< 2 Kings 1 >
1 Lẹ́yìn ikú Ahabu, Moabu ṣọ̀tẹ̀ sí Israẹli.
Na rĩrĩ, thuutha wa gĩkuũ kĩa Ahabu, andũ a Moabi makĩrega gwathĩkĩra Isiraeli.
2 Nísinsin yìí Ahasiah ti ṣubú láàrín fèrèsé láti òkè yàrá rẹ̀ tí ó wà ní Samaria, ó sì fi ara pa. Ó sì rán oníṣẹ́, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni, bóyá èmi ó lè rí ìwòsàn ìfarapa yìí.”
Na rĩrĩ, Ahazia nĩagwĩte kuuma ndirica-inĩ ya nyũmba yake ya igũrũ kũu Samaria, akagurario. Nĩ ũndũ ũcio agĩtũma andũ, akĩmeera atĩrĩ, “Thiĩi mũkoorie Baali-Zebubu, ngai ya Ekironi, kana hihi nĩngũhona nguraro ici.”
3 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa wí fún Elijah ará Tiṣibi pé, “Lọ sókè kí o lọ bá ìránṣẹ́ ọba Samaria kí o sì béèrè lọ́wọ́ wọn, ‘Ṣé nítorí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli ni ẹ̀yìn fi jáde lọ ṣèwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu òrìṣà Ekroni?’
No mũraika wa Jehova akĩĩra Elija ũrĩa Mũtishibi atĩrĩ, “Ambata, ũthiĩ ũtũngane na andũ acio matũmĩtwo nĩ mũthamaki wa Samaria, ũmoorie atĩrĩ, ‘Nĩ Ngai gũtarĩ thĩinĩ wa Isiraeli nĩguo mũthiĩ mũkahooe ũhoro kuuma kũrĩ Baali-Zebubu, ngai ya Ekironi?’
4 Nítorí náà ohun tí Olúwa sọ ní èyí, ‘Ìwọ kò ní kúrò lórí ibùsùn tí o dùbúlẹ̀ lé. Dájúdájú ìwọ yóò kú!’” Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ.
Nĩ ũndũ ũcio Jehova ekuuga ũũ: ‘Ndũkuuma gĩtanda-inĩ hau ũkomete. Ti-itherũ nĩũgũkua!’” Nĩ ũndũ ũcio Elija agĩthiĩ.
5 Nígbà tí ìránṣẹ́ náà padà sí ọ̀dọ̀ ọba, ó béèrè ní ọwọ́ wọn pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi tètè padà wá?”
Rĩrĩa andũ acio maatũmĩtwo maacookire kũrĩ mũthamaki, akĩmooria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩatũma mũcooke?”
6 Wọ́n dáhùn pé, “Ọkùnrin kan wá láti pàdé wa, ó sì wí fún wa pé, ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ ọba tí ó rán an yín kí ẹ sì wí fún un pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Ṣé nítorí wí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli ni o fi ń rán àwọn ènìyàn láti lọ ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni? Nítorí náà ìwọ kò ní fi orí ibùsùn tí ìwọ dùbúlẹ̀ lé sílẹ̀. Láìsí àní àní ìwọ yóò kùú!”’”
Nao makĩmũcookeria atĩrĩ, “Nĩ harĩ na mũndũ ũũkire gũtũtũnga, aatwĩra atĩrĩ, ‘Cookai kũrĩ mũthamaki ũrĩa ũmũtũmĩte, mũmwĩre atĩrĩ, “Jehova ekũũria atĩrĩ: Nĩ Ngai gũtarĩ thĩinĩ wa Isiraeli nĩguo ũtũme andũ makahooe ũhoro kuuma kũrĩ Baali-Zebubu, ngai ya Ekironi? Nĩ ũndũ ũcio ndũkuuma gĩtanda-inĩ hau ũkomete. Ti-itherũ nĩũgũkua!”’”
7 Ọba béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Irú ọkùnrin wo ni ó wá pàdé yín, tí ó sì sọ irú èyí fún un yín?”
Nake mũthamaki akĩmooria atĩrĩ, “Mũndũ ũcio ũũkire kũmũtũnga na aamwĩra ũguo-rĩ, ekũhaanaga atĩa?”
