< 2 Kings 8 >
1 Nísinsin yìí, Eliṣa wí fún obìnrin náà tí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin jí padà sáyé pé, “Jáde lọ pẹ̀lú ìdílé rẹ kí o sì lọ dúró fún ìgbà díẹ̀ ní ibikíbi tí o bá le dúró sí, nítorí Olúwa ti pàṣẹ ìyàn ní ìlú tí yóò lò tó ọdún méje.”
Forsothe Elisee spak to the womman, whose sone he made to lyue, and he seide, Rise thou, and go, bothe thou and thin hows, and `go in pilgrimage, where euer thou schalt fynde; for the Lord schal clepe hungur, and it schal come on the lond bi seuene yeer.
2 Obìnrin náà tẹ̀síwájú gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ ènìyàn Ọlọ́run ti sọ. Òun àti ìdílé rẹ̀ sí lọ, wọ́n sì ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọdún méje.
And sche roos, and dide bi the word of the man of God; and sche yede with hir hows, and was in pilgrimage in the lond of Philistym many daies.
3 Ní ẹ̀yìn ọdún méje ó sì padà wá láti ilẹ̀ àwọn ará Filistini ó sì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba láti lọ bẹ̀ ẹ́ fún ilé àti ilẹ̀ rẹ̀.
And whanne seuene yeer weren endid, the womman turnede ayen fro the lond of Philisteis; and sche yede out, to axe the kyng for her hows, and hir feeldis.
4 Ọba sì ń sọ̀rọ̀ sí Gehasi, ìránṣẹ́ ènìyàn Ọlọ́run pé, “Sọ fún mi nípa gbogbo ohun ńlá tí Eliṣa ti ṣe.”
Sotheli the kyng spak with Giezi, child of the man of God, and seide, Telle thou to me alle the grete dedis whiche Elisee dide.
5 Bí Gehasi ti ń sọ bí tí Eliṣa ṣe jí òkú di alààyè, obìnrin náà tí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tí Eliṣa ti dá padà sí ayé wá láti bẹ ọba fún ilé àti ilẹ̀ rẹ̀. Gehasi sì wí pé, “Obìnrin náà nìyìí olúwa mi ọba, ọmọkùnrin rẹ náà nìyí tí Eliṣa ti jí dìde sí ayé.”
And whanne he telde to the kyng, hou Elisee hadde reiside a deed man, the womman apperide, whos sone he hadde maad to lyue, and sche criede to the kyng for hir hows, and for hir feeldis. And Giesi seide, My lord the king, this is the womman, and this is hir sone, whom Elisee reiside.
6 Ọba béèrè lọ́wọ́ obìnrin náà nípa rẹ̀, ó sì sọ fún un. Ó sì yan ìjòyè kan fún ún fún ọ̀rọ̀ rẹ̀ ó sì wí fún un pé, “Ẹ fún un padà gbogbo ohun tí ó bá jẹ́ tirẹ̀, àti pẹ̀lú gbogbo èrè ilé rẹ̀ fún ún láti ọjọ́ tí ó ti kúrò ní ìlú títí di àsìkò yìí.”
And the kyng axide the womman, and sche tolde to hym, that the thingis weren sothe. And the kyng yaf to hir o chaumburleyn, and seide, Restore thou to hir alle thingis that ben hern, and alle fruytis of the feeldis, fro the dai in which she left the lond `til to present tyme.
7 Eliṣa lọ sí Damasku, Beni-Hadadi ọba Siria ń ṣe àìsàn. Nígbà tí wọ́n sọ fún ọba pé, “Ènìyàn Ọlọ́run ti wá láti gbogbo ọ̀nà òkè síbí,”
Also Elisee cam to Damask, and Benadab, kyng of Sirie, was sijk; and thei telden to hym, and seiden, The man of God cam hidur.
8 ọba sì wí fún Hasaeli pé, “Mú ọrẹ lọ́wọ́ rẹ, sì lọ pàdé ènìyàn Ọlọ́run. Kí o sì béèrè Olúwa láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé ṣé èmi yóò sàn nínú àìsàn yìí?”
And the kyng seide to Azael, Take with thee yiftis, and go thou in to the meetyng of the man of God, and `counsele thou bi hym the Lord, and seie thou, Whether Y may ascape fro this `sikenesse of me?
