< 2 Kings 4 >

1 Ìyàwó ọkùnrin kan láti ara ẹgbẹ́ wòlíì sọkún tọ Eliṣa wá, “Ìránṣẹ́ rẹ ọkọ mi ti kú, ó sì mọ̀ wí pé ó bu ọlá fún Olúwa. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, onígbèsè rẹ̀ ti ń bọ̀ láti wá kó ọmọ ọkùnrin mi gẹ́gẹ́ bí ẹrú rẹ̀.”
Na rĩrĩ, mũtumia wa mũndũ ũmwe wa thiritũ ya anabii agĩkaĩra Elisha, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ndungata yaku, mũthuuri wakwa, nĩakuĩte, na wee nĩũũĩ atĩ araarĩ mwĩtigĩri Jehova. No rĩrĩ, mũndũ ũrĩa araarĩ na thiirĩ wake nĩarooka kũiyĩra tũmwana twakwa tweerĩ tũtuĩke ngombo ciake.”
2 Eliṣa dá a lóhùn pé, “Báwo ni èmi ṣe lè ràn ọ́ lọ́wọ́? Sọ fún mi; kí ni ìwọ ní ní ilé rẹ?” Ó wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ kò ní ohunkóhun níbẹ̀ rárá, àyàfi òróró kékeré.”
Elisha akĩmũũria atĩrĩ, “Ingĩhota gũgũteithia atĩa? Ta njĩĩra atĩrĩ, nĩ kĩĩ ũrĩ nakĩo nyũmba gwaku?” Nake akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ndungata yaku ndĩrĩ na kĩndũ o nakĩ, tiga o tũguta tũnini.”
3 Eliṣa wí pé, “Lọ yíká kí o sì béèrè lọ́wọ́ gbogbo àwọn aládùúgbò fún ìkòkò òfìfo. Má ṣe béèrè fún kékeré.
Elisha akiuga atĩrĩ, “Thiĩ kũrĩ andũ a itũũra rĩaku othe ũhooe ndigithũ itarĩ kĩndũ. Ũhooe ndigithũ nyingĩ.
4 Nígbà náà, lọ sí inú ilé kí o sì pa lẹ́kun dé ní ẹ̀gbẹ́ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin, dà òróró sínú gbogbo ìkòkò, gẹ́gẹ́ bí gbogbo rẹ̀ ti kún, kó o sí apá kan.”
Ũcooke ũtoonye nyũmba yaku thĩinĩ hamwe na ariũ aku, na ũhinge mũrango. Ũitĩrĩre maguta ndigithũ-inĩ icio ciothe, na o ĩrĩa yaiyũra ũkamĩiga mwena-inĩ.”
5 Ó sì fi sílẹ̀ lẹ́yìn náà ó ti ìlẹ̀kùn ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀. Wọ́n gbé ìkòkò wá fún un ó sì ń dà á.
Nake akĩmũtiga, na thuutha ũcio mũtumia ũcio akĩĩhingĩra nyũmba hamwe na ariũ ake. Nao makamũrehagĩra ndigithũ, nake agĩthiĩ na mbere gũitĩrĩra maguta.
6 Nígbà tí gbogbo ìkòkò náà kún, ó sọ fún ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ gbé òmíràn fún mi wá.” Ṣùgbọ́n wọ́n dáhùn pé, “Kò sí ìkòkò tí ó kù mọ́.” Nígbà náà ni òróró kò dà mọ́.
Rĩrĩa ndigithũ ciothe ciaiyũrire, akĩĩra mũriũ atĩrĩ, “Ndehere ndigithũ ĩngĩ.” No mũriũ akĩmũcookeria atĩrĩ, “Hatirĩ ndigithũ ĩngĩ ĩtigarĩte.” Namo maguta magĩthira.
7 Ó sì lọ ó sì lọ sọ fún àwọn ènìyàn Ọlọ́run, ó sì wí pé, “Lọ, ta òróró náà kí o sì san gbèsè rẹ. Ìwọ àti ọmọ rẹ kí ẹ máa sinmi lórí èyí tí ó kù.”
Agĩthiĩ akĩĩra mũndũ wa Ngai ũhoro ũcio, nake akĩmwĩra atĩrĩ, “Thiĩ wendie maguta ũrĩhe mathiirĩ maku. We na ariũ aku-rĩ, mũtũũrio nĩ kĩrĩa gĩgũtigara.”
