< 2 Kings 6 >

1 Àwọn ọmọ wòlíì sọ fún Eliṣa pé, “Wò ó, ní ibi tí a ti pàdé pẹ̀lú rẹ, ó kéré fún wa.
Și fiii profeților i-au spus lui Elisei: Iată acum, locul în care locuim cu tine este prea strâmt pentru noi.
2 Jẹ́ kí àwa kí ó lọ sí Jordani, ní ibi tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ti le rí ọ̀pá kan, jẹ́ kí àwa kí ó kọ́lé síbẹ̀ fún wa láti gbé.” Ó sì wí pé, “Lọ.”
Să mergem, te rugăm, la Iordan și să luăm de acolo fiecare om câte o bârnă și să ne facem acolo un loc unde să locuim. Iar el a răspuns: Duceți-vă.
3 Nígbà náà ni ọ̀kan lára wọn wí pé, “Kí ó wù ọ́, èmí bẹ̀ ọ́, láti bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ?” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ,”
Și unul a spus: Binevoiește, te rog, și mergi cu servitorii tăi. Iar el a răspuns: Voi merge.
4 Ó sì lọ pẹ̀lú wọn. Wọ́n sì lọ sí Jordani wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gé igi.
Astfel el a mers cu ei. Și când au venit la Iordan au tăiat lemne.
5 Bí ọ̀kan ṣe gé igi náà, àáké irin náà bọ́ sínú omi, ó kígbe sókè pé, “O! Olúwa mi, mo yá a ni!”
Dar pe când unul dobora o bârnă, capul toporului a căzut în apă; și el a strigat și a spus: Vai, stăpâne! fiindcă era împrumutat.
6 Ènìyàn Ọlọ́run sì béèrè pé, “Níbo ni ó bọ́ sí?” Nígbà tí ó fi ibẹ̀ hàn án, Eliṣa gé igi kan ó sì jù ú síbẹ̀, ó sì mú irin náà fò lójú omi.
Și omul lui Dumnezeu a spus: Unde a căzut? Iar el i-a arătat locul. Și el a tăiat un vreasc și l-a aruncat acolo și fierul a plutit.
7 Ó wí pé, “Gbé e jáde.” Lẹ́yìn náà ọkùnrin náà na ọwọ́ rẹ̀ jáde ó sì mú un.
De aceea el a zis: Ia-ți-l. Iar el și-a întins mâna și l-a luat.
8 Nísinsin yìí ọba Aramu wà ní ogun pẹ̀lú Israẹli ó sì bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ gbèrò, ó wí pé, “Èmi yóò ṣe ibùdó mi sí ibí yìí nínú èyí náà àti bí ibí yìí.”
Atunci împăratul Siriei s-a războit împotriva lui Israel și s-a sfătuit cu servitorii săi, spunând: În cutare și în cutare loc va fi tabăra mea.
9 Ènìyàn Ọlọ́run rán iṣẹ́ sí ọba Israẹli pé, “Kíyèsi ara láti kọjá ní ibẹ̀ yẹn, nítorí pé ará Aramu wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ síbẹ̀.”
Și omul lui Dumnezeu a trimis la împăratul lui Israel, spunând: Ia seama să nu treci prin acel loc, pentru că acolo au coborât sirienii.
10 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli wo ibi tí ènìyàn Ọlọ́run náà fihàn, ní ẹ̀ẹ̀kan sí i Eliṣa kìlọ̀ fún ọba, bẹ́ẹ̀ ni ó wà lórí sísọ ní ibẹ̀.
Și împăratul lui Israel a trimis la locul despre care omul lui Dumnezeu îi spusese și îl avertizase și s-a salvat acolo, nu o dată, nici de două ori.
11 Èyí mú ọba Aramu bínú. Ó pe àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé ìwọ kò ní sọ fún mi èwo nínú wa ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọba Israẹli?”
De aceea inima împăratului Siriei era foarte tulburată pentru acest lucru; și a chemat pe servitorii săi și le-a spus: Nu îmi veți arăta cine dintre noi este pentru împăratul lui Israel?
12 Ọ̀kan lára ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí pé, “Kò sí ọ̀kan nínú wa, olúwa ọba mi, ṣùgbọ́n Eliṣa, wòlíì tí ó wà ní Israẹli, sọ fún ọba Israẹli ọ̀rọ̀ gangan tí ó sọ nínú yàrá rẹ̀.”
Și unul dintre servitorii lui a spus: Nimeni, domnul meu, împărate; ci Elisei profetul, care este în Israel, spune împăratului lui Israel cuvintele pe care tu le vorbești în camera ta de culcare.
13 Ọba pa á láṣẹ, “Lọ, kí ẹ lọ wo ibi tí ó wà, kí èmi kí ó lè rán ènìyàn láti lọ mú un wá.” Ìròyìn padà wá wí pé, “Ó wà ní Dotani.”
Și el a spus: Mergeți și spionați unde este el, ca să trimit și să îl prind. Și i s-a spus, zicând: Iată, el este în Dotan.
