< 2 Kings 6 >

1 Àwọn ọmọ wòlíì sọ fún Eliṣa pé, “Wò ó, ní ibi tí a ti pàdé pẹ̀lú rẹ, ó kéré fún wa.
I synowie proroków powiedzieli do Elizeusza: Oto miejsce, w którym mieszkamy wraz z tobą, jest zbyt ciasne dla nas.
2 Jẹ́ kí àwa kí ó lọ sí Jordani, ní ibi tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ti le rí ọ̀pá kan, jẹ́ kí àwa kí ó kọ́lé síbẹ̀ fún wa láti gbé.” Ó sì wí pé, “Lọ.”
Pozwól, że pójdziemy aż nad Jordan, weźmiemy stamtąd każdy po jednej belce i zbudujemy tam sobie miejsce na mieszkanie. Odpowiedział: Idźcie.
3 Nígbà náà ni ọ̀kan lára wọn wí pé, “Kí ó wù ọ́, èmí bẹ̀ ọ́, láti bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ?” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ,”
Jeden z nich powiedział: Racz, proszę, pójść ze swoimi sługami. Odpowiedział: Pójdę.
4 Ó sì lọ pẹ̀lú wọn. Wọ́n sì lọ sí Jordani wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gé igi.
I poszedł z nimi. Kiedy przybyli nad Jordan, zaczęli ścinać drzewa.
5 Bí ọ̀kan ṣe gé igi náà, àáké irin náà bọ́ sínú omi, ó kígbe sókè pé, “O! Olúwa mi, mo yá a ni!”
I zdarzyło się, że jednemu z nich przy ścinaniu drzewa [siekierą] żelazo wpadło do wody. Zawołał wtedy: Ach, mój panie! Ta [była] pożyczona.
6 Ènìyàn Ọlọ́run sì béèrè pé, “Níbo ni ó bọ́ sí?” Nígbà tí ó fi ibẹ̀ hàn án, Eliṣa gé igi kan ó sì jù ú síbẹ̀, ó sì mú irin náà fò lójú omi.
Mąż Boży zapytał: Gdzie wpadło? I wskazał mu miejsce. A on uciął drewno, wrzucił tam i żelazo wypłynęło.
7 Ó wí pé, “Gbé e jáde.” Lẹ́yìn náà ọkùnrin náà na ọwọ́ rẹ̀ jáde ó sì mú un.
I powiedział: Weź [je] sobie. Wyciągnął więc rękę i wziął je.
8 Nísinsin yìí ọba Aramu wà ní ogun pẹ̀lú Israẹli ó sì bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ gbèrò, ó wí pé, “Èmi yóò ṣe ibùdó mi sí ibí yìí nínú èyí náà àti bí ibí yìí.”
Potem, gdy król Syrii prowadził wojnę z Izraelem, naradzał się ze swoimi sługami, mówiąc: W tym a w tym miejscu będzie mój obóz.
9 Ènìyàn Ọlọ́run rán iṣẹ́ sí ọba Israẹli pé, “Kíyèsi ara láti kọjá ní ibẹ̀ yẹn, nítorí pé ará Aramu wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ síbẹ̀.”
Wtedy mąż Boży posłał do króla Izraela wiadomość: Strzeż się przechodzić przez to miejsce, bo tam Syryjczycy zrobili zasadzkę.
10 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli wo ibi tí ènìyàn Ọlọ́run náà fihàn, ní ẹ̀ẹ̀kan sí i Eliṣa kìlọ̀ fún ọba, bẹ́ẹ̀ ni ó wà lórí sísọ ní ibẹ̀.
Posłał więc król Izraela na to miejsce, o którym mu powiedział mąż Boży, ostrzegając go, i [król] uratował się nie raz i nie dwa.
11 Èyí mú ọba Aramu bínú. Ó pe àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé ìwọ kò ní sọ fún mi èwo nínú wa ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọba Israẹli?”
Serce króla Syrii zatrwożyło się z tego powodu. Zwołał więc swoje sługi i zapytał ich: Czemu mi nie powiecie, kto z nas [donosi] królowi Izraela?
12 Ọ̀kan lára ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí pé, “Kò sí ọ̀kan nínú wa, olúwa ọba mi, ṣùgbọ́n Eliṣa, wòlíì tí ó wà ní Israẹli, sọ fún ọba Israẹli ọ̀rọ̀ gangan tí ó sọ nínú yàrá rẹ̀.”
Jeden z jego sług odpowiedział: Nikt, mój panie, królu. To prorok Elizeusz, który jest w Izraelu, oznajmia królowi Izraela słowa, które wypowiadasz w swoim pokoju sypialnym.
13 Ọba pa á láṣẹ, “Lọ, kí ẹ lọ wo ibi tí ó wà, kí èmi kí ó lè rán ènìyàn láti lọ mú un wá.” Ìròyìn padà wá wí pé, “Ó wà ní Dotani.”
