< 2 Kings 5 >

1 Naamani jẹ́ olórí ogun ọba Aramu. Ó jẹ́ ènìyàn ńlá níwájú ọ̀gá rẹ̀, wọ́n sì bu ọlá fún un, nítorí nípasẹ̀ rẹ̀ ni Olúwa ti fi ìṣẹ́gun fún Aramu. Òun jẹ́ alágbára, akọni ọkùnrin ṣùgbọ́n, ó dẹ́tẹ̀.
Și Naaman, căpetenia oștirii împăratului Siriei, era un om mare și demn de cinste înaintea stăpânului său, deoarece prin el DOMNUL dăduse eliberare Siriei; el era de asemenea un războinic viteaz, dar era lepros.
2 Nísinsin yìí ẹgbẹgbẹ́ láti Aramu ti jáde lọ láti mú ọmọ obìnrin kékeré kan ní ìgbèkùn láti Israẹli, ó sì sin ìyàwó Naamani.
Și sirienii ieșiseră în cete și aduseseră captivă o tinerică din țara lui Israel; și ea servea soției lui Naaman.
3 Ó sọ fún ọ̀gá rẹ̀ obìnrin pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ọ̀gá mi lè rí wòlíì tí ó wà ní Samaria! Yóò wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
Și ea a spus stăpânei sale: Dacă ar fi voit Dumnezeu ca domnul meu să fie cu profetul din Samaria! El l-ar vindeca de lepra sa.
4 Naamani lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ̀ ó sì wí fún un ohun tí ọmọbìnrin Israẹli ti sọ.
Și unul a intrat și a spus domnului său, zicând: Așa și așa a zis tânăra care este din țara lui Israel.
5 “Ní gbogbo ọ̀nà, lọ,” ọba Aramu dá a lóhùn pé, “Èmi yóò fi ìwé ránṣẹ́ sí ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni Naamani lọ, ó sì mú pẹ̀lú rẹ̀ tálẹ́ǹtì fàdákà mẹ́wàá, ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ìwọ̀n wúrà àti ìpààrọ̀ aṣọ mẹ́wàá.
Și împăratul Siriei a zis: Du-te, mergi, și eu voi trimite o scrisoare împăratului lui Israel. Și el a plecat și a luat cu el zece talanți de argint și șase mii de monede de aur și zece schimburi de haine.
6 Ìwé tí ó mú lọ sọ́dọ̀ ọba Israẹli kà pé, “Pẹ̀lú ìwé yìí èmi ń rán ìránṣẹ́ mi Naamani sí ọ pé o lè wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
Și a adus scrisoarea împăratului lui Israel, spunând: Acum, când această scrisoare ajunge la tine, iată, am trimis pe servitorul meu Naaman la tine, ca să îl vindeci de lepra lui.
7 Bí ọba Israẹli ti ka ìwé náà ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wí pé, “Èmi ha jẹ́ Ọlọ́run? Ǹjẹ́ èmi le pa kí n sì mú wá sí ààyè padà? Kí ni ó dé tí eléyìí rán ènìyàn sí mi láti wo ààrùn ẹ̀tẹ̀ rẹ sàn, kí ẹ wo bí ó ti ń wá ọ̀nà láti wá ìjà pẹ̀lú mi!”
Și s-a întâmplat, după ce împăratul lui Israel a citit scrisoarea, că și-a sfâșiat hainele și a spus: Sunt eu Dumnezeu, ca să omor sau să înviez, că acest om trimite la mine să vindec un om de lepra lui? De aceea luați aminte, vă rog, și vedeți cum caută ceartă împotriva mea.
8 Nígbà tí Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run gbọ́ pé ọba Israẹli ti ya aṣọ rẹ̀, ó sì rán iṣẹ́ yìí sí i pé, “Kí ni ó dé tí o fi fa aṣọ rẹ ya? Jẹ́ kí ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi. Òun yóò sì mọ̀ pé wòlíì wà ní Israẹli.”
Și s-a întâmplat, când Elisei, omul lui Dumnezeu, a auzit că împăratul lui Israel și-a sfâșiat hainele, că a trimis la împărat, spunând: Pentru ce ți-ai sfâșiat hainele? Lasă-l să vină la mine și va cunoaște că este un profet în Israel.
9 Bẹ́ẹ̀ ni Naamani sì lọ pẹ̀lú ẹṣin rẹ̀ àti kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Eliṣa.
Astfel Naaman a venit cu caii săi și cu carul său și a stat în picioare la ușa casei lui Elisei.
10 Eliṣa rán ìránṣẹ́ láti lọ sọ fún un pé, “Lọ, wẹ̀ ara rẹ ní ìgbà méje ní odò Jordani, ẹran-ara rẹ yóò sì tún padà bọ̀ sípò, ìwọ yóò sì mọ́.”
