< 2 Samuel 10 >

1 Ó sì ṣe lẹ́yìn èyí, ọba àwọn ará Ammoni sì kú, Hanuni ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
After this, the King of the children of Ammon dyed, and Hanun his sonne reigned in his steade.
2 Dafidi sì wí pé, “Èmi yóò ṣe oore fún Hanuni ọmọ Nahaṣi gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ sì ti ṣe oore fún mi.” Dafidi sì ránṣẹ́ láti tù Hanuni nínú láti ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wá, nítorí ti baba rẹ̀. Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì wá sí ilé àwọn ọmọ Ammoni.
Then sayde Dauid, I will shewe kindnesse vnto Hanun the sonne of Nahash, as his father shewed kindnesse vnto me. And Dauid sent his seruantes to comfort him for his father. So Dauids seruants came into the lande of the children of Ammon.
3 Àwọn olórí àwọn ọmọ Ammoni sì wí fún Hanuni olúwa wọn pé, “Ǹjẹ́ o rò pé Dafidi ń bu ọlá fún baba rẹ nígbà tí ó rán ènìyàn wá láti bá ọ kẹ́dùn? Kò ha ṣe pé Dafidi rán àwọn ìránṣẹ́ sí ọ láti wo ìlú àti láti yọ́ ọ wò àti láti gbà ọ́.”
And the princes of the children of Ammon sayde vnto Hanun their lorde, Thinkest thou that Dauid doth honour thy father, that he hath sent comforters to thee? hath not Dauid rather sent his seruants vnto thee, to search the citie, and to spie it out, and to ouerthrow it?
4 Hanuni sì mú àwọn ìránṣẹ́ Dafidi ó fá apá kan irùngbọ̀n wọn, ó sì gé ààbọ̀ kúrò ní agbádá wọn, títí ó fi dé ìdí wọn, ó sì rán wọn lọ.
Wherefore Hanun tooke Dauids seruants, and shaued off the halfe of their beard, and cut off their garments in the middle, euen to their buttockes, and sent them away.
5 Wọ́n sì sọ fún Dafidi, ó sì ránṣẹ́ lọ pàdé wọn, nítorí tí ojú ti àwọn ọkùnrin náà púpọ̀: ọba sì wí pé, “Ẹ dúró ní Jeriko títí irùngbọ̀n yín yóò fi hù, nígbà náà ni kí ẹ tó máa bọ̀.”
When it was told vnto Dauid, he sent to meete them (for the men were exceedingly ashamed) and the King sayde, Tary at Iericho, vntill your beards be growen, then returne.
6 Àwọn ará Ammoni sì ri pé, wọ́n di ẹni ìríra níwájú Dafidi, àwọn ọmọ Ammoni sì ránṣẹ́, wọ́n sì fi owó bẹ́ ogún àwọn ará Siria ti Beti-Rehobu; àti Siria-Soba, ogún ẹgbẹ̀rún ẹlẹ́ṣẹ̀ àti ti ọba Maaka, ẹgbẹ̀rún ọkùnrin àti ti Tobu ẹgbàá mẹ́fà ọkùnrin lọ́wẹ̀.
And when the children of Ammon sawe that they stanke in the sight of Dauid, the children of Ammon sent and hired the Aramites of the house of Rehob, and the Aramites of Zoba, twentie thousande footemen, and of King Maacah a thousand men, and of Ish-tob twelue thousande men.
7 Dafidi sì gbọ́, ó sì rán Joabu, àti gbogbo ogún àwọn ọkùnrin alágbára.
And when Dauid heard of it, he sent Ioab, and all the hoste of the strong men.
8 Àwọn ọmọ Ammoni sì jáde wá, wọ́n sì tẹ́ ogun ní ẹnu odi; ará Siria-Soba, àti ti Rehobu, àti Tobu, àti Maaka, wọ́n sì tẹ ogun ni pápá fún ara wọn.
And the children of Ammon came out, and put their armie in araye at the entring in of the gate: and the Aramites of Zoba, and of Rehob, and of Ish-tob, and of Maacah were by themselues in the fielde.
9 Nígbà tí Joabu sì rí i pé ogun náà dojúkọ òun níwájú àti lẹ́yìn, ó sì yàn nínú gbogbo àwọn akíkanjú ọkùnrin ní Israẹli, ó sì tẹ́ ogun kọjú sí àwọn ará Siria.
