< 2 Kings 9 >

1 Wòlíì Eliṣa fi àṣẹ pe ọkùnrin kan láti ẹgbẹ́ àwọn wòlíì, ó sì wí fún un pé, “Ki agbádá rẹ sínú ọ̀já àmùrè rẹ, gba ṣágo kékeré òróró yìí pẹ̀lú rẹ, kí o sì lọ sí Ramoti Gileadi.
Forsothe Elisee, the prophete, clepide oon of the sones of prophetis, and seide to hym, Girde thi leendis, and take this vessel of oile in thin hond, and go in to Ramoth of Galaad.
2 Nígbà tí o bá dé bẹ̀, wá Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi kiri. Lọ sí ọ̀dọ̀ ọ rẹ̀, mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀, kí o sì mú un wọ inú yàrá lọ́hùn ún lọ.
And whanne thou schalt come thidur, thou schalt se Hieu, sone of Josephat, sone of Namsi; and thou schalt entre, and schalt reise hym fro the myddis of hise britheren, and thou schalt lede hym in to the ynnere closet.
3 Nígbà náà, mú ṣágo kékeré yìí, kí o sì da òróró náà lé e lórí, kí o sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’ Nígbà náà, ṣí ìlẹ̀kùn, kí o sì sáré, má ṣe jáfara!”
And thou schalt holde the vessel of oile, and schalt schede on his heed, and schalt seie, The Lord seith these thingis, I haue anoyntid thee in to kyng on Israel; and thou schalt opene the dore, and schalt flee, and schalt not abide there.
4 Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wòlíì náà lọ sí Ramoti Gileadi.
Therfor the yong wexynge man, the child of the prophete, yede in to Ramoth of Galaad, and entride thidur.
5 Nígbà tí ó dé, ó rí àwọn olórí ẹgbẹ́ ọmọ-ogun tí wọ́n jókòó papọ̀. “Èmi ní iṣẹ́ fún ọ, olórí,” Ó wí. “Sí ta ni nínú wa?” Jehu béèrè. Òun sì wí pé, “Sí ọ, balógun,” Ó dáhùn.
Lo! sotheli the princes of the oost saten; and he seide, A! prince, Y haue a word to thee. And Hieu seide, To whom of alle vs? And he seide, To thee, thou prince.
6 Jehu dìde sókè, ó sì wọ inú ilé lọ. Nígbà náà, wòlíì náà da òróró náà sórí Jehu; ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn Olúwa Israẹli.
And he roos, and entride into the closet. And thilk child schedde oile on the heed of hym, and seide, The Lord God of Israel seith these thingis, Y haue anointid thee in to kyng on the puple of the Lord of Israel; and thou schalt smyte the hows of Achab,
7 Kí ìwọ kí ó pa ilé Ahabu ọ̀gá à rẹ̀ run, Èmi yóò sì gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ gbogbo àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì àti gbogbo ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Olúwa tí a ta sílẹ̀ látọwọ́ ọ Jesebeli.
thi lord, that Y venge the blood of my seruauntis prophetis, and the blood of alle the seruauntis of the Lord, of the hond of Jezabel.
8 Gbogbo ilé Ahabu yóò ṣègbé. Èmi yóò gé e kúrò láti orí Ahabu gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó gbẹ̀yìn ni Israẹli, ẹrú tàbí òmìnira.
And Y schal lese al the hows of Achab, and Y schal sle of the hows of Achab a pissere to the wal, and closid, and the laste in Israel.
9 Èmi yóò ṣe ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati àti ilé Baaṣa ọmọ Ahijah.
And Y schal yyue the hows of Achab as the hows of Jeroboam, sone of Nabat, and as the hous of Baasa, sone of Ahia.
10 Fún Jesebeli, ajá ni yóò jẹ ẹ́ ní oko Jesreeli, kò sì sí ẹni tí yóò sin òkú rẹ̀.’” Nígbà náà ó ṣí ìlẹ̀kùn, ó sì sálọ.
Also doggis schulen ete Jezabel in the feeld of Jezrael; and `noon schal be that schal birie hir. And `the child openyde the dore, and fledde.
11 Nígbà tí Jehu jáde lọ bá àwọn ọgbà ìjòyè e rẹ̀, ọ̀kan nínú wọn sì bi í pé, “Ṣé gbogbo nǹkan dára?” Kí ni ó dé tí aṣiwèrè fi tọ̀ ọ́ wá, “Ìwọ mọ ọkùnrin náà àti irú nǹkan tí ó ń sọ,” Jehu fèsì.
