀.
Therfor Joab and his puple that was with hym, bigan batel ayens men of Sirie, whiche fledden anoon fro his face.
14 Nígbà tí àwọn ọmọ Ammoni sì rí i pé àwọn ará Siria sá, àwọn pẹ̀lú sì sá níwájú Abiṣai, wọ́n sì wọ inú ìlú lọ. Joabu sì padà kúrò lẹ́yìn àwọn ọmọ Ammoni, ó sì wá sí Jerusalẹmu.
Forsothe the sones of Amon sien, that men of Sirie hadden fled; and thei fledden also fro the face of Abisai, and entriden in to the citee; and Joab turnede ayen fro the sones of Amon, and cam in to Jerusalem.
15 Nígbà tí àwọn ará Siria sì rí i pé àwọn ṣubú níwájú Israẹli, wọ́n sì kó ara wọn jọ
Forsothe men of Sirye sien that thei hadden feld bifor Israel, and thei weren gaderid to gidere.
16 Hadadeseri sì ránṣẹ́, ó sì mú àwọn Siria tí ó wà ní òkè odò Eufurate jáde wá, wọ́n sì wá sí Helami; Sobaki olórí ogun Hadadeseri sì ṣe olórí wọn.
And Adadezer sente, and ledde out men of Sirie that weren biyende the flood, and he brouyte the oost of hem; sotheli Sobach, mayster of the chyualrie of Adadezer, was the prince of hem.
17 Nígbà tí a sọ fún Dafidi, ó sì kó gbogbo Israẹli jọ, wọ́n sì kọjá Jordani, wọ́n sì wá sí Helami, àwọn ará Siria sì tẹ́ ogun kọjú sí Dafidi, wọ́n sì bá a jà.
And whanne this was teld to Dauid, he drow togidere al Israel, and passide Jordan, and cam in to Helama. And men of Sirie dressiden scheltrun ayens Dauid, and fouyten ayens hym.
18 Àwọn ará Siria sì sá níwájú Israẹli, Dafidi sì pa nínú àwọn ará Siria ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin àwọn oníkẹ̀kẹ́, àti ọ̀kẹ́ méjì ẹlẹ́ṣin, wọ́n sì kọlu Sobaki olórí ogun wọn, ó sì kú níbẹ̀.
And Sireis fledden fro the face of Israel; and Dauid killide of Sireis seuene hundrid charis, and fourti thousynde of knyytis; and he smoot Sobach, the prince of chyualrie, which was deed anoon.
19 Nígbà tí gbogbo àwọn ọba tí ó wà lábẹ́ Hadadeseri sì rí i pé wọ́n di bíbì ṣubú níwájú Israẹli, wọ́n sì bá Israẹli làjà, wọ́n sì ń sìn wọ́n. Àwọn ará Siria sì bẹ̀rù láti máa ran àwọn ọmọ Ammoni lọ́wọ́ mọ́.
Forsothe alle kyngis, that weren in the help of Adadezer, siyen that thei weren ouercomun of Israel, and thei maden pees with Israel, and serueden hem; and Sireis dredden to yyue help to the sones of Amon.

< 2 Samuel 10 >