[On] odpowiedział: Idźcie i dowiedzcie się, gdzie on jest, abym posłał [po niego] i pojmał go. I doniesiono mu: Oto jest w Dotan.
14 Nígbà náà ni ó rán àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ àti ogun ńlá tí ó le síbẹ̀. Wọ́n sì lọ ní alẹ́ wọ́n sì yí ìlú náà ká.
Posłał więc tam konie i rydwany, i znaczny [oddział] wojska. Wyruszyli w nocy i oblegli miasto.
15 Nígbà tí ìránṣẹ́ ènìyàn Ọlọ́run dìde ó sì jáde lọ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, ogun pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ wọn ti yí ìlú náà ká. “Yé è, olúwa mi! Kí ni kí àwa kí ó ṣe?” ìránṣẹ́ náà béèrè.
Kiedy sługa męża Bożego wstał wcześnie rano i wyszedł, oto wojsko otoczyło miasto razem z końmi i rydwanami. Jego sługa powiedział do niego: Ach, mój panie! Cóż mamy czynić?
16 “Má ṣe bẹ̀rù,” wòlíì náà dáhùn, “Àwọn tí ó wà pẹ̀lú wa, wọ́n pọ̀ ju àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn lọ.”
Odpowiedział: Nie bój się, bo więcej jest tych, którzy [są] z nami, niż tych, którzy [są] z nimi.
17 Eliṣa sì gbàdúrà, “Olúwa, la ojú rẹ̀ kí ó ba à lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú ìránṣẹ́ náà, ó sì wò, ó sì rí òkè ńlá tí ó kún fún ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ iná gbogbo yí Eliṣa ká.
Wtedy modlił się Elizeusz: PANIE, otwórz, proszę, jego oczy, aby widział. PAN otworzył oczy tego sługi i ten zobaczył: oto góra była pełna koni i ognistych rydwanów wokół Elizeusza.
18 Bí àwọn ọ̀tá ṣe ń sọ̀kalẹ̀ wá níwájú rẹ, Eliṣa gbàdúrà sí Olúwa pé. “Bu ìfọ́jú lu àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” Olúwa sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Eliṣa ti béèrè.
A gdy [Syryjczycy] zeszli do niego, Elizeusz modlił się do PANA i powiedział: Proszę, dotknij ten lud ślepotą. I [PAN] dotknął go ślepotą według słowa Elizeusza.
19 Eliṣa sọ fún wọn pé, “Èyí kì í ṣe ọ̀nà bẹ́ẹ̀ ni èyí kì í ṣe ìlú náà. Tẹ̀lé mi, èmi yóò mú u yín lọ sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin tí ẹ̀yin ń wá.” Ó sì sìn wọ́n lọ sí Samaria.
Wtedy Elizeusz powiedział do nich: To nie ta droga ani nie to miasto. Pójdźcie za mną, a zaprowadzę was do człowieka, którego szukacie. I zaprowadził ich do Samarii.
20 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n wọ ìlú náà, Eliṣa wí pé, “Olúwa, la ojú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kí wọn kí ó lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú wọn, wọ́n sì ríran, wọ́n sì wà níbẹ̀, nínú Samaria.
A gdy weszli do Samarii, Elizeusz powiedział: PANIE, otwórz im oczy, aby przejrzeli. PAN otworzył im oczy i zobaczyli, że [są] w środku Samarii.
21 Nígbà tí ọba Israẹli rí wọn, ó béèrè lọ́wọ́ Eliṣa pé, “Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n, baba mi? Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n?”
Gdy król Izraela zobaczył ich, zapytał Elizeusza: Czy mam ich zabić, mój ojcze?
22 “Má ṣe pa wọ́n,” ó dáhùn. “Ṣé ìwọ yóò pa àwọn ọkùnrin tí ìwọ mú pẹ̀lú idà rẹ tàbí ọrun rẹ? Gbé oúnjẹ àti omi síwájú wọn kí wọn kí ó lè jẹ kí wọn sì mu, nígbà náà kí wọn padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn.”
Odpowiedział: Nie zabijaj. Czy zabijasz tych, których pojmałeś swoim mieczem i swoim łukiem? Połóż przed nimi chleb i wodę, aby jedli i pili, i wrócili do swego pana.
23 Bẹ́ẹ̀ ni ó pèsè àsè ńlá fún wọn, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jẹ tí wọ́n mu, ó sì rán wọn lọ, wọ́n sì padà sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ẹgbẹ́ láti Aramu dáwọ́ ìgbógunti ilẹ̀ Israẹli dúró.
Przygotował więc dla nich wielką ucztę. A gdy jedli i pili, odprawił ich i poszli do swego pana. Odtąd bandy Syryjczyków już nie wpadały do ziemi Izraela.
24 Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ni Beni-Hadadi ọba Aramu kó gbogbo àwọn ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì yan sókè wọ́n sì dúró ti Samaria.
Potem Ben-Hadad, król Syrii, zebrał całe swoje wojsko, wyruszył i obległ Samarię.