8 Ní ọjọ́ kan Eliṣa lọ sí Ṣunemu. Obìnrin ọlọ́rọ̀ kan sì wà níbẹ̀, ẹni tí ó rọ̀ ọ́ kí ó dúró jẹun. Bẹ́ẹ̀ ni nígbàkígbà tí ó bá ń kọjá lọ, ó máa ń dúró níbẹ̀ láti jẹun.
Na rĩrĩ, mũthenya ũmwe Elisha agĩthiĩ Shunemu, na kũu nĩ kwarĩ na mũtumia warĩ mũtongu, ũrĩa wamũringĩrĩirie mathiĩ gwake akarĩe irio. Nĩ ũndũ ũcio rĩrĩa rĩothe aahĩtũkagĩra hau nĩatoonyaga kuo akarĩa irio.
9 Ó sọ fún ọkọ rẹ̀, “Mo mọ̀ pé ọkùnrin tí ó máa ń sábà wá sí ọ̀dọ̀ wa jẹ́ ọkùnrin mímọ́ Ọlọ́run.
Mũtumia ũcio akĩĩra mũthuuriwe atĩrĩ, “Nĩnjũũĩ atĩ mũndũ ũyũ ũhĩtũkagĩra gũkũ gwitũ kaingĩ nĩ mũndũ mũtheru wa Ngai.
10 Jẹ́ kí a ṣe yàrá kékeré kan sórí ilé kí a sì gbé ibùsùn àti tábìlì oúnjẹ, àga kan àti fìtílà fún un. Nígbà náà ó lè dúró níbẹ̀ ní ìgbàkúgbà tí ó bá wá sọ́dọ̀ wa.”
Reke twake kanyũmba kanini nyũmba-igũrũ na tũige gĩtanda, na metha, na gĩtĩ, na tawa nĩ ũndũ wake. Nĩgeetha aikarage ho rĩrĩa ooka gũkũ gwitũ.”
11 Ní ọjọ́ kan nígbà tí Eliṣa wá, ó lọ sí orí òkè ní yàrá rẹ̀ ó sì dùbúlẹ̀ síbẹ̀.
Mũthenya ũmwe rĩrĩa Elisha ookire-rĩ, akĩambata kanyũmba-inĩ gake na agĩkoma kuo.
12 Ó sì wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Gehasi pé, “Pe ará Ṣunemu.” Bẹ́ẹ̀ ni ó sì pè é wá, ó sì dúró níwájú rẹ̀.
Akĩĩra Gehazi ndungata yake atĩrĩ, “Ĩta mũtumia ũcio Mũshunami.” Nĩ ũndũ ũcio akĩmwĩta nake akĩrũgama mbere yake.
13 Eliṣa wí fún un pé, “Wí fún un, ‘Ìwọ ti lọ ṣe gbogbo àníyàn iṣẹ́ ìyìnrere fún wa. Nísinsin yìí kí ni a lè ṣe fún ọ?’” “Ṣé a lè jẹ́ agbẹnusọ fún ọ ní ọ̀dọ̀ ọba tàbí olórí ogun?”
Elisha akĩmwĩra atĩrĩ, “Ĩra mũtumia ũcio atĩrĩ, ‘Nĩwĩthĩnĩtie mũno nĩ ũndũ witũ. Na rĩrĩ, ũngĩenda gwĩkĩrwo atĩa? No tũkwarĩrĩrie harĩ mũthamaki kana harĩ mũnene wa mbũtũ ya ita?’” Nake agĩcookia atĩrĩ, “Niĩ ndirĩ na thĩĩna, ndũũranagia na andũ aitũ.”
14 “Kí ni a lè ṣe fún obìnrin yìí?” Eliṣa béèrè. Gehasi wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, kò ní ọmọ, ọkọ rẹ̀ náà sì tún di arúgbó.”
Ningĩ Elisha akĩũria Gehazi atĩrĩ, “Mũtumia ũyũ angĩĩkĩrwo atĩa?” Gehazi akiuga atĩrĩ, “Ndarĩ mwana wa kahĩĩ, na mũthuuriwe nĩ mũkũrũ.”
15 Nígbà náà Eliṣa wí pé, “Pè é,” bẹ́ẹ̀ ni ó sì pè é, ó sì dúró ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà.
Hĩndĩ ĩyo Elisha akiuga atĩrĩ, “Mwĩte.” Nĩ ũndũ ũcio Gehazi akĩmwĩta, nake mũtumia ũcio akĩrũgama mũromo-inĩ.
