< 2 Kings 5 >

1 Naamani jẹ́ olórí ogun ọba Aramu. Ó jẹ́ ènìyàn ńlá níwájú ọ̀gá rẹ̀, wọ́n sì bu ọlá fún un, nítorí nípasẹ̀ rẹ̀ ni Olúwa ti fi ìṣẹ́gun fún Aramu. Òun jẹ́ alágbára, akọni ọkùnrin ṣùgbọ́n, ó dẹ́tẹ̀.
Naaman, prince of the chyualrye of the kyng of Syrie, was a greet man, and worschipid anentis his lord; for bi hym the Lord yaf helthe to Sirie; sotheli he was a strong man and riche, but leprouse.
2 Nísinsin yìí ẹgbẹgbẹ́ láti Aramu ti jáde lọ láti mú ọmọ obìnrin kékeré kan ní ìgbèkùn láti Israẹli, ó sì sin ìyàwó Naamani.
Forsothe theues yede out of Sirie, and ledden prisonere fro the lond of Israel a litil damysele, that was in the seruyce of the wijf of Naaman.
3 Ó sọ fún ọ̀gá rẹ̀ obìnrin pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ọ̀gá mi lè rí wòlíì tí ó wà ní Samaria! Yóò wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
`Which damysele seide to hir ladi, `Y wolde, that my lord hadde be at the prophete which is in Samarie; sotheli the prophete schulde haue curid hym of the lepre which he hath.
4 Naamani lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ̀ ó sì wí fún un ohun tí ọmọbìnrin Israẹli ti sọ.
Therfor Naaman entride to his lord, and telde to hym, and seide, A damysel of the lond of Israel spak so and so.
5 “Ní gbogbo ọ̀nà, lọ,” ọba Aramu dá a lóhùn pé, “Èmi yóò fi ìwé ránṣẹ́ sí ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni Naamani lọ, ó sì mú pẹ̀lú rẹ̀ tálẹ́ǹtì fàdákà mẹ́wàá, ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ìwọ̀n wúrà àti ìpààrọ̀ aṣọ mẹ́wàá.
Therfor the kyng of Syrie seide to hym, Go thou, and Y schal sende lettris to the kyng of Israel. And whanne he hadde go forth, and hadde take with hym ten talentis of siluer, and sixe thousynde goldun platis, `ether floreyns, and ten chaungyngis of clothis,
6 Ìwé tí ó mú lọ sọ́dọ̀ ọba Israẹli kà pé, “Pẹ̀lú ìwé yìí èmi ń rán ìránṣẹ́ mi Naamani sí ọ pé o lè wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
he brouyte lettris to the kyng of Israel bi these wordis; Whanne thou hast take this pistle, wite thou, that Y haue sent to thee Naaman, my seruaunt, that thou cure hym of his lepre.
7 Bí ọba Israẹli ti ka ìwé náà ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wí pé, “Èmi ha jẹ́ Ọlọ́run? Ǹjẹ́ èmi le pa kí n sì mú wá sí ààyè padà? Kí ni ó dé tí eléyìí rán ènìyàn sí mi láti wo ààrùn ẹ̀tẹ̀ rẹ sàn, kí ẹ wo bí ó ti ń wá ọ̀nà láti wá ìjà pẹ̀lú mi!”
And whanne the kyng of Israel hadde red the lettris, he to-rente his clothis, and seide, Whether Y am God, that may sle and quykene, for this kyng sente to me, that Y cure a man of his lepre? Perseyue ye, and se, that he sekith occasiouns ayens me.
8 Nígbà tí Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run gbọ́ pé ọba Israẹli ti ya aṣọ rẹ̀, ó sì rán iṣẹ́ yìí sí i pé, “Kí ni ó dé tí o fi fa aṣọ rẹ ya? Jẹ́ kí ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi. Òun yóò sì mọ̀ pé wòlíì wà ní Israẹli.”
And whanne Elisee, the man of God, hadde herd this, that is, that the kyng of Israel hadde to-rente hise clothis, he sente to the kyng, and seide, Whi to-rentist thou thi clothis? come he to me, and wite he, that a prophete is in Israel.
9 Bẹ́ẹ̀ ni Naamani sì lọ pẹ̀lú ẹṣin rẹ̀ àti kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Eliṣa.
Therfor Naaman cam with horsis and charis, and stood at the dore of the hows of Elisee.
10 Eliṣa rán ìránṣẹ́ láti lọ sọ fún un pé, “Lọ, wẹ̀ ara rẹ ní ìgbà méje ní odò Jordani, ẹran-ara rẹ yóò sì tún padà bọ̀ sípò, ìwọ yóò sì mọ́.”
And Elisee sente to hym a messanger, and seide, Go thou, and be thou waischun seuensithis in Jordan; and thi fleisch shal resseyue helthe, and thou schalt be clensid.
