< 2 Kings 9 >

1 Wòlíì Eliṣa fi àṣẹ pe ọkùnrin kan láti ẹgbẹ́ àwọn wòlíì, ó sì wí fún un pé, “Ki agbádá rẹ sínú ọ̀já àmùrè rẹ, gba ṣágo kékeré òróró yìí pẹ̀lú rẹ, kí o sì lọ sí Ramoti Gileadi.
Elísá próféta pedig hívott egyet a prófétafiak közül; és mondta neki: Övezd föl derekadat, vedd ez olajkorsót kezedbe és menj Rámót-Gileádba.
2 Nígbà tí o bá dé bẹ̀, wá Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi kiri. Lọ sí ọ̀dọ̀ ọ rẹ̀, mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀, kí o sì mú un wọ inú yàrá lọ́hùn ún lọ.
Ha odaérkeztél, nézd ott Jéhút, Jehósáfátnak, Nimsí fiának fiát, akkor menj oda, szólítsd ki testvérei közül és vezesd őt be szobából szobába;
3 Nígbà náà, mú ṣágo kékeré yìí, kí o sì da òróró náà lé e lórí, kí o sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’ Nígbà náà, ṣí ìlẹ̀kùn, kí o sì sáré, má ṣe jáfara!”
és vedd az olajkorsót, önts a fejére és mondd: így szól az Örökkévaló: fölkentelek királynak Izraél fölött. Erre nyisd ki az ajtót és fuss el, s ne várakozzál.
4 Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wòlíì náà lọ sí Ramoti Gileadi.
Ment tehát az ifjú, a próféta ifjú, Rámót-Gileádba.
5 Nígbà tí ó dé, ó rí àwọn olórí ẹgbẹ́ ọmọ-ogun tí wọ́n jókòó papọ̀. “Èmi ní iṣẹ́ fún ọ, olórí,” Ó wí. “Sí ta ni nínú wa?” Jehu béèrè. Òun sì wí pé, “Sí ọ, balógun,” Ó dáhùn.
Odaért, s íme a sereg vezérei ott ültek, és szólt: Szavam van hozzád, oh vezér! Mondta Jéhú: Kihez mindnyájunk közül? És mondta: Hozzád, oh vezér!
6 Jehu dìde sókè, ó sì wọ inú ilé lọ. Nígbà náà, wòlíì náà da òróró náà sórí Jehu; ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn Olúwa Israẹli.
Erre fölkelt, bement a házba, és öntött olajat a fejére; s mondta neki: Így szól az Örökkévaló Izraél Istene: fölkentelek királynak az Örökkévaló népe fölött, Izraél fölött!
7 Kí ìwọ kí ó pa ilé Ahabu ọ̀gá à rẹ̀ run, Èmi yóò sì gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ gbogbo àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì àti gbogbo ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Olúwa tí a ta sílẹ̀ látọwọ́ ọ Jesebeli.
Hogy megverjed uradnak Achábnak házát, és bosszút álljak Izébelen szolgáimnak, a prófétáknak véréért és mind az Örökkévaló szolgáinak véréért;
8 Gbogbo ilé Ahabu yóò ṣègbé. Èmi yóò gé e kúrò láti orí Ahabu gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó gbẹ̀yìn ni Israẹli, ẹrú tàbí òmìnira.
hogy elvesszen Acháb egész háza; kiirtok Acháb házából falra vizelőt, elzártat és magára hagyottat Izraélben.
9 Èmi yóò ṣe ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati àti ilé Baaṣa ọmọ Ahijah.
És olyanná teszem Acháb házát, mint Járobeámnak, Nebát fiának házát és mint Báesának, Achíja fiának házát.
10 Fún Jesebeli, ajá ni yóò jẹ ẹ́ ní oko Jesreeli, kò sì sí ẹni tí yóò sin òkú rẹ̀.’” Nígbà náà ó ṣí ìlẹ̀kùn, ó sì sálọ.
Izébelt pedig megeszik a kutyák Jizreél határában, és nincs ki eltemeti. Ezzel kinyitotta az ajtót és elfutott.
11 Nígbà tí Jehu jáde lọ bá àwọn ọgbà ìjòyè e rẹ̀, ọ̀kan nínú wọn sì bi í pé, “Ṣé gbogbo nǹkan dára?” Kí ni ó dé tí aṣiwèrè fi tọ̀ ọ́ wá, “Ìwọ mọ ọkùnrin náà àti irú nǹkan tí ó ń sọ,” Jehu fèsì.