16 Eliṣa sọ wí pé, “Ìwòyí ọdún tí ń bọ̀, ìwọ yóò fi ọwọ́ rẹ gbé ọmọ.” “Bẹ́ẹ̀ kọ́, olúwa mi!” n kò fi ara mọ́ ọn. “Jọ̀wọ́, ìwọ ènìyàn Ọlọ́run, ma ṣe ṣi ìránṣẹ́ rẹ lọ́nà!”
Nake Elisha akĩmwĩra atĩrĩ, “Ihinda ta rĩĩrĩ mwaka ũyũ ũgũũka-rĩ, nĩũkanyiita mwana waku wa kahĩĩ na moko maku.” Nake akĩrega, akiuga atĩrĩ, “Aca, mwathi wakwa, tiga kũheenia ndungata yaku, wee mũndũ wa Ngai!”
17 Ṣùgbọ́n obìnrin náà lóyún ní ọdún kejì ní àkókò náà, ó bí ọmọ ọkùnrin kan, gẹ́gẹ́ bí Eliṣa ti sọ fún un.
No rĩrĩ, mũtumia ũcio akĩgĩa nda, na mwaka ũcio ũngĩ ihinda o ta rĩu agĩciara kahĩĩ, o ta ũrĩa Elisha aamwĩrĩte.
18 Ọmọ náà dàgbà, ní ọjọ́ kan, ó jáde lọ sí ọ̀dọ̀ baba rẹ̀, ó wà pẹ̀lú àwọn olùkórè.
Mwana ũcio agĩkũra, na mũthenya ũmwe akiumagara, agĩthiĩ kũrĩ ithe, ũrĩa warĩ hamwe na agethi.
19 “Orí mi! Orí mi!” Ó wí fún baba rẹ̀. Baba rẹ̀ sọ fún ìránṣẹ́, “Gbé e lọ sọ́dọ̀ ìyá rẹ̀.”
Nake akĩĩra ithe atĩrĩ, “Wũi mũtwe-ĩ! Wũi mũtwe-ĩ!” Nake ithe akĩĩra ndungata atĩrĩ, “Mũkuue ũmũtwarĩre nyina.”
20 Lẹ́yìn ìgbà tí ìránṣẹ́ náà ti gbé e sókè tí ó sì gbé e tọ ìyá rẹ̀ lọ, ọmọ ọkùnrin náà jókòó sórí ẹsẹ̀ rẹ̀ títí ó fi di ọ̀sán gangan, nígbà náà ó sì kú.
Na thuutha wa ndungata kũmũkuua na kũmũtwarĩra nyina-rĩ, mwana ũcio agĩikara magũrũ-inĩ ma nyina nginya mĩaraho, agĩcooka agĩkua.
21 Ó lọ sí òkè ó sì tẹ́ ọmọ náà lórí ibùsùn ènìyàn Ọlọ́run, ó sì tìlẹ̀kùn, ó jáde lọ.
Nyina agĩthiĩ, akĩmũkomia ũrĩrĩ-inĩ wa mũndũ wa Ngai, agĩcooka akĩhinga mũrango, agĩthiĩ.
22 Ó pe ọkọ rẹ̀ ó sì wí pé, “Jọ̀wọ́ rán ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ rẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan kí èmi kí ó lè lọ sí ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run kíákíá kí n sì padà.”
Nake agĩĩta mũthuuriwe, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ndagũthaitha ũndũmĩre ndungata ĩmwe na ndigiri, nĩguo thiĩ kũrĩ mũndũ wa Ngai na ihenya na njooke.”
23 “Kí ni ó dé tí o fi fẹ́ lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ lónìí?” Ó béèrè. “Kì í ṣe oṣù tuntun tàbí ọjọ́ ìsinmi.” Ó wí pé, “Gbogbo rẹ̀ ti dára.”
Nake akĩmũũria atĩrĩ, “Ũgũthiĩ kũrĩ we ũmũthĩ nĩkĩ, na ti Karũgamo ka Mweri kana Thabatũ?” Nake akiuga atĩrĩ, “Hatirĩ na thĩĩna.”
24 Ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì ó sì wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Máa nìṣó; má ṣe dẹ́sẹ̀ dúró dè mí àyàfi tí mo bá sọ fún ọ.”
