< 2 Kings 6 >

1 Àwọn ọmọ wòlíì sọ fún Eliṣa pé, “Wò ó, ní ibi tí a ti pàdé pẹ̀lú rẹ, ó kéré fún wa.
One day a group of prophets said to Elisha, “Look, this place where we meet together with you is very small.
2 Jẹ́ kí àwa kí ó lọ sí Jordani, ní ibi tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ti le rí ọ̀pá kan, jẹ́ kí àwa kí ó kọ́lé síbẹ̀ fún wa láti gbé.” Ó sì wí pé, “Lọ.”
Allow us to go to the Jordan [River and cut down some trees to make] logs to build a new meeting place.” So Elisha said, “Okay, go.”
3 Nígbà náà ni ọ̀kan lára wọn wí pé, “Kí ó wù ọ́, èmí bẹ̀ ọ́, láti bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ?” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ,”
One of them said to Elisha, “Please come with us.” So Elisha replied, “Okay, I will go with you.”
4 Ó sì lọ pẹ̀lú wọn. Wọ́n sì lọ sí Jordani wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gé igi.
So they went together. When they reached the Jordan [River], they cut down some trees.
5 Bí ọ̀kan ṣe gé igi náà, àáké irin náà bọ́ sínú omi, ó kígbe sókè pé, “O! Olúwa mi, mo yá a ni!”
But while one of them was cutting down a tree, suddenly the axe head [separated from the handle and] fell into the water. He cried out to Elisha, “O, Master, what shall I do? [The axe is not mine]; I borrowed it!”
6 Ènìyàn Ọlọ́run sì béèrè pé, “Níbo ni ó bọ́ sí?” Nígbà tí ó fi ibẹ̀ hàn án, Eliṣa gé igi kan ó sì jù ú síbẹ̀, ó sì mú irin náà fò lójú omi.
Elisha replied, “Where did it fall into the water?” After the man showed him the place, Elisha cut off a stick, and threw it into the water, and caused the iron axe head to float [on top of the water].
7 Ó wí pé, “Gbé e jáde.” Lẹ́yìn náà ọkùnrin náà na ọwọ́ rẹ̀ jáde ó sì mú un.
Elisha said, “Take it out of the water.” So the man reached his hand down and picked up the axe head.
8 Nísinsin yìí ọba Aramu wà ní ogun pẹ̀lú Israẹli ó sì bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ gbèrò, ó wí pé, “Èmi yóò ṣe ibùdó mi sí ibí yìí nínú èyí náà àti bí ibí yìí.”
Whenever the king of Syria [prepared to send his army to] fight against Israel, he first consulted his officers, and then told them where they should set up their tents.
9 Ènìyàn Ọlọ́run rán iṣẹ́ sí ọba Israẹli pé, “Kíyèsi ara láti kọjá ní ibẹ̀ yẹn, nítorí pé ará Aramu wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ síbẹ̀.”
But each time, Elisha would send a message to warn the king of Israel, [telling him where the army of Syria was planning to attack them, ] saying, “Be sure that your army does not go near that place, because the army of Syria has set up their tents there.”
10 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli wo ibi tí ènìyàn Ọlọ́run náà fihàn, ní ẹ̀ẹ̀kan sí i Eliṣa kìlọ̀ fún ọba, bẹ́ẹ̀ ni ó wà lórí sísọ ní ibẹ̀.
So the king of Israel would send [messengers] to warn [the people who lived in] that place, and the people would remain on guard. That happened several times.
11 Èyí mú ọba Aramu bínú. Ó pe àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé ìwọ kò ní sọ fún mi èwo nínú wa ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọba Israẹli?”
The king of Syria was very upset/disturbed/angry about that. So he summoned his army officers and said to them, “[Obviously] one of you is (betraying us/revealing our plans) to the king of Israel. Which one of you is doing it?”
12 Ọ̀kan lára ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí pé, “Kò sí ọ̀kan nínú wa, olúwa ọba mi, ṣùgbọ́n Eliṣa, wòlíì tí ó wà ní Israẹli, sọ fún ọba Israẹli ọ̀rọ̀ gangan tí ó sọ nínú yàrá rẹ̀.”
One of his officers answered, “Your Majesty, it is not one of us. Elisha the prophet [knows what we plan to do, and he] tells the king of Israel everything. He even knows what you say in your own bedroom!”
13 Ọba pa á láṣẹ, “Lọ, kí ẹ lọ wo ibi tí ó wà, kí èmi kí ó lè rán ènìyàn láti lọ mú un wá.” Ìròyìn padà wá wí pé, “Ó wà ní Dotani.”
The king of Syria replied, “Go and find out where he is, and I will send [some men there] to capture him.” Someone told him, “People say that he is in Dothan [town north of Samaria].”