11 Ṣùgbọ́n Naamani lọ pẹ̀lú ìbínú ó sì wí pé, “Mo lérò pé yóò sì dìde jáde wá nítòótọ́ sí mi, yóò sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run, fi ọwọ́ rẹ̀ lórí ibẹ̀ kí ó sì wo ẹ̀tẹ̀ mi sàn.
Naaman was wrooth, and yede awei, and seide, Y gesside, that he schulde go out to me, and that he schulde stonde, and clepe the name of `the Lord his God, and that he schulde touche with his hond the place of lepre, and schulde cure me.
12 Abana àti Fapari, odò Damasku kò ha dára ju gbogbo omi Israẹli lọ? Ṣé èmi kò le wẹ̀ nínú wọn kí n sì mọ́?” Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà, ó sì lọ pẹ̀lú ìrunú.
Whether Abana and Pharphar, floodis of Damask, ben not betere than alle the watris of Israel, that Y be waischun in tho, and be clensid?
13 Ìránṣẹ́ Naamani lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ó sì wí pé, “Baba mi, tí wòlíì bá ti sọ fún ọ láti ṣe ohun ńlá kan, ṣé ìwọ kì bá ti ṣe, mélòó mélòó nígbà náà, nígbà tí ó sọ fún ọ pé, ‘Wẹ̀ kí o sì mọ́’!”
Therfor whanne he hadde turned hym silf, and yede awei, hauynge indignacioun, hise seruauntis neiyiden to hym, and spaken to hym, Fadir, thouy the prophete hadde seid to thee a greet thing, certis thou owist to do; hou myche more for now he seide to thee, Be thou waischun, and thou schalt be clensid.
14 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ ó sì tẹ ara rẹ̀ bọ inú odò Jordani ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti sọ fún un, ẹran-ara rẹ̀ sì tún padà sí mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọkùnrin kékeré.
He yede doun, and waischide hym seuensithis in Jordan, bi the word of the man of God; and his fleisch was restored as the fleisch of a litil child, and he was clensid.
15 Nígbà náà Naamani àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ padà lọ sí ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run. Ó sì dúró níwájú rẹ̀ ó sì wí pé, “Nísinsin yìí èmi mọ̀ pé kò sí Ọlọ́run ní gbogbo àgbáyé àyàfi ní Israẹli nìkan. Jọ̀wọ́ gba ẹ̀bùn láti ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ.”
And he turnede ayen with al his felouschipe to the man of God, and cam, and stood bifor hym; and seide, Verili Y knowe, that noon other God is in al erthe, no but oneli God of Israel; therfor, Y biseche, that thou take blessyng of thi seruaunt.
16 Wòlíì náà dáhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ẹni tí mo ń sìn, èmi kò nígbà ohun kan,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Naamani rọ̀ ọ́ láti gbà á, ó kọ̀.
And he answeride, The Lord lyueth bifor whom Y stonde, for Y schal not take. And whanne he made `strengthe, that is, greet preier, Elisee assentide not outirli.
17 Naamani wí pé, “Tí o kò bá nígbà, jọ̀wọ́ jẹ́ kí a fi fún èmi ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ ẹrù erùpẹ̀ tí ìbáaka méjì le rù, nítorí láti òní lọ ìránṣẹ́ rẹ kì yóò rú ẹbọ sísun àti rú ẹbọ sí ọ̀kan lára àwọn ọlọ́run mìíràn mọ́ bí kò ṣe sí Olúwa.
Therfor Naaman seide, As thou wolt; but, I biseche, graunte thou to me, thi seruaunt, that Y take of `the lond the birthun of twei burdones; for thi seruaunt schal no more make brent sacrifice, ether slayn sacrifice, to alien goddis, no but to the Lord.
18 Ṣùgbọ́n kí Olúwa kí ó dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún nǹkan yìí. Nígbà tí ọ̀gá mi wọ inú ilé Rimoni láti fi orí balẹ̀ tí ó sì fi ara ti ọwọ́ mi tí mo sì tẹ ara mi ba pẹ̀lú níbẹ̀. Nígbà tí èmi tẹ ara mi ba ní ilé Rimoni, kí Olúwa dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún èyí.”
Forsothe this thing is oneli, of which thou schalt preie the Lord for thi seruaunt, whanne my lord shal entre into the temple of Remmon, that he worschipe, and while he `schal lene on myn hond, if Y worschipe in the temple of Remmon, while he worschipith in the same place, that the Lord foryyue to thi seruaunt for this thing.
19 Eliṣa wí pé, “Máa lọ ní àlàáfíà.” Lẹ́yìn ìgbà tí Naamani tí rin ìrìnàjò tí ó jìnnà,
Which Elisee seide to hym, Go thou in pees. `Therfor he yede fro Elisee in a chosun tyme of the lond.