Și Elisei a trimis un mesager la el, spunând: Du-te și spală-te de șapte ori în Iordan, și carnea ta își va reveni și vei fi curat.
11 Ṣùgbọ́n Naamani lọ pẹ̀lú ìbínú ó sì wí pé, “Mo lérò pé yóò sì dìde jáde wá nítòótọ́ sí mi, yóò sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run, fi ọwọ́ rẹ̀ lórí ibẹ̀ kí ó sì wo ẹ̀tẹ̀ mi sàn.
Dar Naaman s-a înfuriat și a plecat și a zis: Iată, eu gândeam: El va ieși negreșit la mine și va sta în picioare și va chema numele DOMNULUI Dumnezeului său și își va legăna mâna asupra locului și va vindeca pe cel lepros.
12 Abana àti Fapari, odò Damasku kò ha dára ju gbogbo omi Israẹli lọ? Ṣé èmi kò le wẹ̀ nínú wọn kí n sì mọ́?” Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà, ó sì lọ pẹ̀lú ìrunú.
Nu sunt Abana și Parpar, râurile Damascului, mai bune decât toate apele lui Israel? Nu aș putea să mă spăl în ele și să fiu curat? Astfel el s-a întors și a plecat în furie.
13 Ìránṣẹ́ Naamani lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ó sì wí pé, “Baba mi, tí wòlíì bá ti sọ fún ọ láti ṣe ohun ńlá kan, ṣé ìwọ kì bá ti ṣe, mélòó mélòó nígbà náà, nígbà tí ó sọ fún ọ pé, ‘Wẹ̀ kí o sì mọ́’!”
Și servitorii lui s-au apropiat și i-au vorbit și au spus: Tatăl meu, dacă profetul ți-ar fi cerut să faci vreun lucru mare, nu l-ai fi făcut? Cu cât mai mult atunci, când îți spune: Spală-te și fii curat?
14 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ ó sì tẹ ara rẹ̀ bọ inú odò Jordani ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti sọ fún un, ẹran-ara rẹ̀ sì tún padà sí mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọkùnrin kékeré.
Atunci el a coborât și s-a scufundat de șapte ori în Iordan, conform spusei omului lui Dumnezeu; și carnea lui s-a făcut din nou precum este carnea unui copilaș, și el a fost curat.
15 Nígbà náà Naamani àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ padà lọ sí ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run. Ó sì dúró níwájú rẹ̀ ó sì wí pé, “Nísinsin yìí èmi mọ̀ pé kò sí Ọlọ́run ní gbogbo àgbáyé àyàfi ní Israẹli nìkan. Jọ̀wọ́ gba ẹ̀bùn láti ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ.”
Și s-a întors la omul lui Dumnezeu, el și toată ceata lui, și a venit și a stat în picioare înaintea lui și a zis: Iată acum cunosc că nu este Dumnezeu pe tot pământul, decât în Israel; și acum, te rog, primește un dar de la servitorul tău.
16 Wòlíì náà dáhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ẹni tí mo ń sìn, èmi kò nígbà ohun kan,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Naamani rọ̀ ọ́ láti gbà á, ó kọ̀.
Dar el a spus: Precum DOMNUL trăiește înaintea căruia stau în picioare, nu voi primi. Iar el l-a constrâns să ia; dar Elisei a refuzat.
17 Naamani wí pé, “Tí o kò bá nígbà, jọ̀wọ́ jẹ́ kí a fi fún èmi ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ ẹrù erùpẹ̀ tí ìbáaka méjì le rù, nítorí láti òní lọ ìránṣẹ́ rẹ kì yóò rú ẹbọ sísun àti rú ẹbọ sí ọ̀kan lára àwọn ọlọ́run mìíràn mọ́ bí kò ṣe sí Olúwa.
Și Naaman a spus: Să nu se dea atunci, te rog, servitorului tău din pământul acesta povara a doi catâri? Pentru că servitorul tău nu va mai oferi de acum înainte nici ofrandă arsă, nici sacrificiu altor dumnezei, ci DOMNULUI.
18 Ṣùgbọ́n kí Olúwa kí ó dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún nǹkan yìí. Nígbà tí ọ̀gá mi wọ inú ilé Rimoni láti fi orí balẹ̀ tí ó sì fi ara ti ọwọ́ mi tí mo sì tẹ ara mi ba pẹ̀lú níbẹ̀. Nígbà tí èmi tẹ ara mi ba ní ilé Rimoni, kí Olúwa dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún èyí.”
În acest lucru DOMNUL să ierte pe servitorul tău: că atunci când stăpânul meu intră în casa lui Rimon să se închine acolo și se sprijină de mâna mea și eu mă prosternez în casa lui Rimon: când mă prosternez eu însumi în casa lui Rimon, DOMNUL să ierte pe servitorul tău în acest lucru.
