< 2 Samuel 1 >

1 Lẹ́yìn ikú Saulu, Dafidi ti ibi tí ó ti ṣẹ́gun àwọn ará Amaleki bọ̀, ó sì dúró ní Siklagi ní ọjọ́ méjì.
And it comes to pass after the death of Saul, that David has returned from striking the Amalekite, and David dwells in Ziklag [for] two days,
2 Ní ọjọ́ kẹta, ọkùnrin kan dé láti ibi ibùdó Saulu, pẹ̀lú aṣọ rẹ̀ tí ó ti ya; àti erùpẹ̀ ní orí rẹ̀. Nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ Dafidi, ó wólẹ̀ fún un láti bu ọlá fún un.
and it comes to pass, on the third day, that behold, a man has come in out of the camp from Saul, and his garments [are] torn, and earth [is] on his head; and it comes to pass in his coming to David, that he falls to the earth and pays respect.
3 Dafidi sì béèrè pé, “Ibo ni ìwọ ti wá?” “Èmi sá láti ibùdó àwọn ọmọ Israẹli.”
And David says to him, “Where do you come from?” And he says to him, “I have escaped out of the camp of Israel.”
4 Dafidi béèrè pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” “Sọ fún mi.” Ó wí pé, “Àwọn ọkùnrin náà sá láti ojú ogun. Ọ̀pọ̀ wọn ṣubú, wọ́n sì kú. Saulu àti ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Jonatani sì kú pẹ̀lú.”
And David says to him, “What has been the matter? Please declare [it] to me.” And he says, “That the people have fled from the battle, and also a multitude of the people have fallen, and they die; and also Saul and his son Jonathan have died.”
5 Nígbà náà, ní Dafidi sọ fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún un pé, “Báwo ni o ṣe mọ̀ pé Saulu àti ọmọkùnrin rẹ̀ Jonatani ti kú.”
And David says to the youth who is declaring [it] to him, “How have you known that Saul and his son Jonathan [are] dead?”
6 Ọ̀dọ́mọkùnrin náà sọ pé, “Mo wà ní orí òkè Gilboa níbẹ̀ ni Saulu fi ara tí ọkọ̀ rẹ̀, àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin sì ń lépa rẹ̀.
And the youth who is declaring [it] to him says, “I happened to meet in Mount Gilboa, and behold, Saul is leaning on his spear; and behold, the chariots and those possessing horses have followed him;
7 Nígbà tí ó wò yíká, tí ó rí mí, ó pè mi, mo sì wí pé, ‘Kí ni mo lè ṣe?’
and he turns behind him, and sees me, and calls to me, and I say, Here I [am].
8 “Ó bi mí wí pé, ‘Ta ni ìwọ?’ “Mo dáhùn pé, ‘Ará a Amaleki.’
And he says to me, Who [are] you? And I say to him, I [am] an Amalekite.
9 “Nígbà náà ó wí fún mi pé, ‘Dúró lórí ì mi kí o sì pa mí! Èmi wà nínú ìrora ikú, ṣùgbọ́n mo wà láààyè.’
And he says to me, Please stand over me and put me to death, for the arrow has seized me, for all my soul [is] still in me.
10 “Nígbà náà, mo dúró lórí i rẹ̀, mo sì pa á nítorí mo mọ̀ wí pé, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣubú, kò le è yè mọ́. Mo sì mú adé tí ó wà lórí rẹ̀, idẹ tí ó wà ní apá a rẹ̀, mo sì kó wọn wá síbí fún olúwa mi.”
And I stand over him, and put him to death, for I knew that he does not live after his falling, and I take the crown which [is] on his head, and the bracelet which [is] on his arm, and bring them to my lord here.”
11 Nígbà náà ni, Dafidi àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, di aṣọ wọn mú, wọ́n sì fà á ya.
And David takes hold on his garments, and tears them, and also all the men who [are] with him,
12 Wọ́n ṣọ̀fọ̀, wọ́n sì sọkún, wọ́n sì gbààwẹ̀ títí di ìrọ̀lẹ́ fún Saulu àti ọmọ rẹ̀ Jonatani àti fún àwọn ọmọ-ogun Olúwa, àti fún àwọn ilé Israẹli, nítorí wọ́n ti ṣubú nípa idà.
and they mourn, and weep, and fast until the evening, for Saul, and for his son Jonathan, and for the people of YHWH, and for the house of Israel, because they have fallen by the sword.
13 Dafidi sọ fún ọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún un pé, “Níbo ni ó ti wá?” O dáhùn pé, “Ọmọ àlejò ni mo jẹ́, ará Amaleki.”
And David says to the youth who is declaring [it] to him, “Where [are] you from?” And he says, “I [am] the son of a sojourner, an Amalekite.”