Forsothe Hieu yede out to the seruauntis of his lord, whiche seiden to hym, Whether alle thingis ben riytfuli? What cam this wood man to thee? Which seide to hem, Ye knowen the man, and what he spak.
12 “Ìyẹn kì í ṣe òótọ́!” Wọ́n wí. “Sọ fún wa.” Jehu wí, “Èyí ni ohun tí ó sọ fún mi: ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’”
And thei answeriden, It is fals; but more telle thou to vs. Which seide to hem, He spak these and these thingis to me, and seide, The Lord seith these thingis, Y haue anoyntid thee kyng on Israel.
13 Wọ́n ṣe gírí, wọ́n sì mú agbádá a wọn, wọ́n sì tàn wọ́n sí abẹ́ rẹ̀ ní orí àtẹ̀gùn. Nígbà náà, wọ́n fọn ìpè, wọ́n sì kígbe, “Jehu jẹ ọba!”
Therfor thei hastiden, and ech man took his mentil, and puttide vndir hise feet bi the licnesse of a trone. And thei sungen with a trumpe, and seiden, Hieu schal regne.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi, dìtẹ̀ sí Joramu. (Nísinsin yìí Joramu àti gbogbo Israẹli ti ń dáàbò bo Ramoti Gileadi nítorí Hasaeli ọba Aramu.
Therfor Hieu, sone of Josephat, sone of Namsi, swoor to gidere ayens Joram. Forsothe Joram hadde bisegid Ramoth of Galaad, he and al Israel, ayens Azael, kyng of Sirie.
15 ṣùgbọ́n ọba Joramu ti padà sí Jesreeli láti lọ sàn nínú ọgbẹ́ tí àwọn ará Aramu ti dá sí i lára nínú ogun pẹ̀lú ọba Hasaeli ti Aramu.) Jehu wí pé, “Tí èyí bá jẹ́ ọ̀nà tí ò ń rò, má ṣe jẹ́ kí ẹnìkankan kí ó yọ jáde nínú ìlú ńlá láti lọ sọ ìròyìn náà ní Jesreeli.”
And he turnede ayen to be heelid in Jezrael for woundis; for men of Sirie hadden smyte hym fiytynge ayens Azael, kyng of Sirie. And Hieu seide, If it plesith you, no man go out fleynge fro the citee, lest he go, and telle in Jezrael.
16 Nígbà náà Jehu wọ inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ó sì gùn ún lọ sí Jesreeli, nítorí Joramu ń sinmi níbẹ̀ àti Ahasiah ọba Juda sì sọ̀kalẹ̀ láti wá wò Joramu.
And he stiede, and yede forth in to Jezrael; for Joram was sijk there, and Ocozie, kyng of Juda, cam doun to visite Joram.
17 Nígbà tí olùṣọ́ kan tí ó dúró ní ilé ìṣọ́ ní Jesreeli, rí ọ̀wọ́ ogun Jehu tí wọ́n ń súnmọ́ tòsí, ó pè jáde, “Mo rí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí ó ń bọ̀.” “Mú ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kan,” Joramu pa á láṣẹ. “Rán an lọ sí ọ̀dọ̀ wọn kí o sì béèrè pé, ‘Ṣé ẹ̀yin wá pẹ̀lú àlàáfíà?’”
Therfor a spiere, that stood aboue a tour of Jezrael, siy the multitude of Hieu comynge, and he seide, Y se a multitude. And Joram seide, Take thou a chare, and sende in to the metyng of hem; and seie the goere, Whether alle thingis ben riytfuli?
18 Ọkùnrin ẹlẹ́ṣin náà, lọ láti lọ bá Jehu ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba wí: ‘Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?’” “Kí ni ìwọ ní ṣe pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu sì dáhùn. “Bọ́ sí ẹ̀yìn mi.” Olùṣọ́ náà sì wí fún un pé, “Ìránṣẹ́ náà ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́.”
Therfor he, that stiede on the chare, yede in to the meetyng of hym, and seide, The kyng seith these thingis, Whether alle thingis ben peesid? And Hieu seide to hym, What to thee and to pees? Passe thou, and sue me. And the aspiere telde, and seide, the messanger cam to hem, and he turneth not ayen.
