< 2 Kings 8 >

1 Nísinsin yìí, Eliṣa wí fún obìnrin náà tí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin jí padà sáyé pé, “Jáde lọ pẹ̀lú ìdílé rẹ kí o sì lọ dúró fún ìgbà díẹ̀ ní ibikíbi tí o bá le dúró sí, nítorí Olúwa ti pàṣẹ ìyàn ní ìlú tí yóò lò tó ọdún méje.”
És Elizeus szólott volt annak az asszonynak, a kinek a fiát feltámasztotta volt, mondván: Kelj fel, és menj el a te házadnépével együtt, és tartózkodjál, a hol tartózkodhatol; mert az Úr éhséget hívott elő, és el is jött a földre hét esztendeig.
2 Obìnrin náà tẹ̀síwájú gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ ènìyàn Ọlọ́run ti sọ. Òun àti ìdílé rẹ̀ sí lọ, wọ́n sì ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọdún méje.
És felkelt az asszony, és az Isten emberének beszéde szerint cselekedék, és elment ő és az ő háznépe, és lakék a Filiszteusok földében hét esztendeig.
3 Ní ẹ̀yìn ọdún méje ó sì padà wá láti ilẹ̀ àwọn ará Filistini ó sì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba láti lọ bẹ̀ ẹ́ fún ilé àti ilẹ̀ rẹ̀.
Mikor pedig elmult a hét esztendő, visszatért az asszony a Filiszteusok földéből, és elment, hogy panaszolkodjék a királynak az ő házáért és szántóföldeiért.
4 Ọba sì ń sọ̀rọ̀ sí Gehasi, ìránṣẹ́ ènìyàn Ọlọ́run pé, “Sọ fún mi nípa gbogbo ohun ńlá tí Eliṣa ti ṣe.”
A király pedig beszélt Géházival, az Isten emberének szolgájával, mondván: Beszéld el, kérlek, nékem mindazokat a csudálatos dolgokat, a melyeket Elizeus cselekedett.
5 Bí Gehasi ti ń sọ bí tí Eliṣa ṣe jí òkú di alààyè, obìnrin náà tí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tí Eliṣa ti dá padà sí ayé wá láti bẹ ọba fún ilé àti ilẹ̀ rẹ̀. Gehasi sì wí pé, “Obìnrin náà nìyìí olúwa mi ọba, ọmọkùnrin rẹ náà nìyí tí Eliṣa ti jí dìde sí ayé.”
És mikor elbeszélé a királynak, mimódon támasztotta fel a halottat, ímé az asszony, a kinek a gyermekét feltámasztotta volt, éppen akkor kiáltott a királyhoz az ő házáért és szántóföldeiért; és monda Géházi: Uram király, ez az az asszony és ez az ő fia, a kit feltámasztott Elizeus.
6 Ọba béèrè lọ́wọ́ obìnrin náà nípa rẹ̀, ó sì sọ fún un. Ó sì yan ìjòyè kan fún ún fún ọ̀rọ̀ rẹ̀ ó sì wí fún un pé, “Ẹ fún un padà gbogbo ohun tí ó bá jẹ́ tirẹ̀, àti pẹ̀lú gbogbo èrè ilé rẹ̀ fún ún láti ọjọ́ tí ó ti kúrò ní ìlú títí di àsìkò yìí.”
És kikérdezé a király az asszonyt, és az elbeszélé néki; és ada a király ő mellé egy udvari szolgát, mondván: Adasd vissza néki minden jószágát, és a szántóföldnek minden hasznát attól az időtől fogva, a mióta elhagyta a földet egész mostanig.
7 Eliṣa lọ sí Damasku, Beni-Hadadi ọba Siria ń ṣe àìsàn. Nígbà tí wọ́n sọ fún ọba pé, “Ènìyàn Ọlọ́run ti wá láti gbogbo ọ̀nà òkè síbí,”
És Elizeus elment Damaskusba, Benhadád pedig, Siria királya beteg volt, és hírül adák néki, mondván: Az Isten embere ide jött.
8 ọba sì wí fún Hasaeli pé, “Mú ọrẹ lọ́wọ́ rẹ, sì lọ pàdé ènìyàn Ọlọ́run. Kí o sì béèrè Olúwa láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé ṣé èmi yóò sàn nínú àìsàn yìí?”
És monda a király Hazáelnek: Végy ajándékot kezedbe, és menj eleibe az Isten emberének, és kérj tanácsot az Úrtól ő általa, mondván: Meggyógyulok-é ebből a betegségből?