14 Dafidi béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ kò fi bẹ̀rù láti gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè láti fi pa ẹni àmì òróró Olúwa?”
And David says to him, “How were you not afraid to put forth your hand to destroy the anointed of YHWH?”
15 Nígbà náà Dafidi pe ọ̀kan nínú ọkùnrin, ó sì wí pé, “Lọ, gbé e lulẹ̀!” Nígbà náà ó gbé e lulẹ̀, ó sì kú.
And David calls to one of the youths and says, “Draw near—fall on him”; and he strikes him, and he dies;
16 Nítorí Dafidi wí fún un pé, “Ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò wà lórí ara rẹ, nítorí ẹnu ara rẹ ni o fi sọ pé, ‘Mo pa ẹni àmì òróró Olúwa.’”
and David says to him, “Your blood [is] on your own head, for your mouth has testified against you, saying, I put to death the anointed of YHWH.”
17 Dafidi sì fi orin ọ̀fọ̀ yìí ṣọ̀fọ̀ lórí Saulu àti lórí Jonatani ọmọ rẹ̀,
And David laments with this lamentation over Saul, and over his son Jonathan;
18 Ó sì pàṣẹ pé kí a kọ́ àwọn ọkùnrin Juda ní orin arò yìí tí ó jẹ́ ti ọrun (a kọ ọ́ sí inú ìwé Jaṣari):
and he says to teach the sons of Judah “The Bow”; behold, it is written on the Scroll of the Upright:
19 “Ògo rẹ, Israẹli ni a pa ní òkè gíga rẹ. Wò bí àwọn alágbára ṣe ń ṣubú!
“The beauty of Israel [Is] wounded on your high places; How the mighty have fallen!
20 “Ẹ má ṣe sọ ọ́ ní Gati, ẹ má ṣe kéde rẹ̀ ní òpópónà Aṣkeloni, kí àwọn ọmọbìnrin Filistini má bá à yọ̀, kí àwọn ọmọbìnrin aláìkọlà má ba à dunnú.
Do not declare [it] in Gath, Do not proclaim the tidings in the streets of Ashkelon, Lest they rejoice—The daughters of the Philistines, Lest they exult—The daughters of the uncircumcised!
21 “Ẹ̀yin òkè Gilboa, kí ẹ̀yin kí ó má ṣe rí ìrì tàbí òjò, tàbí oko tí ó mú èso ọrẹ wá. Nítorí ibẹ̀ ni asà alágbára ti ṣègbé, asà Saulu, bí ẹni pé a kò fi òróró yàn án.
Mountains of Gilboa! No dew nor rain be on you, And fields of raised-offerings! For there has become loathsome The shield of the mighty, The shield of Saul—without the anointed with oil.
22 “Ọrun Jonatani kì í padà bẹ́ẹ̀ ni idà Saulu kì í padà lásán, láì kan ẹ̀jẹ̀ àwọn tí a pa, àti ẹran àwọn alágbára.
From the blood of the wounded, From the fat of the mighty, The bow of Jonathan Has not turned backward; And the sword of Saul does not return empty.
23 Saulu àti Jonatani— ní ọjọ́ ayé, wọ́n fẹ́ràn ara, wọn sì dùn, ní ikú, wọn kò sì yà ara wọ́n. Wọ́n yára ju idì lọ, wọ́n lágbára ju kìnnìún lọ.
Saul and Jonathan! They are loved and pleasant in their lives, And in their death they have not been parted. They have been lighter than eagles, They have been mightier than lions!
24 “Ẹ̀yin ọmọbìnrin Israẹli, ẹ sọkún lórí Saulu, ẹni tí ó fi aṣọ ọ̀gbọ̀ dáradára wọ̀ yín, ẹni tí ó fi wúrà sí ara aṣọ yín.
Daughters of Israel! Weep for Saul, Who is clothing you [in] scarlet with delights. Who is lifting up ornaments of gold on your clothing.
25 “Wò ó bí alágbára ti ṣubú ní ojú ogun! Jonatani, ìwọ tí a pa ní òkè gíga.
How the mighty have fallen In the midst of the battle! Jonathan [was] wounded on your high places!
26 Ọkàn mi gbọgbẹ́ fún ọ Jonatani arákùnrin mi; ìwọ ṣọ̀wọ́n fún mi. Ìfẹ́ rẹ sí mi jẹ́ ìyanu, ó jẹ́ ìyanu ju ti obìnrin lọ.
I am in distress for you, my brother Jonathan, You were very pleasant to me; Your love was wonderful to me, Above the love of women!
27 “Wò ó bí alágbára ti ṣubú! Ohun ìjà sì ti ṣègbé!”
How the mighty have fallen, Indeed, the weapons of war perish!”

< 2 Samuel 1 >