14 Nígbà náà ni ó rán àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ àti ogun ńlá tí ó le síbẹ̀. Wọ́n sì lọ ní alẹ́ wọ́n sì yí ìlú náà ká.
De aceea a trimis el acolo cai și care și o mare oștire; și ei au venit noaptea și au încercuit cetatea.
15 Nígbà tí ìránṣẹ́ ènìyàn Ọlọ́run dìde ó sì jáde lọ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, ogun pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ wọn ti yí ìlú náà ká. “Yé è, olúwa mi! Kí ni kí àwa kí ó ṣe?” ìránṣẹ́ náà béèrè.
Și când servitorul omului lui Dumnezeu s-a sculat devreme și a ieșit, iată, o oștire încercuise cetatea deopotrivă cu cai și cu care. Și servitorul său i-a spus: Vai, stăpâne! Ce vom face?
16 “Má ṣe bẹ̀rù,” wòlíì náà dáhùn, “Àwọn tí ó wà pẹ̀lú wa, wọ́n pọ̀ ju àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn lọ.”
Și el a răspuns: Nu te teme, pentru că aceia ce sunt cu noi sunt mai mulți decât aceia ce sunt cu ei.
17 Eliṣa sì gbàdúrà, “Olúwa, la ojú rẹ̀ kí ó ba à lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú ìránṣẹ́ náà, ó sì wò, ó sì rí òkè ńlá tí ó kún fún ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ iná gbogbo yí Eliṣa ká.
Și Elisei s-a rugat și a spus: Doamne, te rog, deschide-i ochii pentru a vedea. Și DOMNUL a deschis ochii tânărului; și el a văzut; și, iată, muntele era plin de cai și de care de foc de jur împrejurul lui Elisei.
18 Bí àwọn ọ̀tá ṣe ń sọ̀kalẹ̀ wá níwájú rẹ, Eliṣa gbàdúrà sí Olúwa pé. “Bu ìfọ́jú lu àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” Olúwa sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Eliṣa ti béèrè.
Și după ce au coborât la el, Elisei s-a rugat DOMNULUI și a spus: Lovește acest popor, te rog, cu orbire. Și el i-a lovit cu orbire conform cuvântului lui Elisei.
19 Eliṣa sọ fún wọn pé, “Èyí kì í ṣe ọ̀nà bẹ́ẹ̀ ni èyí kì í ṣe ìlú náà. Tẹ̀lé mi, èmi yóò mú u yín lọ sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin tí ẹ̀yin ń wá.” Ó sì sìn wọ́n lọ sí Samaria.
Și Elisei le-a spus: Nu aceasta este calea, nici cetatea nu este aceasta; urmați-mă, și vă voi duce la omul pe care îl căutați. Dar el i-a condus în Samaria.
20 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n wọ ìlú náà, Eliṣa wí pé, “Olúwa, la ojú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kí wọn kí ó lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú wọn, wọ́n sì ríran, wọ́n sì wà níbẹ̀, nínú Samaria.
Și s-a întâmplat, când au intrat în Samaria, că Elisei a zis: DOAMNE, deschide ochii acestor oameni, ca să vadă. Și DOMNUL le-a deschis ochii și ei au văzut; și, iată, erau în mijlocul Samariei.
21 Nígbà tí ọba Israẹli rí wọn, ó béèrè lọ́wọ́ Eliṣa pé, “Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n, baba mi? Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n?”
Și împăratul lui Israel i-a spus lui Elisei, când i-a văzut: Părintele meu, să îi lovesc? Să îi lovesc?
22 “Má ṣe pa wọ́n,” ó dáhùn. “Ṣé ìwọ yóò pa àwọn ọkùnrin tí ìwọ mú pẹ̀lú idà rẹ tàbí ọrun rẹ? Gbé oúnjẹ àti omi síwájú wọn kí wọn kí ó lè jẹ kí wọn sì mu, nígbà náà kí wọn padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn.”
Iar el a răspuns: Să nu îi lovești, vrei să lovești pe aceia pe care i-ai luat captivi cu sabia ta și cu arcul tău? Pune-le pâine și apă înainte, ca să mănânce și să bea și să meargă la stăpânul lor.
23 Bẹ́ẹ̀ ni ó pèsè àsè ńlá fún wọn, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jẹ tí wọ́n mu, ó sì rán wọn lọ, wọ́n sì padà sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ẹgbẹ́ láti Aramu dáwọ́ ìgbógunti ilẹ̀ Israẹli dúró.
Și a pregătit un ospăț mare pentru ei; și după ce au mâncat și au băut, i-a trimis și au mers la stăpânul lor. Astfel cetele înarmate ale Siriei nu au mai venit în țara lui Israel.
24 Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ni Beni-Hadadi ọba Aramu kó gbogbo àwọn ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì yan sókè wọ́n sì dúró ti Samaria.
Și s-a întâmplat după aceasta, că Ben-Hadad, împăratul Siriei, și-a adunat toată oștirea și s-a urcat și a asediat Samaria.