19 Eliṣa wí pé, “Máa lọ ní àlàáfíà.” Lẹ́yìn ìgbà tí Naamani tí rin ìrìnàjò tí ó jìnnà,
Iar el i-a spus: Du-te în pace. Astfel a plecat de la el o bucată de cale.
20 Gehasi, ìránṣẹ́ Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run, ó wí fún ara rẹ̀ pé, “Ọ̀gá mi jẹ́ ẹni tí ó rọ́nú lórí Naamani, ará Aramu, nípa pé kò gba ohunkóhun ní ọwọ́ rẹ̀ ohun tí ó mú wá, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, èmi yóò sá tẹ̀lé e èmi yóò sì gba ohun kan ní ọwọ́ rẹ̀.”
Dar Ghehazi, servitorul lui Elisei, omul lui Dumnezeu, a spus: Iată, stăpânul meu a cruțat pe Naaman, acest sirian, neprimind din mâinile lui ceea ce a adus; precum DOMNUL trăiește, voi alerga după el și voi lua ceva de la el.
21 Bẹ́ẹ̀ ni Gehasi sáré tẹ̀lé Naamani. Nígbà tí Naamani rí i tí ó ń sáré tẹ̀lé e, ó sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ̀. “Ṣé gbogbo nǹkan wà dáradára?” ó béèrè.
Astfel Ghehazi l-a urmat pe Naaman. Și, când Naaman l-a văzut alergând după el, a coborât din car să îl întâlnească și a spus: Este totul bine?
22 “Gbogbo nǹkan wà dáradára,” Gehasi dá a lóhùn. “Ọ̀gá mi rán mi láti sọ wí pé, ‘Àwọn ọ̀dọ́ ọmọkùnrin méjì láti ọ̀dọ̀ ọmọ wòlíì wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi láti orí òkè ìlú ti Efraimu. Jọ̀wọ́ fún wọn ní ẹ̀bùn fàdákà àti ìpààrọ̀ aṣọ méjì.’”
Iar el a zis: Totul este bine. Stăpânul meu m-a trimis, spunând: Iată, chiar acum au venit la mine din muntele Efraim, doi tineri dintre fiii profeților; dă-le, te rog, un talant de argint și două schimburi de haine.
23 Naamani wí pé, “Ní gbogbo ọ̀nà, mú ẹ̀bùn méjì.” Ó sì rọ Gehasi láti gbà wọ́n, ó sì di ẹ̀bùn méjì náà ti fàdákà ní inú àpò méjì, pẹ̀lú ìpààrọ̀ aṣọ méjì, ó sì fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ méjì, wọ́n sì kó wọn lọ sọ́dọ̀ Gehasi.
Și Naaman a spus: Binevoiește și ia doi talanți. Și l-a constrâns și a legat doi talanți de argint în doi saci, cu două schimburi de haine și le-a pus pe doi dintre servitorii săi; și ei le-au purtat înaintea lui.
24 Nígbà tí Gehasi sì dé ibi ilé ìṣọ́, ó gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn, ó sì tó wọ́n sínú ilé, ó sì jọ̀wọ́ àwọn ọkùnrin náà lọ́wọ́ lọ, wọ́n sì jáde lọ.
Și când a ajuns la turn, el le-a luat din mâna lor și le-a pus în casă; și a dat drumul oamenilor și ei au plecat.
25 Nígbà náà ó sì wọlé wá ó sì dúró níwájú ọ̀gá rẹ̀ Eliṣa. “Níbo ni o ti wà Gehasi?” Eliṣa béèrè. “Ìránṣẹ́ rẹ kò lọ sí ibìkan kan.” Gehasi dá a lóhùn.
Dar el a intrat și a stat în picioare înaintea stăpânului său. Și Elisei i-a spus: De unde vii tu, Ghehazi? Iar el a zis: Servitorul tău nu a mers nicăieri.
26 Ṣùgbọ́n Eliṣa wí fún un pé, “Ẹ̀mí mi kò ha wà pẹ̀lú rẹ nígbà tí ọkùnrin náà sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ? Ṣé àsìkò tí ó yẹ láti gba owó nìyìí, tàbí láti gba aṣọ, ọgbà olifi, ọgbà àjàrà, àgùntàn, màlúù tàbí ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin?
Iar el i-a spus: Nu a mers inima mea cu tine, când omul s-a întors din carul său să te întâlnească? Este un timp de primit argint și de primit haine, și măslini și vii, și oi și boi, și robi și roabe?
27 Ẹ̀tẹ̀ Naamani yóò lẹ̀ mọ́ ọ àti sí irú-ọmọ rẹ títí láé.” Nígbà náà Gehasi kúrò níwájú Eliṣa, ó sì di adẹ́tẹ̀, ó sì funfun gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ̀n òwú.
De aceea lepra lui Naaman se va lipi de tine și de sămânța ta pentru totdeauna. Iar el a ieșit lepros din prezența lui, alb ca zăpada.

< 2 Kings 5 >