< 2 Kings 9 >

1 Wòlíì Eliṣa fi àṣẹ pe ọkùnrin kan láti ẹgbẹ́ àwọn wòlíì, ó sì wí fún un pé, “Ki agbádá rẹ sínú ọ̀já àmùrè rẹ, gba ṣágo kékeré òróró yìí pẹ̀lú rẹ, kí o sì lọ sí Ramoti Gileadi.
Prorok pak Elizeus povolal jednoho z synů prorockých, a řekl jemu: Přepaš bedra svá, a vezmi tuto nádobku oleje do ruky své, a jdi do Rámot Galád.
2 Nígbà tí o bá dé bẹ̀, wá Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi kiri. Lọ sí ọ̀dọ̀ ọ rẹ̀, mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀, kí o sì mú un wọ inú yàrá lọ́hùn ún lọ.
A když tam přijdeš, uzříš tam Jéhu, syna Jozafata syna Namsi. K němuž když přijdeš, vyvoláš ho z prostředku bratří jeho, a uvedeš ho do nejtajnějšího pokojíku.
3 Nígbà náà, mú ṣágo kékeré yìí, kí o sì da òróró náà lé e lórí, kí o sì wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’ Nígbà náà, ṣí ìlẹ̀kùn, kí o sì sáré, má ṣe jáfara!”
A vezma nádobku oleje, vyleješ na hlavu jeho a díš: Toto praví Hospodin: Pomazuji tebe za krále nad Izraelem. A hned otevra dvéře, utec a nemeškej se.
4 Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wòlíì náà lọ sí Ramoti Gileadi.
I odšel mládenec ten služebník prorokův do Rámot Galád.
5 Nígbà tí ó dé, ó rí àwọn olórí ẹgbẹ́ ọmọ-ogun tí wọ́n jókòó papọ̀. “Èmi ní iṣẹ́ fún ọ, olórí,” Ó wí. “Sí ta ni nínú wa?” Jehu béèrè. Òun sì wí pé, “Sí ọ, balógun,” Ó dáhùn.
A když přišel, aj, knížata vojska seděli. I řekl: Mámť něco povědíti, ó kníže. I řekl Jéhu: Komu ze všech nás? Odpověděl: Tobě, ó kníže.
6 Jehu dìde sókè, ó sì wọ inú ilé lọ. Nígbà náà, wòlíì náà da òróró náà sórí Jehu; ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn Olúwa Israẹli.
Vyvstav tedy, všel do vnitřku. I vylil olej na hlavu jeho a řekl jemu: Toto praví Hospodin, Bůh Izraelský: Pomazuji tebe za krále nad lidem Hospodinovým, nad Izraelem.
7 Kí ìwọ kí ó pa ilé Ahabu ọ̀gá à rẹ̀ run, Èmi yóò sì gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ gbogbo àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì àti gbogbo ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Olúwa tí a ta sílẹ̀ látọwọ́ ọ Jesebeli.
A zmorduješ dům Achaba pána svého; neboť pomstím krve služebníků svých proroků, a krve všech služebníků Hospodinových z ruky Jezábel.
8 Gbogbo ilé Ahabu yóò ṣègbé. Èmi yóò gé e kúrò láti orí Ahabu gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó gbẹ̀yìn ni Israẹli, ẹrú tàbí òmìnira.
A tak zahyne všecken dům Achabův, a vypléním z domu Achabova močícího na stěnu, a zajatého i zanechaného v Izraeli.
9 Èmi yóò ṣe ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati àti ilé Baaṣa ọmọ Ahijah.
Učiním zajisté domu Achabovu, jako domu Jeroboámovu syna Nebatova, a jako domu Bázy syna Achiášova.
10 Fún Jesebeli, ajá ni yóò jẹ ẹ́ ní oko Jesreeli, kò sì sí ẹni tí yóò sin òkú rẹ̀.’” Nígbà náà ó ṣí ìlẹ̀kùn, ó sì sálọ.
Jezábel pak sežerou psi na poli Jezreel, a nebude, kdo by ji pochoval. A rychle otevřev dvéře, utekl.
11 Nígbà tí Jehu jáde lọ bá àwọn ọgbà ìjòyè e rẹ̀, ọ̀kan nínú wọn sì bi í pé, “Ṣé gbogbo nǹkan dára?” Kí ni ó dé tí aṣiwèrè fi tọ̀ ọ́ wá, “Ìwọ mọ ọkùnrin náà àti irú nǹkan tí ó ń sọ,” Jehu fèsì.