25 Ìyàn ńlá sì mú ní ìlú Samaria; wọ́n dúró tí ì tó bẹ́ẹ̀ tí a fi ń ta orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan ní ọgọ́rùn-ún ìwọ̀n fàdákà àti ìdámẹ́rin òsùwọ̀n kábù imí ẹyẹlé, fún ìwọ̀n fàdákà márùn-ún.
I nastał wielki głód w Samarii. Tak bowiem ją oblegali, że głowa osła [kosztowała] osiemdziesiąt srebrników, a ćwierć kaba gołębiego gnoju – pięć srebrników.
26 Gẹ́gẹ́ bí ọba Israẹli ti ń kọjá lọ lórí odi, obìnrin kan sọkún sí i pé, “Ràn mí lọ́wọ́, olúwa ọba mi!”
A gdy król Izraela przechodził po murze, [pewna] kobieta zawołała do niego: Ratuj mnie, mój panie, królu!
27 Ọba sì dá a lóhùn pé, “Bí Olúwa kò bá gbà ọ́, níbo ni èmi yóò gbé ti gbà ọ́? Láti inú ilẹ̀ ìpakà, tàbí láti inú ibi ìfúntí?”
Odpowiedział: Jeśli PAN cię nie uratuje, jakże [ja] ciebie uratuję? Czy z klepiska lub z tłoczni?
28 Nígbà náà ọba béèrè lọ́wọ́ obìnrin náà pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” Obìnrin náà dáhùn pé, “Obìnrin yìí wí fún mi pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ ẹ́ lónìí, ní ọ̀la àwa yóò jẹ ọmọkùnrin tèmi.’
Następnie król zapytał ją: Co ci jest? Odpowiedziała: Ta oto kobieta powiedziała mi: Daj swojego syna, abyśmy go zjadły dzisiaj, a jutro zjemy mojego syna.
29 Bẹ́ẹ̀ ni a ṣe ọmọkùnrin mi a sì jẹ ẹ́. Ní ọjọ́ kejì mo wí fún un pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ,’ ṣùgbọ́n ó ti gbé e pamọ́.”
Ugotowałyśmy więc mojego syna i zjadłyśmy go. Potem powiedziałam jej na drugi dzień: Daj swojego syna, abyśmy go zjadły. Lecz ona ukryła swojego syna.
30 Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ obìnrin náà, ó fa aṣọ rẹ̀ ya. Gẹ́gẹ́ bí ó sì ti ń kọjá lọ sí orí odi, àwọn ènìyàn wò ó níbẹ̀ ní abẹ́, ó ní aṣọ ọ̀fọ̀ ní ara rẹ̀.
A gdy król usłyszał słowa tej kobiety, rozdarł swoje szaty. I kiedy przechodził po murze, lud zobaczył, że pod spodem nosił wór na swoim ciele.
31 Ó sì wí pé, “Kí Ọlọ́run kí ó fi ìyà jẹ mí, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ dájúdájú, pé orí ọmọkùnrin Eliṣa ọmọ Ṣafati kì ó wà ní ọrùn rẹ̀ ní òní!”
Wtedy [król] powiedział: Niech mi to uczyni Bóg i tamto dorzuci, jeśli głowa Elizeusza, syna Szafata, ostoi się na nim dzisiaj.
32 Nísinsin yìí Eliṣa jókòó ní ilé rẹ̀ àwọn àgbàgbà náà jókòó pẹ̀lú rẹ̀. Ọba sì rán oníṣẹ́ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó tó dé ibẹ̀, Eliṣa sọ fún àwọn àgbàgbà pé, “Ṣé ẹ̀yin kò rí bí apànìyàn ti ń rán ẹnìkan láti gé orí mi kúrò? Ẹ wò ó, nígbà tí ìránṣẹ́ náà bá dé, ẹ ti ìlẹ̀kùn kí ẹ sì dìímú ṣinṣin ní ẹnu-ọ̀nà, ìró ẹsẹ̀ olúwa rẹ̀ kò ha wà lẹ́yìn rẹ?”
Elizeusz zaś siedział w swoim domu i starsi siedzieli razem z nim. I [król] wysłał przed sobą człowieka. Lecz zanim posłaniec przyszedł do niego, powiedział do starszych: Czy widzicie, że ten syn mordercy posłał, aby mi ucięto głowę? Uważajcie, gdy ten posłaniec przyjdzie, zamknijcie drzwi i zatrzymajcie go przed drzwiami. Czy za nim nie słychać kroków mego pana?
33 Nígbà tí ó sì ń sọ̀rọ̀ sí wọn, ìránṣẹ́ náà sọ̀kalẹ̀ wá bá a. Ọba náà sì wí pé, “Ibi yìí láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni. Kí ni ó dé tí èmi yóò fi dúró de Olúwa sí i?”
A gdy jeszcze z nimi rozmawiał, oto posłaniec przybył do niego i powiedział: To nieszczęście jest od PANA. Czego mam jeszcze oczekiwać od PANA?

< 2 Kings 6 >