< 2 Kings 9 >

1 Wòlíì Eliṣa fi àṣẹ pe ọkùnrin kan láti ẹgbẹ́ àwọn wòlíì, ó sì wí fún un pé, “Ki agbádá rẹ sínú ọ̀já àmùrè rẹ, gba ṣágo kékeré òróró yìí pẹ̀lú rẹ, kí o sì lọ sí Ramoti Gileadi.
A prorok Elizeusz zawołał jednego z synów proroków i powiedział mu: Przepasz swoje biodra, weź do ręki ten dzban z oliwą i idź do Ramot-Gilead.
2 Nígbà tí o bá dé bẹ̀, wá Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi kiri. Lọ sí ọ̀dọ̀ ọ rẹ̀, mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀, kí o sì mú un wọ inú yàrá lọ́hùn ún lọ.
A gdy tam przybędziesz, zobaczysz tam Jehu, syna Jehoszafata, syna Nimsziego. Wejdź [tam], spraw, by powstał spośród swych braci i wprowadź go do najskrytszej komnaty.
3 Nígbà náà, mú ṣágo kékeré yìí, kí o sì da òróró náà lé e lórí, kí o sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’ Nígbà náà, ṣí ìlẹ̀kùn, kí o sì sáré, má ṣe jáfara!”
Następnie weź dzban oliwy, wylej na jego głowę i powiedz: Tak mówi PAN: Namaściłem cię na króla nad Izraelem. Potem otwórz drzwi i uciekaj, nie zwlekaj.
4 Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wòlíì náà lọ sí Ramoti Gileadi.
Poszedł więc ten młodzieniec – młody prorok – do Ramot-Gilead.
5 Nígbà tí ó dé, ó rí àwọn olórí ẹgbẹ́ ọmọ-ogun tí wọ́n jókòó papọ̀. “Èmi ní iṣẹ́ fún ọ, olórí,” Ó wí. “Sí ta ni nínú wa?” Jehu béèrè. Òun sì wí pé, “Sí ọ, balógun,” Ó dáhùn.
A gdy przybył, oto dowódcy wojska siedzieli. A on powiedział: Wodzu! Mam do ciebie słowo. Jehu zapytał: Do którego z nas wszystkich? I odpowiedział: Do ciebie, wodzu!
6 Jehu dìde sókè, ó sì wọ inú ilé lọ. Nígbà náà, wòlíì náà da òróró náà sórí Jehu; ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn Olúwa Israẹli.
Wtedy wstał i wszedł do domu, a tamten wylał oliwę na jego głowę i powiedział mu: Tak mówi PAN, Bóg Izraela: Namaściłem cię na króla nad ludem PANA, nad Izraelem.
7 Kí ìwọ kí ó pa ilé Ahabu ọ̀gá à rẹ̀ run, Èmi yóò sì gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ gbogbo àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì àti gbogbo ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Olúwa tí a ta sílẹ̀ látọwọ́ ọ Jesebeli.
Wytracisz dom Achaba, swego pana, ja bowiem pomszczę krew swoich sług, proroków i krew wszystkich sług PANA z ręki Jezabel.
8 Gbogbo ilé Ahabu yóò ṣègbé. Èmi yóò gé e kúrò láti orí Ahabu gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó gbẹ̀yìn ni Israẹli, ẹrú tàbí òmìnira.
I tak zginie cały dom Achaba. Wytępię [z domu] Achaba każdego, aż do najmniejszego szczenięcia, każdego więźnia i opuszczonego w Izraelu.
9 Èmi yóò ṣe ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati àti ilé Baaṣa ọmọ Ahijah.
I uczynię z domem Achaba jak z domem Jeroboama, syna Nebata, i jak z domem Baszy, syna Achiasza.
10 Fún Jesebeli, ajá ni yóò jẹ ẹ́ ní oko Jesreeli, kò sì sí ẹni tí yóò sin òkú rẹ̀.’” Nígbà náà ó ṣí ìlẹ̀kùn, ó sì sálọ.
Psy zjedzą Jezabel na polu Jizreel i nie będzie nikogo, kto ją pogrzebie. Potem otworzył drzwi i uciekł.
11 Nígbà tí Jehu jáde lọ bá àwọn ọgbà ìjòyè e rẹ̀, ọ̀kan nínú wọn sì bi í pé, “Ṣé gbogbo nǹkan dára?” Kí ni ó dé tí aṣiwèrè fi tọ̀ ọ́ wá, “Ìwọ mọ ọkùnrin náà àti irú nǹkan tí ó ń sọ,” Jehu fèsì.
