< 2 Kings 7 >
1 Eliṣa wí pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ‘Ní àsìkò yìí ní ọ̀la, a ó ta òsùwọ̀n ìyẹ̀fun barle kíkúnná kan ní ṣékélì kan àti méjì òsùwọ̀n ọkà barle fún ṣékélì kan ní ẹnu-bodè Samaria.’”
I MAI la o Elisai, E hoolohe oukou i ka olelo a Iehova, Ke olelo mai nei o Iehova peneia, Ma keia manawa i ka la apopo, e lilo kekahi bakeke palaoa no ka sekela hookahi, a elua bakeke bale no ka sekela hookahi ma ka ipuka o Samaria.
2 Ìjòyè kan ẹni tí ọwọ́ ọba ń fi ara tì dáhùn wí fún ènìyàn Ọlọ́run pé, “Ẹ wò ó, tí Olúwa bá tilẹ̀ ṣí fèrèsé ọ̀run sílẹ̀, ṣé èyí lè rí bẹ́ẹ̀?” Eliṣa dáhùn pé, “Ìwọ yóò rí i pẹ̀lú ojú rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ kò ní jẹ nǹkan kan lára rẹ̀!”
Alaila kekahi luna kiai no ke alii ka mea ana i hilinai ai ma kona lima, olelo mai la ia i ke kanaka o ke Akua, i mai la, Aia hoi, ina e hana mai o Iehova i na puka ma ka Iani, e hiki mai anei keia mea? I aku la ia, E ike auanei kou mau maka, aka, aole oe e ai ia mea.
3 Nísinsin yìí àwọn ọkùnrin mẹ́rin kan wà pẹ̀lú ẹ̀tẹ̀ ní ẹnu àbáwọlé ibodè ìlú. Wọ́n wí fún olúkúlùkù pé, “Kí ni ó dé tí àwa yóò fi jókòó síbí títí àwa yóò fi kú?
A eha kanaka lepera ma ke komo ana o ka ipuka; a i ae la lakou i kekahi i kekahi, No ke aha la kakou e noho maanei, a make kakou?
4 Tí àwa bá wí pé, ‘Àwa lọ sí ìlú, ìyàn wà níbẹ̀,’ àwa yóò sì kú. Tí àwa bá dúró níbí, a máa kú, ǹjẹ́ nísinsin yìí ẹ jẹ́ kí a lọ sí ibùdó ti àwọn ará Siria kí àwa kí ó sì tẹríba. Bí wọ́n bá dá wa sí, àwa yóò yè, tí wọ́n bá sì pa wá, bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò kú.”
A i olelo kakou, e komo iloko o ke kulanakauhale, aia hoi, maloko o ke kulanakauhale ka wi, a e make auanei kakou malaila: a i noho kakou maanei, e make kakou. Ano hoi, ea, e haule kakou i ka poe kaua o ko Suria, ina e hoola lakou ia kakou, ua ola; aka, ina e pepehi mai lakou ia kakou, ua make no hoi.
5 Ní àfẹ̀mọ́júmọ́ wọ́n dìde wọ́n sì lọ sí ibùdó àwọn ará Siria. Nígbà tí wọ́n dé ẹ̀gbẹ́ ibùdó náà, kò sí ọkùnrin kan níbẹ̀,
Ku ae la lakou i ka wanaao e hele aku i kahi hoomoana o ko Suria: a hiki lakou ma ka palena o kahi hoomoana o ko Suria, aia hoi, aohe kanaka malaila.
6 nítorí tí Olúwa jẹ́ kí àwọn ará Siria gbọ́ ìró kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin àti ogun ńlá, wọ́n sì wí fún ara wọn pé, “Ẹ wò ó, ọba Israẹli ti bẹ ogun àwọn Hiti àti àwọn ọba Ejibiti láti dojúkọ wá!”
No ka mea, ua haawi mai o Iehova i ka poe kaua o ko Suria i ka lohe i ka halulu o na halekaa, a me ka halulu o na lio, ka halulu o ke kaua nui; i ae la lakou i kekahi i kekahi, Aia hoi, ua hoolimalima ke alii o ka Iseraela i na'lii o ka Heta e ku e mai ia kakou, a me na'lii o Aigupita e hele mai maluna o kakou.
7 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì dìde wọ́n sì sálọ ní àfẹ̀mọ́júmọ́ wọ́n sì fi àgọ́ wọn sílẹ̀ àti ẹṣin wọn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọ́n sì fi ibùdó sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti wà, wọ́n sì sálọ fún ẹ̀mí wọn.