14 Nígbà náà ni ó rán àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ àti ogun ńlá tí ó le síbẹ̀. Wọ́n sì lọ ní alẹ́ wọ́n sì yí ìlú náà ká.
So the king sent a large group of soldiers [to Dothan] with horses and chariots. They arrived at night and surrounded the town.
15 Nígbà tí ìránṣẹ́ ènìyàn Ọlọ́run dìde ó sì jáde lọ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, ogun pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ wọn ti yí ìlú náà ká. “Yé è, olúwa mi! Kí ni kí àwa kí ó ṣe?” ìránṣẹ́ náà béèrè.
Early the next morning, Elisha’s servant got up and went outside the house. He saw the soldiers of Syria with their horses and chariots surrounding the town. So he went inside [the house and reported it to Elisha] and exclaimed, “O, sir! What are we going to do?”
16 “Má ṣe bẹ̀rù,” wòlíì náà dáhùn, “Àwọn tí ó wà pẹ̀lú wa, wọ́n pọ̀ ju àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn lọ.”
Elisha replied, “Do not be afraid! Those who will be helping us will be more than those who will be helping them!”
17 Eliṣa sì gbàdúrà, “Olúwa, la ojú rẹ̀ kí ó ba à lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú ìránṣẹ́ náà, ó sì wò, ó sì rí òkè ńlá tí ó kún fún ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ iná gbogbo yí Eliṣa ká.
Then he prayed, “Yahweh, I request that you open my servant’s eyes in order that he can see [what is out there]!” So Yahweh enabled the servant to look out and see that surrounding the hill on which the town [was built] was a huge number of horses, and chariots made of fire!
18 Bí àwọn ọ̀tá ṣe ń sọ̀kalẹ̀ wá níwájú rẹ, Eliṣa gbàdúrà sí Olúwa pé. “Bu ìfọ́jú lu àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” Olúwa sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Eliṣa ti béèrè.
When the army of Syria prepared to attack Elisha, he prayed again, saying, “Yahweh, cause all these soldiers to become blind!” Yahweh answered his prayer and caused them to be unable to see clearly.
19 Eliṣa sọ fún wọn pé, “Èyí kì í ṣe ọ̀nà bẹ́ẹ̀ ni èyí kì í ṣe ìlú náà. Tẹ̀lé mi, èmi yóò mú u yín lọ sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin tí ẹ̀yin ń wá.” Ó sì sìn wọ́n lọ sí Samaria.
Then Elisha went to them and said, “You are not on the right road; this is not the city that you are searching for. I will take you to the man whom you are searching for.” But he led them to Samaria, [the capital of Israel]!
20 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n wọ ìlú náà, Eliṣa wí pé, “Olúwa, la ojú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kí wọn kí ó lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú wọn, wọ́n sì ríran, wọ́n sì wà níbẹ̀, nínú Samaria.
As soon as they entered Samaria, Elisha prayed again, saying, “Yahweh, now enable these soldiers to see correctly again!” So Yahweh enabled them to see correctly, and they were surprised to see that they were inside Samaria [city].
21 Nígbà tí ọba Israẹli rí wọn, ó béèrè lọ́wọ́ Eliṣa pé, “Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n, baba mi? Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n?”
When the king of Israel saw them, he said to Elisha, “Sir, shall I [tell my soldiers to] kill them? Shall we kill all of them?”
22 “Má ṣe pa wọ́n,” ó dáhùn. “Ṣé ìwọ yóò pa àwọn ọkùnrin tí ìwọ mú pẹ̀lú idà rẹ tàbí ọrun rẹ? Gbé oúnjẹ àti omi síwájú wọn kí wọn kí ó lè jẹ kí wọn sì mu, nígbà náà kí wọn padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn.”
Elisha replied, “No, you must not kill them. If your army captured many of your enemies in a battle, you would certainly not [RHQ] kill them. Give these men something to eat and drink, and then allow them to return to their king.”
23 Bẹ́ẹ̀ ni ó pèsè àsè ńlá fún wọn, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jẹ tí wọ́n mu, ó sì rán wọn lọ, wọ́n sì padà sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ẹgbẹ́ láti Aramu dáwọ́ ìgbógunti ilẹ̀ Israẹli dúró.
So the king of Israel did that. He told his servants to provide a big feast for them. And when they had eaten and drunk plenty, he sent them away. They returned to the king of Syria [and told him what had happened]. So for a while after that, soldiers from Syria stopped raiding/attacking towns in Israel.
24 Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ni Beni-Hadadi ọba Aramu kó gbogbo àwọn ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì yan sókè wọ́n sì dúró ti Samaria.
But some time later, Ben-Hadad, the king of Syria, assembled his entire army, and they went to Samaria and surrounded the city [for a long time].