9 Hasaeli lọ láti pàdé Eliṣa, ó mú lọ pẹ̀lú rẹ̀ ẹ̀bùn gẹ́gẹ́ bí ogójì ẹrù ìbákasẹ tí gbogbo ìní tí ó dára jù fún wíwò ti Damasku, ó sì wọlé lọ ó sì dúró níwájú rẹ̀, ó sì wí pé, “Ọmọ rẹ Beni-Hadadi ọba Siria rán mi láti béèrè pé, ‘Ṣé èmi yóò sàn nínú àìsàn mi yìí?’”
Therfor Azael yede in to the meetyng of hym, and hadde with hym silf yiftis, and alle the goodis of Damask, the burthuns of fourti camels. And whanne he hadde stonde bifor Elisee, he seide, Thi sone, Benadab, kyng of Sirie, sente me to thee, and seide, Whether Y may be helid of this `sikenesse of me?
10 Eliṣa da á lóhùn pé, “Lọ kí o lọ sọ fún un pé, ‘Ìwo ìbá sàn nítòótọ́’; ṣùgbọ́n Olúwa ti fihàn mí pé nítòótọ́ òun yóò kùú.”
And Elisee seide, Go thou, and seye to hym, Thou schalt be heelid; forsothe the Lord schewide to me that he schal die bi deth.
11 Ó sì ranjú mọ́ ọn pẹ̀lú àtẹjúmọ́ gidigidi títí tí ojú fi ti Hasaeli. Nígbà náà ènìyàn Ọlọ́run bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
And he stood with hym, and he was disturblid, `til to the castyng doun of cheer; and the man of God wepte.
12 “Kí ni ó dé tí olúwa mi fi ń sọkún?” Hasaeli béèrè. “Nítorí pé èmi mọ ibi tí ìwọ yóò ṣe sí Israẹli,” ó sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò fi iná si odi agbára wọn, ìwọ yóò, pa àwọn ọ̀dọ́ ọmọkùnrin wọn pẹ̀lú idà, ìwọ yóò kọlù àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ wọn, ìwọ ó sì fọ́ wọn túútúú, ìwọ o sì la inú àwọn aboyún wọn.”
`To whom Azael seide, Whi wepith my lord? And he answeride, For Y woot what yuelis thou schalt do to the sones of Israel; thou schalt brenne bi fier the strengthid citees of hem, and thou schalt sle bi swerd the yonge men of hem, and thou schalt hurtle doun the litle children of hem, and thou schalt departe the women with childe.
13 Hasaeli sì wí pé. “Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ, ajá lásán làsàn yóò ṣe ṣe irú nǹkan ńlá bẹ́ẹ̀?” “Olúwa ti fihàn mí pé ìwọ ni yóò jẹ ọba Siria,” Eliṣa dá a lóhùn.
And Azael seide, What sotheli am Y, thi seruaunt, a dogge, that Y do this grete thing? And Elisee seide, The Lord schewide to me that thou schalt be kyng of Sirie.
14 Nígbà náà Hasaeli fi Eliṣa sílẹ̀ ó sì padà sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ̀. Nígbà tí Beni-Hadadi béèrè, “Kí ni ohun tí Eliṣa sọ fún ọ?” Hasaeli dá a lóhùn, “Ó sọ fún mi wí pé ìwọ yóò sàn nítòótọ́.”
And whanne he hadde departid fro Elisee, he cam to his lord; which seide to Azael, What seide Elisee to thee? And he answeride, Elisee seide to me, Thou schalt resseyue helthe.
15 Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kejì ó mú aṣọ tí ó nípọn, ó sì kì í bọ inú omi ó sì tẹ̀ ẹ́ sí ojú ọba, bẹ́ẹ̀ ni ó sì kú. Nígbà náà Hasaeli sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
And whanne `the tother day hadde come, Azael took the cloth on the bed, and bischedde with watir, and spredde abrood on the face of hym; and whanne he was deed, Azael regnede for hym.
16 Ní ọdún karùn-ún ti Joramu ọmọ Ahabu ọba Israẹli, nígbà tí Jehoṣafati jẹ́ ọba Juda, Jehoramu ọmọ Jehoṣafati bẹ̀rẹ̀ ìjọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba Juda.
In the fyuethe yeer of Joram, sone of Achab, kyng of Israel, and of Josephat, kyng of Juda, Joram, sone of Josephat, kyng of Juda, regnede.
17 Ó jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
He was of two and thretti yeer whanne he bigan to regne, and he regnede eiyte yeer in Jerusalem.
18 Ó sì rìn ní ọ̀nà ọba Israẹli, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti lọ, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu ó sì ṣe ohun búburú níwájú Olúwa.
