< 2 Peter 1 >

1 Simoni Peteru, ìránṣẹ́ àti aposteli Jesu Kristi, Sí àwọn tí ó gba irú iyebíye ìgbàgbọ́ kan náà pẹ̀lú wá nínú òdodo Ọlọ́run wa àti ti Jesu Kristi Olùgbàlà:
Ja, Szymon Piotr, sługa i apostoł Jezusa Chrystusa, piszę do wszystkich, którzy—podobnie jak my—wierzą sprawiedliwemu Bogu i Zbawicielowi, Jezusowi Chrystusowi.
2 Kí oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà máa bí sí i fún yín nínú ìmọ̀ Ọlọ́run àti ti Jesu Olúwa wa.
Niech Boża łaska i pokój wydają wśród was coraz większy owoc, pomagając wam lepiej poznawać Boga oraz Jezusa, naszego Pana!
3 Bí agbára rẹ̀ bí Ọlọ́run ti fún wa ní ohun gbogbo tí a nílò fún ṣe ti ìyè àti ti ìwà-bí-Ọlọ́run, nípa ìmọ̀ ẹni tí ó pè wá nípa Ògo àti ìṣeun rẹ̀.
Bóg, w swojej mocy, dał nam wszystko, czego potrzebujemy do pobożnego życia. Pozwolił nam bowiem poznać Tego, który powołał nas do życia w swojej chwale i doskonałości.
4 Nípa èyí tí ó fi àwọn ìlérí rẹ̀ tí ó tóbi púpọ̀ tí ó ṣe iyebíye fún wa: pé nípa ìwọ̀nyí ni kí ẹ̀yin lè di alábápín nínú àbùdá ti Ọlọ́run, nígbà tí ẹ̀yin bá ti yọ kúrò nínú ìbàjẹ́ tí ó ń bẹ nínú ayé nípa ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́.
Bóg spełnił swoje cudowne i wspaniałe obietnice, sprawiając, że Jego natura stała się waszą naturą, przez co wyrwaliście się z niewoli złych pragnień i uwolniliście się od wpływu tego zepsutego świata.
5 Àti nítorí ìdí èyí, ẹ máa ṣe àìsimi gbogbo, ẹ fi ìwà rere kún ìgbàgbọ́, àti ìmọ̀ kún ìwà rere;
Starajcie się więc uzupełnić waszą wiarę prawością, duchowym rozeznaniem,
6 àti àìrékọjá kún ìmọ̀; àti sùúrù kún àìrékọjá; àti ìwà-bí-Ọlọ́run kún sùúrù.
opanowaniem, wytrwałością, pobożnością,
7 Àti ìfẹ́ ọmọnìkejì kún ìwà-bí-Ọlọ́run; àti ìfẹ́ni kún ìfẹ́ ọmọnìkejì.
przyjaźnią oraz miłością.
8 Nítorí bí ẹ̀yin bá ní nǹkan wọ̀nyí tí wọ́n bá sì pọ̀, wọn kì yóò jẹ́ kí ẹ ṣe ọ̀lẹ tàbí aláìléso nínú ìmọ̀ Olúwa wa Jesu Kristi.
Jeśli nadal będziecie poznawać Jezusa Chrystusa, naszego Pana, i rozwijać w sobie te cechy, nie będziecie bierni, a wasze życie nie będzie bezowocne.
9 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ṣe aláìní nǹkan wọ̀nyí, kò lè ríran ní òkèèrè, ó fọjú, ó sì ti gbàgbé pé a ti wẹ òun nù kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ àtijọ́.
Kto jednak nie rozwija w sobie tych cech, jest duchowo ślepy i ograniczony—zapomniał bowiem o tym, że Bóg przebaczył mu grzechy!
10 Nítorí náà, ará ẹ túbọ̀ máa ṣe àìsimi láti sọ ìpè àti yíyàn yín di dájúdájú, nítorí bí ẹ̀yin bá ń ṣe nǹkan wọ̀nyí, ẹ̀yin kì yóò ṣubú.
