< 2 Kings 4 >

1 Ìyàwó ọkùnrin kan láti ara ẹgbẹ́ wòlíì sọkún tọ Eliṣa wá, “Ìránṣẹ́ rẹ ọkọ mi ti kú, ó sì mọ̀ wí pé ó bu ọlá fún Olúwa. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, onígbèsè rẹ̀ ti ń bọ̀ láti wá kó ọmọ ọkùnrin mi gẹ́gẹ́ bí ẹrú rẹ̀.”
Și o anumită femeie dintre soțiile fiilor profeților a strigat către Elisei, spunând: Servitorul tău, soțul meu, este mort; și tu știi că servitorul tău se temea de DOMNUL; și creditorul a venit să ia la el pe cei doi fii ai mei ca să fie robi.
2 Eliṣa dá a lóhùn pé, “Báwo ni èmi ṣe lè ràn ọ́ lọ́wọ́? Sọ fún mi; kí ni ìwọ ní ní ilé rẹ?” Ó wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ kò ní ohunkóhun níbẹ̀ rárá, àyàfi òróró kékeré.”
Și Elisei i-a zis: Ce să fac pentru tine? Spune-mi, ce ai în casă? Și ea a zis: Roaba ta nu are nimic în casă, decât o oală cu untdelemn.
3 Eliṣa wí pé, “Lọ yíká kí o sì béèrè lọ́wọ́ gbogbo àwọn aládùúgbò fún ìkòkò òfìfo. Má ṣe béèrè fún kékeré.
Atunci el a spus: Du-te, împrumută-ți vase de afară de la toți vecinii tăi, vase goale; împrumută nu puține.
4 Nígbà náà, lọ sí inú ilé kí o sì pa lẹ́kun dé ní ẹ̀gbẹ́ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin, dà òróró sínú gbogbo ìkòkò, gẹ́gẹ́ bí gbogbo rẹ̀ ti kún, kó o sí apá kan.”
Și după ce intri, să închizi ușa după tine și după fiii tăi și să torni în toate vasele acelea și să pui deoparte pe cele care sunt pline.
5 Ó sì fi sílẹ̀ lẹ́yìn náà ó ti ìlẹ̀kùn ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀. Wọ́n gbé ìkòkò wá fún un ó sì ń dà á.
Astfel ea a plecat de la el și a închis ușa după ea și după fiii ei, care îi aduceau vasele; și ea turna.
6 Nígbà tí gbogbo ìkòkò náà kún, ó sọ fún ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ gbé òmíràn fún mi wá.” Ṣùgbọ́n wọ́n dáhùn pé, “Kò sí ìkòkò tí ó kù mọ́.” Nígbà náà ni òróró kò dà mọ́.
Și s-a întâmplat, după ce vasele au fost pline, că ea a spus fiului său: Adu-mi încă un vas. Iar el i-a zis: Nu mai este niciun vas. Și untdelemnul s-a oprit.
7 Ó sì lọ ó sì lọ sọ fún àwọn ènìyàn Ọlọ́run, ó sì wí pé, “Lọ, ta òróró náà kí o sì san gbèsè rẹ. Ìwọ àti ọmọ rẹ kí ẹ máa sinmi lórí èyí tí ó kù.”
Atunci ea a venit și i-a spus omului lui Dumnezeu. Iar el a zis: Du-te, vinde untdelemnul și plătește datoria și trăiește tu și copiii tăi din restul.
8 Ní ọjọ́ kan Eliṣa lọ sí Ṣunemu. Obìnrin ọlọ́rọ̀ kan sì wà níbẹ̀, ẹni tí ó rọ̀ ọ́ kí ó dúró jẹun. Bẹ́ẹ̀ ni nígbàkígbà tí ó bá ń kọjá lọ, ó máa ń dúró níbẹ̀ láti jẹun.
Și s-a întâmplat într-o zi, că Elisei trecea pe la Sunem, unde era o femeie cu vază; și ea l-a constrâns să mănânce pâine. Și a fost astfel, că ori de câte ori el trecea, se abătea pe acolo să mănânce pâine.
9 Ó sọ fún ọkọ rẹ̀, “Mo mọ̀ pé ọkùnrin tí ó máa ń sábà wá sí ọ̀dọ̀ wa jẹ́ ọkùnrin mímọ́ Ọlọ́run.
