< 2 Kings 6 >

1 Àwọn ọmọ wòlíì sọ fún Eliṣa pé, “Wò ó, ní ibi tí a ti pàdé pẹ̀lú rẹ, ó kéré fún wa.
Bir gün peygamber topluluğu Elişa'ya, “Bak, yaşadığımız yer bize küçük geliyor” dedi,
2 Jẹ́ kí àwa kí ó lọ sí Jordani, ní ibi tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ti le rí ọ̀pá kan, jẹ́ kí àwa kí ó kọ́lé síbẹ̀ fún wa láti gbé.” Ó sì wí pé, “Lọ.”
“Lütfen izin ver, Şeria Irmağı kıyısına gidelim, ağaç kesip kendimize ev yapalım.” Elişa, “Gidin” dedi.
3 Nígbà náà ni ọ̀kan lára wọn wí pé, “Kí ó wù ọ́, èmí bẹ̀ ọ́, láti bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ?” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ,”
Peygamberlerden biri, “Lütfen kullarınla birlikte sen de gel” dedi. Elişa, “Olur, gelirim” diye karşılık verdi
4 Ó sì lọ pẹ̀lú wọn. Wọ́n sì lọ sí Jordani wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gé igi.
ve onlarla birlikte gitti. Şeria Irmağı kıyısına varınca ağaç kesmeye başladılar.
5 Bí ọ̀kan ṣe gé igi náà, àáké irin náà bọ́ sínú omi, ó kígbe sókè pé, “O! Olúwa mi, mo yá a ni!”
Biri ağaç keserken balta demirini suya düşürdü. “Eyvah, efendim! Onu ödünç almıştım” diye bağırdı.
6 Ènìyàn Ọlọ́run sì béèrè pé, “Níbo ni ó bọ́ sí?” Nígbà tí ó fi ibẹ̀ hàn án, Eliṣa gé igi kan ó sì jù ú síbẹ̀, ó sì mú irin náà fò lójú omi.
Tanrı adamı, “Nereye düştü?” diye sordu. Adam ona demirin düştüğü yeri gösterdi. Elişa bir dal kesip oraya atınca, balta demiri su yüzüne çıktı.
7 Ó wí pé, “Gbé e jáde.” Lẹ́yìn náà ọkùnrin náà na ọwọ́ rẹ̀ jáde ó sì mú un.
Elişa, “Al onu!” dedi. Adam elini uzatıp balta demirini aldı.
8 Nísinsin yìí ọba Aramu wà ní ogun pẹ̀lú Israẹli ó sì bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ gbèrò, ó wí pé, “Èmi yóò ṣe ibùdó mi sí ibí yìí nínú èyí náà àti bí ibí yìí.”
Aram Kralı İsrail'le savaş halindeydi. Görevlilerine danıştıktan sonra, “Ordugahımı kuracak bir yer seçtim” dedi.
9 Ènìyàn Ọlọ́run rán iṣẹ́ sí ọba Israẹli pé, “Kíyèsi ara láti kọjá ní ibẹ̀ yẹn, nítorí pé ará Aramu wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ síbẹ̀.”
Tanrı adamı Elişa, İsrail Kralı'na şu haberi gönderdi: “Sakın oradan geçmeyin, çünkü Aramlılar oraya doğru iniyorlar.”
10 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli wo ibi tí ènìyàn Ọlọ́run náà fihàn, ní ẹ̀ẹ̀kan sí i Eliṣa kìlọ̀ fún ọba, bẹ́ẹ̀ ni ó wà lórí sísọ ní ibẹ̀.
İsrail Kralı adam gönderip oradaki durumu denetledi. Böylece Tanrı adamı İsrail Kralı'nı birkaç kez uyardı. Kral da önlem aldı.
11 Èyí mú ọba Aramu bínú. Ó pe àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé ìwọ kò ní sọ fún mi èwo nínú wa ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọba Israẹli?”
Bu durum Aram Kralı'nı çok öfkelendirdi. Görevlilerini çağırıp, “İçinizden hanginizin İsrail Kralı'ndan yana olduğunu söylemeyecek misiniz?” dedi.
12 Ọ̀kan lára ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí pé, “Kò sí ọ̀kan nínú wa, olúwa ọba mi, ṣùgbọ́n Eliṣa, wòlíì tí ó wà ní Israẹli, sọ fún ọba Israẹli ọ̀rọ̀ gangan tí ó sọ nínú yàrá rẹ̀.”
Görevlilerden biri, “Hiçbirimiz, efendimiz kral” diye karşılık verdi, “Yalnız İsrail'de yaşayan Peygamber Elişa senin yatak odanda söylediklerini bile İsrail Kralı'na bildiriyor.”
13 Ọba pa á láṣẹ, “Lọ, kí ẹ lọ wo ibi tí ó wà, kí èmi kí ó lè rán ènìyàn láti lọ mú un wá.” Ìròyìn padà wá wí pé, “Ó wà ní Dotani.”
