< 2 Kings 9 >

1 Wòlíì Eliṣa fi àṣẹ pe ọkùnrin kan láti ẹgbẹ́ àwọn wòlíì, ó sì wí fún un pé, “Ki agbádá rẹ sínú ọ̀já àmùrè rẹ, gba ṣágo kékeré òróró yìí pẹ̀lú rẹ, kí o sì lọ sí Ramoti Gileadi.
A KAHEA aku la o Elisai ke kaula i kekahi o na haumana a ka poe kaula, i aku la ia ia, E kaei oe i kou puhaka, a lawe i keia hue aila ma kou lima, a e hele aku i Ramota-Gileada.
2 Nígbà tí o bá dé bẹ̀, wá Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi kiri. Lọ sí ọ̀dọ̀ ọ rẹ̀, mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀, kí o sì mú un wọ inú yàrá lọ́hùn ún lọ.
A hiki oe ilaila, e imi aku oe ilaila ia Iehu, ko keiki a Iehosapata, ke keiki a Nimesi, a komo aku oe, a hooku ia ia mai waena mai o kona poe hoahanau, a hookomo ia ia i ke keena maloko.
3 Nígbà náà, mú ṣágo kékeré yìí, kí o sì da òróró náà lé e lórí, kí o sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’ Nígbà náà, ṣí ìlẹ̀kùn, kí o sì sáré, má ṣe jáfara!”
Alaila e lawe oe i ka hue aila, a e ninini maluna o kona poo, a e i aku, Ke olelo mai nei o Iehova peneia, Ua poni aku au ia oe i alii maluna o ka Iseraela. Alaila e wehe ae oe i ka puka, a holo aku, mai kali oe.
4 Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wòlíì náà lọ sí Ramoti Gileadi.
A hele aku la ke kanaka ui i Ramota-Gileada, he kaula hoi ua kanaka ui la.
5 Nígbà tí ó dé, ó rí àwọn olórí ẹgbẹ́ ọmọ-ogun tí wọ́n jókòó papọ̀. “Èmi ní iṣẹ́ fún ọ, olórí,” Ó wí. “Sí ta ni nínú wa?” Jehu béèrè. Òun sì wí pé, “Sí ọ, balógun,” Ó dáhùn.
A hiki aku ia, aia hoi, e noho ana na luna o ke kaua; i aku la ia, Ho wahi olelo ka'u ia oe, e ka luna. I mai la o Iehu, Ia wai o makou a pau? I aku la ia, Ia oe, e ka luna.
6 Jehu dìde sókè, ó sì wọ inú ilé lọ. Nígbà náà, wòlíì náà da òróró náà sórí Jehu; ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn Olúwa Israẹli.
Ku ae la ia a komo iloko o ka hale; a ninini iho la ia i ka aila maluna o kona poo. a i aku la ia ia, Ke olelo mai nei o Iehova ke Akua o ka Iseraela, Ua poni aku au ia oe i alii maluna o na kanaka o Iehova, maluna o ka Iseraela.
7 Kí ìwọ kí ó pa ilé Ahabu ọ̀gá à rẹ̀ run, Èmi yóò sì gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ gbogbo àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì àti gbogbo ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Olúwa tí a ta sílẹ̀ látọwọ́ ọ Jesebeli.
A e pepehi aku oe i ko ka hale o Ahaba kou haku, i hoopai aku ai au i ko koko o ka'u poe kauwa, o na kaula, a me ke koko o na kauwa a pau a Iehova ma ka lima o Iezebela.
8 Gbogbo ilé Ahabu yóò ṣègbé. Èmi yóò gé e kúrò láti orí Ahabu gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó gbẹ̀yìn ni Israẹli, ẹrú tàbí òmìnira.
A e pau auanei ko ka hale a pau o Ahaba; a oki aku au i na kane a pau no Ahaba, a o ka mea i paa, a me ka mea i paa ole iloko o ka Iseraela.