Și ea a spus soțului ei: Iată acum, eu pricep că acesta este un om sfânt al lui Dumnezeu, care trece întotdeauna pe la noi.
10 Jẹ́ kí a ṣe yàrá kékeré kan sórí ilé kí a sì gbé ibùsùn àti tábìlì oúnjẹ, àga kan àti fìtílà fún un. Nígbà náà ó lè dúró níbẹ̀ ní ìgbàkúgbà tí ó bá wá sọ́dọ̀ wa.”
Te rog, să îi facem o cămăruță pe zid; și să îi punem acolo un pat și o masă și un scaun și un sfeșnic; și va fi, când vine la noi, că se va abate pe acolo.
11 Ní ọjọ́ kan nígbà tí Eliṣa wá, ó lọ sí orí òkè ní yàrá rẹ̀ ó sì dùbúlẹ̀ síbẹ̀.
Și s-a întâmplat într-o zi, că el a venit pe acolo și s-a abătut pe la cameră și s-a culcat acolo.
12 Ó sì wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Gehasi pé, “Pe ará Ṣunemu.” Bẹ́ẹ̀ ni ó sì pè é wá, ó sì dúró níwájú rẹ̀.
Și el i-a spus lui Ghehazi, servitorul său: Cheamă pe sunamita aceasta. Și după ce a chemat-o, ea a stat în picioare înaintea lui.
13 Eliṣa wí fún un pé, “Wí fún un, ‘Ìwọ ti lọ ṣe gbogbo àníyàn iṣẹ́ ìyìnrere fún wa. Nísinsin yìí kí ni a lè ṣe fún ọ?’” “Ṣé a lè jẹ́ agbẹnusọ fún ọ ní ọ̀dọ̀ ọba tàbí olórí ogun?”
Iar el i-a zis: Spune-i acum femeii: Iată, tu te-ai îngrijit de noi cu toată această grijă; ce este de făcut pentru tine? Dorești să se vorbească pentru tine împăratului sau căpeteniei oștirii? Iar ea a răspuns: Eu locuiesc în mijlocul poporului meu.
14 “Kí ni a lè ṣe fún obìnrin yìí?” Eliṣa béèrè. Gehasi wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, kò ní ọmọ, ọkọ rẹ̀ náà sì tún di arúgbó.”
Iar el a zis: Ce este de făcut atunci pentru ea? Și Ghehazi a răspuns: Cu adevărat ea nu are copil și soțul ei este bătrân.
15 Nígbà náà Eliṣa wí pé, “Pè é,” bẹ́ẹ̀ ni ó sì pè é, ó sì dúró ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà.
Iar el a spus: Cheam-o. Și după ce el a chemat-o, ea a stat în picioare la ușă.
16 Eliṣa sọ wí pé, “Ìwòyí ọdún tí ń bọ̀, ìwọ yóò fi ọwọ́ rẹ gbé ọmọ.” “Bẹ́ẹ̀ kọ́, olúwa mi!” n kò fi ara mọ́ ọn. “Jọ̀wọ́, ìwọ ènìyàn Ọlọ́run, ma ṣe ṣi ìránṣẹ́ rẹ lọ́nà!”
Și el a zis: Cam pe timpul acesta, conform cu timpul vieții, tu vei îmbrățișa un fiu. Și ea a spus: Nu, domnul meu, tu om al lui Dumnezeu, nu minții pe roaba ta.
17 Ṣùgbọ́n obìnrin náà lóyún ní ọdún kejì ní àkókò náà, ó bí ọmọ ọkùnrin kan, gẹ́gẹ́ bí Eliṣa ti sọ fún un.
Și femeia a rămas însărcinată și a născut un fiu la acel timp pe care i-l spusese Elisei, conform cu timpul vieții.
18 Ọmọ náà dàgbà, ní ọjọ́ kan, ó jáde lọ sí ọ̀dọ̀ baba rẹ̀, ó wà pẹ̀lú àwọn olùkórè.
Și când copilul a crescut, s-a întâmplat într-o zi, că a ieșit la tatăl său la secerători.