Agĩtandĩka ndigiri, na akĩĩra ndungata yake atĩrĩ, “Tengʼeria ndigiri, na ndũgaathiĩ kahora tiga ngwĩrire.”
25 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì jáde wá, ó sì wá sọ́dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run ní orí òkè Karmeli. Nígbà tí ó sì rí i láti òkèrè, ènìyàn Ọlọ́run sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Gehasi, “Wò ó! Ará Ṣunemu nì!
Nĩ ũndũ ũcio akĩambĩrĩria rũgendo, agĩkinya kũrĩ mũndũ wa Ngai Kĩrĩma-inĩ gĩa Karimeli. Nake mũndũ wa Ngai rĩrĩa aamuonire arĩ o haraihu akĩĩra ndungata yake Gehazi atĩrĩ, “Ta cũthĩrĩria! Ũũrĩa nĩ mũtumia ũrĩa Mũshunami!
26 Sáré lọ pàdé rẹ̀ kí o sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, ‘Ṣé o wà dáradára? Ṣé ọkọ rẹ wà dáradára? Ṣé ọmọ rẹ wà dáradára?’” Ó wí pé, “Gbogbo nǹkan wà dáradára.”
Hanyũka ũmũtũnge na ũmũũrie atĩrĩ, ‘Wee ũrĩ mwega? Ĩ mũthuuri waku no mwega? Mwana waku no mwega?’” Nake mũtumia ũcio akĩmũcookeria atĩrĩ, “Maũndũ mothe nĩ mega.”
27 Nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run ní orí òkè, ó gbá a ní ẹsẹ̀ mú. Gehasi wá láti wá lé e dànù, ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run wí pé, “Fi í sílẹ̀! Ó wà nínú ìpọ́njú kíkorò, ṣùgbọ́n Olúwa fi pamọ́ fún mi kò sì sọ ìdí rẹ̀ fún mi.”
Mũtumia ũcio aakinya harĩ mũndũ wa Ngai kĩrĩma-inĩ, akĩmũnyiita magũrũ. Nake Gehazi agĩũka kũmweheria, no mũndũ wa Ngai akĩmwĩra atĩrĩ, “Tigana nake! Arĩ na ruo rũnene mũno ngoro, no Jehova nĩahithĩte ũhoro ũyũ akaaga kũũmenyithia gĩtũmi kĩa guo.”
28 “Ṣé mo béèrè ọmọ lọ́wọ́ rẹ, olúwa mi?” Obìnrin náà wí pé, “Ṣé mi ò sọ fún ọ pé kí o, ‘Má ṣe fa ìrètí mi sókè’?”
Nake mũtumia ũcio akĩmũũria atĩrĩ, “Wee mwathi wakwa, nĩndakũũrĩtie ũhe kahĩĩ? Githĩ ndiakwĩrire, ‘Ndũkarahũre mwĩhoko wakwa’?”
29 Eliṣa wí fún Gehasi pé, “Ká agbádá rẹ sínú ọ̀já àmùrè, mú ọ̀pá mi sí ọwọ́ rẹ kí o sì sáré. Tí o bá pàdé ẹnikẹ́ni má ṣe kí i, tí ẹnikẹ́ni bá kí ọ, má ṣe dá a lóhùn, fi ọ̀pá náà lé ojú ọmọ ọkùnrin náà.”
Nake Elisha akĩĩra Gehazi atĩrĩ, “Wĩohe mũcibi njohero na ũkuue rũthanju rwakwa na guoko, ũhanyũke. Ũngĩcemania na mũndũ o wothe ndũkamũgeithie, na mũndũ o wothe angĩkũgeithia ndũkamũcookerie. Ũthiĩ ũigĩrĩre rũthanju rwakwa ũthiũ-inĩ wa kamwana kau.”
30 Ṣùgbọ́n ìyá ọmọ náà wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè àti gẹ́gẹ́ bí ó ti wà láààyè, èmi kò ní í fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni ó sì dìde ó sì tẹ̀lé e.
Nowe nyina wa mwana akiuga atĩrĩ, “Ti-itherũ o ta ũrĩa Jehova atũũraga muoyo, na o ta ũrĩa wee ũtũũraga muoyo-rĩ, niĩ ndigũgũtiga.” Nĩ ũndũ ũcio Elisha agĩũkĩra, akĩmũrũmĩrĩra.