Aram Kralı şöyle buyurdu: “Gidip onun nerede olduğunu öğrenin. Adam gönderip onu yakalayacağım.” Elişa'nın Dotan'da olduğu bildirilince,
14 Nígbà náà ni ó rán àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ àti ogun ńlá tí ó le síbẹ̀. Wọ́n sì lọ ní alẹ́ wọ́n sì yí ìlú náà ká.
kral oraya atlılar, savaş arabaları ve büyük bir kuvvet gönderdi. Geceleyin varıp kenti kuşattılar.
15 Nígbà tí ìránṣẹ́ ènìyàn Ọlọ́run dìde ó sì jáde lọ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, ogun pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ wọn ti yí ìlú náà ká. “Yé è, olúwa mi! Kí ni kí àwa kí ó ṣe?” ìránṣẹ́ náà béèrè.
Tanrı adamının uşağı erkenden kalktı. Dışarıya çıkınca kentin askerler, atlılar ve savaş arabalarınca kuşatıldığını gördü. Dönüp Elişa'ya, “Eyvah, efendim, ne yapacağız?” diye sordu.
16 “Má ṣe bẹ̀rù,” wòlíì náà dáhùn, “Àwọn tí ó wà pẹ̀lú wa, wọ́n pọ̀ ju àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn lọ.”
Elişa, “Korkma, çünkü bizim yandaşlarımız onlarınkinden daha çok” diye karşılık verdi.
17 Eliṣa sì gbàdúrà, “Olúwa, la ojú rẹ̀ kí ó ba à lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú ìránṣẹ́ náà, ó sì wò, ó sì rí òkè ńlá tí ó kún fún ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ iná gbogbo yí Eliṣa ká.
Sonra şöyle dua etti: “Ya RAB, lütfen onun gözlerini aç, görsün!” RAB uşağın gözlerini açtı. Uşak Elişa'nın çevresindeki dağların atlılarla, ateşten savaş arabalarıyla dolu olduğunu gördü.
18 Bí àwọn ọ̀tá ṣe ń sọ̀kalẹ̀ wá níwájú rẹ, Eliṣa gbàdúrà sí Olúwa pé. “Bu ìfọ́jú lu àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” Olúwa sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Eliṣa ti béèrè.
Aramlılar kendisine doğru ilerleyince Elişa RAB'be şöyle yalvardı: “Ya RAB, lütfen bu halkı kör et.” RAB Elişa'nın yalvarışını duydu ve onları kör etti.
19 Eliṣa sọ fún wọn pé, “Èyí kì í ṣe ọ̀nà bẹ́ẹ̀ ni èyí kì í ṣe ìlú náà. Tẹ̀lé mi, èmi yóò mú u yín lọ sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin tí ẹ̀yin ń wá.” Ó sì sìn wọ́n lọ sí Samaria.
Bunun üzerine Elişa onlara, “Yanlış yoldasınız” dedi, “Aradığınız kent bu değil. Beni izleyin, sizi aradığınız adama götüreyim.” Sonra onları Samiriye'ye götürdü.
20 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n wọ ìlú náà, Eliṣa wí pé, “Olúwa, la ojú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kí wọn kí ó lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú wọn, wọ́n sì ríran, wọ́n sì wà níbẹ̀, nínú Samaria.
Samiriye'ye girdiklerinde Elişa şöyle dua etti: “Ya RAB, bu adamların gözlerini aç, görsünler.” RAB gözlerini açınca adamlar Samiriye'nin ortasında olduklarını anladılar.
21 Nígbà tí ọba Israẹli rí wọn, ó béèrè lọ́wọ́ Eliṣa pé, “Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n, baba mi? Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n?”
İsrail Kralı adamları görünce Elişa'ya, “Onları öldüreyim mi? Öldüreyim mi, baba?” dedi.
22 “Má ṣe pa wọ́n,” ó dáhùn. “Ṣé ìwọ yóò pa àwọn ọkùnrin tí ìwọ mú pẹ̀lú idà rẹ tàbí ọrun rẹ? Gbé oúnjẹ àti omi síwájú wọn kí wọn kí ó lè jẹ kí wọn sì mu, nígbà náà kí wọn padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn.”
Elişa, “Hayır, öldürme” diye karşılık verdi, “Kendi kılıç ve yayınla tutsak aldığın insanları nasıl öldürürsün. Önlerine yiyecek içecek bir şeyler koy, yiyip içtikten sonra izin ver, krallarına dönsünler.”
23 Bẹ́ẹ̀ ni ó pèsè àsè ńlá fún wọn, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jẹ tí wọ́n mu, ó sì rán wọn lọ, wọ́n sì padà sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ẹgbẹ́ láti Aramu dáwọ́ ìgbógunti ilẹ̀ Israẹli dúró.
Bunun üzerine İsrail Kralı adamlara büyük bir şölen verdi, yedirip içirdikten sonra da onları krallarına gönderdi. Aramlı akıncılar bir daha İsrail topraklarına ayak basmadılar.
24 Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ni Beni-Hadadi ọba Aramu kó gbogbo àwọn ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì yan sókè wọ́n sì dúró ti Samaria.