A gdy Jehu wyszedł do sług swego pana, jeden z nich zapytał go: Czy wszystko dobrze? Po co ten szaleniec przyszedł do ciebie? Odpowiedział im: Wy znacie tego człowieka i jego słowa.
12 “Ìyẹn kì í ṣe òótọ́!” Wọ́n wí. “Sọ fún wa.” Jehu wí, “Èyí ni ohun tí ó sọ fún mi: ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’”
Oni powiedzieli: To nieprawda. Powiedz, proszę. A on powiedział: Tak a tak przemówił do mnie: Tak mówi PAN: Namaściłem cię na króla nad Izraelem.
13 Wọ́n ṣe gírí, wọ́n sì mú agbádá a wọn, wọ́n sì tàn wọ́n sí abẹ́ rẹ̀ ní orí àtẹ̀gùn. Nígbà náà, wọ́n fọn ìpè, wọ́n sì kígbe, “Jehu jẹ ọba!”
Wtedy wszyscy pospiesznie wzięli swoje szaty, podłożyli je pod niego na najwyższym stopniu, zadęli w trąbę i zawołali: Jehu jest królem!
14 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi, dìtẹ̀ sí Joramu. (Nísinsin yìí Joramu àti gbogbo Israẹli ti ń dáàbò bo Ramoti Gileadi nítorí Hasaeli ọba Aramu.
Wtedy Jehu, syn Jehoszafata, syna Nimsziego, uknuł spisek przeciw Joramowi. (A w tym czasie Joram wraz z całym Izraelem strzegł Ramot-Gilead przed Chazaelem, królem Syrii.
15 ṣùgbọ́n ọba Joramu ti padà sí Jesreeli láti lọ sàn nínú ọgbẹ́ tí àwọn ará Aramu ti dá sí i lára nínú ogun pẹ̀lú ọba Hasaeli ti Aramu.) Jehu wí pé, “Tí èyí bá jẹ́ ọ̀nà tí ò ń rò, má ṣe jẹ́ kí ẹnìkankan kí ó yọ jáde nínú ìlú ńlá láti lọ sọ ìròyìn náà ní Jesreeli.”
Lecz król Joram wrócił, by leczyć się w Jizreel z ran, które mu zadali Syryjczycy, gdy walczył z Chazaelem, królem Syrii). Jehu powiedział: Jeśli się na to zgadzacie, niech nikt nie wychodzi z miasta, aby pójść i oznajmić to w Jizreel.
16 Nígbà náà Jehu wọ inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ó sì gùn ún lọ sí Jesreeli, nítorí Joramu ń sinmi níbẹ̀ àti Ahasiah ọba Juda sì sọ̀kalẹ̀ láti wá wò Joramu.
Następnie Jehu wsiadł na rydwan i pojechał do Jizreel, bo tam leżał Joram. Także Achazjasz, król Judy, przyjechał, aby odwiedzić Jorama.
17 Nígbà tí olùṣọ́ kan tí ó dúró ní ilé ìṣọ́ ní Jesreeli, rí ọ̀wọ́ ogun Jehu tí wọ́n ń súnmọ́ tòsí, ó pè jáde, “Mo rí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí ó ń bọ̀.” “Mú ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kan,” Joramu pa á láṣẹ. “Rán an lọ sí ọ̀dọ̀ wọn kí o sì béèrè pé, ‘Ṣé ẹ̀yin wá pẹ̀lú àlàáfíà?’”
A gdy strażnik, który stał na wieży w Jizreel, zobaczył nadjeżdżający oddział Jehu, powiedział: Widzę oddział. Joram rzekł: Weź jeźdźca i wyślij [go] naprzeciw [nich], niech zapyta: Czy jest pokój?
18 Ọkùnrin ẹlẹ́ṣin náà, lọ láti lọ bá Jehu ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba wí: ‘Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?’” “Kí ni ìwọ ní ṣe pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu sì dáhùn. “Bọ́ sí ẹ̀yìn mi.” Olùṣọ́ náà sì wí fún un pé, “Ìránṣẹ́ náà ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́.”