A když Jéhu vyšel k služebníkům pána svého, řekl mu jeden: Dobře-li se děje? Proč přišel ten blázen k tobě? Odpověděl jim: Vy znáte člověka i řeč jeho.
12 “Ìyẹn kì í ṣe òótọ́!” Wọ́n wí. “Sọ fún wa.” Jehu wí, “Èyí ni ohun tí ó sọ fún mi: ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.”’”
I řekli: Klamť jest, pověz nám medle. Kterýž řekl: Takto a takto mluvil mi, řka: Toto praví Hospodin: Pomazuji tě za krále nad Izraelem.
13 Wọ́n ṣe gírí, wọ́n sì mú agbádá a wọn, wọ́n sì tàn wọ́n sí abẹ́ rẹ̀ ní orí àtẹ̀gùn. Nígbà náà, wọ́n fọn ìpè, wọ́n sì kígbe, “Jehu jẹ ọba!”
Tedy rychle vzali jeden každý roucho své, a prostřeli pod něj na nejvyšším stupni, a troubíce v troubu, pravili: Kralujeť Jéhu.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu ọmọ Jehoṣafati, ọmọ Nimṣi, dìtẹ̀ sí Joramu. (Nísinsin yìí Joramu àti gbogbo Israẹli ti ń dáàbò bo Ramoti Gileadi nítorí Hasaeli ọba Aramu.
Zatím spuntoval se Jéhu syn Jozafata, syna Namsi, proti Joramovi, (když Joram ostříhaje Rámot Galád spolu se vším Izraelem, před Hazaelem králem Syrským,
15 ṣùgbọ́n ọba Joramu ti padà sí Jesreeli láti lọ sàn nínú ọgbẹ́ tí àwọn ará Aramu ti dá sí i lára nínú ogun pẹ̀lú ọba Hasaeli ti Aramu.) Jehu wí pé, “Tí èyí bá jẹ́ ọ̀nà tí ò ń rò, má ṣe jẹ́ kí ẹnìkankan kí ó yọ jáde nínú ìlú ńlá láti lọ sọ ìròyìn náà ní Jesreeli.”
Navrátil se byl Joram král, aby se hojil v Jezreel na rány, kterýmiž ho ranili Syrští, když bojoval proti Hazaelovi králi Syrskému). A řekl Jéhu: Vidí-li se vám, nechť nevychází žádný z města, kterýž by šel a oznámil to v Jezreel.
16 Nígbà náà Jehu wọ inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ó sì gùn ún lọ sí Jesreeli, nítorí Joramu ń sinmi níbẹ̀ àti Ahasiah ọba Juda sì sọ̀kalẹ̀ láti wá wò Joramu.
I vsedl na vůz Jéhu a jel do Jezreel, nebo Joram ležel tam. Ochoziáš také král Judský přijel byl, aby navštívil Jorama.
17 Nígbà tí olùṣọ́ kan tí ó dúró ní ilé ìṣọ́ ní Jesreeli, rí ọ̀wọ́ ogun Jehu tí wọ́n ń súnmọ́ tòsí, ó pè jáde, “Mo rí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí ó ń bọ̀.” “Mú ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kan,” Joramu pa á láṣẹ. “Rán an lọ sí ọ̀dọ̀ wọn kí o sì béèrè pé, ‘Ṣé ẹ̀yin wá pẹ̀lú àlàáfíà?’”
V tom strážný, kterýž stál na věži v Jezreel, když viděl houf Jéhu přicházející, řekl: Vidím jakýsi houf. I řekl Joram: Povolej jízdného, a pošli vstříc jim, aby se otázal: Jest-li pokoj?
18 Ọkùnrin ẹlẹ́ṣin náà, lọ láti lọ bá Jehu ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba wí: ‘Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?’” “Kí ni ìwọ ní ṣe pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu sì dáhùn. “Bọ́ sí ẹ̀yìn mi.” Olùṣọ́ náà sì wí fún un pé, “Ìránṣẹ́ náà ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́.”
I vyjel jízdný proti nim a řekl: Takto praví král: Jest-li pokoj? Odpověděl Jéhu: Co tobě do pokoje? Jeď za mnou. Protož oznámil to strážný, řka: Přijel posel až k nim, ale nevracuje se.