9 Hasaeli lọ láti pàdé Eliṣa, ó mú lọ pẹ̀lú rẹ̀ ẹ̀bùn gẹ́gẹ́ bí ogójì ẹrù ìbákasẹ tí gbogbo ìní tí ó dára jù fún wíwò ti Damasku, ó sì wọlé lọ ó sì dúró níwájú rẹ̀, ó sì wí pé, “Ọmọ rẹ Beni-Hadadi ọba Siria rán mi láti béèrè pé, ‘Ṣé èmi yóò sàn nínú àìsàn mi yìí?’”
És eleibe ment Hazáel, és ajándékokat vitt kezében mindenféle drága damaskusi jószágból negyven teve terhét; és elment, és megállott előtte, és így szólt: A te fiad, Benhadád, Siria királya, az küldött engem hozzád, mondván: Vajjon meggyógyulok-é ebből a betegségből?
10 Eliṣa da á lóhùn pé, “Lọ kí o lọ sọ fún un pé, ‘Ìwo ìbá sàn nítòótọ́’; ṣùgbọ́n Olúwa ti fihàn mí pé nítòótọ́ òun yóò kùú.”
Felele néki Elizeus: Menj el, mondd meg néki: Nem maradsz életben, mert megjelentette nékem az Úr, hogy halált hal.
11 Ó sì ranjú mọ́ ọn pẹ̀lú àtẹjúmọ́ gidigidi títí tí ojú fi ti Hasaeli. Nígbà náà ènìyàn Ọlọ́run bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
És mereven ránézett Hazáelre, mígnem zavarba jött; végre sírni kezdett az Isten embere.
12 “Kí ni ó dé tí olúwa mi fi ń sọkún?” Hasaeli béèrè. “Nítorí pé èmi mọ ibi tí ìwọ yóò ṣe sí Israẹli,” ó sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò fi iná si odi agbára wọn, ìwọ yóò, pa àwọn ọ̀dọ́ ọmọkùnrin wọn pẹ̀lú idà, ìwọ yóò kọlù àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ wọn, ìwọ ó sì fọ́ wọn túútúú, ìwọ o sì la inú àwọn aboyún wọn.”
És monda Hazáel: Miért sír az én uram? És felele: Mert tudom a veszedelmet, a melyet az Izráel fiaira hozol; az ő erős városait megégeted, az ő ifjait fegyverrel levágatod, és kis gyermekeit a földhöz vered, és terhes asszonyait ketté vágod.
13 Hasaeli sì wí pé. “Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ, ajá lásán làsàn yóò ṣe ṣe irú nǹkan ńlá bẹ́ẹ̀?” “Olúwa ti fihàn mí pé ìwọ ni yóò jẹ ọba Siria,” Eliṣa dá a lóhùn.
És monda Hazáel: Kicsoda a te szolgád, ez az eb, hogy ilyen nagy dolgokat cselekednék? És felele Elizeus: Megjelentette nékem az Úr, hogy te leszel Siria királya.
14 Nígbà náà Hasaeli fi Eliṣa sílẹ̀ ó sì padà sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ̀. Nígbà tí Beni-Hadadi béèrè, “Kí ni ohun tí Eliṣa sọ fún ọ?” Hasaeli dá a lóhùn, “Ó sọ fún mi wí pé ìwọ yóò sàn nítòótọ́.”
És elméne Elizeustól, és beméne az ő urához, és az monda néki: Mit mondott Elizeus? és monda: Azt mondta, hogy meggyógyulsz.
15 Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kejì ó mú aṣọ tí ó nípọn, ó sì kì í bọ inú omi ó sì tẹ̀ ẹ́ sí ojú ọba, bẹ́ẹ̀ ni ó sì kú. Nígbà náà Hasaeli sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Másnap azonban elővett egy takarót és bemártván azt vízbe, ráteríté az ő arczára, és meghalt: és uralkodék Hazáel ő helyette.
16 Ní ọdún karùn-ún ti Joramu ọmọ Ahabu ọba Israẹli, nígbà tí Jehoṣafati jẹ́ ọba Juda, Jehoramu ọmọ Jehoṣafati bẹ̀rẹ̀ ìjọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba Juda.
És Jórámnak, az Akháb fiának, az Izráel királyának ötödik esztendejében, mikor még Josafát vala Júda királya, uralkodni kezdett Jórám, a Josafát fia, Júda királya.
17 Ó jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
Harminczkét esztendős volt, mikor uralkodni kezdett, és nyolcz esztendeig uralkodott Jeruzsálemben.
18 Ó sì rìn ní ọ̀nà ọba Israẹli, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti lọ, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu ó sì ṣe ohun búburú níwájú Olúwa.