Bir süre sonra, Aram Kralı Ben-Hadat bütün ordusunu toplayıp İsrail'e girdi ve Samiriye'yi kuşattı.
25 Ìyàn ńlá sì mú ní ìlú Samaria; wọ́n dúró tí ì tó bẹ́ẹ̀ tí a fi ń ta orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan ní ọgọ́rùn-ún ìwọ̀n fàdákà àti ìdámẹ́rin òsùwọ̀n kábù imí ẹyẹlé, fún ìwọ̀n fàdákà márùn-ún.
Samiriye'de büyük bir kıtlık oldu. Kuşatma sonunda bir eşek kellesinin fiyatı seksen şekel gümüşe, dörtte bir kav güvercin gübresinin fiyatı ise beş şekel gümüşe çıktı.
26 Gẹ́gẹ́ bí ọba Israẹli ti ń kọjá lọ lórí odi, obìnrin kan sọkún sí i pé, “Ràn mí lọ́wọ́, olúwa ọba mi!”
İsrail Kralı surların üzerinde yürürken, bir kadın, “Efendim kral, bana yardım et!” diye seslendi.
27 Ọba sì dá a lóhùn pé, “Bí Olúwa kò bá gbà ọ́, níbo ni èmi yóò gbé ti gbà ọ́? Láti inú ilẹ̀ ìpakà, tàbí láti inú ibi ìfúntí?”
Kral, “RAB sana yardım etmiyorsa, ben nasıl yardım edebilirim ki?” diye karşılık verdi, “Buğday mı, yoksa şarap mı istersin?
28 Nígbà náà ọba béèrè lọ́wọ́ obìnrin náà pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” Obìnrin náà dáhùn pé, “Obìnrin yìí wí fún mi pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ ẹ́ lónìí, ní ọ̀la àwa yóò jẹ ọmọkùnrin tèmi.’
Derdin ne?” Kadın şöyle yanıtladı: “Geçen gün şu kadın bana dedi ki, ‘Oğlunu ver, bugün yiyelim, yarın da benim oğlumu yeriz.’
29 Bẹ́ẹ̀ ni a ṣe ọmọkùnrin mi a sì jẹ ẹ́. Ní ọjọ́ kejì mo wí fún un pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ,’ ṣùgbọ́n ó ti gbé e pamọ́.”
Böylece oğlumu pişirip yedik. Ertesi gün ona, ‘Oğlunu ver de yiyelim’ dedim. Ama o, oğlunu gizledi.”
30 Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ obìnrin náà, ó fa aṣọ rẹ̀ ya. Gẹ́gẹ́ bí ó sì ti ń kọjá lọ sí orí odi, àwọn ènìyàn wò ó níbẹ̀ ní abẹ́, ó ní aṣọ ọ̀fọ̀ ní ara rẹ̀.
Kadının bu sözlerini duyan kral giysilerini yırttı. Surların üzerinde yürürken, halk onun giysilerinin altına çul giydiğini gördü.
31 Ó sì wí pé, “Kí Ọlọ́run kí ó fi ìyà jẹ mí, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ dájúdájú, pé orí ọmọkùnrin Eliṣa ọmọ Ṣafati kì ó wà ní ọrùn rẹ̀ ní òní!”
Kral, “Eğer bugün Şafat oğlu Elişa'nın başı yerinde kalırsa, Tanrı bana aynısını, hatta daha kötüsünü yapsın!” dedi.
32 Nísinsin yìí Eliṣa jókòó ní ilé rẹ̀ àwọn àgbàgbà náà jókòó pẹ̀lú rẹ̀. Ọba sì rán oníṣẹ́ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó tó dé ibẹ̀, Eliṣa sọ fún àwọn àgbàgbà pé, “Ṣé ẹ̀yin kò rí bí apànìyàn ti ń rán ẹnìkan láti gé orí mi kúrò? Ẹ wò ó, nígbà tí ìránṣẹ́ náà bá dé, ẹ ti ìlẹ̀kùn kí ẹ sì dìímú ṣinṣin ní ẹnu-ọ̀nà, ìró ẹsẹ̀ olúwa rẹ̀ kò ha wà lẹ́yìn rẹ?”
Elişa o sırada halkın ileri gelenleriyle birlikte evinde oturuyordu. Kral önden bir haberci gönderdi. Ama daha haberci gelmeden, Elişa ileri gelenlere, “Görüyor musunuz caniyi?” dedi, “Kalkmış, başımı kestirmek için adam gönderiyor! Haberci geldiğinde kapıyı kapayın, onu içeri almayın. Çünkü ardından efendisi kral da gelecek.”
33 Nígbà tí ó sì ń sọ̀rọ̀ sí wọn, ìránṣẹ́ náà sọ̀kalẹ̀ wá bá a. Ọba náà sì wí pé, “Ibi yìí láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni. Kí ni ó dé tí èmi yóò fi dúró de Olúwa sí i?”
Elişa konuşmasını bitirmeden, haberci yanına geldi ve, “Bu felaket RAB'dendir” dedi, “Neden hâlâ RAB'bi bekleyeyim?”

< 2 Kings 6 >