25 Ìyàn ńlá sì mú ní ìlú Samaria; wọ́n dúró tí ì tó bẹ́ẹ̀ tí a fi ń ta orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan ní ọgọ́rùn-ún ìwọ̀n fàdákà àti ìdámẹ́rin òsùwọ̀n kábù imí ẹyẹlé, fún ìwọ̀n fàdákà márùn-ún.
Și era o mare foamete în Samaria; și, iată, au asediat-o, până când s-a vândut un cap de măgar pentru optzeci de arginți, și a patra parte a unui cab de găinaț de porumbel pentru cinci arginți.
26 Gẹ́gẹ́ bí ọba Israẹli ti ń kọjá lọ lórí odi, obìnrin kan sọkún sí i pé, “Ràn mí lọ́wọ́, olúwa ọba mi!”
Și pe când împăratul lui Israel trecea pe zid, o femeie a strigat la el, spunând: Ajută-mă, domnul meu, împărate.
27 Ọba sì dá a lóhùn pé, “Bí Olúwa kò bá gbà ọ́, níbo ni èmi yóò gbé ti gbà ọ́? Láti inú ilẹ̀ ìpakà, tàbí láti inú ibi ìfúntí?”
Și el a spus: Dacă DOMNUL nu te ajută, de unde să te ajut eu? Din hambar, sau din teasc?
28 Nígbà náà ọba béèrè lọ́wọ́ obìnrin náà pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” Obìnrin náà dáhùn pé, “Obìnrin yìí wí fún mi pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ ẹ́ lónìí, ní ọ̀la àwa yóò jẹ ọmọkùnrin tèmi.’
Și împăratul i-a zis: Ce îți este? Și ea a răspuns: Această femeie mi-a spus: Dă pe fiul tău, ca să îl mâncăm astăzi și îl vom mânca pe fiul meu mâine.
29 Bẹ́ẹ̀ ni a ṣe ọmọkùnrin mi a sì jẹ ẹ́. Ní ọjọ́ kejì mo wí fún un pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ,’ ṣùgbọ́n ó ti gbé e pamọ́.”
Astfel noi am fiert pe fiul meu și l-am mâncat; și i-am zis a doua zi: Dă pe fiul tău, ca să îl mâncăm, dar ea a ascuns pe fiul ei.
30 Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ obìnrin náà, ó fa aṣọ rẹ̀ ya. Gẹ́gẹ́ bí ó sì ti ń kọjá lọ sí orí odi, àwọn ènìyàn wò ó níbẹ̀ ní abẹ́, ó ní aṣọ ọ̀fọ̀ ní ara rẹ̀.
Și s-a întâmplat, când împăratul a auzit cuvintele femeii, că și-a sfâșiat hainele; și trecea pe zid și poporul privea și, iată, el avea pânză de sac pe interior, pe carnea lui.
31 Ó sì wí pé, “Kí Ọlọ́run kí ó fi ìyà jẹ mí, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ dájúdájú, pé orí ọmọkùnrin Eliṣa ọmọ Ṣafati kì ó wà ní ọrùn rẹ̀ ní òní!”
Atunci el a spus: Dumnezeu să îmi facă astfel și încă mai mult, dacă va rămâne pe el în această zi capul lui Elisei, fiul lui Șafat.
32 Nísinsin yìí Eliṣa jókòó ní ilé rẹ̀ àwọn àgbàgbà náà jókòó pẹ̀lú rẹ̀. Ọba sì rán oníṣẹ́ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó tó dé ibẹ̀, Eliṣa sọ fún àwọn àgbàgbà pé, “Ṣé ẹ̀yin kò rí bí apànìyàn ti ń rán ẹnìkan láti gé orí mi kúrò? Ẹ wò ó, nígbà tí ìránṣẹ́ náà bá dé, ẹ ti ìlẹ̀kùn kí ẹ sì dìímú ṣinṣin ní ẹnu-ọ̀nà, ìró ẹsẹ̀ olúwa rẹ̀ kò ha wà lẹ́yìn rẹ?”
Dar Elisei ședea în casa lui și bătrânii ședeau cu el; și împăratul a trimis un om înaintea sa; dar înainte ca mesagerul să vină la el, a spus bătrânilor: Vedeți cum acest fiu de ucigaș a trimis să îmi ia capul? Priviți, când mesagerul vine, închideți ușa și opriți-l la ușă; nu este sunetul picioarelor stăpânului său înapoia lui?
33 Nígbà tí ó sì ń sọ̀rọ̀ sí wọn, ìránṣẹ́ náà sọ̀kalẹ̀ wá bá a. Ọba náà sì wí pé, “Ibi yìí láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni. Kí ni ó dé tí èmi yóò fi dúró de Olúwa sí i?”
Și în timp ce încă vorbea cu ei, iată, mesagerul a coborât la el; iar împăratul a spus: Iată, acest rău este de la DOMNUL; ce să mai aștept de la DOMNUL?

< 2 Kings 6 >