Jeździec więc wyruszył mu naprzeciw i zapytał: Tak mówi król: Czy jest pokój? Jehu odpowiedział: Co tobie do pokoju? Zawróć i [jedź] za mną. Strażnik oznajmił: Posłaniec dotarł do nich, ale nie wraca.
19 Bẹ́ẹ̀ ni, ọba rán ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kejì. Nígbà náà ó wá sí ọ̀dọ̀ wọn, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba sọ: “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu dáhùn, “Dúró sí ẹ̀yìn mi.”
Wysłał więc drugiego jeźdźca, który przybył do nich i powiedział: Tak mówi król: Czy jest pokój? Jehu odpowiedział: Co tobie do pokoju? Zawróć i jedź za mną.
20 Olùṣọ́ náà sì fi sùn. “Ó ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́ pẹ̀lú. Wíwá rẹ̀ sì dàbí ti Jehu ọmọ Nimṣi, ó ń wa kẹ̀kẹ́ bí ti aṣiwèrè.”
Strażnik znowu oznajmił: Dotarł do nich, ale nie wraca. A jego jazda jest jak jazda Jehu, syna Nimsziego, bo jedzie jak szalony.
21 “Fi ìwọ̀ kọ́ kẹ̀kẹ́ ogun mi.” Joramu pa á láṣẹ. Àti nígbà tí a fi kọ́, Joramu ọba Israẹli àti Ahasiah ọba Juda, gun kẹ̀kẹ́ lọ, olúkúlùkù nínú kẹ̀kẹ́ ogun tirẹ̀, láti lọ bá Jehu. Wọ́n bá a pàdé ní ibi oko tí ó ti jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli.
Wtedy Joram powiedział: Zaprzęgaj. Zaprzężono więc jego rydwan. I Joram, król Izraela, i Achazjasz, król Judy, wyjechali, każdy na swoim rydwanie. Wyjechali naprzeciw Jehu i spotkali go na polu Nabota Jizreelity.
22 Nígbà tí Joramu rí Jehu, ó béèrè pé, “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà, Jehu?” “Báwo ni àlàáfíà yóò ṣe wà,” Jehu dáhùn, “Ní ìwọ̀n ìgbà tí gbogbo ìbọ̀rìṣà àti iṣẹ́ àjẹ́ ti màmá rẹ Jesebeli di púpọ̀?”
A gdy Joram zobaczył Jehu, zapytał: Czy jest pokój, Jehu? Odpowiedział: Co to za pokój, dopóki [trwają] cudzołóstwa Jezabel, twojej matki, i jej liczne czary.
23 Joramu yí ọwọ́ rẹ̀ padà, ó sì sálọ, ó sì ń pe Ahasiah, “Ọ̀tẹ̀ dé, Ahasiah!”
Wtedy Joram zawrócił i uciekł, mówiąc do Achazjasza: Zdrada, Achazjaszu!
24 Nígbà náà, Jehu fa ọrun rẹ̀, ó sì yin Joramu láàrín èjìká méjèèjì. Ọfà náà sì wọ inú ọkàn rẹ̀, ó sì ṣubú lulẹ̀ láti orí kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
A Jehu wziął do rąk łuk i trafił Jorama między ramiona tak, że strzała przeszyła jego serce, a on padł na swój rydwan.
25 Jehu sọ fún Bidikari, balógun kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Gbé e sókè kí ó sì jù ú sí orí oko tí ó jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli. Rántí bí èmi àti ìwọ ti ń gun kẹ̀kẹ́ papọ̀ lẹ́yìn Ahabu baba à rẹ nígbà tí Olúwa sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀,
Potem [Jehu] odezwał się do Bidkara, swego dowódcy: Weź go i porzuć na polu Nabota Jizreelity. Pamiętasz bowiem: gdy ja i ty jechaliśmy razem za Achabem, jego ojcem, PAN wydał przeciwko niemu ten wyrok:
26 ‘Ní àná, mo rí ẹ̀jẹ̀ Naboti pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ni Olúwa wí.’ Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ gbé e sókè, kí o sì jù ú sí orí ilẹ̀ oko náà ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa.”
Z pewnością widziałem wczoraj krew Nabota i krew jego synów – mówi PAN. I zemszczę się na tobie na tym polu – mówi PAN. Teraz więc weź go i porzuć na polu według słowa PANA.