19 “Orí mi! Orí mi!” Ó wí fún baba rẹ̀. Baba rẹ̀ sọ fún ìránṣẹ́, “Gbé e lọ sọ́dọ̀ ìyá rẹ̀.”
Și el a spus tatălui său: Capul meu, capul meu. Iar el a zis unui tânăr: Du-l la mama lui.
20 Lẹ́yìn ìgbà tí ìránṣẹ́ náà ti gbé e sókè tí ó sì gbé e tọ ìyá rẹ̀ lọ, ọmọ ọkùnrin náà jókòó sórí ẹsẹ̀ rẹ̀ títí ó fi di ọ̀sán gangan, nígbà náà ó sì kú.
Și după ce l-a luat și l-a dus la mama lui, el a șezut pe genunchii ei până la amiază și apoi a murit.
21 Ó lọ sí òkè ó sì tẹ́ ọmọ náà lórí ibùsùn ènìyàn Ọlọ́run, ó sì tìlẹ̀kùn, ó jáde lọ.
Și ea s-a urcat și l-a culcat pe patul omului lui Dumnezeu și a închis ușa după el și a plecat.
22 Ó pe ọkọ rẹ̀ ó sì wí pé, “Jọ̀wọ́ rán ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ rẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan kí èmi kí ó lè lọ sí ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run kíákíá kí n sì padà.”
Și a chemat la ea pe soțul ei și a spus: Trimite-mi, te rog, pe unul dintre tineri și unul dintre măgari, ca să alerg la omul lui Dumnezeu și să mă întorc.
23 “Kí ni ó dé tí o fi fẹ́ lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ lónìí?” Ó béèrè. “Kì í ṣe oṣù tuntun tàbí ọjọ́ ìsinmi.” Ó wí pé, “Gbogbo rẹ̀ ti dára.”
Și el a spus: Pentru ce dorești să te duci la el astăzi? Nu este nici lună nouă, nici sabat. Și ea a zis: Va fi bine.
24 Ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì ó sì wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Máa nìṣó; má ṣe dẹ́sẹ̀ dúró dè mí àyàfi tí mo bá sọ fún ọ.”
Atunci a înșeuat un măgar și a spus servitorului ei: Mână și mergi înainte; să nu încetinești din călărit pentru mine, doar dacă îți poruncesc.
25 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì jáde wá, ó sì wá sọ́dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run ní orí òkè Karmeli. Nígbà tí ó sì rí i láti òkèrè, ènìyàn Ọlọ́run sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Gehasi, “Wò ó! Ará Ṣunemu nì!
Astfel, ea a mers și a ajuns la omul lui Dumnezeu la muntele Carmel. Și s-a întâmplat, când omul lui Dumnezeu a văzut-o de departe, că i-a zis lui Ghehazi, servitorul său: Iat-o pe sunamita aceea;
26 Sáré lọ pàdé rẹ̀ kí o sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, ‘Ṣé o wà dáradára? Ṣé ọkọ rẹ wà dáradára? Ṣé ọmọ rẹ wà dáradára?’” Ó wí pé, “Gbogbo nǹkan wà dáradára.”
Aleargă acum, te rog, să o întâlnești și spune-i: Ești bine? Este bine soțul tău? Este bine copilul? Iar ea a răspuns: Este bine.
27 Nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run ní orí òkè, ó gbá a ní ẹsẹ̀ mú. Gehasi wá láti wá lé e dànù, ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run wí pé, “Fi í sílẹ̀! Ó wà nínú ìpọ́njú kíkorò, ṣùgbọ́n Olúwa fi pamọ́ fún mi kò sì sọ ìdí rẹ̀ fún mi.”
Și când ea a venit la omul lui Dumnezeu pe deal, l-a prins de picioare; dar Ghehazi s-a apropiat să o împingă. Și omul lui Dumnezeu a spus: Las-o, pentru că sufletul ei este chinuit în ea; și DOMNUL a ascuns aceasta de la mine și nu mi-a zis.
28 “Ṣé mo béèrè ọmọ lọ́wọ́ rẹ, olúwa mi?” Obìnrin náà wí pé, “Ṣé mi ò sọ fún ọ pé kí o, ‘Má ṣe fa ìrètí mi sókè’?”
