< 2 Kings 1 >

1 Lẹ́yìn ikú Ahabu, Moabu ṣọ̀tẹ̀ sí Israẹli.
Tukun Tokosra Ahab lun Israel el misa, acn Moab tuyak ac alein nu sin Israel.
2 Nísinsin yìí Ahasiah ti ṣubú láàrín fèrèsé láti òkè yàrá rẹ̀ tí ó wà ní Samaria, ó sì fi ara pa. Ó sì rán oníṣẹ́, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni, bóyá èmi ó lè rí ìwòsàn ìfarapa yìí.”
Tokosra Ahaziah lun Israel el putatla ke sawalsrisr fulat in lohm sel in acn Samaria ac arulana musalla manol. Ouinge el supwala kutu mwet lal in som lolngok yorol Baalzebub, god lun acn Ekron, sie siti in acn Philistia, in konauk lah el ac kwela ku tia.
3 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa wí fún Elijah ará Tiṣibi pé, “Lọ sókè kí o lọ bá ìránṣẹ́ ọba Samaria kí o sì béèrè lọ́wọ́ wọn, ‘Ṣé nítorí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli ni ẹ̀yìn fi jáde lọ ṣèwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu òrìṣà Ekroni?’
A sie lipufan lun LEUM GOD sapkin nu sel Elijah, mwet palu in acn Tishbe, elan som osun nu sin mwet lal Tokosra Ahaziah ac siyuk selos, “Efu kowos ku som lolngok yorol Baalzebub, god lun Ekron? Ya mweyen kowos nunku mu wangin god lun Israel?
4 Nítorí náà ohun tí Olúwa sọ ní èyí, ‘Ìwọ kò ní kúrò lórí ibùsùn tí o dùbúlẹ̀ lé. Dájúdájú ìwọ yóò kú!’” Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ.
Fahk nu sel tokosra lah LEUM GOD El fahk, ‘Kom ac fah tia kwela. Kom ac misa!’” Elijah el oru oana ma LEUM GOD El sapkin,
5 Nígbà tí ìránṣẹ́ náà padà sí ọ̀dọ̀ ọba, ó béèrè ní ọwọ́ wọn pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi tètè padà wá?”
ac mwet ma supweyuk sel tokosra inge folokla nu yorol. Na tokosra el siyuk, “Efu kowos ku sa na foloko?”
6 Wọ́n dáhùn pé, “Ọkùnrin kan wá láti pàdé wa, ó sì wí fún wa pé, ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ ọba tí ó rán an yín kí ẹ sì wí fún un pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Ṣé nítorí wí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli ni o fi ń rán àwọn ènìyàn láti lọ ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni? Nítorí náà ìwọ kò ní fi orí ibùsùn tí ìwọ dùbúlẹ̀ lé sílẹ̀. Láìsí àní àní ìwọ yóò kùú!”’”
Elos topuk, “Kut sun mwet se su fahk nu sesr kut in foloko fahk nu sum mu LEUM GOD El fahk nu sum ouinge, ‘Efu kom ku supweyuk mwet in som lolngok yorol Baalzebub, god lun Ekron? Ya mweyen kom nunku mu wangin god lun Israel? Kom ac tia kwela. Kom ac misa!’”
7 Ọba béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Irú ọkùnrin wo ni ó wá pàdé yín, tí ó sì sọ irú èyí fún un yín?”
Ac tokosra el siyuk, “Fuka luman mwet sacn?”
8 Wọ́n dáhùn pé, “Ó jẹ́ ọkùnrin tí ó wọ ẹ̀wù onírun lára pẹ̀lú ọ̀já àmùrè aláwọ tí ó gbà yíká ìbàdí rẹ̀.” Ọba sì wí pé, “Elijah ará Tiṣibi ni.”
Ac elos topuk, “El nukum nuknuk lik se orekla ke unen kosro, ac losya infulwal ke pel se orekla ke kulun kosro.” Na tokosra el fahk, “Elijah pa mwet sacn!”
9 Ó sì rán balógun pẹ̀lú àwọn ẹgbẹ́ ogun àádọ́ta rẹ̀. Balógun náà sì gòkè tọ Elijah lọ, ẹni tí ó jókòó ní orí òkè, wọ́n sì wí fún un pé, “Ènìyàn Ọlọ́run, ọba wí pé, ‘Sọ̀kalẹ̀ wá!’”
Na el supwala sie mwet leum lun mwet mweun wi mwet lumngaul lal in som usalu Elijah. Mwet leum sac konalak ke el muta fin inging soko ac el fahk nu sel Elijah, “Mwet lun God, tokosra el sap kom in oatui.”
10 Elijah sì dá balógun lóhùn pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ènìyàn Ọlọ́run ni mí, kí iná kí ó sọ̀kalẹ̀ láti òkè ọ̀run wá kí ó sì jó ìwọ àti àwọn àádọ́ta ọkùnrin rẹ!” Nígbà náà iná náà sì sọ̀kalẹ̀ wá láti òkè ọ̀run ó sì jó balógun àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
Elijah el topuk, “Nga fin mwet lun God, lela e in tuku inkusrao me unikomi ac mwet lom ingan!” In pacl sacna, e tuku inkusrao me ac uniya leum sac ac mwet lal ah.