19 Bẹ́ẹ̀ ni, ọba rán ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kejì. Nígbà náà ó wá sí ọ̀dọ̀ wọn, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba sọ: “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu dáhùn, “Dúró sí ẹ̀yìn mi.”
Also the kyng sente the secounde chare of horsis, and he cam to hem, and seide, The kyng seith these thingis, Whether pees is? And Hieu seide, What to thee and to pees? Passe thou, and sue me.
20 Olùṣọ́ náà sì fi sùn. “Ó ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́ pẹ̀lú. Wíwá rẹ̀ sì dàbí ti Jehu ọmọ Nimṣi, ó ń wa kẹ̀kẹ́ bí ti aṣiwèrè.”
Sotheli the aspiere telde, and seide, He cam `til to hem, and he turneth not ayen; forsothe the goyng is as the goyng of Hieu, sone of Namsi; sothely he goith faste.
21 “Fi ìwọ̀ kọ́ kẹ̀kẹ́ ogun mi.” Joramu pa á láṣẹ. Àti nígbà tí a fi kọ́, Joramu ọba Israẹli àti Ahasiah ọba Juda, gun kẹ̀kẹ́ lọ, olúkúlùkù nínú kẹ̀kẹ́ ogun tirẹ̀, láti lọ bá Jehu. Wọ́n bá a pàdé ní ibi oko tí ó ti jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli.
And Joram seide, Ioyn ye a chare. And thei ioyneden his chare. And Joram, kyng of Israel, yede out, and Ocozie, kyng of Juda, yede out, ech in his chare; and thei yeden out in to the meetyng of Hieu, and thei founden hym in the feeld of Naboth of Jezrael.
22 Nígbà tí Joramu rí Jehu, ó béèrè pé, “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà, Jehu?” “Báwo ni àlàáfíà yóò ṣe wà,” Jehu dáhùn, “Ní ìwọ̀n ìgbà tí gbogbo ìbọ̀rìṣà àti iṣẹ́ àjẹ́ ti màmá rẹ Jesebeli di púpọ̀?”
And whanne Joram hadde seyn Hieu, he seide, Hieu, `is pees? And he answeride, What pees? Yit the fornycaciouns of Jezabel, thi modir, and many poisenyngis of hir ben in strengthe.
23 Joramu yí ọwọ́ rẹ̀ padà, ó sì sálọ, ó sì ń pe Ahasiah, “Ọ̀tẹ̀ dé, Ahasiah!”
Forsothe Joram turnede his hond, and fledde, and seide to Ocozie, Tresouns! tresouns!
24 Nígbà náà, Jehu fa ọrun rẹ̀, ó sì yin Joramu láàrín èjìká méjèèjì. Ọfà náà sì wọ inú ọkàn rẹ̀, ó sì ṣubú lulẹ̀ láti orí kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
Ocozie. Forsothe Hieu bente a bouwe with the hond, and smoot Joram bitwixe the schuldris, and the arowe yede out thoruy his herte; and anoon he felde doun in his chare.
25 Jehu sọ fún Bidikari, balógun kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Gbé e sókè kí ó sì jù ú sí orí oko tí ó jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli. Rántí bí èmi àti ìwọ ti ń gun kẹ̀kẹ́ papọ̀ lẹ́yìn Ahabu baba à rẹ nígbà tí Olúwa sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀,
And Hieu seide to Badacher duyk, Take thou awei, cast forth hym in the feeld of Naboth of Jezrael; for Y haue mynde, whanne Y and thou saten in the chare, and suede Achab, the fadir of hym, that the Lord reiside on hym this birthun, and seide, If not for the blood of Naboth,
26 ‘Ní àná, mo rí ẹ̀jẹ̀ Naboti pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ni Olúwa wí.’ Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ gbé e sókè, kí o sì jù ú sí orí ilẹ̀ oko náà ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa.”
and for the blood of hise sones, which Y siy yistirdai, seith the Lord, Y schal yeeld to thee in this feeld, seith the Lord. Now therfor do awei him, and cast forth him in the feeld, bi the word of the Lord.
27 Nígbà tí Ahasiah ọba, Juda rí ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀, ó sálọ sójú ọ̀nà sí Beti-Haggani. Jehu sì lépa rẹ̀, ó ń kígbe, “Pa á pẹ̀lú!” Wọ́n ṣá a ní ọgbẹ́ nínú kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ ní ọ̀nà lọ sí Guri lẹ́bàá a Ibleamu, ṣùgbọ́n ó sálọ sí Megido, ó sì kú síbẹ̀.