And he yede in the weies of the kyngis of Israel, as the hows of Achab hadde go; for the douyter of Achab was his wijf; and he dide that, that is yuel in the siyt of the Lord.
19 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, nítorí ti ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi. Olúwa kò fẹ́ pa Juda run, ó ti ṣèlérí láti ṣètọ́jú ìmọ́lẹ̀ fún Dafidi àti àwọn ilé rẹ̀ títí láéláé.
Forsothe the Lord nolde distrie Juda, for Dauid, his seruaunt, as he `hadde bihiyt to Dauid, that he schulde yyue to hym a lanterne, and to hise sones in alle daies.
20 Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
In tho daies Edom, `that is, Ydumee, yede awei, that it schulde not be vndur Juda; and made a kyng to it silf.
21 Bẹ́ẹ̀ ni Jehoramu lọ sí Sairi pẹ̀lú gbogbo kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Àwọn ará Edomu sì yí i ká àti kẹ̀kẹ́ àwọn olórí wọn, ṣùgbọ́n ó dìde dúró ní òru; àwọn ogun rẹ̀ síbẹ̀síbẹ̀, sá padà lọ ilé.
And Joram cam to Seira, and alle the charis with hym; and he roos bi nyyt, and smoot Ydumeis, that cumpassiden hym, and the princis of charis; sotheli the puple fledde in to her tabernaclis.
22 Títí ó fi di òní, Edomu wà nínú ọ̀tẹ̀ lórí Juda, Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkókò kan náà.
Therfor Edom yede awei, that it was not vndur Juda `til to this day; thanne also Lobna yede awey in that tyme.
23 Gẹ́gẹ́ bí fún iṣẹ́ mìíràn ti ìjọba Jehoramu, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda?
Forsothe the residues of wordis of Joram, and alle thingis whiche he dide, whether these ben not writun in the book of wordis of daies of the kingis of Juda?
24 Jehoramu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú Dafidi, Ahasiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
And Joram slepte with hise fadris, and was biried with hem in the citee of Dauid; and Ocozie, his sone, regnede for hym.
25 Ní ọdún méjìlá Joramu ọmọkùnrin Ahabu ọba Israẹli, Ahasiah ọmọkùnrin Jehoramu ọba Juda bẹ̀rẹ̀ ìjọba rẹ̀.
In the tweluethe yeer of Joram, sone of Achab, kyng of Israel, Ocozie, sone of Joram, kyng of Juda, regnede.
26 Ahasiah jẹ́ ẹni ọdún méjìlélógún nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní ọdún kan ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ a sì máa jẹ́ Ataliah, ọmọbìnrin Omri ọba Israẹli.
Ocozie, the sone of Joram, was of two and twenti yeer whanne he bigan to regne, and he regnede o yeer in Jerusalem; the name of his moder was Athalia, the douyter of Amry, kyng of Israel.
27 Nígbà tí ó rin ọ̀nà ilé Ahabu ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe, nítorí ó tan nípa ìgbéyàwó sí ìdílé Ahabu.
And he yede in the waies of the hows of Achab, and dide that, that is yuel, bifor the Lord, as the hows of Achab dide; for he was hosebonde of a douyter of the hows of Achab.
28 Ahasiah sì lọ pẹ̀lú Joramu ọmọ Ahabu lọ sí ogun lórí Hasaeli ọba Aramu ní Ramoti Gileadi. Àwọn ará Siria ṣẹ́ Joramu lẹ́sẹ̀.
Also he yede with Joram, sone of Achab, to fiyt ayens Azael, kyng of Sirie, in Ramoth of Galaad; and men of Sirie woundiden Joram.
29 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Joramu padà sí Jesreeli láti wo ọgbẹ́ rẹ̀ sàn tí ará Siria ti jẹ ní yà lórí rẹ̀ ní Ramoti ní ojú ogun rẹ̀ pẹ̀lú Hasaeli ọba Aramu. Nígbà náà Ahasiah ọmọ Jehoramu ọba Juda sọ̀kalẹ̀ lọ sí Jesreeli láti lọ wo Joramu ọmọ Ahabu nítorí tí ó fi ara pa.
Which turnede ayen, to be heelid in Jezrael; for men of Sirie woundiden hym in Ramoth, fiytynge ayens Azael, kyng of Sirye. Forsothe Ocozie, sone of Joram, the kyng of Juda, cam doun to se Joram, sone of Achab, in to Jezrael, that was sijk there.