19 Bẹ́ẹ̀ ni, ọba rán ọkùnrin ẹlẹ́ṣin kejì. Nígbà náà ó wá sí ọ̀dọ̀ wọn, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí ọba sọ: “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà?” Jehu dáhùn, “Dúró sí ẹ̀yìn mi.”
Ještě poslal druhého jízdného. Kterýž přijel k nim a řekl: Takto praví král: Jest-li pokoj? Odpověděl Jéhu: Co tobě do pokoje? Jeď za mnou.
20 Olùṣọ́ náà sì fi sùn. “Ó ti dé ọ̀dọ̀ wọn, ṣùgbọ́n kò tún padà wá mọ́ pẹ̀lú. Wíwá rẹ̀ sì dàbí ti Jehu ọmọ Nimṣi, ó ń wa kẹ̀kẹ́ bí ti aṣiwèrè.”
Opět oznámil to strážný, řka: Přijel až k nim, ale nevrací se. Příjezd pak jest jako příjezd Jéhu syna Namsi; nebo vztekle jede.
21 “Fi ìwọ̀ kọ́ kẹ̀kẹ́ ogun mi.” Joramu pa á láṣẹ. Àti nígbà tí a fi kọ́, Joramu ọba Israẹli àti Ahasiah ọba Juda, gun kẹ̀kẹ́ lọ, olúkúlùkù nínú kẹ̀kẹ́ ogun tirẹ̀, láti lọ bá Jehu. Wọ́n bá a pàdé ní ibi oko tí ó ti jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli.
Tedy řekl Joram: Zapřáhni. I zapřáhl k vozu jeho. Takž vyjel Joram král Izraelský a Ochoziáš král Judský, každý na voze svém, a vyjevše proti Jéhu, potkali se s ním na poli Nábota Jezreelského.
22 Nígbà tí Joramu rí Jehu, ó béèrè pé, “Ṣé ìwọ wá pẹ̀lú àlàáfíà, Jehu?” “Báwo ni àlàáfíà yóò ṣe wà,” Jehu dáhùn, “Ní ìwọ̀n ìgbà tí gbogbo ìbọ̀rìṣà àti iṣẹ́ àjẹ́ ti màmá rẹ Jesebeli di púpọ̀?”
I stalo se, když uzřel Joram Jéhu, že řekl: Jest-liž pokoj, Jéhu? Odpověděl: Jaký pokoj, poněvadž ještě smilství Jezábel matky tvé a kouzelnictví její velmi mnohá trvají?
23 Joramu yí ọwọ́ rẹ̀ padà, ó sì sálọ, ó sì ń pe Ahasiah, “Ọ̀tẹ̀ dé, Ahasiah!”
Pročež obrátiv se Joram, utíkal a řekl Ochoziášovi: Zrada, Ochoziáši!
24 Nígbà náà, Jehu fa ọrun rẹ̀, ó sì yin Joramu láàrín èjìká méjèèjì. Ọfà náà sì wọ inú ọkàn rẹ̀, ó sì ṣubú lulẹ̀ láti orí kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
Ale Jéhu pochytiv lučiště, postřelil Jorama mezi ramenem jeho, tak že střela pronikla srdce jeho. I padl na voze svém.
25 Jehu sọ fún Bidikari, balógun kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Gbé e sókè kí ó sì jù ú sí orí oko tí ó jẹ́ ti Naboti ará Jesreeli. Rántí bí èmi àti ìwọ ti ń gun kẹ̀kẹ́ papọ̀ lẹ́yìn Ahabu baba à rẹ nígbà tí Olúwa sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀,
Zatím řekl Jéhu Badakerovi, hejtmanu svému: Vezma, povrz jej na pole Nábota Jezreelského; nebo pamatuješ, když jsme já a ty jeli spolu za Achabem otcem jeho, že Hospodin vynesl proti němu pohrůžku tuto, řka:
26 ‘Ní àná, mo rí ẹ̀jẹ̀ Naboti pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ni Olúwa wí.’ Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ gbé e sókè, kí o sì jù ú sí orí ilẹ̀ oko náà ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa.”
Zajisté krve Nábotovy a krve synů jeho, kterouž jsem viděl včera, řekl Hospodin, pomstím na tobě na poli tomto. Hospodin to řekl, nyní tedy vezma, povrz jej na pole, vedlé řeči Hospodinovy.