31 Gehasi sì ń lọ síbẹ̀ ó sì fi ọ̀pá náà lé ojú ọmọ náà, ṣùgbọ́n kò sí ohùn tàbí ìdáhùn. Bẹ́ẹ̀ ni Gehasi padà lọ láti lọ bá Eliṣa láti sọ fún un pé, “Ọmọ ọkùnrin náà kò tí ì dìde.”
Na rĩrĩ, Gehazi agĩthiĩ arĩ mbere yao, akĩigĩrĩra rũthanju ũthiũ-inĩ wa kahĩĩ kau, no gatiagambire kana kwĩnyagunyia. Nĩ ũndũ ũcio Gehazi akĩhũndũka agatũnge Elisha, na akĩmwĩra atĩrĩ, “Kamwana gatiinokĩra.”
32 Nígbà tí Eliṣa dé inú ilé, níbẹ̀ ni òkú ọmọ ọkùnrin náà dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn.
Rĩrĩa Elisha aakinyire nyũmba, agĩkora kamwana gakomete gĩtanda-inĩ gĩake karĩ gakuũ.
33 Ó sì wọ ilé, ó sì ti ìlẹ̀kùn mọ́ àwọn méjèèjì ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
Nake agĩtoonya thĩinĩ, akĩĩhingĩra na mũrango marĩ o eerĩ nako, akĩhooya Jehova.
34 Nígbà náà ó dé orí ibùsùn, ó sùn sórí ọmọ ọkùnrin náà, ẹnu sí ẹnu, ojú sí ojú, ọwọ́ sí ọwọ́. Gẹ́gẹ́ bí ó ti nà ara rẹ̀ lórí rẹ̀, ara ọmọ náà sì gbóná.
Ningĩ akĩhaica ũrĩrĩ, agĩkomera kamwana kau, kanua gwa kanua, maitho kwa maitho, na moko kwa moko. Na rĩrĩa eetambũrũkĩtie igũrũ rĩako, mwĩrĩ wa kamwana kau ũkĩgĩa ũrugarĩ.
35 Eliṣa yípadà lọ, ó sì rìn padà ó sì jáde wá sínú ilé nígbà náà ó sì padà sí orí ibùsùn ó sì tún nà lé e ní ẹ̀ẹ̀kan sí i. Ọmọ ọkùnrin náà sì sín ní ìgbà méje ó sì ṣí ojú rẹ̀.
Nake Elisha agĩũkĩra, akĩehera, akĩũrũũranga kanyũmba thĩinĩ, agĩcooka gĩtanda-inĩ, agĩĩtambũrũkia rĩngĩ igũrũ rĩako. Kamwana kau gagĩathimũra maita mũgwanja, na gakĩhingũra maitho.
36 Eliṣa sì pe Gehasi ó sì wí pé, “Pe ará Ṣunemu.” Ó sì ṣe bẹ́ẹ̀. Nígbà tí ó dé, ó wí pé, “Gba ọmọ rẹ.”
Nake Elisha agĩĩta Gehazi, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ĩta mũtumia ũcio Mũshunami.” Nake akĩmwĩta. Rĩrĩa mũtumia ookire-rĩ, Elisha akĩmwĩra atĩrĩ, “Oya mũrũguo.”
37 Ó sì wọlé, ó sì kúnlẹ̀ síwájú ẹsẹ̀ rẹ̀ ó sì tẹ̀ orí sílẹ̀. Nígbà náà ó sì mú ọmọ rẹ̀ ó sì jáde lọ.
Nake agĩtoonya, akĩĩgũithia thĩ magũrũ-inĩ make, akĩinamia ũthiũ thĩ. Agĩcooka akĩoya mwana wake, akiuma.
38 Eliṣa padà sí Gilgali ìyàn sì wà ní ilẹ̀ náà. Nígbà tí àwọn ọmọ wòlíì ṣe ìpàdé pẹ̀lú rẹ̀, ó sì wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Gbé ìkòkò ńlá ka iná kí o sì se ọbẹ̀ aláta díẹ̀ fún àwọn ọkùnrin yìí.”
Nake Elisha agĩcooka Giligali, nakuo kũu bũrũri-inĩ ũcio nĩ kwarĩ na ngʼaragu. Rĩrĩa thiritũ ya anabii yacemanagia nake, akĩĩra ndungata yake atĩrĩ, “Hagĩra nyũngũ nene ũrugĩre andũ aya irio.”