8 Wọ́n dáhùn pé, “Ó jẹ́ ọkùnrin tí ó wọ ẹ̀wù onírun lára pẹ̀lú ọ̀já àmùrè aláwọ tí ó gbà yíká ìbàdí rẹ̀.” Ọba sì wí pé, “Elijah ará Tiṣibi ni.”
Nao makĩmũcookeria atĩrĩ, “Nĩ mũndũ wĩhumbĩte nguo ya guoya, na akeoha mũcibi wa ngoothi njohero.” Nake mũthamaki akiuga atĩrĩ, “Ũcio oima Elija ũrĩa Mũtishibi.”
9 Ó sì rán balógun pẹ̀lú àwọn ẹgbẹ́ ogun àádọ́ta rẹ̀. Balógun náà sì gòkè tọ Elijah lọ, ẹni tí ó jókòó ní orí òkè, wọ́n sì wí fún un pé, “Ènìyàn Ọlọ́run, ọba wí pé, ‘Sọ̀kalẹ̀ wá!’”
Nake agĩtũmĩra Elija mũnene wa thigari arĩ na gĩkundi gĩake kĩa andũ mĩrongo ĩtano; mũnene ũcio akĩambata kũrĩ Elija, ũrĩa waikarĩte gacũmbĩrĩ ga kĩrĩma, akĩmwĩra atĩrĩ, “Wee mũndũ wa Ngai, mũthamaki ekuuga atĩrĩ, ‘Ikũrũka!’”
10 Elijah sì dá balógun lóhùn pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ènìyàn Ọlọ́run ni mí, kí iná kí ó sọ̀kalẹ̀ láti òkè ọ̀run wá kí ó sì jó ìwọ àti àwọn àádọ́ta ọkùnrin rẹ!” Nígbà náà iná náà sì sọ̀kalẹ̀ wá láti òkè ọ̀run ó sì jó balógun àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
Nake Elija agĩcookeria mũnene ũcio atĩrĩ, “Akorwo ndĩ mũndũ wa Ngai-rĩ, mwaki nĩũikũrũke uume igũrũ, ũgũcine hamwe na andũ aya aku mĩrongo ĩtano!” Hĩndĩ o ĩyo mwaki ũgĩikũrũka kuuma igũrũ, ũgĩcina mũnene ũcio hamwe na andũ ake.
11 Ọba sì tún rán balógun àádọ́ta pẹ̀lú àwọn ènìyàn àádọ́ta rẹ̀ sí Elijah. Balógun náà sì wí fún un pé, “Ènìyàn Ọlọ́run, èyí ni ohun tí ọba sọ, ‘Sọ̀kalẹ̀ kánkán!’”
Ningĩ mũthamaki agĩtũmĩra Elija mũnene ũngĩ wa thigari arĩ na andũ ake mĩrongo ĩtano. Nake mũnene ũcio akĩmwĩra atĩrĩ, “Wee mũndũ wa Ngai, mũthamaki ekuuga atĩrĩ, ‘Ikũrũka narua!’”
12 “Tí èmi bá jẹ́ ènìyàn Ọlọ́run,” Elijah sì dáhùn, “Ǹjẹ́ kí iná kí ó sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run kí ó sì jó ọ run àti àwọn àádọ́ta ènìyàn rẹ!” Nígbà náà iná Ọlọ́run sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run ó sì jó o run pẹ̀lú àwọn àádọ́ta ènìyàn rẹ̀.
Nake Elija akĩmũcookeria atĩrĩ, “Akorwo ndĩ mũndũ wa Ngai-rĩ, mwaki nĩũikũrũke uume igũrũ, ũgũcine hamwe na andũ aya aku mĩrongo ĩtano!” Hĩndĩ ĩyo mwaki wa Ngai ũgĩikũrũka kuuma igũrũ, ũgĩcina mũnene ũcio hamwe na andũ ake mĩrongo ĩtano.
