< 2 Kings 5 >
1 Naamani jẹ́ olórí ogun ọba Aramu. Ó jẹ́ ènìyàn ńlá níwájú ọ̀gá rẹ̀, wọ́n sì bu ọlá fún un, nítorí nípasẹ̀ rẹ̀ ni Olúwa ti fi ìṣẹ́gun fún Aramu. Òun jẹ́ alágbára, akọni ọkùnrin ṣùgbọ́n, ó dẹ́tẹ̀.
Na'aman, Kongen af Arams Hærfører, havde meget at sige hos sin Herre og var højt agtet; thi ved ham havde HERREN givet Aramæerne Sejr; men Manden var spedalsk.
2 Nísinsin yìí ẹgbẹgbẹ́ láti Aramu ti jáde lọ láti mú ọmọ obìnrin kékeré kan ní ìgbèkùn láti Israẹli, ó sì sin ìyàwó Naamani.
Nu havde Aramæerne engang paa et Strejftog røvet en lille Pige i Israels Land; hun var kommet i Tjeneste hos Na'amans Hustru,
3 Ó sọ fún ọ̀gá rẹ̀ obìnrin pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ọ̀gá mi lè rí wòlíì tí ó wà ní Samaria! Yóò wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
og hun sagde til sin Frue: »Gid min Herre var hos Profeten i Samaria; han vilde sikkert skille ham af med hans Spedalskhed!«
4 Naamani lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ̀ ó sì wí fún un ohun tí ọmọbìnrin Israẹli ti sọ.
Saa kom Na'aman og fortalte sin Herre, hvad Pigen fra Israels Land havde sagt.
5 “Ní gbogbo ọ̀nà, lọ,” ọba Aramu dá a lóhùn pé, “Èmi yóò fi ìwé ránṣẹ́ sí ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni Naamani lọ, ó sì mú pẹ̀lú rẹ̀ tálẹ́ǹtì fàdákà mẹ́wàá, ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ìwọ̀n wúrà àti ìpààrọ̀ aṣọ mẹ́wàá.
Da sagde Arams Konge: »Rejs derhen! Jeg skal sende et Brev med til Israels Konge!« Saa rejste han og tog ti Talenter Sølv, 6000 Sekel Guld og ti Sæt Festklæder med.
6 Ìwé tí ó mú lọ sọ́dọ̀ ọba Israẹli kà pé, “Pẹ̀lú ìwé yìí èmi ń rán ìránṣẹ́ mi Naamani sí ọ pé o lè wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
Og han overbragte Israels Konge Brevet. Deri stod der: »Naar dette Brev kommer dig i Hænde, skal du vide, at jeg sender min Tjener Na'aman til dig, for at du skal skille ham af med hans Spedalskhed!«
7 Bí ọba Israẹli ti ka ìwé náà ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wí pé, “Èmi ha jẹ́ Ọlọ́run? Ǹjẹ́ èmi le pa kí n sì mú wá sí ààyè padà? Kí ni ó dé tí eléyìí rán ènìyàn sí mi láti wo ààrùn ẹ̀tẹ̀ rẹ sàn, kí ẹ wo bí ó ti ń wá ọ̀nà láti wá ìjà pẹ̀lú mi!”
Da Israels Konge havde læst Brevet, sønderrev han sine klæder og sagde: »Er jeg Gud, saa jeg raader over Liv og Død, siden han skriver til mig, at jeg skal skille en Mand af med hans Spedalskhed Nej, I kan da se, at han søger Lejlighed til Strid med mig!«
8 Nígbà tí Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run gbọ́ pé ọba Israẹli ti ya aṣọ rẹ̀, ó sì rán iṣẹ́ yìí sí i pé, “Kí ni ó dé tí o fi fa aṣọ rẹ ya? Jẹ́ kí ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi. Òun yóò sì mọ̀ pé wòlíì wà ní Israẹli.”
Men da den Guds Mand Elisa hørte, at Israels Konge havde sønderrevet sine klæder, sendte han det Bud til Kongen: »Hvorfor sønderriver du dine Klæder? Lad ham komme til mig, saa skal han kende, at der er en Profet i Israel!«
9 Bẹ́ẹ̀ ni Naamani sì lọ pẹ̀lú ẹṣin rẹ̀ àti kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Eliṣa.
Da kom Na'aman med Heste og Vogne og holdt uden for Døren til Elisas Hus.
10 Eliṣa rán ìránṣẹ́ láti lọ sọ fún un pé, “Lọ, wẹ̀ ara rẹ ní ìgbà méje ní odò Jordani, ẹran-ara rẹ yóò sì tún padà bọ̀ sípò, ìwọ yóò sì mọ́.”