11 Ọba sì tún rán balógun àádọ́ta pẹ̀lú àwọn ènìyàn àádọ́ta rẹ̀ sí Elijah. Balógun náà sì wí fún un pé, “Ènìyàn Ọlọ́run, èyí ni ohun tí ọba sọ, ‘Sọ̀kalẹ̀ kánkán!’”
Tokosra el supwala pac sie leum wi mwet lumngaul lal, su som ac fahk nu sel Elijah, “Mwet lun God, tokosra el sap kom in oatui ingena!”
12 “Tí èmi bá jẹ́ ènìyàn Ọlọ́run,” Elijah sì dáhùn, “Ǹjẹ́ kí iná kí ó sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run kí ó sì jó ọ run àti àwọn àádọ́ta ènìyàn rẹ!” Nígbà náà iná Ọlọ́run sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run ó sì jó o run pẹ̀lú àwọn àádọ́ta ènìyàn rẹ̀.
Elijah el topuk, “Nga fin mwet lun God, lela e in tuku inkusrao me unikomi ac mwet lom ingan!” In pacl sacna, e lun God tuku lucng me ac uniya leum sac ac mwet lal ah.
13 Bẹ́ẹ̀ ni ọba tún rán balógun kẹta pẹ̀lú àwọn àádọ́ta ọkùnrin. Balógun ẹ̀ẹ̀kẹ́ta lọ sí òkè, ó sì kúnlẹ̀ lórí orókún rẹ̀ níwájú Elijah. “Ènìyàn Ọlọ́run,” Ó sì bẹ̀bẹ̀ pé, “Ìwọ ènìyàn Ọlọ́run, jọ̀wọ́ jẹ́ kí ẹ̀mí mi àti ẹ̀mí àwọn àádọ́ta ìránṣẹ́ rẹ wọ̀nyí ṣọ̀wọ́n ní ojú rẹ!
Na tokosra el sifilpa supwala sie pac leum wi mwet lumngaul lal. El utyak nu fin inging soko ah, sikukmutunteyak ye mutal Elijah ac kwafe sel, “Mwet lun God, pakoten nu sik ac mwet luk inge. Nimet unikuti!
14 Wò ó, iná ti sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run láti jó àwọn balógun méjì àràádọ́ta àkọ́kọ́ pẹ̀lú àràádọ́ta wọn. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ní ojúrere fún ẹ̀mí mi!”
Leum luo meet ah wi mwet laltal ah anwuki ke e inkusrao me. A nga siyuk kom in nunak munas ac pakoten nu sik!”
15 Angẹli Olúwa sọ fún Elijah pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ pẹ̀lú rẹ̀; má ṣe bẹ̀rù rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni Elijah dìde ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ pẹ̀lú rẹ̀ sí ọ̀dọ̀ ọba.
Lipufan lun LEUM GOD fahk nu sel Elijah, “Oatui welul ac nimet sangeng.” Ouinge Elijah el wi mwet leum sac som nu yorol tokosra
16 Ó sọ fún ọba pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ‘Ṣé nítorí wí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli fún ọ láti pè ni ìwọ fi rán ìránṣẹ́ lọ sí ọ̀dọ̀ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni láti lọ ṣe ìwádìí?’ Nítorí pé o ṣe èyí, ìwọ kò ní dìde lórí ibùsùn tí o dùbúlẹ̀ lé láìsí àní àní ìwọ yóò kú!”
ac fahk nu sel, “Pa inge ma LEUM GOD El fahk, ‘Mweyen kom supwala mwet in som lolngok yorol Baalzebub, god lun Ekron, srulukin wangin god lun Israel kom in lolngok se, na pa kom ac tia kwela. Kom ac misa!’”
17 Bẹ́ẹ̀ ó sì kú, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí Elijah ti sọ. Nítorí Ahasiah kò ní ọmọ, Jehoramu jẹ ọba ní ọdún kejì tí Jehoramu ọmọ Jehoṣafati ọba Juda.
Ahaziah el misa oana ma LEUM GOD El fahkak sel Elijah. Wangin wen natul Ahaziah, na pa Joram tamulel lal, el aolul in tokosra ke yac akluo ke pacl in leum lal Jehoram wen natul Jehoshaphat, tokosra lun Judah.
18 Àti ní ti gbogbo àwọn ohun tí ó ṣẹlẹ̀ nígbà ìjọba Ahasiah, àti ohun tí ó ṣe, ṣe a kò ha kọ wọ́n sí inú ìwé ọdọọdún ti àwọn ọba Israẹli?
Ma nukewa saya ma Tokosra Ahaziah el orala, simla oasr in [Sramsram Matu Ke Tokosra Lun Israel.]

< 2 Kings 1 >