Atunci ea a spus: Am dorit eu un fiu de la domnul meu? Nu am zis eu: Nu mă înșela?
29 Eliṣa wí fún Gehasi pé, “Ká agbádá rẹ sínú ọ̀já àmùrè, mú ọ̀pá mi sí ọwọ́ rẹ kí o sì sáré. Tí o bá pàdé ẹnikẹ́ni má ṣe kí i, tí ẹnikẹ́ni bá kí ọ, má ṣe dá a lóhùn, fi ọ̀pá náà lé ojú ọmọ ọkùnrin náà.”
Atunci el i-a spus lui Ghehazi: Încinge-ți coapsele și ia toiagul meu în mâna ta și mergi pe calea ta; dacă întâlnești vreun om, să nu îl saluți; și dacă cineva te va saluta, să nu îi răspunzi; și pune toiagul meu pe fața copilului.
30 Ṣùgbọ́n ìyá ọmọ náà wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè àti gẹ́gẹ́ bí ó ti wà láààyè, èmi kò ní í fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni ó sì dìde ó sì tẹ̀lé e.
Și mama copilului a spus: Precum DOMNUL trăiește și precum sufletul tău trăiește, nu te voi părăsi. Și el s-a ridicat și a urmat-o.
31 Gehasi sì ń lọ síbẹ̀ ó sì fi ọ̀pá náà lé ojú ọmọ náà, ṣùgbọ́n kò sí ohùn tàbí ìdáhùn. Bẹ́ẹ̀ ni Gehasi padà lọ láti lọ bá Eliṣa láti sọ fún un pé, “Ọmọ ọkùnrin náà kò tí ì dìde.”
Și Ghehazi a trecut înaintea lor și a pus toiagul pe fața copilului; dar nu a fost nici voce, nici auzire. Pentru aceea el a mers să îl întâlnească și i-a spus, zicând: Copilul nu s-a trezit.
32 Nígbà tí Eliṣa dé inú ilé, níbẹ̀ ni òkú ọmọ ọkùnrin náà dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn.
Și când Elisei a intrat în casă, iată, copilul era mort și întins pe patul său.
33 Ó sì wọ ilé, ó sì ti ìlẹ̀kùn mọ́ àwọn méjèèjì ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
Și de aceea a intrat și a închis ușa după ei amândoi și s-a rugat DOMNULUI.
34 Nígbà náà ó dé orí ibùsùn, ó sùn sórí ọmọ ọkùnrin náà, ẹnu sí ẹnu, ojú sí ojú, ọwọ́ sí ọwọ́. Gẹ́gẹ́ bí ó ti nà ara rẹ̀ lórí rẹ̀, ara ọmọ náà sì gbóná.
Și s-a urcat și s-a culcat peste copil și și-a pus gura pe gura lui și ochii lui pe ochii lui și mâinile lui pe mâinile lui; și s-a întins peste copil; și carnea copilului s-a încălzit.
35 Eliṣa yípadà lọ, ó sì rìn padà ó sì jáde wá sínú ilé nígbà náà ó sì padà sí orí ibùsùn ó sì tún nà lé e ní ẹ̀ẹ̀kan sí i. Ọmọ ọkùnrin náà sì sín ní ìgbà méje ó sì ṣí ojú rẹ̀.
Atunci s-a întors și a umblat prin casă încoace și încolo; și s-a urcat și s-a întins peste el; și copilul a strănutat de șapte ori și copilul și-a deschis ochii.
36 Eliṣa sì pe Gehasi ó sì wí pé, “Pe ará Ṣunemu.” Ó sì ṣe bẹ́ẹ̀. Nígbà tí ó dé, ó wí pé, “Gba ọmọ rẹ.”
Și el l-a chemat pe Ghehazi și a spus: Cheam-o pe sunamita aceasta. Astfel, el a chemat-o. Și după ce ea a venit la el, el a zis: Ridică-ți fiul.
37 Ó sì wọlé, ó sì kúnlẹ̀ síwájú ẹsẹ̀ rẹ̀ ó sì tẹ̀ orí sílẹ̀. Nígbà náà ó sì mú ọmọ rẹ̀ ó sì jáde lọ.