9 Èmi yóò ṣe ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati àti ilé Baaṣa ọmọ Ahijah.
A e hana like aku au i ko ka hale o Ahaba me ko ka hale o Ieroboama ke keiki a Nebata, a me ko ka hale o Baasa, ke keiki a Ahiia.
10 Fún Jesebeli, ajá ni yóò jẹ ẹ́ ní oko Jesreeli, kò sì sí ẹni tí yóò sin òkú rẹ̀.’” Nígbà náà ó ṣí ìlẹ̀kùn, ó sì sálọ.
A e ai na ilio ia Iezebela ma ka aina i Iezereela, aohe mea nana ia e kanu. A wehe ae la ia i ka puka, a holo aku la.
11 Nígbà tí Jehu jáde lọ bá àwọn ọgbà ìjòyè e rẹ̀, ọ̀kan nínú wọn sì bi í pé, “Ṣé gbogbo nǹkan dára?” Kí ni ó dé tí aṣiwèrè fi tọ̀ ọ́ wá, “Ìwọ mọ ọkùnrin náà àti irú nǹkan tí ó ń sọ,” Jehu fèsì.
Alaila puka iwaho o Iehu i na kauwa a kona haku, a ninau mai kekahi ia ia, He pono anei? No ke aha la i hele mai ai keia hehena i ou la? I aku la ia ia lakou, Ua ike oukou i ke kanaka, a me kana olelo.
12 “Ìyẹn kì í ṣe òótọ́!” Wọ́n wí. “Sọ fún wa.” Jehu wí, “Èyí ni ohun tí ó sọ fún mi: ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’”
I aku la lakou ia ia, He wahahee; e hai mai oe ia makou ano. I mai la ia, Me neia, me neia kana i olelo mai ai ia'u, i mai la, Ke i mai nei o Iehova peneia, Ua poni aku au ia oe i alii maluna o ka Iseraela.
13 Wọ́n ṣe gírí, wọ́n sì mú agbádá a wọn, wọ́n sì tàn wọ́n sí abẹ́ rẹ̀ ní orí àtẹ̀gùn. Nígbà náà, wọ́n fọn ìpè, wọ́n sì kígbe, “Jehu jẹ ọba!”
Alaila wikiwiki lakou, a lawe ae la kela kanaka keia kanaka i kona aahu, a waiho malalo iho ona maluna o ke alapii, a puhi i na pu, i aku la, E alii ana o Iehu.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi, dìtẹ̀ sí Joramu. (Nísinsin yìí Joramu àti gbogbo Israẹli ti ń dáàbò bo Ramoti Gileadi nítorí Hasaeli ọba Aramu.
A kipi iho la o Iehu ke keiki a Iehosapata, ke keiki a Nimesi, ia Iorama. (A o Iorama e kiai ana ia ma Ramota-Gileada, oia, a me ka Iseraela a pau, no Hazaela ke alii o Suria.
15 ṣùgbọ́n ọba Joramu ti padà sí Jesreeli láti lọ sàn nínú ọgbẹ́ tí àwọn ará Aramu ti dá sí i lára nínú ogun pẹ̀lú ọba Hasaeli ti Aramu.) Jehu wí pé, “Tí èyí bá jẹ́ ọ̀nà tí ò ń rò, má ṣe jẹ́ kí ẹnìkankan kí ó yọ jáde nínú ìlú ńlá láti lọ sọ ìròyìn náà ní Jesreeli.”
A ua hoi aku o Iorama ke alii ma Iezereela e hoolaia i kona eha a ko Suria i hana eha ai ia ia, i kona manawa i kaua aku ai ia Hazaela ke alii o Suria.) A i aku la o Iehu, Ina oukou e manao, mai puka aku e pakele kekahi mai ke kulanakauhale aku e hele ia e hai aku ma Iezereela.