When Ioab saw that the front of the battel was against him before and behinde, he chose of all the choyse of Israel, and put them in aray against the Aramites.
10 Ó sì fi àwọn ènìyàn tí ó kù lé Abiṣai àbúrò rẹ̀ lọ́wọ́, kí ó lè tẹ ogun kọjú sí àwọn ọmọ Ammoni.
And the rest of the people hee deliuered into the hande of Abishai his brother, that hee might put them in aray against the children of Ammon.
11 Ó sì wí pé, “Bí agbára àwọn ará Siria bá pọ̀ ju èmi lọ, ìwọ yóò sì wá ràn mí lọ́wọ́, ṣùgbọ́n bí ọwọ́ àwọn ọmọ Ammoni bá sì pọ̀jù ọ́ lọ, èmi ó sì wá ràn ọ́ lọ́wọ́.
And he sayde, If the Aramites be stronger then I, thou shalt helpe me, and if the children of Ammon be too strong for thee, I will come and succour thee.
12 Mú ọkàn lè, jẹ́ kí a ṣe onígboyà nítorí àwọn ènìyàn wa, àti nítorí àwọn ìlú Ọlọ́run wa; Olúwa yóò sì ṣe èyí tí ó dára lójú rẹ̀.”
Be strong and let vs be valiant for our people, and for the cities of our God, and let the Lord do that which is good in his eyes.
13 Joabu àti àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì bá àwọn ará Siria pàdé ìjà, wọ́n sì sá níwájú rẹ̀.
Then Ioab, and the people that was with him, ioyned in battel with the Aramites, who fled before him.
14 Nígbà tí àwọn ọmọ Ammoni sì rí i pé àwọn ará Siria sá, àwọn pẹ̀lú sì sá níwájú Abiṣai, wọ́n sì wọ inú ìlú lọ. Joabu sì padà kúrò lẹ́yìn àwọn ọmọ Ammoni, ó sì wá sí Jerusalẹmu.
And when the children of Ammon sawe that the Aramites fled, they fled also before Abishai, and entred into the citie. so Ioab returned from the children of Ammon, and came to Ierusalem.
15 Nígbà tí àwọn ará Siria sì rí i pé àwọn ṣubú níwájú Israẹli, wọ́n sì kó ara wọn jọ
And when the Aramites sawe that they were smitten before Israel, they gathered them together.
16 Hadadeseri sì ránṣẹ́, ó sì mú àwọn Siria tí ó wà ní òkè odò Eufurate jáde wá, wọ́n sì wá sí Helami; Sobaki olórí ogun Hadadeseri sì ṣe olórí wọn.
And Hadarezer sent, and brought out the Aramites that were beyond the Riuer: and they came to Helam, and Shobach the captaine of the hoste of Hadarezer went before them.
17 Nígbà tí a sọ fún Dafidi, ó sì kó gbogbo Israẹli jọ, wọ́n sì kọjá Jordani, wọ́n sì wá sí Helami, àwọn ará Siria sì tẹ́ ogun kọjú sí Dafidi, wọ́n sì bá a jà.
When it was shewed Dauid, then he gathered all Israel together, and passed ouer Iorden and came to Helam: and the Aramites set themselues in aray against Dauid, and fought with him:
18 Àwọn ará Siria sì sá níwájú Israẹli, Dafidi sì pa nínú àwọn ará Siria ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin àwọn oníkẹ̀kẹ́, àti ọ̀kẹ́ méjì ẹlẹ́ṣin, wọ́n sì kọlu Sobaki olórí ogun wọn, ó sì kú níbẹ̀.
And the Aramites fled before Israel: and Dauid destroyed seuen hundreth charets of the Aramites, and fourtie thousande horsemen, and smote Shobach the captaine of his hoste, who dyed there.
19 Nígbà tí gbogbo àwọn ọba tí ó wà lábẹ́ Hadadeseri sì rí i pé wọ́n di bíbì ṣubú níwájú Israẹli, wọ́n sì bá Israẹli làjà, wọ́n sì ń sìn wọ́n. Àwọn ará Siria sì bẹ̀rù láti máa ran àwọn ọmọ Ammoni lọ́wọ́ mọ́.
And when all the Kings, that were seruants to Hadarezer, saw that they fell before Israel, they made peace with Israel, and serued them. and the Aramites feared to helpe the children of Ammon any more.

< 2 Samuel 10 >