< 2 Kings 1 >

1 Lẹ́yìn ikú Ahabu, Moabu ṣọ̀tẹ̀ sí Israẹli.
Un Moabs atkāpās no Israēla, kad Ahabs bija nomiris.
2 Nísinsin yìí Ahasiah ti ṣubú láàrín fèrèsé láti òkè yàrá rẹ̀ tí ó wà ní Samaria, ó sì fi ara pa. Ó sì rán oníṣẹ́, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni, bóyá èmi ó lè rí ìwòsàn ìfarapa yìí.”
Un Ahazija nokrita caur savas augšistabas treliņiem Samarijā, un sasitās un sūtīja vēstnešus un tiem sacīja: ejat un vaicājiet BaālZebubu, Ekronas dievu, vai es palikšu vesels?
3 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa wí fún Elijah ará Tiṣibi pé, “Lọ sókè kí o lọ bá ìránṣẹ́ ọba Samaria kí o sì béèrè lọ́wọ́ wọn, ‘Ṣé nítorí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli ni ẹ̀yìn fi jáde lọ ṣèwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu òrìṣà Ekroni?’
Bet Tā Kunga eņģelis runāja uz Eliju no Tizbes: celies, ej pretī Samarijas ķēniņa vēstnešiem un runā uz tiem: vai tad Dieva nav iekš Israēla, ka jūs ejat, vaicāt BaālZebubu, Ekronas dievu?
4 Nítorí náà ohun tí Olúwa sọ ní èyí, ‘Ìwọ kò ní kúrò lórí ibùsùn tí o dùbúlẹ̀ lé. Dájúdájú ìwọ yóò kú!’” Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ.
Tāpēc Tas Kungs tā saka: tu necelsies no tās gultas, kur tu guli, bet tev jāmirst. Un Elija aizgāja.
5 Nígbà tí ìránṣẹ́ náà padà sí ọ̀dọ̀ ọba, ó béèrè ní ọwọ́ wọn pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi tètè padà wá?”
Tā tie vēstneši nāca atpakaļ pie viņa, un viņš uz tiem sacīja: kāpēc jūs nākat atpakaļ?
6 Wọ́n dáhùn pé, “Ọkùnrin kan wá láti pàdé wa, ó sì wí fún wa pé, ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ ọba tí ó rán an yín kí ẹ sì wí fún un pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Ṣé nítorí wí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli ni o fi ń rán àwọn ènìyàn láti lọ ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni? Nítorí náà ìwọ kò ní fi orí ibùsùn tí ìwọ dùbúlẹ̀ lé sílẹ̀. Láìsí àní àní ìwọ yóò kùú!”’”
Un tie uz viņu sacīja: viens vīrs mums nāca pretī un uz mums sacīja: ejat, griežaties atpakaļ pie ķēniņa, kas jūs sūtījis, un sakāt tam: tā saka Tas Kungs: vai tad nav Dieva iekš Israēla, ka tu sūti, vaicāt BaālZebubu, Ekronas dievu? Tāpēc tu necelsies no tās gultas, kur tu guli, bet tev jāmirst.
7 Ọba béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Irú ọkùnrin wo ni ó wá pàdé yín, tí ó sì sọ irú èyí fún un yín?”
Un viņš uz tiem sacīja: kādu izskatu tas vīrs bija, kas jums pretī nāca un šos vārdus uz jums runāja?
8 Wọ́n dáhùn pé, “Ó jẹ́ ọkùnrin tí ó wọ ẹ̀wù onírun lára pẹ̀lú ọ̀já àmùrè aláwọ tí ó gbà yíká ìbàdí rẹ̀.” Ọba sì wí pé, “Elijah ará Tiṣibi ni.”
Un tie uz viņu sacīja: tas bija vīrs spalvas drēbēs un ar ādas jostu apjozies ap saviem gurniem. Tad viņš sacīja: tas ir Elija no Tizbes.
9 Ó sì rán balógun pẹ̀lú àwọn ẹgbẹ́ ogun àádọ́ta rẹ̀. Balógun náà sì gòkè tọ Elijah lọ, ẹni tí ó jókòó ní orí òkè, wọ́n sì wí fún un pé, “Ènìyàn Ọlọ́run, ọba wí pé, ‘Sọ̀kalẹ̀ wá!’”
Un viņš pie tā sūtīja virsnieku pār piecdesmit un tos piecdesmit, kas tam bija. Un kad tas pie viņa nonāca, redzi, tad viņš sēdēja kalna galā, un tas uz viņu sacīja: tu Dieva vīrs, ķēniņš tev liek sacīt: nāc lejā.
10 Elijah sì dá balógun lóhùn pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ènìyàn Ọlọ́run ni mí, kí iná kí ó sọ̀kalẹ̀ láti òkè ọ̀run wá kí ó sì jó ìwọ àti àwọn àádọ́ta ọkùnrin rẹ!” Nígbà náà iná náà sì sọ̀kalẹ̀ wá láti òkè ọ̀run ó sì jó balógun àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
Bet Elija atbildēja un sacīja uz to virsnieku pār tiem piecdesmit: ja es esmu Dieva vīrs, tad lai uguns krīt no debesīm un aprij tevi ar taviem piecdesmit. Tad uguns krita no debesīm un aprija to un viņa piecdesmit.