13 Bẹ́ẹ̀ ni ọba tún rán balógun kẹta pẹ̀lú àwọn àádọ́ta ọkùnrin. Balógun ẹ̀ẹ̀kẹ́ta lọ sí òkè, ó sì kúnlẹ̀ lórí orókún rẹ̀ níwájú Elijah. “Ènìyàn Ọlọ́run,” Ó sì bẹ̀bẹ̀ pé, “Ìwọ ènìyàn Ọlọ́run, jọ̀wọ́ jẹ́ kí ẹ̀mí mi àti ẹ̀mí àwọn àádọ́ta ìránṣẹ́ rẹ wọ̀nyí ṣọ̀wọ́n ní ojú rẹ!
Nĩ ũndũ ũcio mũthamaki agĩtũma mũnene wa gatatũ na andũ ake mĩrongo ĩtano. Mũnene ũcio wa gatatũ akĩambata, agĩturia ndu mbere ya Elija. Akĩmũthaitha, akĩmwĩra atĩrĩ, “Wee mũndũ wa Ngai, reke muoyo wakwa na wa andũ aya mĩrongo ĩtano wonwo ũrĩ kĩndũ kĩrĩ bata nĩwe, ithuĩ ndungata ciaku!
14 Wò ó, iná ti sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run láti jó àwọn balógun méjì àràádọ́ta àkọ́kọ́ pẹ̀lú àràádọ́ta wọn. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ní ojúrere fún ẹ̀mí mi!”
Kĩone, mwaki nĩũikũrũkĩte kuuma igũrũ, na ũgacina anene acio eerĩ a mbere hamwe na andũ ao. No rĩrĩ, reke muoyo wakwa wonwo ũrĩ kĩndũ kĩrĩ bata nĩwe!”
15 Angẹli Olúwa sọ fún Elijah pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ pẹ̀lú rẹ̀; má ṣe bẹ̀rù rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni Elijah dìde ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ pẹ̀lú rẹ̀ sí ọ̀dọ̀ ọba.
Nake mũraika wa Jehova akĩĩra Elija atĩrĩ, “Ikũrũkania hamwe nake, na ndũkamwĩtigĩre.” Nĩ ũndũ ũcio Elija agĩũkĩra, agĩikũrũkania nake nginya kũrĩ mũthamaki.
16 Ó sọ fún ọba pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ‘Ṣé nítorí wí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli fún ọ láti pè ni ìwọ fi rán ìránṣẹ́ lọ sí ọ̀dọ̀ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni láti lọ ṣe ìwádìí?’ Nítorí pé o ṣe èyí, ìwọ kò ní dìde lórí ibùsùn tí o dùbúlẹ̀ lé láìsí àní àní ìwọ yóò kú!”
Nake akĩĩra mũthamaki atĩrĩ, “Jehova ekuuga ũũ: Nĩ Ngai gũtarĩ thĩinĩ wa Isiraeli wa kũhooywo ũhoro nĩwe, atĩ nĩkĩo ũgũtũma andũ makahooe ũhoro kũrĩ Baali-Zebubu, ngai ya Ekironi? Tondũ nĩwĩkĩte ũguo-rĩ, ndũrĩ hĩndĩ ũkoima gĩtanda-inĩ kĩu ũkomeire. Ti-itherũ nĩũgũkua!”
17 Bẹ́ẹ̀ ó sì kú, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí Elijah ti sọ. Nítorí Ahasiah kò ní ọmọ, Jehoramu jẹ ọba ní ọdún kejì tí Jehoramu ọmọ Jehoṣafati ọba Juda.
Nĩ ũndũ ũcio agĩkua, kũringana na kiugo kĩa Jehova kĩrĩa kĩarĩtio nĩ Elija. Na tondũ Ahazia ndaarĩ na mwana wa kahĩĩ-rĩ, Joramu nĩwe watuĩkire mũthamaki ithenya rĩake mwaka-inĩ wa keerĩ wa Jehoramu mũrũ wa Jehoshafatu mũthamaki wa Juda.
18 Àti ní ti gbogbo àwọn ohun tí ó ṣẹlẹ̀ nígbà ìjọba Ahasiah, àti ohun tí ó ṣe, ṣe a kò ha kọ wọ́n sí inú ìwé ọdọọdún ti àwọn ọba Israẹli?
Maũndũ marĩa mangĩ mothe makoniĩ wathani wa Ahazia, na marĩa eekire-rĩ, githĩ matiandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩa maũndũ ma ihinda rĩa athamaki a Isiraeli?