16 Nígbà náà Jehu wọ inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ó sì gùn ún lọ sí Jesreeli, nítorí Joramu ń sinmi níbẹ̀ àti Ahasiah ọba Juda sì sọ̀kalẹ̀ láti wá wò Joramu.
A holo aku la o Iehu ma ka halekaa, a hele aku la i Iezereela; no ka mea, e waiho ana o Iorama malaila. A ua iho mai o Ahazia, ke alii o ka Iuda, e ike ia Iorama.
17 Nígbà tí olùṣọ́ kan tí ó dúró ní ilé ìṣọ́ ní Jesreeli, rí ọ̀wọ́ ogun Jehu tí wọ́n ń súnmọ́ tòsí, ó pè jáde, “Mo rí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí ó ń bọ̀.” “Mú ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kan,” Joramu pa á láṣẹ. “Rán an lọ sí ọ̀dọ̀ wọn kí o sì béèrè pé, ‘Ṣé ẹ̀yin wá pẹ̀lú àlàáfíà?’”
A e ku ana ke kanaka kiai maluna o ka hale kiai ma Iezereela, a ike aku la ia i ka poe nui o Iehu i kona hele ana mai, i aku la ia, Ke ike nei au i ka poe nui. I mai la o Iorama, e lawe oe i ka hooholelio, a e hoouna aku e halawai me lakou, a e ninau aku ia, He aloha anei?
18 Ọkùnrin ẹlẹ́ṣin náà, lọ láti lọ bá Jehu ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba wí: ‘Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?’” “Kí ni ìwọ ní ṣe pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu sì dáhùn. “Bọ́ sí ẹ̀yìn mi.” Olùṣọ́ náà sì wí fún un pé, “Ìránṣẹ́ náà ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́.”
A holo aku la kekahi maluna o ka lio e halawai me ia, a i aku la, Ke olelo mai nei ke alii peneia, He aloha anei? I aku la o Iehu, Heaha kau i ke aloha? e huli ae oe mahope o'u. A hai aku la ke kanaka kiai, i aku la, Hele aku la ke elele io lakou la, aole i hoi hou mai.
19 Bẹ́ẹ̀ ni, ọba rán ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kejì. Nígbà náà ó wá sí ọ̀dọ̀ wọn, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba sọ: “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu dáhùn, “Dúró sí ẹ̀yìn mi.”
A hoouna hou aku la ia i ka lua maluna o ka lio a hiki aku la ia io lakou la, i aku la, Ke olelo mai nei ke alii peneia, He aloha anei? I aku la o Iehu, Heaha kau i ke aloha? E huli ae oe mahope o'u.
20 Olùṣọ́ náà sì fi sùn. “Ó ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́ pẹ̀lú. Wíwá rẹ̀ sì dàbí ti Jehu ọmọ Nimṣi, ó ń wa kẹ̀kẹ́ bí ti aṣiwèrè.”
A hai aku la ke kiai, i aku la, Ua hele aku ia io lakou la, aole i hoi hou mai; a o ka holo ana, ua like me ka holo ana o Iehu ke keiki a Nimesi, no ka mea, ke holo la ia e like me ka hehena huhu.
21 “Fi ìwọ̀ kọ́ kẹ̀kẹ́ ogun mi.” Joramu pa á láṣẹ. Àti nígbà tí a fi kọ́, Joramu ọba Israẹli àti Ahasiah ọba Juda, gun kẹ̀kẹ́ lọ, olúkúlùkù nínú kẹ̀kẹ́ ogun tirẹ̀, láti lọ bá Jehu. Wọ́n bá a pàdé ní ibi oko tí ó ti jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli.
I aku o Iorama, E hoomakaukau; a hoomakaukauia iho la kona halekaa. A hele aku la o Iorama ke alii o ka Iseraela, a o Ahazia ke alii o ka Iuda, o kela keia ma kona halekaa iho, a hele aku e halawai me Iehu, a loaa ia lakou ia ma ka aina o Nabota no Iezereela.