No ia mea, ku ae la lakou, a holo i ka wanaao, a haalele aku la lakou i ko lakou mau halelewa, a me ko lakou lio, a me na hoki o lakou, a i kahi hoomoana pela, a holo aku la lakou, i ola.
8 Nígbà tí àwọn ọkùnrin tí ó ní ààrùn ẹ̀tẹ̀ dé ẹ̀gbẹ́ ibùdó wọ́n sì wọ inú ọ̀kan nínú àgọ́ náà. Wọ́n jẹ wọ́n sì mu, wọ́n sì kó fàdákà, wúrà àti ẹ̀wù, wọ́n sì lọ. Wọ́n sì wọ àgọ́ mìíràn lọ, wọ́n kó àwọn nǹkan láti ibẹ̀ wọ́n sì kó wọn pamọ́ pẹ̀lú.
A hiki aku la na lepero ma ka palena o kahi hoomoana, komo aku la lakou iloko o kekahi halelewa, a ai iho la lakou, a inu hoi, a lawe aku lakou i ke kala a me ke gula, a me na aahu mai laila aku, hele aku, a huna; a hoi mai a komo aku iloko o kekahi halelewa e ae, a lawe aku no hoi mai laila aku, a hele aku, a huna.
9 Nígbà náà wọ́n wí fún ara wọn pé, “Àwa kò ṣe ohun rere. Òní yìí jẹ́ ọjọ́ ìròyìn rere àwa sì pa á mọ́ ara wa. Tí àwa bá dúró títí di àfẹ̀mọ́júmọ́, ìjìyà yóò jẹ́ ti wa. Ẹ jẹ́ kí a lọ ní ẹ̀ẹ̀kan kí a lọ ròyìn èyí fún àwọn ilé ọba.”
I ae la lakou i kekahi i kekahi. Aole pono ka kakou hana ana; o keia la, he la pomaikai, a ke noho malie nei kakou; a i noho a hiki i ka malamalama o ke ao, e loaa uanei ia kakou ka hewa: ano hoi e hele aku kakou, a o hai aku i ko ka hale o ke alii.
10 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì lọ wọ́n sì pe àwọn asọ́bodè ìlú, wọ́n sì wí fún wọn pé, “Àwa lọ sí ibùdó àwọn ará Siria kò sì sí ọkùnrin kankan níbẹ̀ tàbí ohùn ènìyàn kan àyàfi ẹṣin tí a so àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn àgọ́ náà sì wà gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti wà.”
A hele lakou, a kahea aku i ke kiai-puka o ke kulanakauhale; a hai aku ia lakou, i aku la, Hele aku makou i kahi hoomoana o ko Suria, aia hoi, aohe kanaka malaila, aohe leo o ke kanaka, o na lio wale no i nakiiia, a me na hoki i nakiiia, a me na halelewa e waiho ana pela.
11 Àwọn aṣọ́bodè náà pariwo ìròyìn náà, wọ́n sì sọ nínú ààfin ọba.
Kahea aku la ia i na kiai-puka, a hai aku la lakou i ko ka hale o ke alii maloko.
12 Ọba sì dìde ní òru ó sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Èmi yóò sọ fún yín ohun tí àwọn ará Siria tí ṣe fún wa. Wọ́n mọ̀ wí pé ebi ń pa wá; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ti kúrò ni ibùdó láti sá pamọ́ sí ẹ̀gbẹ́ ilé, wọ́n rò wí pé, ‘Wọn yóò jáde lóòtítọ́, nígbà náà àwa yóò mú wọn ní ààyè, àwa yóò sì wọ inú ìlú lọ.’”
Ala mai ke alii i ka po, i aku la i kana poe kauwa, Ano e hoike aku au ia oukou i ka mea a ko Suria i hana mai ai ia kakou. Ua ike lakou i ko kakou pololi ana; nolaila, ua hele aku lakou mai ko lakou wahi hoomoana aku e pee ma ke kula, i ka i ana'e, Aia puka lakou mailoko mai o ke kulanakauhale, alaila lawe pio kakou ia lakou e ola ana, a komo iloko o ke kulanakauhale.
13 Ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ dáhùn pé, “Èmí o bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí àwa kí ó mú márùn-ún nínú àwọn ẹṣin tí ó kù, nínú àwọn tí ó kù ní ìlú—kíyèsí i, wọ́n sá dàbí gbogbo àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ Israẹli tí ó kù nínú rẹ̀, kíyèsí i, àní bí gbogbo ènìyàn Israẹli tí a run, sí jẹ́ kí a rán wọn lọ láti lọ wo ohun tí ó ṣẹlẹ̀.”