11 Ọba sì tún rán balógun àádọ́ta pẹ̀lú àwọn ènìyàn àádọ́ta rẹ̀ sí Elijah. Balógun náà sì wí fún un pé, “Ènìyàn Ọlọ́run, èyí ni ohun tí ọba sọ, ‘Sọ̀kalẹ̀ kánkán!’”
Bet viņš pie tā sūtīja vēl otru virsnieku pār piecdesmit un tos piecdesmit, kas tam bija, un tas bildināja un uz to sacīja: tu Dieva vīrs, tā ķēniņš saka: nāc tūdaļ lejā.
12 “Tí èmi bá jẹ́ ènìyàn Ọlọ́run,” Elijah sì dáhùn, “Ǹjẹ́ kí iná kí ó sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run kí ó sì jó ọ run àti àwọn àádọ́ta ènìyàn rẹ!” Nígbà náà iná Ọlọ́run sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run ó sì jó o run pẹ̀lú àwọn àádọ́ta ènìyàn rẹ̀.
Bet Elija atbildēja un uz tiem sacīja: ja es esmu Dieva vīrs, tad lai uguns krīt no debesīm, un aprij tevi ar taviem piecdesmit. Tad Dieva uguns nokrita no debesīm un aprija to un viņa piecdesmit.
13 Bẹ́ẹ̀ ni ọba tún rán balógun kẹta pẹ̀lú àwọn àádọ́ta ọkùnrin. Balógun ẹ̀ẹ̀kẹ́ta lọ sí òkè, ó sì kúnlẹ̀ lórí orókún rẹ̀ níwájú Elijah. “Ènìyàn Ọlọ́run,” Ó sì bẹ̀bẹ̀ pé, “Ìwọ ènìyàn Ọlọ́run, jọ̀wọ́ jẹ́ kí ẹ̀mí mi àti ẹ̀mí àwọn àádọ́ta ìránṣẹ́ rẹ wọ̀nyí ṣọ̀wọ́n ní ojú rẹ!
Bet viņš sūtīja atkal trešo reiz virsnieku pār piecdesmit un tos piecdesmit, kas tam bija. Un tas trešais virsnieks pār piecdesmit nāca augšām un piegāja un metās ceļos priekš Elijas, to lūdza un uz to sacīja: tu Dieva vīrs, lai jel mana dvēsele un šo tavu piecdesmit kalpu dvēseles atrod žēlastību tavās acīs.
14 Wò ó, iná ti sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run láti jó àwọn balógun méjì àràádọ́ta àkọ́kọ́ pẹ̀lú àràádọ́ta wọn. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ní ojúrere fún ẹ̀mí mi!”
Redzi, uguns ir kritis no debesīm un aprijis tos divus pirmos virsniekus pār piecdesmit līdz ar viņu piecdesmitiem, bet nu lai jel mana dvēsele ir dārga tavās acīs.
15 Angẹli Olúwa sọ fún Elijah pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ pẹ̀lú rẹ̀; má ṣe bẹ̀rù rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni Elijah dìde ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ pẹ̀lú rẹ̀ sí ọ̀dọ̀ ọba.
Un Tā Kunga eņģelis sacīja uz Eliju: noej ar viņu un nebīsties no viņa. Tad viņš cēlās un ar to nogāja pie ķēniņa,
16 Ó sọ fún ọba pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ‘Ṣé nítorí wí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli fún ọ láti pè ni ìwọ fi rán ìránṣẹ́ lọ sí ọ̀dọ̀ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni láti lọ ṣe ìwádìí?’ Nítorí pé o ṣe èyí, ìwọ kò ní dìde lórí ibùsùn tí o dùbúlẹ̀ lé láìsí àní àní ìwọ yóò kú!”
Un sacīja uz to: tā saka Tas Kungs: tāpēc ka tu vēstnešus esi sūtījis, vaicāt BaālZebubu, Ekronas dievu, kā kad nebūtu Dieva iekš Israēla, kura vārdu varētu vaicāt tāpēc tu necelsies no tās gultas, kur tu guli, bet tev jāmirst.
17 Bẹ́ẹ̀ ó sì kú, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí Elijah ti sọ. Nítorí Ahasiah kò ní ọmọ, Jehoramu jẹ ọba ní ọdún kejì tí Jehoramu ọmọ Jehoṣafati ọba Juda.
Tā viņš nomira pēc Tā Kunga vārda, ko Elija bija runājis, un Jorams palika par ķēniņu viņa vietā, Jehorama, Jehošafata dēla, Juda ķēniņa, otrā gadā, jo viņam nebija dēla.
18 Àti ní ti gbogbo àwọn ohun tí ó ṣẹlẹ̀ nígbà ìjọba Ahasiah, àti ohun tí ó ṣe, ṣe a kò ha kọ wọ́n sí inú ìwé ọdọọdún ti àwọn ọba Israẹli?
Un kas vēl stāstāms par Ahaziju, ko viņš darījis, tas viss rakstīts Israēla ķēniņu laiku grāmatā.

< 2 Kings 1 >