Elisa sendte et Bud ud til ham og lod sige: »Gaa hen og bad dig syv Gange i Jordan, saa bliver dit Legeme atter friskt, og du bliver ren!«
11 Ṣùgbọ́n Naamani lọ pẹ̀lú ìbínú ó sì wí pé, “Mo lérò pé yóò sì dìde jáde wá nítòótọ́ sí mi, yóò sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run, fi ọwọ́ rẹ̀ lórí ibẹ̀ kí ó sì wo ẹ̀tẹ̀ mi sàn.
Men Na'aman blev vred og drog bort med de Ord: »Se, jeg havde tænkt, at han vilde komme ud til mig, staa og paakalde HERREN sin Guds Navn og svinge sin Haand i Retning af Helligdommen og saaledes gøre Ende paa Spedalskheden!
12 Abana àti Fapari, odò Damasku kò ha dára ju gbogbo omi Israẹli lọ? Ṣé èmi kò le wẹ̀ nínú wọn kí n sì mọ́?” Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà, ó sì lọ pẹ̀lú ìrunú.
Er ikke Damaskus's Floder Abana og Parpar fuldt saa gode som alle Israels Vande? Kunde jeg ikke blive ren ved at bade mig i dem?« Og han vendte sig og drog bort i Vrede.
13 Ìránṣẹ́ Naamani lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ó sì wí pé, “Baba mi, tí wòlíì bá ti sọ fún ọ láti ṣe ohun ńlá kan, ṣé ìwọ kì bá ti ṣe, mélòó mélòó nígbà náà, nígbà tí ó sọ fún ọ pé, ‘Wẹ̀ kí o sì mọ́’!”
Men hans Trælle kom og sagde til ham: »Dersom Profeten havde paalagt dig noget, som var vanskeligt vilde du saa ikke have gjort det? Hvor meget mere da nu, da han sagde til dig: Bad dig, saa bliver du ren!«
14 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ ó sì tẹ ara rẹ̀ bọ inú odò Jordani ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti sọ fún un, ẹran-ara rẹ̀ sì tún padà sí mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọkùnrin kékeré.
Saa drog han ned og dykkede sig syv Gange i Jordan efter den Guds Mands Ord; og hans Legeme blev atter friskt som et Barns, og han blev ren.
15 Nígbà náà Naamani àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ padà lọ sí ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run. Ó sì dúró níwájú rẹ̀ ó sì wí pé, “Nísinsin yìí èmi mọ̀ pé kò sí Ọlọ́run ní gbogbo àgbáyé àyàfi ní Israẹli nìkan. Jọ̀wọ́ gba ẹ̀bùn láti ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ.”
Saa vendte han med hele sit Følge tilbage til den Guds Mand, og da han var kommet derhen, traadte han frem for ham og sagde: »Nu ved jeg, at der ingensteds paa Jorden er nogen Gud uden i Israel! Saa modtag nu en Takkegave af din Træl!«
16 Wòlíì náà dáhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ẹni tí mo ń sìn, èmi kò nígbà ohun kan,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Naamani rọ̀ ọ́ láti gbà á, ó kọ̀.
Men han svarede: »Saa sandt HERREN lever, for hvis Aasyn jeg staar, jeg modtager ikke noget!« Og skønt han nødte ham, vægrede han sig ved at modtage noget.
17 Naamani wí pé, “Tí o kò bá nígbà, jọ̀wọ́ jẹ́ kí a fi fún èmi ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ ẹrù erùpẹ̀ tí ìbáaka méjì le rù, nítorí láti òní lọ ìránṣẹ́ rẹ kì yóò rú ẹbọ sísun àti rú ẹbọ sí ọ̀kan lára àwọn ọlọ́run mìíràn mọ́ bí kò ṣe sí Olúwa.
Da sagde Na'aman: »Saa lad da være! Men lad din Træl faa saa meget Jord, som et Par Muldyr kan bære, thi din Træl vil aldrig mere ofre Brændoffer eller Slagtoffer til nogen anden Gud end HERREN!
18 Ṣùgbọ́n kí Olúwa kí ó dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún nǹkan yìí. Nígbà tí ọ̀gá mi wọ inú ilé Rimoni láti fi orí balẹ̀ tí ó sì fi ara ti ọwọ́ mi tí mo sì tẹ ara mi ba pẹ̀lú níbẹ̀. Nígbà tí èmi tẹ ara mi ba ní ilé Rimoni, kí Olúwa dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún èyí.”