Jéhú pedig kiment urának szolgáihoz, és mondták neki: Béke van-e? Miért jött hozzád az az őrült? Szólt hozzájuk: Ti ismeritek azt az embert és beszédét.
12 “Ìyẹn kì í ṣe òótọ́!” Wọ́n wí. “Sọ fún wa.” Jehu wí, “Èyí ni ohun tí ó sọ fún mi: ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’”
De mondták: Hazugság! Csak mondd meg nekünk. Mondta: Így meg úgy szólt hozzám, mondván: így szól az Örökkévaló: fölkentelek királynak Izraél fölött!
13 Wọ́n ṣe gírí, wọ́n sì mú agbádá a wọn, wọ́n sì tàn wọ́n sí abẹ́ rẹ̀ ní orí àtẹ̀gùn. Nígbà náà, wọ́n fọn ìpè, wọ́n sì kígbe, “Jehu jẹ ọba!”
Erre siettek és vették kiki a ruháját és ő alája tették azt a lépcső tetején, megfútták a harsonát és mondták: király lett Jéhú.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi, dìtẹ̀ sí Joramu. (Nísinsin yìí Joramu àti gbogbo Israẹli ti ń dáàbò bo Ramoti Gileadi nítorí Hasaeli ọba Aramu.
Összeesküdött tehát Jéhú, Jehósáfátnak, Nimaí fiának fia, Jórám ellen, Jórám pedig megszállva tartotta Rámót-Gileádot, ő meg egész Izraél Chazáél, Arám királya ellenében.
15 ṣùgbọ́n ọba Joramu ti padà sí Jesreeli láti lọ sàn nínú ọgbẹ́ tí àwọn ará Aramu ti dá sí i lára nínú ogun pẹ̀lú ọba Hasaeli ti Aramu.) Jehu wí pé, “Tí èyí bá jẹ́ ọ̀nà tí ò ń rò, má ṣe jẹ́ kí ẹnìkankan kí ó yọ jáde nínú ìlú ńlá láti lọ sọ ìròyìn náà ní Jesreeli.”
De visszament Jehórám király, hogy gyógyíttassa magát Jizreélben a sebekből, melyeket ütöttek rajta az Arámbeliek, mikor harcolt Chazáél Arám királya ellen és mondta Jéhú: Ha nektek tetszik, ne menjen ki menekülő a városból, hogy elmenne jelenteni Jizréelbe.
16 Nígbà náà Jehu wọ inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ó sì gùn ún lọ sí Jesreeli, nítorí Joramu ń sinmi níbẹ̀ àti Ahasiah ọba Juda sì sọ̀kalẹ̀ láti wá wò Joramu.
És kocsira ült Jéhú és elment Jizreélbe, mert Jórám ott feküdt, Achazja pedig, Jehúda királya, lement volt, hogy meglátogassa Jórámot.
17 Nígbà tí olùṣọ́ kan tí ó dúró ní ilé ìṣọ́ ní Jesreeli, rí ọ̀wọ́ ogun Jehu tí wọ́n ń súnmọ́ tòsí, ó pè jáde, “Mo rí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí ó ń bọ̀.” “Mú ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kan,” Joramu pa á láṣẹ. “Rán an lọ sí ọ̀dọ̀ wọn kí o sì béèrè pé, ‘Ṣé ẹ̀yin wá pẹ̀lú àlàáfíà?’”
Az őr pedig ott állt a tornyon Jizreélben és látta Jéhúnak csapatját, amint jött; akkor mondta: Csapatot látok! Erre mondta Jehórám: Végy egy lovast és küldj elébök és szóljon: Béke van-e?
18 Ọkùnrin ẹlẹ́ṣin náà, lọ láti lọ bá Jehu ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba wí: ‘Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?’” “Kí ni ìwọ ní ṣe pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu sì dáhùn. “Bọ́ sí ẹ̀yìn mi.” Olùṣọ́ náà sì wí fún un pé, “Ìránṣẹ́ náà ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́.”
Elébe ment a lovas és mondta: Így szól a király: béke van-e? Mondta Jéhú: Mi közöd a békéhez? Fordulj én mögém! És az őr jelentette, mondván: Eljutott a követ hozzájuk, de vissza nem tért.