27 Nígbà tí Ahasiah ọba, Juda rí ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀, ó sálọ sójú ọ̀nà sí Beti-Haggani. Jehu sì lépa rẹ̀, ó ń kígbe, “Pa á pẹ̀lú!” Wọ́n ṣá a ní ọgbẹ́ nínú kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ ní ọ̀nà lọ sí Guri lẹ́bàá a Ibleamu, ṣùgbọ́n ó sálọ sí Megido, ó sì kú síbẹ̀.
Gdy zobaczył to Achazjasz, król Judy, zaczął uciekać drogą do domu ogrodowego. Lecz Jehu ścigał go i polecił: Tego także zabijcie na jego rydwanie. I [zranili go] na wzniesieniu Gur, które jest przy Jibleam. Uciekł do Megiddo i tam umarł.
28 Ìránṣẹ́ rẹ̀ sì gbé e pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lọ sí Jerusalẹmu, ó sì sin ín pẹ̀lú, baba a rẹ̀ nínú ibojì rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Dafidi.
Jego słudzy przewieźli go do Jerozolimy i pogrzebali w jego grobie z jego ojcami w mieście Dawida.
29 (Ní ọdún kọkànlá ti Joramu ọmọ Ahabu, Ahasiah ti di ọba Juda.)
W jedenastym roku Jorama, syna Achaba, Achazjasz zaczął królować nad Judą.
30 Nígbà náà Jehu lọ sí Jesreeli. Nígbà tí Jesebeli gbọ́ nípa rẹ̀, ó kun ojú u rẹ̀, ó to irun rẹ̀, ó sì wò jáde láti ojú fèrèsé.
Potem Jehu przybył do Jizreel. Gdy Jezabel usłyszała o tym, pomalowała swoją twarz, upiększyła włosy i wyglądała przez okno.
31 Bí Jehu ti wọ ẹnu ìlẹ̀kùn, ó béèrè, “Ṣé ìwọ wá ní àlàáfíà, Simri, ìwọ olùpa ọ̀gá à rẹ?”
A gdy Jehu wjeżdżał przez bramę, zapytała: Czy miał pokój Zimri, który zabił swego pana?
32 Ó gbójú sókè láti wo fèrèsé, ó sì pè jáde, “Ta ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ mi? Ta ni?” Ìwẹ̀fà méjì tàbí mẹ́ta bojú wò ó nílẹ̀.
On zaś podniósł twarz ku oknu i zawołał: Kto [jest] ze mną? Kto? Wtedy wyjrzeli ku niemu dwaj [albo] trzej eunuchowie.
33 Jehu sọ wí pé, “Gbé e jù sílẹ̀!” Wọ́n sì jù ú sílẹ̀. Díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sì fọ́n sí ara ògiri àti àwọn ẹṣin bí wọ́n ti tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ wọn.
Powiedział im: Zrzućcie ją. Wtedy zrzucili ją. Jej krew obryzgała mur i konie, a on podeptał ją.
34 Jehu wọ inú ilé lọ, ó jẹ, ó sì mu. “Tọ́jú obìnrin yẹn tí a fi bú,” Ó wí, “Kí o sì sin ín, nítorí ọmọbìnrin ọba ni ó jẹ́.”
A gdy [tam] wszedł, najadł się i napił, potem powiedział: Zajmijcie się teraz tą przeklętą i pogrzebcie ją. Jest bowiem córką króla.
35 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde lọ láti lọ sin ín, wọn kò rí nǹkan kan àyàfi agbárí i rẹ̀, ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì àti ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì.
Poszli, aby ją pogrzebać, lecz nie znaleźli z niej nic poza czaszką, stopami i dłońmi.
36 Wọ́n padà lọ sọ fún Jehu, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah ará Tiṣibi wí pé, ‘Ní orí oko Jesreeli ni àwọn ajá yóò ti jẹ ẹran-ara Jesebeli.
Wrócili więc i oznajmili mu to. On zaś powiedział: [Wypełniło się] słowo PANA, które wypowiedział przez swego sługę Eliasza Tiszbitę: Na polu Jizreel psy zjedzą ciało Jezabel.
37 Òkú Jesebeli yóò dàbí ohun ẹ̀gbin ní orí oko Jesreeli, dé bi pé, ẹnikẹ́ni kì yóò lè sọ pé, “Jesebeli ni èyí.”’”
A trup Jezabel będzie jak gnój leżący na powierzchni roli, na polu Jizreel, tak że nikt nie powie: To jest Jezabel.

< 2 Kings 9 >