Men i een Ting vil HERREN nok bære over med din Træl: Naar min Herre gaar ind i Rimmons Hus for at tilbede og støtter sig til min Arm og jeg saa sammen med ham kaster mig til Jorden i Rimmons Hus, da vil HERREN nok bære over med din Træl i den Ting!«
19 Eliṣa wí pé, “Máa lọ ní àlàáfíà.” Lẹ́yìn ìgbà tí Naamani tí rin ìrìnàjò tí ó jìnnà,
Han svarede: »Far i Fred!« Men da han var kommet et Stykke hen ad Vejen,
20 Gehasi, ìránṣẹ́ Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run, ó wí fún ara rẹ̀ pé, “Ọ̀gá mi jẹ́ ẹni tí ó rọ́nú lórí Naamani, ará Aramu, nípa pé kò gba ohunkóhun ní ọwọ́ rẹ̀ ohun tí ó mú wá, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, èmi yóò sá tẹ̀lé e èmi yóò sì gba ohun kan ní ọwọ́ rẹ̀.”
sagde Gehazi, den Guds Mand Elisas Tjener, ved sig selv: »Der har min Herre ladet denne Aramæer Na'aman slippe og ikke modtaget af ham, hvad han havde med; saa sandt HERREN lever, jeg vil løbe efter ham for at faa noget af ham!«
21 Bẹ́ẹ̀ ni Gehasi sáré tẹ̀lé Naamani. Nígbà tí Naamani rí i tí ó ń sáré tẹ̀lé e, ó sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ̀. “Ṣé gbogbo nǹkan wà dáradára?” ó béèrè.
Saa satte Gehazi efter Na'aman, og da Na'aman saa ham komme løbende efter sig, sprang han af Vognen, gik ham i Møde og spurgte: »Staar det godt til?«
22 “Gbogbo nǹkan wà dáradára,” Gehasi dá a lóhùn. “Ọ̀gá mi rán mi láti sọ wí pé, ‘Àwọn ọ̀dọ́ ọmọkùnrin méjì láti ọ̀dọ̀ ọmọ wòlíì wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi láti orí òkè ìlú ti Efraimu. Jọ̀wọ́ fún wọn ní ẹ̀bùn fàdákà àti ìpààrọ̀ aṣọ méjì.’”
Han svarede: »Ja, det staar godt til! Min Herre sender mig med det Bud: Der kom lige nu to unge Mænd, som hører til Profetsønnerne, til mig fra Efraims Bjerge: giv dem en Talent Sølv og to Sæt Festklæder!«
23 Naamani wí pé, “Ní gbogbo ọ̀nà, mú ẹ̀bùn méjì.” Ó sì rọ Gehasi láti gbà wọ́n, ó sì di ẹ̀bùn méjì náà ti fàdákà ní inú àpò méjì, pẹ̀lú ìpààrọ̀ aṣọ méjì, ó sì fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ méjì, wọ́n sì kó wọn lọ sọ́dọ̀ Gehasi.
Da sagde Na'aman: »Tag dog mod to Talenter Sølv!« Og han nødte ham. Saa bandt han to Talenter ind i to Punge og tog to Sæt Festklæder og gav to af sine Trælle dem, for at de skulde bære dem foran ham.
24 Nígbà tí Gehasi sì dé ibi ilé ìṣọ́, ó gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn, ó sì tó wọ́n sínú ilé, ó sì jọ̀wọ́ àwọn ọkùnrin náà lọ́wọ́ lọ, wọ́n sì jáde lọ.
Men da de kom til Højen, tog han Pengene fra dem, gemte dem i Huset og lod Mændene gaa.
25 Nígbà náà ó sì wọlé wá ó sì dúró níwájú ọ̀gá rẹ̀ Eliṣa. “Níbo ni o ti wà Gehasi?” Eliṣa béèrè. “Ìránṣẹ́ rẹ kò lọ sí ibìkan kan.” Gehasi dá a lóhùn.
Saa gik han ind til sin Herre og traadte hen til ham. Da spurgte Elisa: »Hvor har du været, Gehazi?« Han svarede: »Din Træl har ingen Steder været!«
26 Ṣùgbọ́n Eliṣa wí fún un pé, “Ẹ̀mí mi kò ha wà pẹ̀lú rẹ nígbà tí ọkùnrin náà sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ? Ṣé àsìkò tí ó yẹ láti gba owó nìyìí, tàbí láti gba aṣọ, ọgbà olifi, ọgbà àjàrà, àgùntàn, màlúù tàbí ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin?
Saa sagde han til ham: »Gik jeg ikke i Aanden hos dig, da en stod af sin Vogn og gik tilbage for at møde dig? Nu har du faaet Penge, og du kan faa Klæder, Olivenlunde og Vingaarde, Smaakvæg og Hornkvæg, Trælle og Trælkvinder,
27 Ẹ̀tẹ̀ Naamani yóò lẹ̀ mọ́ ọ àti sí irú-ọmọ rẹ títí láé.” Nígbà náà Gehasi kúrò níwájú Eliṣa, ó sì di adẹ́tẹ̀, ó sì funfun gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ̀n òwú.
men Na'amans Spedalskhed skal hænge ved dig og dit Afkom til evig Tid!« Og Gehazi gik fra ham, hvid som Sne af Spedalskhed.