Forsothe Ocozie, king of Juda, siy this, and fledde bi the weie of the hows of the gardyn; and Hieu pursuede hym, and seide, Also smyte ye this man in his chare. And thei smytiden hym in the stiyng of Gaber, which is bisidis Jeblaam; and he fledde into Mageddo, and was deed there.
28 Ìránṣẹ́ rẹ̀ sì gbé e pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lọ sí Jerusalẹmu, ó sì sin ín pẹ̀lú, baba a rẹ̀ nínú ibojì rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Dafidi.
And hise seruauntis puttiden hym on his chare, and brouyten hym in to Jerusalem; and thei birieden hym in a sepulcre with hise fadris, in the citee of Dauid.
29 (Ní ọdún kọkànlá ti Joramu ọmọ Ahabu, Ahasiah ti di ọba Juda.)
In the eleuenthe yeer of Joram, sone of Achab, kyng of Israel, Ocozie regnede on Juda.
30 Nígbà náà Jehu lọ sí Jesreeli. Nígbà tí Jesebeli gbọ́ nípa rẹ̀, ó kun ojú u rẹ̀, ó to irun rẹ̀, ó sì wò jáde láti ojú fèrèsé.
And Hieu cam in to Jezrael. Forsothe whanne his entryng was herd, Jezabel peyntide hir iyen with oynement of wymmen, and ournede hir heed;
31 Bí Jehu ti wọ ẹnu ìlẹ̀kùn, ó béèrè, “Ṣé ìwọ wá ní àlàáfíà, Simri, ìwọ olùpa ọ̀gá à rẹ?”
and sche bihelde bi a wyndow Hieu entrynge bi the yate, and sche seide, Whether pees may be to Zamri, that kyllide his lord?
32 Ó gbójú sókè láti wo fèrèsé, ó sì pè jáde, “Ta ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ mi? Ta ni?” Ìwẹ̀fà méjì tàbí mẹ́ta bojú wò ó nílẹ̀.
And Hieu reiside his face to the wyndow, and seide, What womman is this? And tweyne ether thre chaumbirleyns bowiden hem silf to hym, and seiden to hym, This is thilke Jezabel.
33 Jehu sọ wí pé, “Gbé e jù sílẹ̀!” Wọ́n sì jù ú sílẹ̀. Díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sì fọ́n sí ara ògiri àti àwọn ẹṣin bí wọ́n ti tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ wọn.
And he seide to hem, Caste ye hir doun. And thei `castiden doun hir; and the wal was bispreynt with blood, and the howues of horsis, that `to tredden hir.
34 Jehu wọ inú ilé lọ, ó jẹ, ó sì mu. “Tọ́jú obìnrin yẹn tí a fi bú,” Ó wí, “Kí o sì sin ín, nítorí ọmọbìnrin ọba ni ó jẹ́.”
And whanne he hadde entrid to ete and drynke, he seide, Go ye, and se thilke cursid womman, and birie ye hir, for sche is a kyngis douyter.
35 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde lọ láti lọ sin ín, wọn kò rí nǹkan kan àyàfi agbárí i rẹ̀, ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì àti ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì.
And whanne thei hadden go to birie hir, thei founden not, no but the sculle, and the feet, and the endis of hondis;
36 Wọ́n padà lọ sọ fún Jehu, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah ará Tiṣibi wí pé, ‘Ní orí oko Jesreeli ni àwọn ajá yóò ti jẹ ẹran-ara Jesebeli.
and thei turneden ayen, and telden to hym. And Hieu seide, It is the word of the Lord, which he spak bi his seruaunt, Elie `of Thesbi, and seide, Doggis schulen ete the fleisch of Jezabel in the feeld of Jezrael;
37 Òkú Jesebeli yóò dàbí ohun ẹ̀gbin ní orí oko Jesreeli, dé bi pé, ẹnikẹ́ni kì yóò lè sọ pé, “Jesebeli ni èyí.”’”
and the fleischis of Jezabel schulen be as `a toord on the face of erthe in the feeld of Jezrael, so that men passynge forth seie, Lo! this is thilke Jezabel.

< 2 Kings 9 >