39 Ọ̀kan lára wọn jáde lọ sí orí pápá láti kó ewébẹ̀ jọ àti láti wá àjàrà igbó. Ó sì kó díẹ̀ nínú ẹ̀fọ́ gbọ̀rọ̀ rẹ̀ jọ, ó sì ka a kún aṣọ agbádá rẹ̀. Nígbà tí ó padà dé, ó sì gé wọn sínú ìkòkò ọbẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kò sí ẹni tí ó mọ ohun tí wọ́n ń jẹ.
Hĩndĩ ĩyo ũmwe wa anabii agĩthiĩ mũgũnda gwetha nyeni, agĩkora rũũngũ rwa gĩthaka. Agĩtua maciaro maruo, akĩmaiyũria ruuno-inĩ rwa nguo yake ya igũrũ. Acooka akĩmatinangĩria nyũngũ-inĩ ĩyo yarugaga irio, o na gũtuĩka gũtirĩ mũndũ wamenyire ciarĩ kĩĩ.
40 Wọ́n da ọbẹ̀ náà jáde fun àwọn ọkùnrin náà, ṣùgbọ́n bí wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ oúnjẹ náà, wọ́n sọkún jáde, “Ìwọ ènìyàn Ọlọ́run ikú ń bẹ nínú ìkòkò yìí!” Wọn kò sì le jẹ ẹ́.
Andũ acio makĩihũrĩrwo irio icio, no rĩrĩa maambĩrĩirie gũcirĩa-rĩ, magĩkaya makiuga atĩrĩ, “Wũi mũndũ wa Ngai, nyũngũ-inĩ ĩno he na gĩkuũ!” Nao makĩremwo nĩ gũcirĩa.
41 Eliṣa sì wí pé, “Mú ìyẹ̀fun díẹ̀ wá,” Ó sì fi sínú ìkòkò ó sì wí pé, “Kí ó sì fi fún àwọn ènìyàn láti jẹ.” Kò sì sí ohun tí ó léwu nínú ìkòkò náà.
Nake Elisha akiuga atĩrĩ, “Rehei mũtu.” Nake akĩwĩkĩra nyũngũ-inĩ ĩyo, akiuga atĩrĩ, “Ihũrĩra andũ marĩe.” Na hakĩaga kĩndũ kĩngĩmathũkia irio-inĩ icio.
42 Ọkùnrin kan wá láti Baali-Ṣaliṣa, ó sì mú àkàrà àkọ́so èso, ogún ìṣù àkàrà barle, tí wọ́n dín láti ara àkọ́so èso àgbàdo, àti pẹ̀lú síírí ọkà tuntun nínú àpò rẹ̀ wá fún ènìyàn Ọlọ́run náà. Òun sì wí pé, “Fún àwọn ènìyàn láti jẹ.”
Na rĩrĩ, hagĩũka mũndũ oimĩte Baali-Shalisha, akĩrehera mũndũ wa Ngai mĩgate mĩrongo ĩĩrĩ ya cairi, ĩrĩa yarugĩtwo na maciaro ma mbere ma ngano, na igira cia ngano ya mũgethano. Nake Elisha akĩmwĩra atĩrĩ, “Mĩnengere andũ marĩe.”
43 “Báwo ni èmi yóò ṣe gbé èyí ka iwájú àwọn ọgọ́rùn-ún ènìyàn?” ìránṣẹ́ rẹ̀ béèrè. Ṣùgbọ́n Eliṣa dá a lóhùn pé, “Gbé e fún àwọn ènìyàn láti jẹ, nítorí èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Wọn yóò jẹ yóò sì tún ṣẹ́kù.’”
Nayo ndungata yake ĩkĩmũũria atĩrĩ, “Ndaahota atĩa kũhe andũ igana rĩmwe mĩgate ĩno?” No Elisha akĩmũcookeria atĩrĩ, “Mĩnengere andũ marĩe. Nĩgũkorwo Jehova ekuuga ũũ: ‘Mekũrĩa na matigie.’”
44 Nígbà náà ó gbé e ka iwájú wọn, wọ́n sì jẹ ẹ́, wọ́n sì ní èyí tó ṣẹ́kù, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
Nake akĩnengera andũ, makĩrĩa na ĩgĩtigara, kũringana na kiugo kĩa Jehova.

< 2 Kings 4 >