19 Bẹ́ẹ̀ ni, ọba rán ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kejì. Nígbà náà ó wá sí ọ̀dọ̀ wọn, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba sọ: “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu dáhùn, “Dúró sí ẹ̀yìn mi.”
Erre küldött egy másik lovast; hozzájuk jutott és mondta: Így szól a király: béke van-e? Mondta Jéhú: Mi közöd a békéhez? Fordulj én mögém!
20 Olùṣọ́ náà sì fi sùn. “Ó ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́ pẹ̀lú. Wíwá rẹ̀ sì dàbí ti Jehu ọmọ Nimṣi, ó ń wa kẹ̀kẹ́ bí ti aṣiwèrè.”
És az őr jelentette, mondván: Egészen hozzájuk ért, de vissza nem tért; a hajtás pedig olyan, mint Jéhú, Nimsí fiának hajtása, mert őrületesen hajt.
21 “Fi ìwọ̀ kọ́ kẹ̀kẹ́ ogun mi.” Joramu pa á láṣẹ. Àti nígbà tí a fi kọ́, Joramu ọba Israẹli àti Ahasiah ọba Juda, gun kẹ̀kẹ́ lọ, olúkúlùkù nínú kẹ̀kẹ́ ogun tirẹ̀, láti lọ bá Jehu. Wọ́n bá a pàdé ní ibi oko tí ó ti jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli.
Erre mondta Jehórám: Fogj be! És befogták a kocsiját. És kiment Jehórám, Izraél királya, meg Achazjáhú, Jehúda királya, kiki a maga kocsiján és kimentek Jéhú elébe és találták őt a Jizreélbeli Nábót telkén.
22 Nígbà tí Joramu rí Jehu, ó béèrè pé, “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà, Jehu?” “Báwo ni àlàáfíà yóò ṣe wà,” Jehu dáhùn, “Ní ìwọ̀n ìgbà tí gbogbo ìbọ̀rìṣà àti iṣẹ́ àjẹ́ ti màmá rẹ Jesebeli di púpọ̀?”
És volt, a mint Jehórám meglátta Jéhút, mondta: Béke van-e Jéhú? Mondta: Mit békét, a míg tartanak Ízébel anyádnak paráználkodásai és sok boszorkánysága?
23 Joramu yí ọwọ́ rẹ̀ padà, ó sì sálọ, ó sì ń pe Ahasiah, “Ọ̀tẹ̀ dé, Ahasiah!”
Ekkor megfordította Jehórám a kezeit és megfutamodott. Így szólt Achazjáhúhoz: Árulás, Achazja!
24 Nígbà náà, Jehu fa ọrun rẹ̀, ó sì yin Joramu láàrín èjìká méjèèjì. Ọfà náà sì wọ inú ọkàn rẹ̀, ó sì ṣubú lulẹ̀ láti orí kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
De Jéhú meghúzta kezével az íjat és találta Jehórámot a lapockák között, úgy hogy szívéből jött ki a nyíl és összerogyott kocsijában.
25 Jehu sọ fún Bidikari, balógun kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Gbé e sókè kí ó sì jù ú sí orí oko tí ó jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli. Rántí bí èmi àti ìwọ ti ń gun kẹ̀kẹ́ papọ̀ lẹ́yìn Ahabu baba à rẹ nígbà tí Olúwa sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀,
És szólt Bidkárhoz, a hadnagyához: Vedd föl, dobd őt a Jizreélbeli Nábót mezejének telkére; mert emlékezzél, hogy én és te párosan nyargaltunk Acháb, az ő atyja után és az Örökkévaló kimondta ellene ezt a kijelentést:
26 ‘Ní àná, mo rí ẹ̀jẹ̀ Naboti pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ni Olúwa wí.’ Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ gbé e sókè, kí o sì jù ú sí orí ilẹ̀ oko náà ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa.”
bizony Nábótnak ontott vérét és fiainak ontott vérét láttam tegnap, úgy mond az Örökkévaló, de megfizetem neked ezen a telken, úgy mond az Örökkévaló. Most tehát vedd fel, dobd őt a telekre, az Örökkévaló igéje szerint.