Olelo mai kekahi o na kauwa ana, i mai la, Ke noi aku nei au ia oe, e lawe lakou i elima o na lio e koe ana, na mea i koe iloko olaila, (aia, ua like lakou me ka Iseraela a pau e koe ana; aia hoi, ua like lakou mo ka poe nui o ka Iseraela i make, ) a hoouna aku kakou, a ike.
14 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yan kẹ̀kẹ́ méjì pẹ̀lú ẹṣin wọn, ọba sì ránṣẹ́ tọ ogun àwọn ará Siria lẹ́yìn ó pàṣẹ fún àwọn awakọ̀ pé, “Ẹ lọ kí ẹ lọ wo ohun tí ó ṣẹlẹ̀.”
A lawe lakou i elua kaulualio, a hoouna aku la ke alii mahope o ka poe kaua o ko Suria, i aku la, E hele aku a ike.
15 Wọ́n sì tẹ̀lé wọn títí dé Jordani, wọ́n sì rí gbogbo ọ̀nà kún fún agbádá pẹ̀lú ohun èlò tí ará àwọn Siria gbé sọnù ní yàrá wọn. Ìránṣẹ́ náà padà ó sì wá sọ fún ọba.
A hele aku lakou mahope o lakou la, a Ioredane; aia hoi, ua paapu ke alanui a pau i na aahu, a me na mea kaua a ko Suria i hoolei ai i ko lakou holo kiki ana. A hoi mai na elele, a hai mai i ke alii.
16 Nígbà náà àwọn ènìyàn jáde lọ ìkógun ní ibùdó àwọn ará Siria. Bẹ́ẹ̀ ni òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kan ni wọ́n tà fún ṣékélì kan, àti òsùwọ̀n barle méjì ní ṣékélì kan, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
A hele aku na kanaka, a hao lakou i ko kahi hoomoana o ko Suria. No ia mea, ua lilo ka bakeke palaoa no ka sekela hookahi, a elua bakeke bale no ka sekela hookahi, e like me ka olelo a Iehova.
17 Nísinsin yìí ọba sì mú ìjòyè náà lórí ẹni tí ó fi ọwọ́ ara rẹ̀ tì ní ìkáwọ́ ẹnu ibodè, àwọn ènìyàn sì tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ní ẹnu ibodè. Ó sì kú, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti sọtẹ́lẹ̀ nígbà tí ọba sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.
A hoonoho aku la ke alii i ka lunakiai, i ka mea ana i hilinai ai ma kona lima, e malama i ka ipuka; a hehi iho la na kanaka maluna ona, a make iho la ia, e like me ka olelo a ke kanaka o ke Akua, ana i olelo ai i ka hele ana o ke alii io na la.
18 Ó sì ti ṣẹlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti sọ fún ọba: “Ní àsìkò yìí ní ọ̀la, òsùwọ̀n ìyẹ̀fun ni a ó ta nì ṣékélì kan àti òsùwọ̀n méjì barle ní ṣékélì kan ní ẹnu-ọ̀nà ibodè Samaria.”
E like no me ka olelo a ke kanaka o ke Akua i ke alii, i ka i ana'e, Elua bakeke bale no ka sekela hookahi, a hookahi bakeke palaoa no ka sekela hookahi, i keia manawa i ka la apopo ma ka ipuka o Samaria.
19 Ìjòyè náà ti wí fún ènìyàn Ọlọ́run pé, “Wò ó, kódà ti Olúwa bá ṣí fèrèsé ní ọ̀run, ṣé èyí lè ṣẹlẹ̀?” Ènìyàn Ọlọ́run sì ti dáhùn pé, “Kìkì ojú rẹ ni ìwọ yóò fi rí i, ṣùgbọ́n ìwọ kò ní jẹ ọ̀kankan lára rẹ̀.”
A olelo mai ua lunakiai la i ke kanaka o ke Akua, i mai la, Aia hoi, ina e hana mai o Iehova i na puka ma ka lani, e hiki mai anei keia mea? I aku la ia, Aia hoi, e ike auanei kou mau maka, aka, aole oe e ai ia mea.
20 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí fún un gẹ́lẹ́, nítorí tí àwọn ènìyàn tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ní ẹnu ibodè, ó sì kú.
A pela i hanaia mai ai ia ia: no ka mea, hehi iho la na kanaka maluna ona ma ka ipuka, a make iho la ia.