20 Gehasi, ìránṣẹ́ Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run, ó wí fún ara rẹ̀ pé, “Ọ̀gá mi jẹ́ ẹni tí ó rọ́nú lórí Naamani, ará Aramu, nípa pé kò gba ohunkóhun ní ọwọ́ rẹ̀ ohun tí ó mú wá, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, èmi yóò sá tẹ̀lé e èmi yóò sì gba ohun kan ní ọwọ́ rẹ̀.”
And Giezi, the child of the man of God, seide, My lord sparide this Naaman of Syrie, that he took not of hym that, that he brouyte; the Lord lyueth, for Y schal renne aftir hym, and Y schal take of hym sum thing.
21 Bẹ́ẹ̀ ni Gehasi sáré tẹ̀lé Naamani. Nígbà tí Naamani rí i tí ó ń sáré tẹ̀lé e, ó sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ̀. “Ṣé gbogbo nǹkan wà dáradára?” ó béèrè.
And Giezi suede aftir the bak of Naaman; and whanne Naaman hadde seyn Giezi rennynge to hym, he skippide doun of the chare in to the metyng of Giezi; and seide, Whether alle thingis ben riytfuli?
22 “Gbogbo nǹkan wà dáradára,” Gehasi dá a lóhùn. “Ọ̀gá mi rán mi láti sọ wí pé, ‘Àwọn ọ̀dọ́ ọmọkùnrin méjì láti ọ̀dọ̀ ọmọ wòlíì wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi láti orí òkè ìlú ti Efraimu. Jọ̀wọ́ fún wọn ní ẹ̀bùn fàdákà àti ìpààrọ̀ aṣọ méjì.’”
And he seide, Riytfuli; my lord sente me to thee, and seide, Twey yonge men of the hille of Effraym, of the sones of prophetis, camen now to me; yyue thou to hem a talent of siluer, and double chaungyng clothis.
23 Naamani wí pé, “Ní gbogbo ọ̀nà, mú ẹ̀bùn méjì.” Ó sì rọ Gehasi láti gbà wọ́n, ó sì di ẹ̀bùn méjì náà ti fàdákà ní inú àpò méjì, pẹ̀lú ìpààrọ̀ aṣọ méjì, ó sì fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ méjì, wọ́n sì kó wọn lọ sọ́dọ̀ Gehasi.
And Naaman seide, It is betere that thou take twei talentis. And Naaman constreynede hym; and Naaman boond twei talentis of siluer in twei sackis, and double clothis, and puttide on his twey children, `that is, seruauntis, whiche also baren bifor Giezi.
24 Nígbà tí Gehasi sì dé ibi ilé ìṣọ́, ó gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn, ó sì tó wọ́n sínú ilé, ó sì jọ̀wọ́ àwọn ọkùnrin náà lọ́wọ́ lọ, wọ́n sì jáde lọ.
And whanne he hadde come thanne in the euentid, he took fro the hond of hem, and leide vp in the hows; and he delyuerede the men, and thei yeden.
25 Nígbà náà ó sì wọlé wá ó sì dúró níwájú ọ̀gá rẹ̀ Eliṣa. “Níbo ni o ti wà Gehasi?” Eliṣa béèrè. “Ìránṣẹ́ rẹ kò lọ sí ibìkan kan.” Gehasi dá a lóhùn.
Forsothe Giezi entride, and stood bifor his lord. And Elise seide, Giezi, fro whennus comest thou? Which answeride, Thi seruaunt yede not to ony place.
26 Ṣùgbọ́n Eliṣa wí fún un pé, “Ẹ̀mí mi kò ha wà pẹ̀lú rẹ nígbà tí ọkùnrin náà sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ? Ṣé àsìkò tí ó yẹ láti gba owó nìyìí, tàbí láti gba aṣọ, ọgbà olifi, ọgbà àjàrà, àgùntàn, màlúù tàbí ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin?
And Elise seide, Whether myn herte was not in present, whanne the man turnede ayen fro his chare in to the metyng of thee? Now therfor thou hast take siluer, and thou hast take clothis, that thou bie places of olyues, and vyneris, and scheep, and oxis, and seruauntis, and handmaydis;
27 Ẹ̀tẹ̀ Naamani yóò lẹ̀ mọ́ ọ àti sí irú-ọmọ rẹ títí láé.” Nígbà náà Gehasi kúrò níwájú Eliṣa, ó sì di adẹ́tẹ̀, ó sì funfun gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ̀n òwú.
but also the lepre of Naaman schal cleue to thee, and to thi seed withouten ende. And Giezi yede leprouse as snow, `fro hym.

< 2 Kings 5 >