27 Nígbà tí Ahasiah ọba, Juda rí ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀, ó sálọ sójú ọ̀nà sí Beti-Haggani. Jehu sì lépa rẹ̀, ó ń kígbe, “Pa á pẹ̀lú!” Wọ́n ṣá a ní ọgbẹ́ nínú kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ ní ọ̀nà lọ sí Guri lẹ́bàá a Ibleamu, ṣùgbọ́n ó sálọ sí Megido, ó sì kú síbẹ̀.
Achazja pedig, Jehúda királya, látta és megfutamodott a kert házának útján; de üldözőbe vette őt Jéhú és mondta: Őt is üssétek le a kocsiban, a Jibleám mellett levő Gúr hágóján. Megfutamodott Megiddóig és meghalt ott.
28 Ìránṣẹ́ rẹ̀ sì gbé e pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lọ sí Jerusalẹmu, ó sì sin ín pẹ̀lú, baba a rẹ̀ nínú ibojì rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Dafidi.
Jeruzsálembe szállították őt szolgái és eltemették őt sírjában ősei mellett, Dávid városában.
29 (Ní ọdún kọkànlá ti Joramu ọmọ Ahabu, Ahasiah ti di ọba Juda.)
Tizenegyedik évében pedig Jórámnak, Acháb fiának, király lett Achazja Jehúda fölött.
30 Nígbà náà Jehu lọ sí Jesreeli. Nígbà tí Jesebeli gbọ́ nípa rẹ̀, ó kun ojú u rẹ̀, ó to irun rẹ̀, ó sì wò jáde láti ojú fèrèsé.
Bevonult Jéhú Jizreélbe, Ízébel pedig hallotta, kendőzte a szemeit és ékesítette fejét és kitekintett az ablakon.
31 Bí Jehu ti wọ ẹnu ìlẹ̀kùn, ó béèrè, “Ṣé ìwọ wá ní àlàáfíà, Simri, ìwọ olùpa ọ̀gá à rẹ?”
Mikor Jéhú bejött a kapun, mondta: Béke van-e, te Zimrí, uradnak gyilkosa?
32 Ó gbójú sókè láti wo fèrèsé, ó sì pè jáde, “Ta ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ mi? Ta ni?” Ìwẹ̀fà méjì tàbí mẹ́ta bojú wò ó nílẹ̀.
Erre fölemelte arcát az ablak felé és mondta: Ki van velem? Ki? És kitekintett feléje két-három udvari tiszt.
33 Jehu sọ wí pé, “Gbé e jù sílẹ̀!” Wọ́n sì jù ú sílẹ̀. Díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sì fọ́n sí ara ògiri àti àwọn ẹṣin bí wọ́n ti tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ wọn.
Akkor mondta: Lökjétek le! És lelökték. És freccsent véréből a falra és a lovakra, őt meg összetaposta.
34 Jehu wọ inú ilé lọ, ó jẹ, ó sì mu. “Tọ́jú obìnrin yẹn tí a fi bú,” Ó wí, “Kí o sì sin ín, nítorí ọmọbìnrin ọba ni ó jẹ́.”
Bement, evett és ivott; ekkor mondta: Nézzetek csak utána ennek az átkozottnak és temessétek el, mert király leánya ő!
35 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde lọ láti lọ sin ín, wọn kò rí nǹkan kan àyàfi agbárí i rẹ̀, ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì àti ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì.
Mentek tehát hogy eltemessék, de nem találtak belőle semmit, csak a koponyát, a két lábát és a két keze fejét.
36 Wọ́n padà lọ sọ fún Jehu, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah ará Tiṣibi wí pé, ‘Ní orí oko Jesreeli ni àwọn ajá yóò ti jẹ ẹran-ara Jesebeli.
Visszatértek és tudtára adták neki. Ekkor mondta: az Örökkévaló igéje az, melyet szólt az ő szolgája, a Tisbébeli Élijáhú által, mondván: Jizreél határában eszik meg a kutyák Ízébel húsát.
37 Òkú Jesebeli yóò dàbí ohun ẹ̀gbin ní orí oko Jesreeli, dé bi pé, ẹnikẹ́ni kì yóò lè sọ pé, “Jesebeli ni èyí.”’”
És lesz Ízébel hullája mint a trágya a mező színén Jizreél határában, úgy hogy senki nem mondhatja: ez Ízébel.

< 2 Kings 9 >