22 Nígbà tí Joramu rí Jehu, ó béèrè pé, “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà, Jehu?” “Báwo ni àlàáfíà yóò ṣe wà,” Jehu dáhùn, “Ní ìwọ̀n ìgbà tí gbogbo ìbọ̀rìṣà àti iṣẹ́ àjẹ́ ti màmá rẹ Jesebeli di púpọ̀?”
A i ka manawa i ike ai o Iorama ia Iehu, i aku la ia, He aloha anei, e Iehu? Ninau mai la ia, Heaha ke aloha i ka manawa i nui loa ai na hoomanakii o Iezebela kou makuwahine, a me ka anaana ana?
23 Joramu yí ọwọ́ rẹ̀ padà, ó sì sálọ, ó sì ń pe Ahasiah, “Ọ̀tẹ̀ dé, Ahasiah!”
A huli ae la o Iorama, a holo aku la, a i aku la ia Ahazia, He kipi, e Ahazia.
24 Nígbà náà, Jehu fa ọrun rẹ̀, ó sì yin Joramu láàrín èjìká méjèèjì. Ọfà náà sì wọ inú ọkàn rẹ̀, ó sì ṣubú lulẹ̀ láti orí kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
A lawe o Iehu i ke kikoo ma kona lima, a pana aku la ia Iorama mawaena o kona mau lima, a puka aku la ka pua ma kona puuwai, a haule iho la ia maloko o kona halekaa.
25 Jehu sọ fún Bidikari, balógun kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Gbé e sókè kí ó sì jù ú sí orí oko tí ó jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli. Rántí bí èmi àti ìwọ ti ń gun kẹ̀kẹ́ papọ̀ lẹ́yìn Ahabu baba à rẹ nígbà tí Olúwa sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀,
Alaila i aku la oia ia Bidekara i kona luna, E kaikai, a hoolei aku ia ia iloko o ka aina kihapai o Nabota no Iezereela; no ka mea, e hoomanao oe i ka wa a kaua elua i holo pu ai, mamuli o Ahaba kona makuakane, ua kau mai o Iehova i keia mea kaumaha maluna iho ona.
26 ‘Ní àná, mo rí ẹ̀jẹ̀ Naboti pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ni Olúwa wí.’ Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ gbé e sókè, kí o sì jù ú sí orí ilẹ̀ oko náà ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa.”
Ua ike io no au inehinei i ke koko o Nabota, a me ke koko o kana mau keiki, wahi a Iehova; a e hoopai aka au ia oe ma keia aina, wahi a Iehova. Ano hoi, e lawe, a e hoolei aku ia ia iloko o ua aina la, e like me ka olelo a Iehova.
27 Nígbà tí Ahasiah ọba, Juda rí ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀, ó sálọ sójú ọ̀nà sí Beti-Haggani. Jehu sì lépa rẹ̀, ó ń kígbe, “Pa á pẹ̀lú!” Wọ́n ṣá a ní ọgbẹ́ nínú kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ ní ọ̀nà lọ sí Guri lẹ́bàá a Ibleamu, ṣùgbọ́n ó sálọ sí Megido, ó sì kú síbẹ̀.
A ike aku la o Ahazia ke alii o ka Iuda, alaila holo aku la ia ma ke ala o ka hale ma ke kihapai. A hahai aku la o Iehu mahope ona, a i aku la ia, E pepehi aku ia ia hoi ma ka halekaa i ka pii ana ma Gura, e kokoke ana i Ibeleama. A holo aku la ia i Megido, a make iho la ilaila.
28 Ìránṣẹ́ rẹ̀ sì gbé e pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lọ sí Jerusalẹmu, ó sì sin ín pẹ̀lú, baba a rẹ̀ nínú ibojì rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Dafidi.