25 Ìyàn ńlá sì mú ní ìlú Samaria; wọ́n dúró tí ì tó bẹ́ẹ̀ tí a fi ń ta orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan ní ọgọ́rùn-ún ìwọ̀n fàdákà àti ìdámẹ́rin òsùwọ̀n kábù imí ẹyẹlé, fún ìwọ̀n fàdákà márùn-ún.
Because of that, after a while there was hardly any food left inside the city, with the result that eventually a donkey’s head, [which was usually worthless, ] cost eighty pieces of silver, and (one cup/0.3 liter) of dove’s dung cost five pieces of silver.
26 Gẹ́gẹ́ bí ọba Israẹli ti ń kọjá lọ lórí odi, obìnrin kan sọkún sí i pé, “Ràn mí lọ́wọ́, olúwa ọba mi!”
One day when the king of Israel was walking on top of the city wall, a woman cried out to him, “Your Majesty, help me!”
27 Ọba sì dá a lóhùn pé, “Bí Olúwa kò bá gbà ọ́, níbo ni èmi yóò gbé ti gbà ọ́? Láti inú ilẹ̀ ìpakà, tàbí láti inú ibi ìfúntí?”
He replied, “If Yahweh will not help you, I certainly cannot [RHQ] help you. I certainly [RHQ] do not have any wheat or wine!
28 Nígbà náà ọba béèrè lọ́wọ́ obìnrin náà pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” Obìnrin náà dáhùn pé, “Obìnrin yìí wí fún mi pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ ẹ́ lónìí, ní ọ̀la àwa yóò jẹ ọmọkùnrin tèmi.’
What is your problem?” She replied, “Several days ago, that woman [over there] said to me, ‘[Because we have nothing left to eat, ] let’s kill your son today, in order that we can eat his flesh. Then tomorrow we can [kill] my son [and] eat his flesh.’
29 Bẹ́ẹ̀ ni a ṣe ọmọkùnrin mi a sì jẹ ẹ́. Ní ọjọ́ kejì mo wí fún un pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ,’ ṣùgbọ́n ó ti gbé e pamọ́.”
So we [killed my son and cut his body up and] boiled his flesh and ate it. The next day, I said to her, ‘Now give your son to me, in order that we can [kill him and cook his flesh and] eat it.’ But she has hidden her son!”
30 Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ obìnrin náà, ó fa aṣọ rẹ̀ ya. Gẹ́gẹ́ bí ó sì ti ń kọjá lọ sí orí odi, àwọn ènìyàn wò ó níbẹ̀ ní abẹ́, ó ní aṣọ ọ̀fọ̀ ní ara rẹ̀.
When the king heard what the woman said, he tore his robe [to show that he was very distressed]. The people who were standing close to the wall were able to see that the king was wearing rough cloth underneath his robe [because he was very distressed].
31 Ó sì wí pé, “Kí Ọlọ́run kí ó fi ìyà jẹ mí, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ dájúdájú, pé orí ọmọkùnrin Eliṣa ọmọ Ṣafati kì ó wà ní ọrùn rẹ̀ ní òní!”
The king exclaimed, “I wish/hope that God will strike me dead if I do not cut off the head of Elisha today, [because he is the one who has caused these terrible things to happen to us]!”
32 Nísinsin yìí Eliṣa jókòó ní ilé rẹ̀ àwọn àgbàgbà náà jókòó pẹ̀lú rẹ̀. Ọba sì rán oníṣẹ́ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó tó dé ibẹ̀, Eliṣa sọ fún àwọn àgbàgbà pé, “Ṣé ẹ̀yin kò rí bí apànìyàn ti ń rán ẹnìkan láti gé orí mi kúrò? Ẹ wò ó, nígbà tí ìránṣẹ́ náà bá dé, ẹ ti ìlẹ̀kùn kí ẹ sì dìímú ṣinṣin ní ẹnu-ọ̀nà, ìró ẹsẹ̀ olúwa rẹ̀ kò ha wà lẹ́yìn rẹ?”
So the king sent an officer to get Elisha. Before the officer arrived, Elisha was sitting in his house with some Israeli elders who were talking with him. Elisha said to them, “That murderer, [the king of Israel, ] is sending someone here to kill me. Listen: When he arrives, shut the door and do not allow him to come in. And the king will be coming right behind that officer!”
33 Nígbà tí ó sì ń sọ̀rọ̀ sí wọn, ìránṣẹ́ náà sọ̀kalẹ̀ wá bá a. Ọba náà sì wí pé, “Ibi yìí láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni. Kí ni ó dé tí èmi yóò fi dúró de Olúwa sí i?”
And while he was still speaking, the king and the officer arrived. The king said, “It is Yahweh who has caused us to have all this trouble/suffering. (Why should I wait any longer [RHQ] for him to do something [to help us]?/It is useless for me to wait any longer for him [to help us]!)”

< 2 Kings 6 >