És járt az Izráel királyainak útján, a miképen cselekedtek volt az Akháb házából valók; mert az Akháb leánya volt a felesége, és gonoszul cselekedék az Úr szemei előtt.
19 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, nítorí ti ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi. Olúwa kò fẹ́ pa Juda run, ó ti ṣèlérí láti ṣètọ́jú ìmọ́lẹ̀ fún Dafidi àti àwọn ilé rẹ̀ títí láéláé.
De az Úr még sem akarta elveszteni Júdát Dávidért, az ő szolgájáért; a mint megigérte volt néki, hogy szövétneket ad néki és az ő fiainak mindörökké.
20 Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
Az ő idejében szakadt el Edom a Júda birodalmától, és választott királyt magának.
21 Bẹ́ẹ̀ ni Jehoramu lọ sí Sairi pẹ̀lú gbogbo kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Àwọn ará Edomu sì yí i ká àti kẹ̀kẹ́ àwọn olórí wọn, ṣùgbọ́n ó dìde dúró ní òru; àwọn ogun rẹ̀ síbẹ̀síbẹ̀, sá padà lọ ilé.
És átment Jórám Seirbe és minden harczi szekere ő vele, s mikor éjjel felkelt és megtámadta az Edomitákat, a kik körülzárták őt, és a szekerek fejedelmeit, megfutott a nép, kiki az ő hajlékába.
22 Títí ó fi di òní, Edomu wà nínú ọ̀tẹ̀ lórí Juda, Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkókò kan náà.
És elszakadt Edom a Júda birodalmától mind e mai napig; ugyanebben az időben szakadt el Libna is.
23 Gẹ́gẹ́ bí fún iṣẹ́ mìíràn ti ìjọba Jehoramu, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda?
Jórámnak egyéb dolgai pedig és minden cselekedetei, vajjon nincsenek-é megírva a Júda királyainak krónika-könyvében?
24 Jehoramu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú Dafidi, Ahasiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
És elaluvék Jórám az ő atyáival, és eltemetteték az ő atyáival a Dávid városában, és uralkodék Akházia, az ő fia, ő helyette.
25 Ní ọdún méjìlá Joramu ọmọkùnrin Ahabu ọba Israẹli, Ahasiah ọmọkùnrin Jehoramu ọba Juda bẹ̀rẹ̀ ìjọba rẹ̀.
Jórámnak az Akháb, az Izráel királya fiának tizenkettedik esztendejében kezdett uralkodni Akházia, Jórámnak, a Júdabeli királynak fia.
26 Ahasiah jẹ́ ẹni ọdún méjìlélógún nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní ọdún kan ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ a sì máa jẹ́ Ataliah, ọmọbìnrin Omri ọba Israẹli.
Huszonkét esztendős volt Akházia, mikor uralkodni kezdett, és egy esztendeig uralkodott Jeruzsálemben; az ő anyjának neve Athália volt, Omrinak, az Izráel királyának leánya.
27 Nígbà tí ó rin ọ̀nà ilé Ahabu ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe, nítorí ó tan nípa ìgbéyàwó sí ìdílé Ahabu.
És járt az Akháb házának útján, és gonoszul cselekedék az Úr szemei előtt, mint az Akháb háza; mert az Akháb házának veje vala.
28 Ahasiah sì lọ pẹ̀lú Joramu ọmọ Ahabu lọ sí ogun lórí Hasaeli ọba Aramu ní Ramoti Gileadi. Àwọn ará Siria ṣẹ́ Joramu lẹ́sẹ̀.
És hadba ment Jórámmal, az Akháb fiával, Siria királya, Hazáel ellen, Rámóth Gileádba; de a Siriabeliek megverték Jórámot.
29 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Joramu padà sí Jesreeli láti wo ọgbẹ́ rẹ̀ sàn tí ará Siria ti jẹ ní yà lórí rẹ̀ ní Ramoti ní ojú ogun rẹ̀ pẹ̀lú Hasaeli ọba Aramu. Nígbà náà Ahasiah ọmọ Jehoramu ọba Juda sọ̀kalẹ̀ lọ sí Jesreeli láti lọ wo Joramu ọmọ Ahabu nítorí tí ó fi ara pa.
Akkor visszatért Jórám király, hogy meggyógyíttassa magát Jezréelben a sebekből, a melyeket rajta a Siriabeliek Ráma alatt ütöttek, mikor Hazáel, Siria királya ellen harczolt. Akházia pedig, a Jórám fia, Júda királya aláméne, hogy meglátogassa Jórámot, az Akháb fiát Jezréelben, a hol az betegen feküdt.

< 2 Kings 8 >