A lawe aku la kana poe kauwa ia ia maloko o ka halekaa i Ierusalema, a kanu iho la ia ia iloko o ka halelua me kona poe kupuna ma ke kulanakauhale o Davida.
29 (Ní ọdún kọkànlá ti Joramu ọmọ Ahabu, Ahasiah ti di ọba Juda.)
I ka umikumamakahi o ka makahiki o Iorama ke keiki a Ahaba, hoomaka iho la o Ahazia e noho alii maluna o ka Iuda.
30 Nígbà náà Jehu lọ sí Jesreeli. Nígbà tí Jesebeli gbọ́ nípa rẹ̀, ó kun ojú u rẹ̀, ó to irun rẹ̀, ó sì wò jáde láti ojú fèrèsé.
A hiki aku la o Iehu i Iezereela, lohe ae la o Iezebela; a pena iho la ia i kona maka, a hooponopono i kona poo, a nana mai la ma ka pukamakani.
31 Bí Jehu ti wọ ẹnu ìlẹ̀kùn, ó béèrè, “Ṣé ìwọ wá ní àlàáfíà, Simri, ìwọ olùpa ọ̀gá à rẹ?”
A komo aku la o Iehu ma ka pukapa, ninau mai la keia, I maluhia anei o Zimeri, nana i pepehi kona haku?
32 Ó gbójú sókè láti wo fèrèsé, ó sì pè jáde, “Ta ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ mi? Ta ni?” Ìwẹ̀fà méjì tàbí mẹ́ta bojú wò ó nílẹ̀.
A nana aku la ia iluna ma ka pukamakani, i aku la, Owai ka mea ma o'u nei? Owai? A nana mai la ia ia elua a ekolu paha mau luna hale.
33 Jehu sọ wí pé, “Gbé e jù sílẹ̀!” Wọ́n sì jù ú sílẹ̀. Díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sì fọ́n sí ara ògiri àti àwọn ẹṣin bí wọ́n ti tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ wọn.
I aku la ia, E hoolei mai ia ia ilalo. A hoolei iho la lakou ia ia ilalo, a helelei iho kekahi o kona koko ma ka papohaku, a maluna o na lio: a hehiia iho la ia malalo o na wawae.
34 Jehu wọ inú ilé lọ, ó jẹ, ó sì mu. “Tọ́jú obìnrin yẹn tí a fi bú,” Ó wí, “Kí o sì sin ín, nítorí ọmọbìnrin ọba ni ó jẹ́.”
A komo aku la ia maloko, a ai iho la ia, a inu hoi, a i aku la, E hele, e nana aku ano i keia mea i hoinoia, a e kanu aku ia ia, no ka mea, he kaikamahine ia a kekahi alii.
35 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde lọ láti lọ sin ín, wọn kò rí nǹkan kan àyàfi agbárí i rẹ̀, ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì àti ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì.
A hele aku la lakou e kanu ia ia, aole i loaa ia lakou kekahi mea ona, o ka puniu wale no, a me na wawae, a me na poho lima.
36 Wọ́n padà lọ sọ fún Jehu, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah ará Tiṣibi wí pé, ‘Ní orí oko Jesreeli ni àwọn ajá yóò ti jẹ ẹran-ara Jesebeli.
No ia mea, hoi mai lakou, hai aku ia ia. I mai la ia, O keia ka olelo a Iehova ana i olelo mai ai, ma kana kauwa, ma Elia no Tiseba, i ka i ana'e, Ma ka aina i Iezereela e ai iho ai na ilio i ka io o Iezebela.
37 Òkú Jesebeli yóò dàbí ohun ẹ̀gbin ní orí oko Jesreeli, dé bi pé, ẹnikẹ́ni kì yóò lè sọ pé, “Jesebeli ni èyí.”’”
A e like auanei ke kupapau o Iezebela me ka lepo maluna o ke kula o ka aina i Iezereela; nolaila, aole lakou e olelo ae, O Iezebela keia.

< 2 Kings 9 >