27 Nígbà tí Ahasiah ọba, Juda rí ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀, ó sálọ sójú ọ̀nà sí Beti-Haggani. Jehu sì lépa rẹ̀, ó ń kígbe, “Pa á pẹ̀lú!” Wọ́n ṣá a ní ọgbẹ́ nínú kẹ̀kẹ́ ẹ rẹ̀ ní ọ̀nà lọ sí Guri lẹ́bàá a Ibleamu, ṣùgbọ́n ó sálọ sí Megido, ó sì kú síbẹ̀.
Ochoziáš pak král Judský uzřev to, utíkal cestou k domu zahradnímu. Ale honil ho Jéhu a řekl: I toho zabíte na voze jeho. Takž ho ranili, když vyjížděl k Guru, kteréž jest podlé Jibleam. I utekl do Mageddo a tam umřel.
28 Ìránṣẹ́ rẹ̀ sì gbé e pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lọ sí Jerusalẹmu, ó sì sin ín pẹ̀lú, baba a rẹ̀ nínú ibojì rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Dafidi.
Kteréhož vloživše na vůz služebníci jeho, vezli jej do Jeruzaléma, a pochovali jej v hrobě jeho s otci jeho v městě Davidově.
29 (Ní ọdún kọkànlá ti Joramu ọmọ Ahabu, Ahasiah ti di ọba Juda.)
Léta jedenáctého Jorama syna Achabova počal kralovati Ochoziáš nad Judou.
30 Nígbà náà Jehu lọ sí Jesreeli. Nígbà tí Jesebeli gbọ́ nípa rẹ̀, ó kun ojú u rẹ̀, ó to irun rẹ̀, ó sì wò jáde láti ojú fèrèsé.
Potom Jéhu přijel do Jezreel. O čemž když uslyšela Jezábel, ulíčila tvář svou, a ozdobila hlavu svou, a vyhlédala z okna.
31 Bí Jehu ti wọ ẹnu ìlẹ̀kùn, ó béèrè, “Ṣé ìwọ wá ní àlàáfíà, Simri, ìwọ olùpa ọ̀gá à rẹ?”
A když Jéhu jel skrze bránu, řekla: Jest-li pokoj, ó Zamri, mordéři pána svého?
32 Ó gbójú sókè láti wo fèrèsé, ó sì pè jáde, “Ta ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ mi? Ta ni?” Ìwẹ̀fà méjì tàbí mẹ́ta bojú wò ó nílẹ̀.
On pak pozdvih tváři své k oknu, řekl: Kdo drží se mnou, kdo? I vyhlédli na něj dva či tři komorníci její.
33 Jehu sọ wí pé, “Gbé e jù sílẹ̀!” Wọ́n sì jù ú sílẹ̀. Díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sì fọ́n sí ara ògiri àti àwọn ẹṣin bí wọ́n ti tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ wọn.
Jimž řekl: Svrzte ji. Kteřížto svrhli ji. I pokropena jest krví její stěna i koni; a tak pošlapal ji.
34 Jehu wọ inú ilé lọ, ó jẹ, ó sì mu. “Tọ́jú obìnrin yẹn tí a fi bú,” Ó wí, “Kí o sì sin ín, nítorí ọmọbìnrin ọba ni ó jẹ́.”
A když přijel, jedl a pil, a řekl: Pohleďte již na tu zlořečenou a pochovejte ji, nebť jest dcera královská.
35 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde lọ láti lọ sin ín, wọn kò rí nǹkan kan àyàfi agbárí i rẹ̀, ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì àti ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì.
Protož odšedše, aby ji pochovali, nenalezli z ní než leb a nohy a dlaně rukou.
36 Wọ́n padà lọ sọ fún Jehu, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah ará Tiṣibi wí pé, ‘Ní orí oko Jesreeli ni àwọn ajá yóò ti jẹ ẹran-ara Jesebeli.
A navrátivše se, pověděli jemu. Kterýž řekl: Slovo Hospodinovo jest, kteréž mluvil skrze služebníka svého, Eliáše Tesbitského, řka: Na poli Jezreel žráti budou psi tělo Jezábel.
37 Òkú Jesebeli yóò dàbí ohun ẹ̀gbin ní orí oko Jesreeli, dé bi pé, ẹnikẹ́ni kì yóò lè sọ pé, “Jesebeli ni èyí.”’”
Budiž tedy tělo Jezábel na poli Jezreel, jako hnůj na svrchku pole, tak aby žádný neřekl: Tato jest Jezábel.

< 2 Kings 9 >