Dlatego, przyjaciele, poprzez wasze życie starajcie się pokazać, że naprawdę jesteście ludźmi powołanymi i wybranymi przez Boga. Taka postawa uchroni was od upadku
11 Nítorí báyìí ni a ó pèsè fún yín lọ́pọ̀lọ́pọ̀ láti wọ ìjọba àìnípẹ̀kun ti Olúwa àti Olùgbàlà wa Jesu Kristi. (aiōnios g166)
i szeroko otworzy przed wami bramy wiecznego królestwa, należącego do naszego Pana i Zbawiciela, Jezusa Chrystusa. (aiōnios g166)
12 Nítorí náà, èmi ó máa rán yin létí àwọn nǹkan wọ̀nyí nígbà gbogbo, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀yin ti mọ̀ wọ́n, tí ẹsẹ̀ yín sì múlẹ̀ nínú òtítọ́ tí ẹ ní báyìí.
Chociaż dobrze znacie już Bożą prawdę i trzymacie się jej, to jednak zawsze będę ją wam przypominać.
13 Èmi sì rò pé ó tọ́ láti máa mú wọn wá sí ìrántí yín, níwọ̀n ìgbà tí èmí ba ń bẹ nínú àgọ́ ara yìí.
Jestem bowiem przekonany, że dopóki żyję na tym świecie, powinienem w ten sposób umacniać waszą wiarę,
14 Bí èmi ti mọ̀ pé, bíbọ́ àgọ́ ara mi yìí sílẹ̀ kù sí dẹ̀dẹ̀, àní, bí Olúwa wa Jesu Kristi ti fihàn mí.
abyście pamiętali o tym także po mojej śmierci. Wiem bowiem—objawił mi to nasz Pan, Jezus Chrystus—że już wkrótce opuszczę ten świat.
15 Èmi ó sì máa ṣaápọn pẹ̀lú, kí ẹ̀yin lè máa rántí nǹkan wọ̀nyí nígbà gbogbo lẹ́yìn ikú mi.
16 Nítorí kì í ṣe bí ẹni tí ó ń tọ ìtàn asán lẹ́yìn tí a fi ọgbọ́nkọ́gbọ́n là sílẹ̀, nígbà tí àwa sọ fún yín ní ti agbára àti wíwá Jesu Kristi Olúwa, ṣùgbọ́n ẹlẹ́rìí ọláńlá rẹ̀ ni àwa jẹ́.
Gdy mówiliśmy wam o mocy naszego Pana, Jezusa Chrystusa, i o Jego przyjściu, nie opowiadaliśmy wam jakichś zmyślonych bajek, ale mówiliśmy o tym, co widzieliśmy na własne oczy.
17 Nítorí tí Ó gba ọlá àti ògo láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba, nígbà tí irú ohùn yìí fọ̀ sí i láti inú ògo ńlá náà wá pé, “Èyí ni àyànfẹ́ ọmọ mi, ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.”
Bóg Ojciec otoczył Go bowiem chwałą i czcią, gdy przemówił do Niego jako Najwyższy Władca: „Oto mój ukochany Syn, moja największa radość”.
18 Àwa pẹ̀lú sì gbọ́ ohun yìí tí ó ti ọ̀run wá nígbà tí àwa wà pẹ̀lú rẹ̀ ní orí òkè mímọ́ náà.
Usłyszeliśmy ten głos z nieba, gdy razem z Jezusem byliśmy na świętej górze.
19 Àwa sì ní ìfẹsẹ̀múlẹ̀ ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì dunjúdunjú sí i, èyí tí ó yẹ kí ẹ kíyèsi gẹ́gẹ́ bí fìtílà tó ń mọ́lẹ̀ níbi tí òkùnkùn gbé wà, títí ilẹ̀ yóò fi mọ́, tí ìràwọ̀ òwúrọ̀ yóò sì yọ lọ́kàn yín.
W ten sposób Bóg potwierdził zapowiedzi proroków. Zanim nadejdzie dzień i w waszych sercach zabłyśnie Gwiazda Poranna, mocno trzymajcie się ich słów, są one bowiem jak światło świecące w ciemności.
20 Ju gbogbo rẹ̀ lọ, kí ẹ ní òye yìí pé kò sí àsọtẹ́lẹ̀ ìwé mímọ́ kankan tí ó wáyé nípa ìtumọ̀ wòlíì fún rara rẹ̀.
Pamiętajcie jednak, że proroctw zapisanych w Piśmie nie można wyjaśniać według własnego uznania.
21 Nítorí àsọtẹ́lẹ̀ kan kò ti ipá ìfẹ́ ènìyàn wá rí; ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ń sọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run bí a ti ń darí wọn láti ọwọ́ Ẹ̀mí Mímọ́ wá.
Nie są to bowiem jakieś ludzkie mądrości, ale słowa przekazane przez Ducha Świętego.

< 2 Peter 1 >