Atunci ea a intrat și a căzut la picioarele lui și s-a plecat până la pământ și și-a ridicat fiul și a ieșit.
38 Eliṣa padà sí Gilgali ìyàn sì wà ní ilẹ̀ náà. Nígbà tí àwọn ọmọ wòlíì ṣe ìpàdé pẹ̀lú rẹ̀, ó sì wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Gbé ìkòkò ńlá ka iná kí o sì se ọbẹ̀ aláta díẹ̀ fún àwọn ọkùnrin yìí.”
Și Elisei s-a întors la Ghilgal; și era foamete în țară; și fiii profeților ședeau înaintea lui; și el a spus servitorului său: Pune oala cea mare și fierbe supă pentru fiii profeților.
39 Ọ̀kan lára wọn jáde lọ sí orí pápá láti kó ewébẹ̀ jọ àti láti wá àjàrà igbó. Ó sì kó díẹ̀ nínú ẹ̀fọ́ gbọ̀rọ̀ rẹ̀ jọ, ó sì ka a kún aṣọ agbádá rẹ̀. Nígbà tí ó padà dé, ó sì gé wọn sínú ìkòkò ọbẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kò sí ẹni tí ó mọ ohun tí wọ́n ń jẹ.
Și unul a ieșit la câmp să adune ierburi și a găsit o viță sălbatică și a strâns de pe ea o poală plină de curcubete sălbatice și a venit și le-a tăiat în oala de supă, pentru că nu le cunoșteau.
40 Wọ́n da ọbẹ̀ náà jáde fun àwọn ọkùnrin náà, ṣùgbọ́n bí wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ oúnjẹ náà, wọ́n sọkún jáde, “Ìwọ ènìyàn Ọlọ́run ikú ń bẹ nínú ìkòkò yìí!” Wọn kò sì le jẹ ẹ́.
Astfel, ei au turnat oamenilor să mănânce. Și s-a întâmplat, pe când mâncau din supă, că au strigat și au spus: O tu om al lui Dumnezeu, este moarte în oală. Și nu puteau să mănânce din ea.
41 Eliṣa sì wí pé, “Mú ìyẹ̀fun díẹ̀ wá,” Ó sì fi sínú ìkòkò ó sì wí pé, “Kí ó sì fi fún àwọn ènìyàn láti jẹ.” Kò sì sí ohun tí ó léwu nínú ìkòkò náà.
Dar el a spus: Atunci aduceți făină. Și a aruncat-o în oală și a zis: Turnați pentru popor, ca să mănânce. Și nu era nimic vătămător în oală.
42 Ọkùnrin kan wá láti Baali-Ṣaliṣa, ó sì mú àkàrà àkọ́so èso, ogún ìṣù àkàrà barle, tí wọ́n dín láti ara àkọ́so èso àgbàdo, àti pẹ̀lú síírí ọkà tuntun nínú àpò rẹ̀ wá fún ènìyàn Ọlọ́run náà. Òun sì wí pé, “Fún àwọn ènìyàn láti jẹ.”
Și a venit un om de la Baal-Șalișa și a adus omului lui Dumnezeu pâine din cele dintâi roade, douăzeci de pâini de orz și spice proaspete de grâne nebătute. Și a spus: Dă poporului, să mănânce.
43 “Báwo ni èmi yóò ṣe gbé èyí ka iwájú àwọn ọgọ́rùn-ún ènìyàn?” ìránṣẹ́ rẹ̀ béèrè. Ṣùgbọ́n Eliṣa dá a lóhùn pé, “Gbé e fún àwọn ènìyàn láti jẹ, nítorí èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Wọn yóò jẹ yóò sì tún ṣẹ́kù.’”
Și servitorul său a spus: Ce, să pun aceasta înaintea a o sută de oameni? El a zis din nou: Dă poporului, să mănânce, fiindcă astfel spune DOMNUL: Ei vor mânca și va rămâne din aceasta.
44 Nígbà náà ó gbé e ka iwájú wọn, wọ́n sì jẹ ẹ́, wọ́n sì ní èyí tó ṣẹ́kù, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
Astfel el a pus înaintea lor și ei au mâncat și au lăsat o parte, conform cuvântului DOMNULUI.

< 2 Kings 4 >